< 1 Kralji 5 >

1 Tirski kralj Hirám je svoje služabnike poslal k Salomonu, kajti slišal je, da so ga mazilili [za] kralja namesto njegovega očeta, kajti Hirám je bil vedno Davidov oboževalec.
Nígbà tí Hiramu ọba Tire sì gbọ́ pé, a ti fi òróró yan Solomoni ní ọba ní ipò Dafidi baba rẹ̀, ó sì rán àwọn ikọ̀ rẹ̀ sí Solomoni, nítorí ó ti fẹ́ràn Dafidi ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
2 Salomon je poslal k Hirámu, rekoč:
Solomoni sì ránṣẹ́ yìí padà sí Hiramu pé,
3 »Ti veš, da moj oče David ni mogel zgraditi hiše imenu Gospoda, svojega Boga, zaradi vojn, ki so bile okoli njega na vsaki strani, dokler jih ni Gospod položil pod podplate njegovih stopal.
“Ìwọ mọ̀ pé Dafidi baba mi kò le kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, nítorí ogun tí ó wà yí i káàkiri, títí Olúwa fi fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sábẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
4 Toda sedaj mi je Gospod, moj Bog, dal počitek na vsaki strani, tako da ni niti nasprotnika niti zlih dogodkov.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run mi ti fún mi ní ìsinmi ní ibi gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni kò sì sí ọ̀tá tàbí ìjàǹbá kan tí ó ṣe.
5 Glej, namenil sem se zgraditi hišo imenu Gospoda, svojega Boga, kakor je Gospod spregovoril mojemu očetu Davidu, rekoč: ›Tvoj sin, ki ga bom namesto tebe postavil na tvoj prestol, on bo zgradil hišo mojemu imenu.
Nítorí náà mo gbèrò láti kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run mi, bí Olúwa ti sọ fún Dafidi baba mi, nígbà tí ó wí pé, ‘Ọmọ rẹ tí èmi yóò gbé ka orí ìtẹ́ rẹ ní ipò rẹ ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
6 Zdaj torej zapovej, da mi iz Libanona posekajo cedrova drevesa in moji služabniki bodo s tvojimi služabniki in dal ti bom plačilo za tvoje služabnike, glede na vse, kar mi boš določil; kajti veš, da med nami ni nobenega, ki tako vešče seka les kot Sidónci.‹«
“Nítorí náà ni kí o pàṣẹ pé kí wọn kí ó gé igi kedari Lebanoni fún mi wá. Àwọn ènìyàn mi yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú tìrẹ, Èmi yóò sì san owó ọ̀yà tí ìwọ bá ránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn rẹ. Ìwọ mọ̀ pé, a kò ní ẹnìkan nínú wa tí ó mọ bí a ti ń gé igi bí àwọn ará Sidoni.”
7 Ko je Hirám slišal Salomonove besede, se je pripetilo, da se je silno razveselil in rekel: »Blagoslovljen bodi ta dan Gospod, ki je Davidu dal modrega sina nad tem velikim ljudstvom.«
Nígbà tí Hiramu sì gbọ́ iṣẹ́ Solomoni, inú rẹ̀ sì dùn gidigidi, ó sì wí pé, “Ògo ni fún Olúwa lónìí, nítorí tí ó ti fún Dafidi ní ọlọ́gbọ́n ọmọ láti ṣàkóso àwọn ìlú ńlá yìí.”
8 In Hirám je poslal k Salomonu, rekoč: »Preudaril sem stvari, zaradi katerih pošiljaš k meni in izpolnil bom vso tvojo željo glede cedrovega lesa in glede cipresovega lesa.
Hiramu sì ránṣẹ́ sí Solomoni pé, “Èmi ti gbọ́ iṣẹ́ tí ìwọ rán sí mi, èmi yóò sì ṣe gbogbo èyí tí o fẹ́ ní pípèsè igi kedari àti ní ti igi firi.
