< Књига пророка Захарије 5 >
1 Потом опет подигох очи своје и видех; а то књига лећаше.
Nígbà náà ni mo yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ìwé kíká ti ń fò.
2 И он ми рече: Шта видиш? А ја рекох: Видим књигу где лети, дужина јој двадесет лаката, а ширина десет лаката.
Ó sì wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ rí?” Èmi sì dáhùn pé, “Mo rí ìwé kíká tí ń fò; gígùn rẹ̀ jẹ́ ogún ìgbọ̀nwọ́, ìbú rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá.”
3 Тада ми рече: То је проклетство које изађе на сву земљу, јер сваки који краде истребиће се по њој с једне стране, и који се год куне криво истребиће се по њој с друге стране.
Ó sì wí fún mi pé, “Èyí ni ègún tí ó jáde lọ sí gbogbo ilẹ̀ ayé, nítorí gbogbo àwọn tí ó bá jalè ni a ó ké kúrò láti ìhín lọ nípa rẹ̀; gbogbo àwọn tí ó bá sì búra èké ni a ó ké kúrò láti ìhín lọ nípa rẹ̀.
4 Ја ћу је пустити, говори Господ над војскама, те ће доћи на кућу лупежу и на кућу ономе који се куне мојим именом криво, и стајаће му усред куће и сатрће је, и дрвље јој и камење.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò mú un jáde, Èmi yóò si wọ inú ilé olè lọ, àti inú ilé ẹni ti o bá fi orúkọ mi búra èké, yóò si wà ni àárín ilé rẹ̀, yóò si rún pẹ̀lú igi àti òkúta inú rẹ̀.’”
5 Потом изиђе анђео који говораше са мном, и рече ми: Подигни очи своје и види шта је ово што излази.
Angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ sì jáde lọ, ó sì wí fún mi pé, “Gbé ojú rẹ sókè nísinsin yìí, kí o sì wo nǹkan tí yóò jáde lọ.”
6 А ја рекох: Шта је? А он рече: То је ефа што излази. И рече: То им је безбожност по свој земљи.
Mo sì wí pé, “Kí ni nǹkan náà?” Ó sì wí pé, “Èyí ni òsùwọ̀n tí ó jáde lọ.” Ó sì wí pé, “Èyí ni àwòrán ní gbogbo ilẹ̀ ayé.”
7 И гле, подизаше се таланат олова, и једна жена сеђаше усред ефе.
Sì kíyèsi i, a gbé tálẹ́ǹtì òjé sókè, obìnrin kan sì nìyìí tí ó jókòó sí àárín àpẹẹrẹ òsùwọ̀n.
8 И он рече: То је безбожност. И врже је усред ефе, и врже онај комад олова одозго на ждрело јој.
Ó sì wí pé, “Èyí ni ìwà búburú.” Ó sì ti sí àárín òsùwọ̀n, ó sì ju ìdérí òjé sí ẹnu rẹ̀.
9 И подигох очи своје и видех, а то две жене излажаху, и ветар им беше под крилима, а крила им беху као у роде, и дигоше ефу међу земљу и небо.
Mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, obìnrin méjì jáde wá, ẹ̀fúùfù sì wá nínú ìyẹ́ wọn; nítorí wọ́n ní ìyẹ́ bí ìyẹ́ àkọ̀, wọ́n sì gbé àpẹẹrẹ òsùwọ̀n náà dé àárín méjì ayé àti ọ̀run.
10 И рекох анђелу који говораше са мном: Куда оне носе ефу?
Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Níbo ni àwọn wọ̀nyí ń gbé òsùwọ̀n náà lọ.”
11 А он ми рече: Да јој начине кућу у земљи Сенару; и онде ће се наместити и поставити на своје подножје.
Ó si wí fún mi pé, “Sí orílẹ̀-èdè Babeli láti kọ ilé fún un. Tí ó bá ṣetán, a ó sì fi ìdí rẹ̀ mulẹ̀, a o sì fi ka orí ìpìlẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.”