< 1 Мојсијева 10 >

1 А ово су племена синова Нојевих, Сима, Хама и Јафета, којима се родише синови после потопа.
Èyí ni ìran àwọn ọmọ Noa: Ṣemu, Hamu àti Jafeti, tí àwọn náà sì bí ọmọ lẹ́yìn ìkún omi.
2 Синови Јафетови: Гомер и Магог и Мадај и Јаван и Товел и Месех и Тирас.
Àwọn ọmọ Jafeti ni: Gomeri, Magogu, Madai, Jafani, Tubali, Meṣeki àti Tirasi.
3 А синови Гомерови: Асхенас и Рифат и Тогарма.
Àwọn ọmọ Gomeri ni: Aṣkenasi, Rifati àti Togarma.
4 А синови Јаванови: Елиса и Тарсис, Китим и Доданим.
Àwọn ọmọ Jafani ni: Eliṣa, Tarṣiṣi, Kittimu, àti Dodanimu.
5 Од њих се разделише острва народна на земљама својим, свако по језику свом и по породицама својим, у народима својим.
(Láti ọ̀dọ̀ àwọn wọ̀nyí ni àwọn tí ń gbé agbègbè tí omi wà ti tàn ká agbègbè wọn, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, ìdílé wọn ní orílẹ̀-èdè wọn, olúkúlùkù pẹ̀lú èdè tirẹ̀).
6 А синови Хамови: Хус и Месраин, Фуд и Ханан.
Àwọn ọmọ Hamu ni: Kuṣi, Ejibiti, Puti àti Kenaani.
7 А синови Хусови: Сава и Авила и Савата и Регма и Саватака. А синови Регмини: Сава и Дедан.
Àwọn ọmọ Kuṣi ni: Seba, Hafila, Sabta, Raama, àti Sabteka. Àwọn ọmọ Raama ni: Ṣeba àti Dedani.
8 Хус роди и Неврода; а он први би силан на земљи;
Kuṣi sì bí Nimrodu, ẹni tí ó di alágbára jagunjagun ní ayé.
9 Беше добар ловац пред Господом; зато се каже: Добар ловац пред Господом као Неврод.
Ó sì jẹ́ ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa; nítorí náà ni a ṣe ń wí pé, “Bí Nimrodu, ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa.”
10 А почетак царству његовом беше Вавилон и Орех и Архад и Халани у земљи Сенару.
Ìjọba rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni Babeli, Ereki, Akkadi, Kalne, gbogbo wọn wà ní ilẹ̀ Ṣinari.
11 Из те земље изађе Асур, и сазида Ниневију и Ровот град и Халах,
Láti ilẹ̀ náà ni ó ti lọ sí Asiria, níbi tí ó ti tẹ ìlú Ninefe, Rehoboti àti Kala,
12 И Дасем између Ниневије и Халаха; то је град велик.
àti Resini, tí ó wà ní àárín Ninefe àti Kala, tí ó jẹ́ ìlú olókìkí.
13 А Месраин роди Лудеје и Енемеје и Лавеје и Нефталеје,
Ejibiti sì bí Ludimu, Anamimu, Lehabimu, Naftuhimu.
14 И Патросеје и Хасмеје, одакле изађоше Филистеји и Гафтореји.
Patrusimu, Kasluhimu (láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwọn ará Filistini ti wá) àti àwọn ará Kaftorimu.
15 А Ханан роди Сидона, првенца свог, и Хета,
Kenaani sì bí Sidoni àkọ́bí rẹ̀, àti Heti.
16 И Јевусеја и Амореја и Гергесеја,
Àti àwọn ará Jebusi, àti àwọn ará Amori, àti àwọn ará Girgaṣi,
17 И Евеја и Арукеја и Асенеја,
àti àwọn ará Hifi, àti àwọn ará Arki, àti àwọn ará Sini,
18 И Арвадеја и Самареја и Аматеја. А после се расејаше племена хананејска.
àti àwọn ará Arfadi, àti àwọn ará Semari, àti àwọn ará Hamati. Lẹ́yìn èyí ni àwọn ẹ̀yà Kenaani tànkálẹ̀.
19 И беху међе хананејске од Сидона идући на Герар па до Газе, и идући на Содом и Гомор и Адаму и Севојим па до Даса.
Ààlà ilẹ̀ àwọn ará Kenaani sì dé Sidoni, lọ sí Gerari títí dé Gasa, lọ sí Sodomu, Gomorra, Adma àti Seboimu, títí dé Laṣa.
20 То су синови Хамови по породицама својим и по језицима својим, у земљама својим и у народима својим.
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Hamu, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, àti èdè wọn, ní ìpínlẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
21 И Симу родише се синови, најстаријем брату Јафетовом, оцу свих синова Еверових.
A bí àwọn ọmọ fún Ṣemu tí Jafeti jẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin: Ṣemu sì ni baba gbogbo àwọn ọmọ Eberi.
22 Синови Симови беху: Елам и Асур и Арфаксад и Луд и Арам.
Àwọn ọmọ Ṣemu ni: Elamu, Aṣuri, Arfakṣadi, Ludi àti Aramu.
23 А синови Арамови: Уз и Ул и Гатер и Мас.
Àwọn ọmọ Aramu ni: Usi, Huli, Geteri àti Meṣeki.
24 А Арфаксад роди Салу, а Сала роди Евера.
Arfakṣadi sì bí Ṣela, Ṣela sì bí Eberi.
25 А Еверу се родише два сина: једном беше име Фалек, јер се у његово време раздели земља, а брату његовом име Јектан.
Eberi sì bí ọmọ méjì: ọ̀kan ń jẹ́ Pelegi, nítorí ní ìgbà ọjọ́ rẹ̀ ni ilẹ̀ ya; orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Joktani.
26 А Јектан роди Елмодада и Салета и Сармота и Јараха,
Joktani sì bí Almodadi, Ṣelefi, Hasarmafeti, Jera.
27 И Одора и Евила и Деклу,
Hadoramu, Usali, Dikla,
28 И Евала и Авимаила и Саву,
Obali, Abimaeli, Ṣeba.
29 И Уфира и Евилу и Јовава; ти сви беху синови Јектанови.
Ofiri, Hafila àti Jobabu. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Joktani.
30 И живљаху од Масе, како се иде на Сафир до гора источних.
Agbègbè ibi tí wọn ń gbé bẹ̀rẹ̀ láti Meṣa títí dé Sefari, ní àwọn ilẹ̀ tó kún fún òkè ní ìlà-oòrùn.
31 То су синови Симови по породицама својим и по језицима својим, у земљама својим и у народима својим.
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Ṣemu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, ní èdè wọn, ní ilẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
32 То су породице синова Нојевих по племенима својим, у народима својим; и од њих се разделише народи по земљи после потопа.
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Noa gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, ní orílẹ̀-èdè wọn. Ní ipasẹ̀ wọn ni àwọn ènìyàn ti tàn ká ilẹ̀ ayé lẹ́yìn ìkún omi.

< 1 Мојсијева 10 >