< 1 Samuel 10 >
1 Potem je Samuel vzel stekleničko olja in jo izlil na njegovo glavo ter ga poljubil in rekel: » Ali ni to zato, ker te je Gospod mazilil, da bi bil poveljnik nad njegovo dediščino?
Samuẹli sì mú ìgò kékeré tí òróró wà nínú rẹ̀, ó sì dà á sí orí Saulu. Ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu, wí pé, “Olúwa kò ha tí fi òróró yàn ọ ní olórí lórí ohun ìní rẹ̀?
2 Ko danes odideš od mene, potem boš našel dva moža ob Rahelinem mavzoleju, na meji Benjamina, ob Celcáhu; in rekla ti bosta: ›Oslice, ki si jih šel iskat, so najdene in glej, tvoj oče je zapustil skrb nad oslicami in se žalosti zaradi tebe, rekoč: ›Kaj naj storim za svojega sina?‹‹
Bí ìwọ bá kúrò lọ́dọ̀ mi lónìí, ìwọ yóò bá ọkùnrin méjì pàdé lẹ́bàá ibojì Rakeli ní Selsa, ní agbègbè Benjamini. Wọ́n yóò sọ fún ọ pé, ‘Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ìwọ jáde lọ láti wá ní wọn tí rí. Nísinsin yìí, baba à rẹ tí dákẹ́ kò ronú nípa wọn mọ́, ó sì ń dààmú nípa à rẹ. Ó ń béèrè, “Kí ni èmi yóò ṣe nípa ọmọ mi?”’
3 Potem boš šel naprej od tam in prišel boš do ravnine Tabor in tam boš srečal tri može, ki gredo gor k Bogu v Betel. Eden bo nosil tri kozličke, drugi bo nosil tri hlebe kruha in drugi bo nosil vinski meh.
“Nígbà náà, ìwọ yóò lọ láti ibẹ̀ títí yóò fi dé ibi igi ńlá Tabori. Ọkùnrin mẹ́ta tí wọ́n ń gòkè lọ sọ́dọ̀ Ọlọ́run ní Beteli yóò pàdé rẹ níbẹ̀. Ọ̀kan yóò mú ọmọ ewúrẹ́ mẹ́ta lọ́wọ́, èkejì, ìṣù àkàrà mẹ́ta àti ẹ̀kẹta yóò mú ìgò wáìnì.
4 Pozdravili te bodo in ti dali dva hleba kruha, ki ju boš sprejel iz njihovih rok.
Wọ́n yóò kí ọ, wọn yóò sì fún ọ ní ìṣù àkàrà méjì, tí ìwọ yóò gbà lọ́wọ́ wọn.
5 Potem boš prišel do Božjega hriba, kjer je garnizija Filistejcev in zgodilo se bo, ko prideš tja do mesta, da boš srečal skupino prerokov prihajati dol iz visokega kraja, s plunko, bobničem, piščaljo in harfo pred njimi, in oni bodo prerokovali.
“Lẹ́yìn náà, ìwọ yóò lọ sí òkè Ọlọ́run, níbi tí ẹgbẹ́ ogun àwọn Filistini wà. Bí ìwọ ti ń súnmọ́ ìlú náà, ìwọ yóò bá àwọn wòlíì tí ó tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́ bọ̀ láti ibi gíga, pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn, tambori àti fèrè àti haapu níwájú wọn, wọn yóò sì máa sọ àsọtẹ́lẹ̀.
6 Gospodov Duh bo prišel nadte in prerokoval boš z njimi in spremenjen boš v drugega človeka.
Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé ọ, ìwọ yóò sì sọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú wọn, ìwọ yóò sì di ẹni ọ̀tọ̀.
7 Naj bo, ko pridejo k tebi ta znamenja, da storiš, kakor se ti ponuja priložnost, kajti Bog je s teboj.
Bí ìwọ bá ti rí àmì wọ̀nyí, ṣe ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà láti ṣe, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.
