< Књига пророка Јеремије 19 >

1 Овако рече Господ: Иди и купи крчаг земљан у лончара с неколико старешина народних и старешина свештеничких.
Èyí ní ohun tí Olúwa wí: “Lọ ra ìkòkò lọ́dọ̀ alámọ̀, mú dání lára àwọn àgbàgbà ọkùnrin àti wòlíì.
2 И отиди у долину сина Еномовог што је пред вратима источним, и онде прогласи речи које ћу ти казати.
Kí o sì lọ sí àfonífojì ọmọ Beni-Hinnomu, níwájú ẹnu ibodè Harsiti, níbẹ̀ ni kí o sì kéde gbogbo ọ̀rọ̀ tí èmi yóò sọ fún ọ.
3 И реци: Чујте реч Господњу, цареви Јудини и становници јерусалимски; овако вели Господ над војскама Бог Израиљев: Ево, ја ћу пустити зло на то место да ће зујати уши свакоме ко га чује.
Kí o sì wí pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba àwọn Juda àti ẹ̀yin ará Jerusalẹmu. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli sọ. Dẹtí sí mi! Èmi yóò mú ìparun wá síbí, etí gbogbo wọn tó bá gbọ́ ọ yóò hó yaya.
4 Јер ме оставише и оскврнише ово место кадећи на њему другим боговима, којих не знаше ни они ни оци њихови, ни цареви Јудини, и напунише то место крви праве.
Nítorí wọ́n ti gbàgbé mi, wọ́n sì ti sọ ibí di ilé fún òrìṣà àjèjì; wọ́n ti sun ẹbọ nínú rẹ̀ fún òrìṣà tí àwọn baba wọn tàbí tí ọba Juda kò mọ̀ rí, wọ́n ti fi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kún ilẹ̀ yìí.
5 И поградише висине Валу да сажижу синове своје огњем на жртве паљенице Валу, чега не заповедих нити о том говорих, нити ми на ум дође.
Wọ́n ti kọ́ ibi gíga fún Baali láti sun ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí ohun ẹbọ sísun sí Baali—èyí tí èmi kò pàṣẹ láti ṣe, tí èmi kò sì sọ, tàbí tí kò sì ru sókè láti inú ọkàn mi.
6 Зато, ево, иде време, вели Господ, кад се ово место неће више звати Тофет, ни долина сина Еномовог, него крвна долина.
Nítorí náà ṣọ́ra ọjọ́ ń bọ̀ ni Olúwa wí nígbà tí àwọn ènìyàn kì yóò pe ibí ní Tofeti mọ́ tàbí àfonífojì ọmọ Hinnomu, ṣùgbọ́n àfonífojì Ìpakúpa.
7 Јер ћу уништити савет Јудин и јерусалимски на овом месту, и учинићу да падну од мача пред непријатељима својим и од руке оних који траже душу њихову, и мртва ћу телеса њихова дати за храну птицама небеским и зверима земаљским.
“‘Ní ibí yìí ni èmi yóò ti pa èrò Juda àti Jerusalẹmu run. Èmí yóò mú wọn ṣubú nípa idà níwájú àwọn ọ̀tá wọn, lọ́wọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn. Èmi yóò sì fi òkú wọn ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.
8 И обратићу тај град у пустош и руг: ко год прође мимо њ, чудиће се и звиждаће за све муке његове.
Èmi yóò sọ ìlú yìí di ahoro àti ohun ẹ̀gàn, gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò bẹ̀rù wọn yóò sì máa fòyà nítorí gbogbo ọgbẹ́ rẹ̀.
9 И учинићу да једу месо од својих синова и месо од својих кћери, и сваки ће јести месо од друга свог у невољи и тескоби, којом ће им досађивати непријатељи њихови и који траже душу њихову.
Èmi yóò mú kí wọ́n jẹ ẹran-ara ọmọ wọn ọkùnrin àti ẹran-ara ọmọ wọn obìnrin, ẹnìkínní yóò sì jẹ ẹran-ara ẹnìkejì, nígbà ìdótì àti ìhámọ́ láti ọwọ́ ọ̀tá wọn, àti àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn.’
10 Потом разбиј крчаг пред људима који ће ићи с тобом.
“Nígbà náà ni ìwọ yóò fọ́ ìkòkò náà ní ojú àwọn tí ó bá ọ lọ.
11 И реци им: Овако вели Господ над војскама: Тако ћу разбити тај народ и тај град као што се разбије суд лончарски, који се не може више оправити, и у Тофету ће се погребавати, јер неће бити места за погребавање:
Kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. Èmi a fọ́ orílẹ̀-èdè yìí àti ìlú yìí gẹ́gẹ́ bí ìkòkò amọ̀ yìí ṣe fọ́ tí kò sì ní sí àtúnṣe. Wọn a sì sin àwọn òkú sí Tofeti títí tí kò fi ní sí ààyè mọ́.
12 Тако ћу учинити томе месту, вели Господ, и становницима његовим и учинићу тај град да буде као Тофет;
Èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí ibí yìí àti àwọn tí ń gbé ní ibí yìí ni Olúwa wí. Èmi yóò mú ìlú yìí dàbí Tofeti.
13 И куће јерусалимске и куће царева Јудиних биће нечисте као место Тофет, све куће, где на крововима кадише свој војсци небеској и лише наливе другим боговима.
Àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu àti ti ọba ìlú Juda ni a ó sọ di àìmọ́ bí Tofeti, gbogbo ilé tí wọ́n ti ń sun tùràrí ni orí òrùlé sí gbogbo ogun ọ̀run, tí a sì ń rú ẹbọ mímu sí ọlọ́run mìíràn.’”
14 Потом се врати Јеремија из Тофета куда га беше послао Господ да пророкује, и стаде у трему дома Господњег, и рече свему народу:
Jeremiah sì padà láti Tofeti níbi tí Olúwa rán an sí láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ó sì dúró ní gbangba tẹmpili Olúwa, ó sì sọ fún gbogbo ènìyàn pé,
15 Овако вели Господ над војскама, Бог Израиљев: Ево, ја ћу пустити на тај град и на све градове његове све зло које изрекох за њ, јер отврднуше вратом својим да не слушају речи моје.
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò mú ìdààmú tí mo ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ bá ìlú yìí àti ìgbèríko tí ó yí i ká, nítorí ọlọ́rùn líle ni wọ́n, wọn kò si ní fẹ́ fetí sí ọ̀rọ̀ mi.’”

< Књига пророка Јеремије 19 >