< Плач Јеремијин 3 >

1 Ја сам човек који видех муку од прута гнева Његовог.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 Одведе ме и оправи ме у таму, а не на видело.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 Само се на ме обраћа, обраћа руку своју по вас дан.
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 Учини, те ми остаре тело и кожа, потре кости моје.
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 Зазида ме, и опточи ме жучју и муком.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 Посади ме у таму као умрле одавна.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 Огради ме да не изађем, и метну на ме тешке окове.
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 Кад вичем и вапим, одбија молитву моју.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 Загради путеве моје тесаним каменом, и преврати стазе моје.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 Поста ми као медвед у заседи, као лав у потаји.
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 Помете путеве моје, и раздре ме, и уништи ме.
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 Натеже лук свој, и метну ме стрели за белегу.
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 Устрели ме у бубреге стрелама из тула свог.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 Постах подсмех свему народу свом и песма њихова по вас дан.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 Насити ме горчином, опоји ме пеленом.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 Поломи ми зубе камењем, ували ме у пепео.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 Удаљио си душу моју од мира, заборавих добро.
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 И рекох: Пропаде сила моја и надање моје од Господа.
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Опомени се муке моје и јада мог, пелена и жучи.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 Душа се моја опомиње без престанка, и поништила се у мени.
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 Али ово напомињем срцу свом, те се надам:
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 Милост је Господња што не изгибосмо сасвим, јер милосрђа Његовог није нестало.
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 Понавља се свако јутро; велика је вера твоја.
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 Господ је део мој, говори душа моја; зато ћу се у Њега уздати.
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 Добар је Господ онима који га чекају, души, која га тражи.
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 Добро је мирно чекати спасење Господње.
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 Добро је човеку носити јарам за младости своје.
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 Сам ће седети и ћутати, јер Бог метну бреме на њ.
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Метнуће уста своја у прах, еда би било надања.
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 Подметнуће образ свој ономе који га бије, биће сит срамоте.
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 Јер Господ не одбацује за свагда.
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 Јер ако и уцвели, опет ће се и смиловати ради мноштва милости своје.
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 Јер не мучи из срца свог ни цвели синове човечје.
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 Кад газе ногама све сужње на земљи,
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 Кад изврћу правицу човеку пред Вишњим,
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 Кад чине криво човеку у парници његовој, не види ли Господ?
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 Ко је рекао што и збило се, а Господ да није заповедио?
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 Не долазе ли и зла и добра из уста Вишњег?
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 Зашто се тужи човек жив, човек на кар за грехе своје?
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Претражимо и разгледајмо путе своје, и повратимо се ка Господу.
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Подигнимо срце своје и руке к Богу на небесима.
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 Згрешисмо и непокорни бисмо; Ти не прашташ.
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 Обастро си се гневом, и гониш нас, убијаш и не жалиш.
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 Обастро си си се облаком да не продре молитва.
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 Начинио си од нас сметлиште и одмет усред тих народа.
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 Разваљују уста своја на нас сви непријатељи наши.
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 Страх и јама задеси нас, пустошење и затирање.
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 Потоци теку из очију мојих ради погибли кћери народа мог.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 Очи моје лију сузе без престанка, јер нема одмора,
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 Докле Господ не погледа и не види с неба.
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 Око моје мучи ми душу ради свих кћери града мог.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 Терају ме једнако као птицу непријатељи моји низашта.
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 Свалише у јаму живот мој и набацаше камење на ме.
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 Дође ми вода сврх главе; рекох: Погибох!
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 Призивах име Твоје, Господе, из јаме најдубље.
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 Ти чу глас мој; не затискуј уха свог од уздисања мог, од вике моје.
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 Приступао си кад Те призивах, и говорио си: Не бој се.
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 Расправљао си, Господе, парбу душе моје, и избављао си живот мој.
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 Видиш, Господе, неправду која ми се чини; расправи парбу моју.
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 Видиш сву освету њихову, све што ми мисле.
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 Чујеш руг њихов, Господе, све што ми мисле,
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 Шта говоре они који устају на ме и шта намишљају против мене по вас дан.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Види, кад седају и кад устају, ја сам им песма.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 Плати им, Господе, по делима руку њихових.
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 Подај им упорно срце, проклетство своје.
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 Гони их гневом, и истреби их испод небеса Господњих.
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.

< Плач Јеремијин 3 >