8 Šel boš dol pred menoj v Gilgál, in glej, prišel bom dol k tebi, da darujem žgalne daritve in da žrtvujem žrtvovanje mirovnih daritev. Sedem dni boš čakal, dokler ne pridem k tebi in ti pokažem, kaj boš storil.«
“Lọ ṣáájú mi sí Gilgali. Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá láti rú ẹbọ sísun àti láti rú ẹbọ ìrẹ́pọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ dúró fún ọjọ́ méje títí èmi yóò fi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti sọ fún ọ ohun tí ó yẹ tí ìwọ yóò ṣe.”
9 Bilo je tako, da ko je obrnil hrbet, da bi odšel od Samuela, mu je Bog dal drugo srce in vsa ta znamenja so se zgodila tisti dan.
Bí Saulu ti yípadà láti fi Samuẹli sílẹ̀, Ọlọ́run yí ọkàn Saulu padà àti pé gbogbo àmì wọ̀nyí sì wá sí ìmúṣẹ ní ọjọ́ náà.
10 Ko so prišli tja do hriba, glej, ga je srečala skupina prerokov in Božji Duh je prišel nadenj in prerokoval je med njimi.
Nígbà tí wọ́n dé òkè Gibeah náà, àwọn wòlíì tí ó ń tò ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ pàdé rẹ̀, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e nínú agbára, ó sì darapọ̀ bá wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
11 Pripetilo se je, ko so vsi, ki so ga poznali od prej, videli, da je, glej, prerokoval med preroki, potem je ljudstvo reklo drug drugemu: »Kaj je to, kar je prišlo h Kiševemu sinu? Ali je tudi Savel med preroki?«
Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó ti mọ̀ ọ́n tẹ́lẹ̀ rí i tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú àwọn wòlíì, wọ́n bi ara wọn, “Kí ni ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí ọmọ Kiṣi yìí. Ṣé Saulu wà lára àwọn wòlíì ni?”
12 Nekdo iz istega kraja je odgovoril in rekel: »Toda kdo je njihov oče?« Zato je postal pregovor: »Ali je tudi Savel med preroki?«
Ọkùnrin kan tí ó ń gbé níbẹ̀ dáhùn pé, “Ta ni baba wọn?” Ó ti di ohun tí a fi ń pa òwe pé, ǹjẹ́ Saulu náà wà lára àwọn wòlíì bí?
13 Ko je nehal prerokovati, je prišel na visok kraj.
Lẹ́yìn tí Saulu dákẹ́ sísọ àsọtẹ́lẹ̀, ó lọ sí ibi gíga.
14 Savlov stric je rekel njemu in njegovemu služabniku: »Kam sta odšla?« Rekel je: »Iskat oslice. Ko pa sva videla, da jih ni bilo nikjer, sva šla k Samuelu.«
Nísinsin yìí, arákùnrin baba Saulu béèrè lọ́wọ́ Saulu àti ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Níbo ni ẹ lọ?” Ó wí pé, “À ń wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,” ṣùgbọ́n nígbà tí a kò rí wọn, a lọ sí ọ̀dọ̀ Samuẹli.
15 Savlov stric je rekel: »Povej mi, prosim te, kaj ti je Samuel rekel.«
Arákùnrin baba Saulu wí pé, “Sọ fún mi ohun tí Samuẹli wí fún un yín.”
16 Savel je svojemu stricu rekel: »Pojasnil nama je, da so bile oslice najdene.« Toda o zadevi kraljestva, o kateri je govoril Samuel, mu ni povedal.
Saulu dáhùn pé, “Ó fi dá wa lójú pé wọ́n ti rí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún arákùnrin baba a rẹ̀ ohun tí Samuẹli sọ nípa ọba jíjẹ.
17 Samuel je skupaj sklical ljudstvo h Gospodu v Micpo
Samuẹli pé àwọn ọmọ Israẹli jọ sí iwájú Olúwa ní Mispa.
18 in Izraelovim otrokom rekel: »Tako govori Gospod, Izraelov Bog: ›Izraela sem privedel iz Egipta in vas osvobodil iz roke Egipčanov in iz roke vseh kraljestev in od teh, ki so vas zatirali, ‹
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Èmi mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, Èmi sì gbà yín kúrò lọ́wọ́ agbára Ejibiti àti gbogbo ìjọba tí ó ń pọ́n ọn yín lójú.’
