< 1 Мојсијева 16 >

1 Али Сара жена Аврамова не рађаше му деце. А имаше робињу Мисирку, по имену Агара.
Sarai, aya Abramu kò bímọ fún un, ṣùgbọ́n ó ní ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin ará Ejibiti kan tí ń jẹ́ Hagari.
2 Па рече Сара Авраму: Господ ме је затворио да не родим; него иди к робињи мојој, не бих ли добила деце од ње. И Аврам приста на реч Сарину.
Nítorí náà, Sarai wí fún Abramu pé, “Kíyèsi i Olúwa ti sé mi ní inú, èmi kò sì bímọ, wọlé tọ ọmọ ọ̀dọ̀ mi lọ, bóyá èmi yóò le ti ipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.” Abramu sì gba ohun tí Sarai sọ.
3 И Сара жена Аврамова узе Агару Мисирку робињу своју, и даде је за жену Авраму мужу свом после десет година откако се настани Аврам у земљи хананској.
Lẹ́yìn ọdún mẹ́wàá tí Abramu ti ń gbé ni Kenaani ni Sarai mú ọmọbìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Hagari, tí í ṣe ará Ejibiti fún Abramu ọkọ rẹ̀ láti fi ṣe aya.
4 И он отиде к Агари, и она затрудне; а кад виде да је трудна, понесе се од госпође своје.
Abramu sì bá Hagari lòpọ̀, ó sì lóyún. Nígbà tí ó sì ti mọ̀ pé òun lóyún, ó bẹ̀rẹ̀ sì ní kẹ́gàn ọ̀gá rẹ̀.
5 А Сара рече Авраму: Увреда моја паде на тебе; ја ти метнух на крило робињу своју, а она видевши да је трудна понесе се од мене. Господ ће судити мени и теби.
Nígbà náà ni Sarai wí fún Abramu pé, “Ìwọ ni ó jẹ́ kí ẹ̀gbin yìí máa jẹ mí, mo fa ọmọ ọ̀dọ̀ mi lé ọ lọ́wọ́, nígbà tí ó sì rí i pé òun lóyún, mo di ẹni ẹ̀gàn ní ojú rẹ̀. Kí Olúwa kí ó ṣe ìdájọ́ láàrín tèmi tìrẹ.”
6 А Аврам рече Сари: Ето, робиња је твоја у твојим рукама, учини с њом шта ти је воља. И Сара је стаде злостављати, те она побеже од ње.
Abramu dáhùn pé, “Ìwọ ló ni ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣe ohunkóhun tí ó bá tọ́ ní ojú rẹ sí i.” Nígbà náà ni Sarai fi ìyà jẹ Hagari, ó sì sálọ.
7 Али анђео Господњи нађе је код студенца у пустињи, код студенца на путу у Сур.
Angẹli Olúwa sì rí Hagari ní ẹ̀gbẹ́ ìsun omi ní ijù, ìsun omi tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà tí ó lọ sí Ṣuri.
8 И рече јој: Агаро, робињо Сарина, откуд идеш, куда ли идеш? А она рече: Бежим од Саре госпође своје.
Ó sì wí pé, “Hagari, ìránṣẹ́ Sarai, níbo ni o ti ń bọ̀, níbo sì ni ìwọ ń lọ?” Ó sì dáhùn pé, “Mo ń sálọ kúrò lọ́dọ̀ ọ̀gá mi Sarai ni.”
9 А анђео јој Господњи рече: Врати се госпођи својој, и покори јој се.
Angẹli Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ kí o sì tẹríba fún un.”
10 Опет јој рече анђео Господњи: Умножићу веома семе твоје, да се неће моћи пребројати од множине.
Angẹli Olúwa náà sì fi kún fún un pé, “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, ìran rẹ kì yóò sì lóǹkà.”
11 Још јој рече анђео Господњи: Ето си трудна, и родићеш сина, и надени му име Исмаило; јер је Господ видео муку твоју.
Angẹli Olúwa náà sì wí fún un pé, “Ìwọ ti lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Ìwọ yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli, nítorí tí Olúwa ti rí ìpọ́njú rẹ.
12 А биће човек убица; рука ће се његова дизати на сваког а свачија на њега, и наставаће на погледу свој браћи својој.
Òun yóò jẹ́ oníjàgídíjàgan ènìyàn ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára ènìyàn gbogbo, ọwọ́ ènìyàn gbogbo yóò sì wà lára rẹ̀, yóò sì máa gbé ní ìkanra pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀.”
13 Тада Агара призва име Господа који говори с њом: Ти си Бог, који види. Јер говораше: Зар још гледам иза Оног који ме виде?
Ó sì pe orúkọ Olúwa tí o bá sọ̀rọ̀ ní, “Ìwọ ni Ọlọ́run tí ó rí mi,” nítorí tí ó wí pé, “Mo ti ri ẹni tí ó rí mi báyìí.”
14 Тога ради зове се студенац онај студенац Живога који ме види; а он је између Кадиса и Варада.
Nítorí náà ni a ṣe ń pe kànga náà ní Beeri-Lahai-Roi; kànga ẹni alààyè tí ó rí mi. Ó wà ní agbede-méjì Kadeṣi àti Beredi.
15 И роди Агара Авраму сина; и надеде Аврам сину свом, ког му роди Агара, име Исмаило.
Hagari sì bí ọmọkùnrin kan fún Abramu, Abramu sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli.
16 А беше Авраму осамдесет и шест година кад му Агара роди Исмаила.
Abramu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínláàádọ́rùn-ún nígbà tí Hagari bí Iṣmaeli fún un.

< 1 Мојсијева 16 >