< Псалми 19 >
1 Небеса казују славу Божју, и дела руку Његових гласи свод небески.
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Àwọn ọ̀run ń sọ nípa ti ògo Ọlọ́run; àwọsánmọ̀ ń sọ nípa ti iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.
2 Дан дану доказује, и ноћ ноћи јавља.
Wọ́n ń fọhùn ní ọjọ́ dé ọjọ́; wọ́n ń fi ìmọ̀ hàn ní alẹ́ dé alẹ́.
3 Нема језика, нити има говора, где се не би чуо глас њихов.
Kò sí ohùn tàbí èdè níbi tí a kò gbé gbọ́ ìró wọn.
4 По свој земљи иде казивање њихово и речи њихове на крај васиљене. Сунцу је поставио стан на њима;
Ohùn wọn jáde lọ sí gbogbo orílẹ̀ ayé, ọ̀rọ̀ wọn títí dé òpin ilẹ̀ ayé. Ó ti kọ́ àgọ́ fún oòrùn nínú àwọn ọ̀run.
5 И оно излази као женик из ложнице своје, као јунак весело тече путем.
Tí ó dàbí ọkọ ìyàwó tí ó ń jáde ti yàrá rẹ̀ wá, òun yọ bí alágbára ọkùnrin tí ó ń sáré ìje.
6 Излазак му је накрај неба, и ход му до краја његовог; и нико није сакривен од топлоте његове.
Ìjáde lọ rẹ̀ ni láti òpin ọ̀run wá àti àyíká rẹ̀ sì dé ìpínlẹ̀ rẹ̀; kò sì sí ohun tí ó pamọ́ kúrò nínú oore rẹ̀.
7 Закон је Господњи савршен, крепи душу; сведочанство је Господње верно, даје мудрост невештоме.
Pípé ni òfin Olúwa, ó ń yí ọkàn padà. Ẹ̀rí Olúwa dánilójú, ó sọ òpè di ọlọ́gbọ́n.
8 Наредбе су Господње праведне, веселе срце. Заповест је Господња светла, просветљује очи.
Ìlànà Olúwa tọ̀nà, ó ń fi ayọ̀ fún ọkàn. Àṣẹ Olúwa ni mímọ́, ó ń fi ìmọ́lẹ̀ fún ojú.
9 Страх је Господњи чист, остаје довека. Судови су Његови истинити, праведни свиколики.
Ìbẹ̀rù Olúwa mọ́, ó ń faradà títí láéláé. Ìdájọ́ Olúwa dájú òdodo ni gbogbo wọn.
10 Бољи су од злата и драгог камења, слађи од меда који тече из саћа.
Wọn ṣọ̀wọ́n ju wúrà lọ, ju wúrà tí o dára jùlọ, wọ́n dùn ju oyin lọ, àti ju afárá oyin lọ.
11 И слугу Твог они су просветлили; ко их држи има велику плату.
Nípa wọn ni a ti ṣí ìránṣẹ́ rẹ̀ létí; nípa pípa wọ́n mọ́, èrè púpọ̀ ń bẹ.
12 Ко ће знати све своје погрешке? Очисти ме и од тајних;
Ta ni ó lè mọ àṣìṣe rẹ̀? Dáríjì mí nínú àṣìṣe mi tí ó pamọ́.
13 И од вољних сачувај слугу свог, да не овладају мноме. Тада ћу бити савршен и чист од великог преступа.
Wẹ ìránṣẹ́ rẹ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àmọ̀ọ́n-mọ̀-dá; má ṣe jẹ kí wọn kí ó jẹ ọba lórí mi. Nígbà náà ní èmi yóò dúró ṣinṣin, èmi yóò sì ṣe aláìlẹ́bi kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.
14 Да су Му речи уста мојих угодне, и помисао срца мог пред Тобом, Господе, крепости моја и Избавитељу мој!
Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹnu mi àti àṣàrò ọkàn mi kí ó jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní ojú rẹ, Ìwọ Olúwa àpáta mi, àti Olùdáǹdè mi.