< 1 Књига о царевима 3 >

1 А Соломун се опријатељи с фараоном, царем мисирским, и ожени се кћерју фараоновом, и доведе је у град Давидов докле не доврши свој дом и дом Господњи и зид око Јерусалима.
Solomoni sì bá Farao ọba Ejibiti dá àna, ó sì fẹ́ ọmọbìnrin rẹ̀ ní ìyàwó. Ó sì mú un wá sí ìlú Dafidi títí tí ó fi parí kíkọ́ ààfin rẹ̀ àti tẹmpili Olúwa, àti odi tí ó yí Jerusalẹmu ká.
2 Али народ приношаше жртве на висинама; јер још не беше сазидан дом имену Господњем до тада.
Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn ènìyàn ṣì ń rú ẹbọ ní ibi gíga, nítorí a kò tí ì kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa títí di ìgbà náà
3 А Соломун љубљаше Господа ходећи по уредбама оца свог Давида, само што на висинама приношаше жртве и кађаше.
Solomoni sì fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn sí Olúwa nípa rírìn gẹ́gẹ́ bí òfin Dafidi baba rẹ̀, àti pé, ó rú ẹbọ, ó sì fi tùràrí jóná ní ibi gíga.
4 Зато отиде цар у Гаваон да онде принесе жртву, јер то беше велика висина; и Соломун принесе хиљаду жртава паљеница на оном олтару.
Ọba sì lọ sí Gibeoni láti rú ẹbọ, nítorí ibẹ̀ ni ibi gíga tí ó ṣe pàtàkì jù, Solomoni sì rú ẹgbẹ̀rún ọrẹ ẹbọ sísun lórí pẹpẹ.
5 И јави се Господ Соломуну у Гаваону ноћу у сну, и рече Бог: Ишти шта хоћеш да ти дам.
Ní Gibeoni, Olúwa fi ara han Solomoni lójú àlá ní òru, Ọlọ́run sì wí pé, “Béèrè fún ohunkóhun tí o bá ń fẹ́ kí èmi ó fi fún ọ.”
6 А Соломун рече: Ти си учинио велику милост слузи свом Давиду оцу мом, као што је ходио пред Тобом верно и праведно и с правим срцем према Теби; и сачувао си му ову велику милост, те му дао сина да седи на престолу његовом, као што се види данас.
Solomoni sì dáhùn wí pé, “O ti fi inú rere oore ńlá hàn sí ìránṣẹ́ rẹ, Dafidi baba mi, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ àti olódodo àti ẹni tí ó ní ọkàn ìdúró ṣinṣin. Ìwọ sì tẹ̀síwájú nínú oore ńlá yìí fún un, ìwọ sì ti fún un ní ọmọkùnrin láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ ní gbogbo ọjọ́.
7 И тако Господе Боже мој, Ти си поставио слугу свог царем на место Давида оца мог, а ја сам млад, нити знам полазити ни долазити.
“Nísinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run mi, o ti mú ìránṣẹ́ rẹ jẹ ọba ní ipò Dafidi baba mi. Ṣùgbọ́n ọmọ kékeré ni mí, èmi kò sì mọ jíjáde àti wíwọlé mi.
8 И Твој је слуга међу народом Твојим, који си изабрао, народом великим, који се не може избројати ни прорачунати од множине.
Ìránṣẹ́ rẹ nìyí láàrín àwọn ènìyàn tí o ti yàn, àwọn ènìyàn ńlá, wọ́n pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí a kò sì lè kà wọ́n tàbí mọye wọn.
9 Дај дакле слузи свом срце разумно да може судити народу Твом и распознавати добро и зло. Јер ко може судити народу Твом тако великом?
Nítorí náà fi ọkàn ìmòye fún ìránṣẹ́ rẹ láti le ṣàkóso àwọn ènìyàn rẹ àti láti mọ ìyàtọ̀ láàrín rere àti búburú. Nítorí ta ni ó lè ṣe àkóso àwọn ènìyàn ńlá rẹ yìí?”
10 И би мило Господу што Соломун то заиска.
Inú Olúwa sì dùn pé Solomoni béèrè nǹkan yìí.
11 И рече му Бог: Кад то иштеш, а не иштеш дуг живот нити иштеш благо нити иштеш душе непријатеља својих него иштеш разум да умеш судити;
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ ti béèrè fún èyí, tí kì í ṣe ẹ̀mí gígùn tàbí ọrọ̀ fún ara rẹ, tàbí béèrè fún ikú àwọn ọ̀tá rẹ, ṣùgbọ́n fún òye láti mọ ẹjọ́ dá,
12 Ево учиних по твојим речима; ево ти дајем срце мудро и разумно да таквог какав си ти ни пре тебе није било нити ће после тебе настати такав какав си ти.