9 Moji služabniki ga bodo spravljali dol iz Libanona do morja in po morju ga bom spravljal v splavih na mesto, ki mi ga boš določil in povzročim jim, da bodo tam razvezani in jih boš sprejel, ti pa boš izpolnil mojo željo, da mi daješ hrano za mojo družino.«
Àwọn ènìyàn mi yóò mú igi náà sọ̀kalẹ̀ láti Lebanoni wá sí Òkun, èmi ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí ọ ní fífò lójú omi Òkun Ńlá títí dé ibi tí ìwọ ó na ìka sí fún mi. Níbẹ̀ ni èmi yóò ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ìwọ yóò sì kó wọn lọ. Ìwọ yóò sì gba ìfẹ́ mi nípa pípèsè oúnjẹ fún ilé mi.”
10 Tako je Hirám dajal Salomonu cedrov les in cipresov les glede na vse njegove želje.
Báyìí ni Hiramu sì pèsè igi kedari àti igi firi tí Solomoni ń fẹ́ fún un,
11 Salomon je dajal Hirámu dvajset tisoč mer pšenice za hrano njegovi družini in dvajset mer čistega olja. Tako je Salomon dajal Hirámu leto za letom.
Solomoni sì fún Hiramu ní ogún ẹgbẹ̀rún òsùwọ̀n ọkà oúnjẹ fún ilé rẹ̀, àti ogún òsùwọ̀n òróró dáradára. Solomoni sì ń tẹ̀síwájú láti ṣe èyí fún Hiramu lọ́dọọdún.
12 Gospod je dal Salomonu modrost, kakor mu je obljubil in bil je mir med Hirámom in Salomonom in onadva sta sklenila zavezo.
Olúwa sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún un. Ìrẹ́pọ̀ àlàáfíà sì wà láàrín Hiramu àti Solomoni, àwọn méjèèjì sì ṣe àdéhùn.
13 Kralj Salomon je zbral dajatev obveznega dela iz vsega Izraela, in dajatev obveznega dela je bila trideset tisoč mož.
Solomoni ọba sì ṣa asìnrú ènìyàn jọ ní gbogbo Israẹli; àwọn tí ń sìnrú náà jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ènìyàn.
14 Pošiljal jih je k Libanonu, deset tisoč na mesec, v izmenah. En mesec so bili na Libanonu in dva meseca doma. Adonirám pa je bil nad dajatvijo obveznega dela.
Ó sì rán wọn lọ sí Lebanoni, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá lóṣooṣù, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n lo oṣù kan ní Lebanoni, wọn a sì gbé ilé ní oṣù méjì. Adoniramu ni ó ṣe olórí àwọn asìnrú náà.
15 Salomon jih je imel sedemdeset tisoč, ki so nosili bremena in osemdeset tisoč sekalcev v gorah,
Solomoni sì ní ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn tí ń ru ẹrù àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin gbẹ́nàgbẹ́nà lórí òkè,
16 poleg glavnih Salomonovih častnikov, ki so bili nad delom, tri tisoč tristo, ki so vladali nad ljudstvom, ki je opravljalo delo.
àti àwọn ìjòyè nínú àwọn tí a fi ṣe olórí iṣẹ́ Solomoni jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún ó lé ọgọ́rùn-ún ènìyàn, tí ó ń ṣe aláṣẹ àwọn ènìyàn tí ń ṣiṣẹ́ náà.
17 Kralj je zapovedal in prinesli so velike kamne, drage kamne, klesane kamne, da hiši položijo temelj.
Ọba sì pàṣẹ, wọ́n sì mú òkúta wá, òkúta iyebíye, àti òkúta gbígbẹ́ láti fi ìpìlẹ̀ ilé náà lé ilẹ̀.
18 Salomonovi graditelji, Hirámovi graditelji in kamnoseki so jih klesali. Tako so pripravili les in kamne, da zgradijo hišo.
Àwọn oníṣọ̀nà Solomoni àti Hiramu àti àwọn òṣìṣẹ́ láti Gebali sì gbẹ́ wọn, wọ́n sì pèsè igi àti òkúta láti fi kọ́ ilé náà.

< 1 Kralji 5 >