< Књига о Јову 40 >
1 И тако одговарајући Господ Јову рече:
Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
2 Ко се препире с Богом, хоће ли га учити? Који куди Бога, нека одговори на то.
“Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
3 Тада Јов одговори Господу и рече:
Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
4 Гле, ја сам мален, шта бих Ти одговорио? Мећем руку своју на уста своја.
“Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
5 Једном говорих, али нећу одговарати; и другом, али нећу више.
Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
6 А Господ опет одговарајући Јову из вихора рече:
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
7 Опаши се сада као човек; ја ћу те питати, а ти ми казуј.
“Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
8 Хоћеш ли ти уништити мој суд? Хоћеш ли мене осудити да би себе оправдао?
“Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
9 Је ли у тебе мишица као у Бога? Грмиш ли гласом као Он?
Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
10 Окити се сада чашћу и величанством, у славу и красоту обуци се.
Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
11 Проспи јарост гнева свог, и погледај све поносите, и обори их.
Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
12 Погледај све поносите, и понизи их, и потри безбожнике на месту њиховом.
Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
13 Затрпај их све у прах, и повежи им лице на скривеном месту.
Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
14 Тада ћу те и ја хвалити да те чува десница твоја.
Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
15 А гле, слон, ког сам створио с тобом, једе траву као во;
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
16 Гле, снага му је у бедрима његовим, и сила му је у пупку трбуха његовог;
Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
17 Диже реп свој као кедар, жиле од јаја његових сплетене су као гране;
Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
18 Кости су му као цеви бронзане, зглавци као полуге гвоздене.
Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
19 Он је прво између дела Божијих, Творац његов дао му је мач.
Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 Горе носе му пићу, и све зверје пољско игра се онде.
Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
21 У хладу леже, у густој трсци и глибу.
Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
22 Граната дрвета заклањају га сеном својим, и опкољавају га врбе на потоцима.
Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
23 Гле, уставља реку да не тече, узда се да ће испити Јордан губицом својом.
Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
24 Хоће ли га ко ухватити на очи његове? Замку му провући кроз нос?
Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?