< 5 Мојсијева 31 >
1 Потом дође Мојсије и каза ове речи свему Израиљу,
Nígbà náà ni Mose jáde tí ó sì sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí gbogbo Israẹli pé,
2 И рече им: Мени има данас сто и двадесет година, не могу више одлазити и долазити; а и Господ ми је рекао: Нећеш прећи преко тог Јордана.
“Mo jẹ́ ọmọ ọgọ́fà ọdún báyìí àti pé èmi kò ni lè darí i yín mọ́. Olúwa ti sọ fún mi pé, ‘Ìwọ kò ní kọjá Jordani.’
3 Господ ће Бог твој ићи пред тобом, и истребиће оне народе испред тебе, и ти ћеш их наследити; Исус ће ићи пред тобом као што је казао Господ.
Olúwa Ọlọ́run rẹ fúnra rẹ̀ ni yóò rékọjá fún ọ. Yóò pa àwọn orílẹ̀-èdè yìí run níwájú rẹ, ìwọ yóò sì mú ìní ilẹ̀ wọn, Joṣua náà yóò rékọjá fún ọ, bí Olúwa ti sọ.
4 И учиниће Господ с њима како је учинио са Сионом и Огом, царевима аморејским и са земљом њиховом, те их је истребио.
Olúwa yóò sì ṣe fún wọn ohun tí ó ti ṣe sí Sihoni àti sí Ogu ọba Amori, tí ó parun pẹ̀lú ilẹ̀ ẹ wọn.
5 Зато кад вам их преда Господ учините им сасвим онако како сам вам заповедио.
Olúwa yóò fi wọ́n fún ọ, kí o sì ṣe sí wọn gbogbo èyí tí mo ti pàṣẹ fún ọ.
6 Будите слободни и храбри, и не бојте их се и не плашите се од њих; јер Господ Бог твој иде с тобом, неће одступити од тебе, нити ће те оставити.
Jẹ́ alágbára kí o sì ní ìgboyà. Má ṣe bẹ̀rù tàbí jáyà nítorí i wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń lọ pẹ̀lú rẹ, Òun kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
7 Потом дозва Мојсије Исуса, и рече му пред свим Израиљем: Буди слободан и храбар; јер ћеш ући с овим народом у земљу за коју се заклео Господ оцима њиховим да ће им је дати, а ти ћеш им је разделити у наследство.
Nígbà náà ni Mose pe Joṣua ó sì wí fún un níwájú gbogbo Israẹli pé, “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí o ní láti lọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fún wọn, kí o sì pín ilẹ̀ náà láàrín wọn bí ogún wọn.
8 Јер Господ који иде пред тобом биће с тобом, неће одступити од тебе, нити ће те оставити, не бој се и не плаши се.
Olúwa fúnra rẹ̀ ń lọ níwájú rẹ yóò sì wà pẹ̀lú rẹ; kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Má ṣe bẹ̀rù má sì ṣe fòyà.”
9 И Мојсије написа овај закон, и даде га свештеницима, синовима Левијевим, који ношаху ковчег завета Господњег, и свим старешинама Израиљевим.
Nígbà náà ni Mose kọ òfin yìí kalẹ̀ ó sì fi fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, tí ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti fún gbogbo àwọn àgbàgbà ní Israẹli.
10 И заповеди им Мојсије говорећи: Сваке седме године, у одређено време године опросне, на празник сеница,
Nígbà náà ni Mose pàṣẹ fún wọn, “Ní òpin ọdún méje méje, ní àkókò ọdún ìdásílẹ̀, nígbà àjọ àwọn àgọ́.
11 Кад дође сав Израиљ и стане пред Господа Бога свог на месту које изабере, читај овај закон пред свим Израиљем да чују,
Nígbà tí gbogbo Israẹli bá wá láti fi ara hàn níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ibi tí yóò yàn, ìwọ yóò ka òfin yìí níwájú wọn sí etí ìgbọ́ wọn.
