< 4 Мојсијева 27 >
1 Тада дођоше кћери Салпада, сина Офера сина Галада сина Махира сина Манасијиног, од племена Манасије сина Јосифовог, а имена им беху Мала, Нуја, Егла, Мелха и Терса.
Ọmọbìnrin Selofehadi ọmọ Heferi, ọmọ Gileadi, ọmọ Makiri ọmọ Manase tó jẹ́ ìdílé Manase, ọmọ Josẹfu wá. Orúkọ àwọn ọmọbìnrin náà ni Mahila, Noa, Hogla, Milka àti Tirsa.
2 И стадоше пред Мојсија и пред Елеазара свештеника и пед кнезове и сав збор на вратима шатора од састанка, и рекоше:
Wọ́n súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé wọ́n sì dúró níwájú Mose, àti Eleasari àlùfáà, àti níwájú àwọn olórí àti ìjọ, wọ́n sì wí pé,
3 Отац наш умре у пустињи, али не беше у друштву с онима који се побунише на Господа у буни Корејевој, него умре од греха свог, а не остави синове.
“Baba wa kú sí aginjù. Kò sí lára àwọn ẹgbẹ́ Kora tí wọ́n kó ara wọn pọ̀ lòdì sí Olúwa, ṣùgbọ́n ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kò sì fi ọmọkùnrin sílẹ̀.
4 Зашто да се истреби име оца нашег из породице његове зато што није имао сина? Дај нам наследство међу браћом оца нашег.
Kín ni ó dé tí orúkọ baba wa yóò parẹ́ nínú ìdílé rẹ̀ nítorí pé kò ní ọmọkùnrin? Fún wa ní ilẹ̀ ìní láàrín àwọn arákùnrin baba wa.”
5 И изнесе Мојсије ствар њихову пред Господа.
Nígbà náà Mose mú ọ̀rọ̀ wọn wá síwájú Olúwa.
6 А Господ рече Мојсију говорећи:
Olúwa sì wí fún un pé,
7 Право говоре, кћери Салпадове; подај им право да имају наследство међу браћом оца свог, и принеси наследство оца њиховог на њих.
“Ohun tí àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ń sọ tọ̀nà. O gbọdọ̀ fún wọn ní ogún ìní ti baba wọn.
8 А синовима Израиљевим кажи и реци: Кад ко умре, а нема сина, онда пренесите наследство његово на кћер његову;
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Tí ọkùnrin kan bá kú tí kò sì fi ọmọkùnrin sáyé, ẹ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀.
9 Ако ли ни кћери нема, онда подајте наследство његово браћи његовој;
Tí kò bá ní ọmọbìnrin, fi ohun ìní rẹ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
10 Ако ли ни браће нема, онда подајте наследство његово браћи оца његовог;
Tí kò bá ní arákùnrin, fi ogún ìní rẹ̀ fún arákùnrin baba rẹ̀.
11 Ако ли нема ни браћу очеву, онда подајте наследство његово ономе ко му је најближи у роду његовом, и нека је његово. И то нека буде синовима Израиљевим закон за суђење, како заповеди Господ Мојсију.
Tí baba rẹ̀ kò bá ní arákùnrin, fún ará ilé rẹ̀ tí ó bá súnmọ́ jù ní ìdílé rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀, kí ó lè jogún rẹ̀. Èyí gbọdọ̀ jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.’”
12 Још рече Господ Мојсију: Изиђи на гору ову аваримску, и види земљу коју сам дао синовима Израиљевим.
Nígbà náà Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sì orí òkè Abarimu yìí, kí o sì lọ wo ilẹ̀ tí mo fún àwọn ọmọ Israẹli.
13 И кад је видиш, прибраћеш се к роду свом и ти, као што се прибрао Арон, брат твој.
Lẹ́yìn ìgbà tí o bá sì ti rí i, ìwọ náà yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ gẹ́gẹ́ bí Aaroni arákùnrin rẹ ṣe ṣe,
14 Јер не послушасте речи моје у пустињи Сину у свађи народној, кад је требало да ме прославите на води пред очима њиховим. То је вода од свађе у Кадису у пустињи Сину.
nítorí nígbà tí ìlú ṣọ̀tẹ̀ níbi omi ní aginjù Sini, tí gbogbo yín ṣe àìgbọ́ràn sí mi láti yà mí sí mímọ́ níwájú wọn.” (Èyí ni omi Meriba ní Kadeṣi ní aginjù Sini.)
15 И рече Мојсије Господу говорећи:
Mose sọ fún Olúwa wí pé,
16 Господе Боже духовима и сваком телу, постави човека над овим збором,
“Jẹ́ kí Olúwa, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, kí ó yan ọkùnrin kan sí orí ìjọ ènìyàn yìí,
17 Који ће излазити пред њима и који ће долазити пред њима, који ће их изводити и опет доводити, да не би био збор Господњи као овце које немају пастира.
láti máa darí wọn, ẹni tí yóò mú wọn jáde, tí yóò sì mú wọn wọlé, gbogbo ènìyàn Olúwa kí yóò dàbí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́.”
18 А Господ рече Мојсију: Узми к себи Исуса сина Навиног, човека у коме је дух мој, и метни руку своју на њ,
Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú Joṣua ọmọ Nuni, ọkùnrin nínú ẹni tí èmi wà, kí o sì gbé ọwọ́ rẹ lé e.
19 И изведи га пред Елеазара свештеника и пред сав збор, и подај му заповести пред њима.
Jẹ́ kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti ojú gbogbo àwọn ìjọ ènìyàn Israẹli kí o sì fi àṣẹ fún un ní ojú wọn.
20 И подај му од славе своје, да га слуша сав збор синова Израиљевих.
Kí ìwọ kí ó sì fi nínú ọláńlá rẹ sí i lára, kí gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kí ó lè gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu.
21 И нека стаје пред Елеазара свештеника да га пита за суд Урим пред Господом; по заповести Његовој нека полазе и по заповести Његовој нека долазе он и сви синови Израиљеви с њим и сав збор.
Kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà, tí yóò gba ìpinnu fún láti béèrè Urimu níwájú Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí òfin yìí ni òun pẹ̀lú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò jáde lọ, pẹ̀lú òfin rẹ̀ sì ni wọn ó wọlé.”
22 И учини Мојсије како му заповеди Господ; и узевши Исуса постави га пред Елеазара свештеника и пред сав збор.
Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó mú Joṣua ó sì mú kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti níwájú gbogbo ìjọ.
23 И метну руке своје на њ, и даде му заповести, како беше заповедио Господ преко Мојсија.
Nígbà náà ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ le e, ó sì fi àṣẹ fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.