19 vi pa ste ta dan zavrnili svojega Boga, ki vas je sam rešil vseh vaših nasprotnikov in vaših stisk in ste mu rekli: › Ne, temveč nad nami postavi kralja.‹ Sedaj se torej predstavite pred Gospodom po vaših rodovih in po vaših tisočih.«
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti kọ Ọlọ́run yín, tí ó gbà yín kúrò nínú gbogbo wàhálà àti ìpọ́njú yín. Ẹ̀yin sì ti sọ pé, ‘Rárá, yan ọba kan fún wa.’ Báyìí, ẹ kó ara yín jọ níwájú Olúwa ní ẹ̀yà àti ìdílé yín.”
20 Ko je Samuel vsem Izraelovim rodovom velel, da se približajo, je bil izbran Benjaminov rod.
Nígbà tí Samuẹli mú gbogbo ẹ̀yà Israẹli súnmọ́ tòsí, ó yan ẹ̀yà Benjamini.
21 Ko je Benjaminovemu rodu velel, da pride bliže po svojih družinah, je bila izbrana Matríjeva družina in izbran je bil Kišev sin Savel. Ko pa so ga iskali, ga niso mogli najti.
Ó kó ẹ̀yà Benjamini síwájú ní ìdílé ìdílé, a sì yan ìdílé Matiri. Ní ìparí a sì yan Saulu ọmọ Kiṣi. Ṣùgbọ́n ní ìgbà tí wọ́n wá a, a kò rí i,
22 Zato so naprej povpraševali od Gospoda, ali bi mož še moral priti tja. Gospod je odgovoril: »Glejte, skril se je med stvari.«
bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Olúwa pé, “Ṣé ọkùnrin náà ti wá sí bí ni?” Olúwa sì sọ pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ láàrín àwọn ẹrù.”
23 Stekli so in ga vzeli od tam. Ko je stal med ljudstvom, je bil višji kakor katerikoli izmed ljudstva, od njegovih ramen navzgor.
Wọ́n sáré, wọ́n sì mú un jáde wá. Bí ó ti dúró láàrín àwọn ènìyàn, ó sì ga ju gbogbo àwọn tí ó kù lọ láti èjìká rẹ̀ sókè.
24 Samuel je vsemu ljudstvu rekel: »Vidite koga je Gospod izbral, da tu ni podobnega njemu izmed vsega ljudstva?« Vse ljudstvo je zavpilo in reklo: »Živel kralj.«
Samuẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ṣé ẹ ti ri ọkùnrin tí Olúwa ti yàn? Kò sí ẹnìkan bí i rẹ̀ láàrín gbogbo àwọn ènìyàn.” Nígbà náà àwọn ènìyàn kígbe pé, “Kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn!”
25 Potem je Samuel ljudstvu povedal o načinu kraljestva in to zapisal v knjigo ter jo položil pred Gospoda. In Samuel je vse ljudstvo poslal proč, vsakega k svoji hiši.
Samuẹli ṣàlàyé fún àwọn ènìyàn àwọn ìlànà ìjọba. Ó kọ wọ́n sínú ìwé, ó sì fi lélẹ̀ níwájú Olúwa. Lẹ́yìn náà, Samuẹli tú àwọn ènìyàn ká olúkúlùkù sí ilé e rẹ̀.
26 Tudi Savel je odšel domov v Gíbeo in z njim je šla četa mož, čigar src se je Bog dotaknil.
Saulu náà padà sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah. Àwọn akọni ọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi ọwọ́ tọ́ ọkàn wọ́n sì sìn ín.
27 Toda Beliálovi otroci so rekli: »Kako nas bo ta človek rešil?« Prezirali so ga in mu niso prinesli daril. Toda on je ohranil svoj mir.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Beliali wí pé, “Báwo ni ọkùnrin yìí yóò ti ṣe gbà wá?” Wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọn kò sì mú ẹ̀bùn wá fún un, ṣùgbọ́n Saulu fọwọ́ lérán.