12 Сабравши народ, људе и жене, децу и дошљаке, који буду у местима твојим, да чују и уче да се боје Господа Бога вашег, и држе и творе све речи овог закона;
Pe àwọn ènìyàn jọ àwọn ọkùnrin, àwọn obìnrin àti àwọn àjèjì tí ń gbé àwọn ìlú u yín kí wọn lè fetí sí i kí wọn sì lè kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ kí wọn sì rọra tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí.
13 И синови њихови, који још не знају, нека чују и уче бојати се Господа Бога вашег, докле сте год живи на земљи у коју идете преко Јордана да је наследите.
Àwọn ọmọ wọn tí wọn kò mọ òfin yìí, gbọdọ̀ gbọ́ kí wọn sì kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ níwọ̀n ìgbà tí o tí ń gbé ní ilẹ̀ tí ò ń kọjá la Jordani lọ láti ni.”
14 А Господ рече Мојсију: Ево, приближи се време да умреш. Дозови Исуса и станите обојица у шатору од састанка, да му дам заповести. И отиде Мојсије и Исус, и стадоше у шатору од састанка.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọjọ́ ikú rẹ ti súnmọ́ etílé báyìí. Pe Joṣua kí ẹ sì fi ara yín hàn nínú àgọ́ àjọ, níbi tí èmi yóò ti fi àṣẹ fún un.” Nígbà náà ni Mose àti Joṣua wá, wọ́n sì fi ara wọn hàn níbi àgọ́ àjọ.
15 И јави се Господ у шатору у ступу од облака, и стајаше ступ од облака над вратима од шатора.
Nígbà náà ni Olúwa farahàn níbi àgọ́ ní ọ̀wọ́ àwọsánmọ̀, àwọsánmọ̀ náà sì dúró sókè ẹnu-ọ̀nà àgọ́.
16 И рече Господ Мојсију: Ево, ти ћеш починути с оцима својим; а народ овај уставши чиниће прељубу за туђим боговима оне земље у коју иде, и оставиће ме и поквариће завет мој, који учиних с њима.
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ìwọ ń lọ sinmi pẹ̀lú àwọn baba à rẹ, àwọn wọ̀nyí yóò sì ṣe àgbèrè ara wọn sí ọlọ́run àjèjì ilẹ̀ tí wọn ń wọ̀ lọ láìpẹ́. Wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀ wọn yóò sì da májẹ̀mú tí mo bá wọn dá.
17 И онда ће се распалити мој гнев на њих, и оставићу их, и сакрићу лице своје од њих; они ће се прождрети, и снаћи ће их зла многа и невоље; и онда ће рећи: Да ме не снађоше ова зла зато што Бог мој није посред мене?
Ní ọjọ́ náà ni èmi yóò bínú sí wọn èmi yóò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀; èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò fún wọn, wọn yóò sì parun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àjálù àti ìṣòro yóò wá sórí wọn, àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò béèrè pé, ‘Ǹjẹ́ ìpọ́njú wọ̀nyí kò wá sórí i wa nítorí Ọlọ́run wa kò sí pẹ̀lú u wa?’
18 А ја ћу онда сасвим сакрити лице своје за сва зла која учинише обративши се к другим боговима.
Èmi yóò sì pa ojú mi mọ́ dájúdájú ní ọjọ́ náà nítorí i gbogbo ìwà búburú wọn ní yíyípadà sí ọlọ́run mìíràn.
19 Зато сад напишите себи ову песму, и научи је синове Израиљеве; метни им је у уста да ми та песма буде сведок на синове израиљеве.
“Ní báyìí kọ ọ́ kalẹ̀ fúnra à rẹ orin yìí kí o sì kọ ọ́ sí Israẹli kí o sì jẹ́ kí wọn kọ ọ́ kí ó lè jẹ́ ẹ̀rí ì mi sí wọn.
20 Јер ћу га одвести у земљу за коју сам се заклео оцима његовим, у којој тече млеко и мед; онде ће јести и наситиће се и угојиће се, па ће се онда обратити к другим боговима и њима ће служити, а за мене неће марити, и поквариће завет мој.
Nígbà tí mo ti mú wọn wá sí ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, ilẹ̀ tí mo ti ṣe ìlérí ní ìbúra fún àwọn baba ńlá wọn, àti nígbà tí wọ́n bá jẹ, tí ó sì tẹ́ wọn lọ́rùn, tí wọ́n sì gbilẹ̀, wọn yóò yí padà sí ọlọ́run mìíràn wọn yóò sì sìn wọ́n, wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀, wọn yóò sì da májẹ̀mú mi.
