< Књига пророка Јеремије 51 >
1 Овако говори Господ: Ево, ја ћу подигнути на Вавилон и на оне који живе усред оних који устају на ме, ветар који мори.
Ohùn ti Olúwa wí nìyìí: “Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai,
2 Послаћу на Вавилон вијаче који ће га развијати и земљу његову испразнити, јер ће га опколити са свих страна у дан невоље његове.
Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo; wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.
3 Стрелац нека натеже лук на стрелца и на оног који се поноси својим оклопом, и не жалите младића његових, потрите му сву војску,
Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀, jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀. Má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sí; pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
4 Нека падну побијени у земљи халдејској и избодени на улицама његовим.
Gbogbo wọn ni yóò ṣubú ní Babeli, tí wọn yóò sì fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.
5 Јер није оставио Израиља и Јуде Бог њихов, Господ над војскама, ако и јесте земља њихова пуна кривице Свецу Израиљевом.
Nítorí pé Juda àti Israẹli ni Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun, kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.
6 Бежите из Вавилона и избавите сваки душу своју да се не истребите у безакоњу његовом, јер је време освете Господње, плаћа му шта је заслужио.
“Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Àsìkò àti gbẹ̀san Olúwa ni èyí; yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.
7 Вавилон беше златна чаша у руци Господњој, којом опоји сву земљу; вино његово пише народи, зато полудеше народи.
Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa; ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí. Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀, wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.
8 Уједанпут паде Вавилон и разби се; ридајте за њим; донесите балсама за ране његове, не би ли се исцелио.
Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́. Ẹ hu fun un! Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ, bóyá yóò le wo ọ́ sàn.
9 Лечисмо Вавилон, али се не исцели; оставите га, и да идемо сваки у своју земљу; јер до неба допире суд његов и диже се до облака.
“‘À bá ti wo Babeli sàn, ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀, kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè, ó ga àní títí dé òfúrufú.’
10 Господ је изнео правду нашу; ходите, да приповедамо на Сиону дело Господа Бога свог.
“‘Olúwa ti dá wa láre, wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa ti ṣe.’
11 Чистите стреле, узмите штитове; Господ подиже дух царева мидских, јер је Вавилону намислио да га затре; јер је освета Господња, освета цркве Његове.
“Ṣe ọfà rẹ ní mímú, mú àpáta! Olúwa ti ru ọba Media sókè, nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
12 На зидовима вавилонским подигните заставу, утврдите стражу, поставите стражаре, наместите заседе; јер је Господ намислио, и учиниће шта је рекао за становнике вавилонске.
Gbé àsíá sókè sí odi Babeli! Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí, ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri, ẹ ṣètò àwọn tí yóò sá pamọ́ Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde, òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.
13 О ти, што станујеш крај воде велике и имаш много блага! Дође крај твој и свршетак лакомству твом.
Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀, tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé, àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
14 Господ над војскама закле се собом: Напунићу те људима као скакавцима, и они ће ти певати песму.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀, Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú, wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.
15 Он је створио земљу силом својом, утврдио васиљену мудрошћу својом, и разумом својим разапео небеса.
“Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀, o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
16 Кад пусти глас свој, буче воде на небесима, подиже пару с крајева земаљских, и пушта муње с даждем, и изводи ветар из стаја његових.
Nígbà tí ará omi ọ̀run hó ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.
17 Сваки човек поста безуман од знања, сваки се златар осрамоти ликом резаним; јер су лаж ликови његови ливени и нема духа у њима.
“Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀. Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn; wọn kò ní èémí nínú.
18 Таштина су, дело преварно; кад их походим, погинуће.
Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà, nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.
19 Није такав део Јаковљев; јер је Он Творац свему и Он је део наследства његовог; име Му је Господ над војскама.
Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí; nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo, àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
20 Ти си ми био маљ, оружје убојно, и тобом сатрх народе и тобом расух царства.
“Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi, ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú, èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.
21 И тобом сатрх коња и јахача његовог; и тобом сатрх кола и који сеђаху на њима.
Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀; èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú èmi ó pa awakọ̀,
22 И тобом сатрх човека и жену, и сатрх тобом старца и дете, и сатрх тобом момка и девојку.
pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin, pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbàlagbà àti ọmọdé, pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
23 И тобом сатрх пастира и стадо његово, и тобом сатрх орача и волове његове ујармљене, и сатрх тобом кнезове и властеље.
Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn, àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.
24 И платићу Вавилону и свим становницима халдејским за све зло које учинише Сиону, на ваше очи, говори Господ.
“Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,” ni Olúwa wí.
25 Ево мене на тебе, горо, која сатиреш, говори Господ, која затиреш сву земљу, и замахнућу руком својом на те и свалићу те са стена, и начинићу од тебе гору изгорелу.
“Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,” ni Olúwa wí. “Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ, èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta, Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.
26 И неће узети од тебе камена за угао ни камена за темељ, јер ћеш бити пустош вечна, говори Господ.
A kò ní mú òkúta kankan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di ahoro títí ayé,” ní Olúwa wí.
27 Подигните заставу у земљи, затрубите у трубе међу народима, приправите народе на њ, сазовите на њ царство араратско, минијско и асханаско; поставите војводу супрот њему, доведите коње као скакавце бодљикасте.
“Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà! Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè! Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀, pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́: Ararati, Minini àti Aṣkenasi. Yan olùdarí ogun láti kọlù ú, rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.
28 Приправите народе супрот њему, цареве мидске и војводе њихове и све властеље њихове и сву земљу државе њихове.
Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀, àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.
29 И земља ће се затрести и узмучити, јер ће се мисао Господња извршити на Вавилону да обрати земљу вавилонску у пустињу да нико не живи у њој.
Ilẹ̀ wárìrì síyìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé ète Olúwa, sí Babeli dúró, láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.
30 Престаше војевати јунаци вавилонски, стоје у граду, неста силе њихове, посташе као жене, изгореше станови њихови, преворнице њихове поломише се.
Gbogbo àwọn jagunjagun Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn. Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin. Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun, gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.
31 Гласник ће сретати гласника, и посланик ће сретати посланика да јаве цару вавилонском да му је узет град са свих крајева,
Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn láti sọ fún ọba Babeli pé gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.
32 И да се бродови узеше и језера изгореше огњем и војници се препали.
Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́ ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”
33 Јер овако вели Господ над војскама Бог Израиљев: Кћи је вавилонска као гумно; време је да се набије, још мало, па ће доћи време да се пожње.
Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí: “Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”
34 Изједе ме и потре ме Навуходоносор, цар вавилонски, начини од мене непотребан суд, прождре ме као змај, напуни трбух свој милинама мојим, и отера ме.
“Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run, ó ti mú kí ìdààmú bá wa, ó ti sọ wá di àgbá òfìfo. Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì. Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀, lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.
35 Неправда која се чини мени и мом телу нека дође на Вавилон, рећи ће становница сионска, и крв моја на становнике халдејске, говориће Јерусалим.
Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,” èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí. “Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,” ni Jerusalẹmu wí.
36 Зато овако вели Господ: Ево, ја ћу расправити парбу твоју и осветићу те; и осушићу море његово, и изворе ћу његове осушити.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san, èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.
37 И Вавилон ће постати гомила, стан змајевски, чудо и подсмех, да нико неће живети у њему.
Babeli yóò parun pátápátá, yóò sì di ihò àwọn akátá, ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.
38 Рикаће сви као лавови и вити као лавићи.
Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù bí ọmọ kìnnìún.
39 Кад се угреју, изнећу им да пију, и опојићу их да се развеселе и заспе вечним сном, да се не пробуде, говори Господ.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè, èmi yóò ṣe àsè fún wọn, èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín, lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,” ni Olúwa wí.
40 Свешћу их на заклање као јагањце, као овнове с јарцима.
“Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.
41 Како се предоби Сисах и узе се хвала све земље? Како Вавилон поста чудо међу народима?
“Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé. Irú ìpayà wo ni yóò bá Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
42 Море уста на Вавилон, покри га мноштво вала његових.
Òkun yóò ru borí Babeli, gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.
