< Књига пророка Језекиља 8 >
1 А шесте године, шестог месеца, дана петог, кад сеђах у својој кући и старешине Јудине сеђаху преда мном, паде онде на ме рука Господа Господа.
Ní ọjọ́ karùn-ún, oṣù kẹfà ọdún kẹfà bí mo ṣe jókòó nílé mi pẹ̀lú àwọn àgbàgbà Juda níwájú mi, ọwọ́ Olúwa Olódùmarè bà lé mi níbẹ̀.
2 И видех, а то облик на очи као огањ, од бедара Му доле беше огањ, а од бедара горе беше као светлост, као јака светлост.
Nígbà tí mo wò, mo rí ohun kan tí ó jọ ènìyàn. Láti ibi ìbàdí rẹ lọ sísàlẹ̀ dàbí iná, láti ibi ìbàdí yìí sókè sì mọ́lẹ̀ bí idẹ tó ń kọ mọ̀nà.
3 И пружи као руку, и ухвати ме за косу на глави, и подиже ме дух међу небо и земљу, и однесе ме у Јерусалим у утвари Божјој на врата унутрашња која гледају на север, где стајаше идол од ревности, који дражи на ревност.
Ó na ohun tó dàbí ọwọ́ jáde, ó fi gba mi ní irun orí mú, Ẹ̀mí sì gbé mi sókè sí agbede-méjì ayé àti ọ̀run, ó sì mú mi lọ rí ìran Ọlọ́run, mo sì lọ sí Jerusalẹmu, ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òde àríwá níbi tí ère owú tí ó ń mú ni bínú wá níwájú mi.
4 И гле, онде беше слава Бога Израиљевог на очи као она што је видех у пољу.
Sì kíyèsi i, ògo Ọlọ́run Israẹli wà níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìran ti mo rí ni pẹ̀tẹ́lẹ̀.
5 И рече ми: Сине човечји, подигни очи своје к северу. И подигох очи своје к северу, и гле, са севера на вратима олтарским беше онај идол од ревности на уласку.
Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbójú sókè sí ìhà àríwá.” Èmi náà sì gbójú sókè sí ìhà àríwá mo sì rí ère tí ó ń mú ni jowú ní ẹnu-ọ̀nà ibi pẹpẹ.
6 Потом ми рече: Сине човечји, видиш ли шта ти раде? Велике гадове које ту чини дом Израиљев да отидем далеко од светиње своје? Али ћеш још видети већих гадова.
Ó sì wí fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o rí ohun tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra ńlá tí ilé Israẹli ń ṣe, láti lé mi jìnnà réré sí ibi mímọ́ mi? Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tún rí àwọn ìríra ńlá tó tóbi jù èyí lọ.”
7 И одведе ме на врата од трема, и погледах, а то једна рупа у зиду.
Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà àgbàlá. Mo wò ó, mo sì rí ihò kan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri.
8 А Он ми рече: Сине човечји, прокопај овај зид. И прокопах зид, а то једна врата.
Nígbà náà ló sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbẹ́ inú ògiri náà,” nígbà tí mo sì gbẹ́ inú ògiri, mo rí ìlẹ̀kùn kan.
9 Тада ми рече: Уђи и види опаке гадове које чине ту.
Ó sì wí fún mi pé, “Wọlé kí ìwọ kí ó rí ohun ìríra búburú tí wọ́n ń ṣe níbẹ̀.”
10 И ушавши видех, и гле, свакојаке животиње што гамижу и свакојаки гадни скотови, и сви гадни богови дома Израиљевог беху написани по зиду свуда унаоколо.
Mo wọlé, mo sì rí àwòrán oríṣìíríṣìí ẹranko tí ń fà nílẹ̀ àti àwọn ẹranko ìríra àti gbogbo òrìṣà ilẹ̀ Israẹli tí wọ́n yà sára ògiri.
11 И пред њима стајаше седамдесет људи између старешина дома Израиљевог с Јазанијом, сином Сафановим, који стајаше међу њима, сваки с кадионицом својом у руци, и подизаше се густ облак од када.
Níwájú wọn ni àádọ́rin ọkùnrin tó jẹ́ àgbàgbà ilé Israẹli dúró sí, Jaaṣaniah ọmọ Ṣafani sì dúró sí àárín wọn. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì mú àwo tùràrí lọ́wọ́, òórùn sì ń tú jáde.
12 Тада ми рече: Видиш ли, сине човечји, шта чине старешине дома Израиљевог у мраку свак у својој писаној клети? Јер говоре: Не види нас Господ, оставио је Господ ову земљу.
Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o ti rí ohun tí àwọn àgbàgbà ilé Israẹli ń ṣe nínú òkùnkùn, olúkúlùkù ní yàrá òrìṣà rẹ̀? Wọ́n ní, ‘Olúwa kò rí wa; Olúwa ti kọ̀ ilé náà sílẹ̀.’”
13 Потом ми рече: Још ћеш видети већих гадова које они чине.
Ó tún sọ fún mi pé, “Ìwọ yóò rí wọn tí wọ́n ń ṣe àwọn ohun ìríra tó burú jù bẹ́ẹ̀ lọ.”
14 И одведе ме на врата дома Господњег која су са севера; и гле, жене сеђаху и плакаху за Тамузом.
Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sì ń ṣọ̀fọ̀ fún Tamusi.
15 И рече ми: Јеси ли видео, сине човечји? Још ћеш видети већих гадова од тих.
Ó sọ fún mi pé, “Ṣé ìwọ rí báyìí, ọmọ ènìyàn? Ìwọ yóò tún rí ìríra tó ga jù èyí lọ.”
16 И одведе ме у трем унутрашњи дома Господњег; и гле, на уласку у цркву Господњу између трема и олтара беше око двадесет и пет људи окренутих леђима к цркви Господњој, лицем к истоку, и клањаху се сунцу према истоку.
Ó mú mi wá sí ibi àgbàlá ilé Olúwa, ní ẹnu-ọ̀nà tẹmpili Olúwa, láàrín ìloro àti pẹpẹ, ni ìwọ̀n ọkùnrin mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n wà, tí wọ́n kẹ́yìn sí tẹmpili Olúwa tí wọn sì kọjú sí ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún oòrùn ní apá ìlà-oòrùn.
17 Тада ми рече: Јеси ли видео, сине човечји? Мало ли је дому Јудином што чине те гадове које чине овде? Него још напунише земљу насиља и окренуше се да ме драже; и ето држе грану пред носом својим.
Ó sì wí fún mi, “Ṣé ìwọ ti rí èyí ọmọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ohun kékeré ni fún ilé Juda láti ṣe àwọn ohun ìríra tí wọn ń ṣe níbi yìí? Ṣé o tún yẹ kí wọ́n fi ìwà ipá kún ilẹ̀ kí wọn sì máa mú mi bínú ní gbogbo ìgbà? Wò wọn bi wọn ṣe n fi ẹ̀ka wọn sínú inú wọn.
18 Зато ћу и ја учинити у гневу, неће жалити око моје, нити ћу се смиловати, и кад стану викати гласно у моје уши, нећу их услишити.
Nítorí náà, èmi yóò fi ìbínú bá wọn wí; èmi kò ní i dá wọn sí bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ní fojú àánú wò wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ ń pariwo sí mi létí, èmi kò ní fetí sí wọn.”