21 А кад га снађу зла многа и невоље, онда ће та песма сведочити на њих; јер се неће заборавити нити ће је нестати из уста семена њиховог. Јер знам мисли њихове и шта ће још данас чинити, пре него их уведем у земљу за коју сам се заклео.
Àti nígbà tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpọ́njú àti ìṣòro bá wá sórí i wọn, orin yìí yóò jẹ́ ẹ̀rí sí wọn, nítorí kò ní di ìgbàgbé fún àwọn ọmọ wọn. Mo mọ̀ ohun tí wọ́n ní inú dídùn sí láti ṣe, pàápàá kí èmi tó mú wọn wá sí ilẹ̀ tí mo ṣe ìlérí fún wọn lórí ìbúra.”
22 И написа Мојсије ту песму онај дан, и научи синове Израиљеве.
Nígbà náà ni Mose kọ orin yìí kalẹ̀ ní ọjọ́ náà ó sì kọ ọ́ sí Israẹli.
23 И Господ даде заповести Исусу Навином говорећи: Буди слободан и храбар, јер ћеш ти увести синове Израиљеве у земљу за коју сам им се заклео и ја ћу бити с тобом.
Olúwa sì fún Joṣua ọmọ Nuni ní àṣẹ yìí: “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí ìwọ yóò mú Israẹli wá sí ilẹ̀ tí mo ṣèlérí fún wọn lórí ìbúra, èmi fúnra à mi yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.”
24 И кад написа речи овог закона у књигу, све до краја,
Lẹ́yìn ìgbà tí Mose ti parí i kíkọ ọ̀rọ̀ òfin yìí sínú ìwé láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin,
25 Заповеди Мојсије Левитима, који ношаху ковчег завета Господњег, говорећи:
ó sì fi àṣẹ yìí fún àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa:
26 Узмите ову књигу закона и метните је покрај ковчега завета Господа Бога свог, да буде онде сведок на вас.
“Gba ìwé òfin yìí kí o sì fi sí ẹ̀gbẹ́ àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Níbẹ̀ ni yóò wà bí ẹ̀rí sí ọ.
27 Јер знам непокорност твоју и тврди врат твој. Ето, докле сам још жив с вама, до данас, бејасте непокорни Господу; а камоли кад ја умрем?
Nítorí mo mọ irú ọlọ̀tẹ̀ àti ọlọ́rùn líle tí ẹ jẹ́. Bí o bá ṣe ọlọ̀tẹ̀ sí Olúwa nígbà tí mo pàpà wà láyé pẹ̀lú yín, báwo ní ẹ ó ti ṣe ọlọ̀tẹ̀ tó nígbà tí mo bá kú tán!
28 Скупите мени све старешине од племена својих и управитеље своје да им кажем да чују ове речи, и да им засведочим небом и земљом.
Ẹ péjọpọ̀ síwájú mi gbogbo àgbà ẹ̀yà yín àti àwọn aláṣẹ yín, kí èmi lè sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí etí ìgbọ́ ọ́ wọn.
29 Јер знам да ћете се по смрти мојој покварити, и заћи с пута који вам заповедих; и зато ће вас задесити ово зло најпосле, кад станете чинити што је зло пред Господом гневећи Га делом руку својих.
Nítorí tí mo mọ̀ pé lẹ́yìn ikú mi, ó dájú pé ìwọ yóò padà di ìbàjẹ́ pátápátá, ẹ ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ní ọjọ́ tó ń bọ̀, ìpọ́njú yóò sọ̀kalẹ̀ sórí i yín nítorí ẹ̀yin yóò ṣe búburú níwájú Olúwa ẹ ó sì mú u bínú nípa ohun tí ọwọ́ yín ti ṣe.”
30 И изговори Мојсије да чује сав збор Израиљев речи ове песме до краја.
Mose sì ka ọ̀rọ̀ inú orin yìí láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin sí etí ìgbọ́ ọ gbogbo ìjọ Israẹli: