< Књига пророка Јеремије 21 >

1 Реч која дође Јеремији од Господа кад посла к њему цар Седекија Пасхора сина Мелхијиног и Софонију сина Масијиног свештеника, и поручи:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
2 Упитај Господа за нас, јер Навуходоносор, цар вавилонски, завојшти на нас; еда би нам учинио Господ по свим чудесима својим, да отиде од нас.
“Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
3 А Јеремија им рече: Овако реците Седекији:
Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
4 Овако вели Господ Бог Израиљев: Ево, ја ћу окренути натраг оружје што је у вашим рукама, којим се бијете с царем вавилонским и с Халдејцима који су вас опколили иза зидова, и скупићу их усред тог града.
‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
5 И ја ћу војевати на вас руком подигнутом и мишицом крепком и гневом и јарошћу и жестином великом.
Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
6 И побићу становнике тог града, и људе и стоку; од помора великог помреће.
Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
7 А после, вели Господ, даћу Седекију цара Јудиног и слуге њихове и народ, оне који остану у том граду од помора, од мача и од глади, у руке Навуходоносору цару вавилонском и у руке непријатељима њиховим и у руке онима који траже душу њихову, те ће их побити мачем, неће их жалити ни штедети нити ће се смиловати.
Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
8 А народу том реци: Овако вели Господ: Ево ја стављам пред вас пут к животу и пут к смрти.
“Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
9 Ко остане у том граду, погинуће од мача или од глади или од помора; а ко изађе и преда се Халдејцима који су вас опколили, остаће жив, и душа ће му бити место плена.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
10 Јер окретох лице своје томе граду на зло, а не на добро, говори Господ; у руке цару вавилонском биће предан, и он ће га спалити огњем.
Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
11 А за дом цара Јудиног чујте реч Господњу:
“Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Доме Давидов, тако вели Господ, судите свако јутро, и коме се отима избављајте га из руку насилникових да не изиђе као огањ гнев мој и разгори се да га нико не може угасити за злоћу дела ваших.
Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
13 Ево ме на тебе, који седиш у долини, као стена у равници, говори Господ, на вас, који говорите: Ко ће доћи на нас? И ко ће ући у станове наше?
Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
14 Јер ћу вас покарати по плоду дела ваших, вели Господ, и распалићу огањ у шуми његовој, који ће прождрети све што је око њега.
Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”

< Књига пророка Јеремије 21 >