< 1 Мојсијева 12 >

1 И рече Господ Авраму: Иди из земље своје и од рода свог и из дома оца свог у земљу коју ћу ти ја показати.
Olúwa sì wí fún Abramu, “Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.
2 И учинићу од тебе велик народ, и благословићу те, и име твоје прославићу, и ти ћеш бити благослов.
“Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, èmi yóò sì bùkún fún ọ; èmi yóò sọ orúkọ rẹ di ńlá, ìbùkún ni ìwọ yóò sì jásí.
3 Благословићу оне који тебе узблагосиљају, и проклећу оне који тебе успроклињу; и у теби ће бити благословена сва племена на земљи.
Èmi yóò bùkún fún àwọn tí ó súre fún ọ, ẹni tí ó fi ọ́ ré ni Èmi yóò fi ré; nínú rẹ ni a ó bùkún gbogbo ìdílé ayé.”
4 Тада пође Аврам, као што му каза Господ, и с њим пође Лот. А беше Авраму седамдесет и пет година кад пође из Харана.
Bẹ́ẹ̀ ni Abramu lọ bí Olúwa ti sọ fún un. Lọti náà sì bá a lọ. Abramu jẹ́ ẹni àrùndínlọ́gọ́rin ọdún nígbà tí ó jáde kúrò ní Harani.
5 И узе Аврам Сару жену своју и Лота сина брата свог са свим благом које беху стекли и с душама које беху добили у Харану; и пођоше у земљу хананску, и дођоше у њу.
Abramu sì mú Sarai aya rẹ̀, àti Lọti ọmọ arákùnrin rẹ̀: gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti kójọ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n ní ní Harani. Wọ́n sì jáde lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Wọ́n sì gúnlẹ̀ síbẹ̀.
6 И пође Аврам ту земљу до места Сихема и до равнице морешке; а беху тада Хананеји у тој земљи.
Abramu sì rìn la ilẹ̀ náà já títí dé ibi igi ńlá kan tí à ń pè ni More ní Ṣekemu. Àwọn ará Kenaani sì wà ní ilẹ̀ náà.
7 И јави се Господ Авраму и рече: Твом семену даћу земљу ову. И Аврам начини онде жртвеник Господу, који му се јавио.
Olúwa sì farahan Abramu, ó sì wí fún un pé, “Irú-ọmọ rẹ ni Èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún.” Abramu tẹ́ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Olúwa tí ó fi ara hàn án.
8 После отиде оданде на брдо, које је према истоку од Ветиља, и онде разапе шатор свој, те му Ветиљ беше са запада а Гај с истока; и онде начини Господу жртвеник, и призва име Господње.
Ó sì kúrò níbẹ̀ lọ sí agbègbè àwọn òkè kan ní ìhà ìlà-oòrùn Beteli, ó sì pàgọ́ rẹ̀ síbẹ̀. Beteli wà ní ìwọ̀-oòrùn, Ai wà ní ìlà-oòrùn. Ó tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ó sì ké pe orúkọ Olúwa.
9 Оданде отиде Аврам даље идући на југ.
Nígbà náà ni Abramu tẹ̀síwájú sí ìhà gúúsù.
10 Али наста глад у оној земљи, те Аврам сиђе у Мисир да се онде склони; јер глад беше велика у оној земљи.
Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, Abramu sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ṣe àtìpó níbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, nítorí ìyàn náà mú gidigidi.
11 А кад се приближи да већ уђе у Мисир, рече Сари жени својој: Гле, знам да си жена лепа у лицу.
Bí ó ti ku díẹ̀ kí ó wọ Ejibiti, ó wí fún Sarai, aya rẹ̀ pé, “Mo mọ̀ pé arẹwà obìnrin ni ìwọ,
12 Зато кад те виде Мисирци рећи ће: Ово му је жена. Па ће ме убити, а тебе ће оставити у животу.
nígbà tí àwọn ará Ejibiti bá rí ọ, wọn yóò wí pé, ‘Aya rẹ̀ nìyí.’ Wọn yóò si pa mí, ṣùgbọ́n wọn yóò dá ọ sí.
13 Него хајде кажи да си ми сестра, те ће мени бити добро тебе ради и остаћу у животу уз тебе.
Nítorí náà, sọ pé, arábìnrin mi ni ìwọ, wọn yóò sì ṣe mí dáradára, a ó sì dá ẹ̀mí mi sí nítorí tìrẹ.”
14 И кад дође Аврам у Мисир, видеше Мисирци жену да је врло лепа.
Nígbà tí Abramu dé Ejibiti, àwọn ará Ejibiti ri i pé aya rẹ̀ rẹwà gidigidi.
15 И видеше је кнезови Фараонови, и хвалише је пред Фараоном. И узеше је у двор Фараонов.
Nígbà tí àwọn ìjòyè Farao sì rí i, wọ́n ròyìn rẹ̀ níwájú Farao, wọ́n sì mú un lọ sí ààfin.
16 И он чињаше добро Авраму ње ради, те имаше оваца и говеда и магараца и слуга и слушкиња и магарица и камила.
Ó sì kẹ́ Abramu dáradára nítorí Sarai, Abramu sì ní àgùntàn àti màlúù, akọ àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin, pẹ̀lú ìbákasẹ.
17 Али Господ пусти велика зла на Фараона и на дом његов ради Саре жене Аврамове.
Olúwa sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn búburú sí Farao àti ilé rẹ̀, nítorí Sarai aya Abramu.
18 Тада дозва Фараон Аврама и рече му: Шта ми то учини? Зашто ми ниси казао да ти је жена?
Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Abramu, ó sì wí fun pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé aya rẹ ní í ṣe?
19 Зашто си казао: Сестра ми је? Те је узех за жену. Сад ето ти жене, узми је, па иди.
Èéṣe tí o fi wí pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ tí èmi sì fi fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí aya? Nítorí náà nísinsin yìí, aya rẹ náà nìyí, mú un kí o sì máa lọ.”
20 И Фараон заповеди људима за њ, те га испратише и жену његову и шта год имаше.
Nígbà náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ nípa Abramu, wọ́n sì lé e jáde ti òun ti aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.

< 1 Мојсијева 12 >