43 Градови његови посташе пустош, земља сасушена и пуста, земља где нико не живи, нити пролази кроз њу син човечји.
Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro, ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.
44 И походићу Вила у Вавилону и извући ћу из уста његових шта је прождрао, и неће се више стицати к њему народи, и зид ће вавилонски пасти.
Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì. Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́. Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.
45 Изиђи из њега, народе мој, и избавите сваки своју душу од жестоког гнева Господњег.
“Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn mi! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Sá fún ìbínú ńlá Olúwa.
46 Немојте да одмекне срце ваше и да се уплашите од гласа који ће се чути у земљи; а доћи ће глас једне године, а после њега други глас друге године, и насиље ће бити у земљи, и господар ће устати на господара.
Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa; àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí, òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.
47 Зато ево иду дани кад ћу походити резане ликове вавилонске, и сва ће се земља његова посрамити, и сви ће побијени његови пасти усред њега.
Nítorí ìgbà náà yóò wá dandan nígbà tí èmi yóò fi ìyà jẹ àwọn òrìṣà Babeli; gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.
48 Небо и земља и све што је у њима певаће над Вавилоном, јер ће доћи на њ са севера затирач, говори Господ.
Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn, yóò sì kọrin lórí Babeli: nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,” ni Olúwa wí.
49 И као што је Вавилон учинио да падну побијени Израиљеви, тако ће пасти у Вавилону побијени све земље.
“Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.
50 Који утекосте од мача, идите, не стојте; помињите Господа издалека, и Јерусалим нека вам је у срцу.
Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró. Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè, ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”
51 Посрамисмо се, што чусмо руг, стид попаде лице наше, што туђини уђоше у светињу дома Господњег.
“Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn: ìtìjú ti bò wá lójú nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”
52 Зато, гле, иду дани, говори Господ, кад ћу походити резане ликове његове, и по свој земљи његовој јечаће рањеници.
“Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀, àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀.
53 Да се Вавилон и на небо попне, и на висини да утврди силу своју, доћи ће од мене на њ затирачи, говори Господ.
Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run, bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ, síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,” ní Olúwa wí.
54 Чује се велика вика из Вавилона, и велик полом из земље халдејске.
“Ìró igbe láti Babeli, àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!
55 Јер Господ затире Вавилон, и укида у њему велику вреву; и вали ће њихови бучати као велика вода, вика ће се њихова разлегати.
Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ, ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀; àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.
56 Јер дође на њ, на Вавилон, затирач, јунаци се његови заробише, лукови се њихови потрше; јер је Господ Бог који плаћа, доиста ће платити.
Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀, àní sórí Babeli; a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn: nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa, yóò san án nítòótọ́.
57 Опојићу кнезове његове и мудраце његове, војводе његове и властеље његове и јунаке његове, да ће заспати вечним сном и неће се пробудити, говори цар, коме је име Господ над војскама.
Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí, àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀ àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀, wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,” ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
58 Овако вели Господ над војскама: Широки зидови вавилонски сасвим ће се раскопати, и висока врата његова огњем ће се спалити, те су људи узалуд радили, и народи се трудили за огањ.
Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá, ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun: tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán, àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná, tí àárẹ̀ sì mú wọn.”
59 Реч што заповеди пророк Јеремија Сераји сину Нирије сина Масијиног, кад пође од Седекије, цара Јудиног, у Вавилон четврте године царовања његовог; а Сераја беше главни постељник.
Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó.
60 А Јеремија написа у једну књигу све зло које хтеде доћи на Вавилон, све ове речи што су написане за Вавилон.
Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli.
61 И рече Јеремија Сераји: Кад дођеш у Вавилон, тада гледај и прочитај све ове речи;
Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “Nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
62 И реци: Господе, Ти си говорио за ово место да ћеш га затрти да нико не живи у њему, ни човек ни живинче, него да је пустош до века.
Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’
63 А кад прочиташ ову књигу, вежи камен за њу, и баци је у Ефрат.
Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate.
64 И реци: Тако ће потонути Вавилон и неће се подигнути ода зла које ћу пустити на њ, и они ће изнемоћи. Довде су речи Јеремијине.
Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’” Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.