< Књига Исуса Навина 20 >

1 Потом рече Господ Исусу говорећи:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé,
2 Кажи синовима Израиљевим и реци: Одредите градове за уточишта, за које сам вам говорио преко Мојсија,
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn yan àwọn ìlú ààbò, gẹ́gẹ́ bí mo ti pàṣẹ fún ọ láti ẹnu Mose,
3 Да онамо утече крвник који убије кога нехотице, не мислећи, да вам буду уточишта од осветника.
kí ẹni tí ó bá ṣèèṣì pa ènìyàn tàbí tí ó bá pa ènìyàn láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ lè sálọ sí ibẹ̀, fún ààbò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó pa.
4 Па кад ко утече у који од тих градова, нека стане пред вратима градским и нека каже старешинама оног града ствар своју, па нека га приме к себи, и дају му место да седи код њих.
Nígbà tí ó bá sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí, yóò sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àtiwọ ibodè ìlú, kí ó sì ṣe àlàyé ara rẹ̀ ní iwájú àwọn àgbàgbà ìlú náà. Nígbà náà ni wọn yóò gbà á sí ìlú wọn, wọn yóò sì fun ní ibùgbé láàrín wọn.
5 И ако дође за њим осветник, нека му не дају крвника у руке, јер је нехотице убио ближњег нити је пре мрзео на њега.
Bí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ bá ń lépa rẹ̀, wọn kò gbọdọ̀ fi àwọn ọ̀daràn náà lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ láìmọ̀, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
6 Него нека седи у граду оном докле не стане пред збор на суд, до смрти поглавара свештеничког који буде онда, тада нека се крвник врати и иде у свој град и својој кући, у град из ког је утекао.
Òun ó sì máa gbé inú ìlú náà, títí yóò fi jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn àti títí ikú olórí àlùfáà tí ó ń ṣiṣẹ́ ìsìn nígbà náà. Nígbà náà ó lè padà sí ilé rẹ̀ ní ìlú tí ó ti sá wá.”
7 И оделише Кедес у Галилеји у гори Нефталимовој и Сихем у гори Јефремовој и Киријат-Арву, то је Хеврон, у гори Јудиној.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan Kedeṣi ní Galili ní ìlú òkè Naftali, Ṣekemu ní ìlú òkè Efraimu, àti Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) ní ìlú òkè Juda.
8 А преко Јордана од Јерихона на исток одредише Восор у пустињи, у равни, од племена Рувимовог, и Рамот у Галаду од племена Гадовог, и Голан у Васану од племена Манасијиног.
Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani ti Jeriko, wọ́n ya Beseri ní aginjù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ẹ̀yà Reubeni, Ramoti ní Gileadi ní ẹ̀yà Gadi, àti Golani ní Baṣani ní ẹ̀yà Manase.
9 То су градови одређени свим синовима Израиљевим и дошљаку који живи међу њима, да побегне код њих ко год убије кога нехотице и да не погине од руке осветникове док не стане пред збор.
Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé ní àárín wọn tí ó ṣèèṣì pa ẹnìkan lè sálọ sí àwọn ìlú tí a yà sọ́tọ̀ wọ̀nyí, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má sì ṣe pa á kí ó to di àkókò tí yóò jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn.

< Књига Исуса Навина 20 >