èmi yóò ṣe ohun tí ìwọ ti béèrè. Èmi yóò fún ọ ní ọgbọ́n àti ọkàn ìmòye, tó bẹ́ẹ̀ tí kò fi ní sí ẹnìkan tí ó dàbí rẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò dìde tí yóò dàbí rẹ lẹ́yìn rẹ.
13 А сврх тога дајем ти и шта ниси искао, и благо и славу, да таквог какав ћеш ти бити неће бити међу царевима свега века твог.
Síwájú sí i, èmi yóò fi ohun tí ìwọ kò béèrè fún ọ: ọrọ̀ àti ọlá ní gbogbo ayé rẹ, tí kì yóò sí ẹnìkan nínú àwọn ọba tí yóò dàbí rẹ.
14 И ако узидеш мојим путевима држећи уредбе моје и заповести моје, као што је ишао Давид отац твој, продужићу дане твоје.
Àti bí ìwọ bá rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì pa òfin àti àṣẹ mi mọ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.”
15 Тада се пробуди Соломун, и гле, оно беше сан. И дође у Јерусалим, и ставши пред ковчег завета Господњег принесе жртве паљенице и жртве захвалне, и почасти све слуге своје.
Solomoni jí: ó sì mọ̀ pé àlá ni. Ó sì padà sí Jerusalẹmu, ó sì dúró níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà. Nígbà náà ni ó ṣe àsè fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
16 Тада дођоше две жене курве к цару, и стадоше пред њим.
Lẹ́yìn náà ni àwọn obìnrin alágbèrè méjì wá sọ́dọ̀ ọba, wọ́n sì dúró níwájú rẹ̀.
17 И рече једна жена: Ах, господару; ја и ова жена седимо у једној кући, и породих се код ње у истој кући.
Ọ̀kan nínú wọn sì wí pé, “Olúwa mi, èmi àti obìnrin yìí ń gbé nínú ilé kan. Èmi sì bí ọmọ ní ilé pẹ̀lú rẹ̀.
18 А трећи дан после мог порођаја породи се и ова жена, и бејасмо заједно и не беше нико други с нама у кући, само нас две бејасмо у кући.
Ní ọjọ́ kẹta lẹ́yìn ìgbà tí mo bímọ tan, obìnrin yìí sì bímọ pẹ̀lú. A sì nìkan dá wà; kò sí àlejò ní ilé bí kò ṣe àwa méjèèjì nìkan.
19 И умре син ове жене ноћас, јер она леже на њ.
“Ní òru, ọmọ obìnrin yìí kú nítorí tí ó sùn lé e.
20 Па уставши у по ноћи узе сина мог искрај мене, кад слушкиња твоја спаваше, и стави га себи у наручје, а сина свог мртвог стави мени у наручје.
Nígbà náà ni ó sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó sì gbé ọmọ tèmi lẹ́gbẹ̀ẹ́ mi, nígbà tí èmi ìránṣẹ́ rẹ̀ ti sùn lọ. Ó sì tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì tẹ́ òkú ọmọ tirẹ̀ sí àyà mi.
21 А кад устах ујутру да подојим сина свог, а то мртав; али кад разгледах ујутру, а то, не беше мој син, ког ја родих.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo sì dìde láti fi ọmú fún ọmọ mi: ó sì ti kú! Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo sì wò ó fín ní òwúrọ̀, mo sì rí i pé kì í ṣe ọmọ mi tí mo bí.”
22 Тада рече друга жена: Није тако; него је мој син овај живи, а твој је син онај мртви. Али она рече: Није тако, него је твој син онај мртви, а мој је син овај живи. Тако говораху пред царем.
Obìnrin kejì sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí alààyè ni ọmọ mi, èyí òkú ni ọmọ tirẹ̀.” Èyí òkú ni tirẹ̀; èyí alààyè ni tèmi. Ṣùgbọ́n èyí àkọ́kọ́ tún wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí òkú ni tìrẹ; èyí alààyè ni tèmi.” Báyìí ni wọ́n sì ń jiyàn níwájú ọba.
23 А цар рече: Ова каже: Овај је живи мој син, а твој је син овај мртви; а она каже: Није тако, него је твој син онај мртви, а мој је син овај живи.
Ọba sì wí pé, “Ẹni yìí wí pé, ‘Ọmọ mi ni ó wà láààyè, ọmọ tirẹ̀ ni ó kú,’ nígbà tí ẹni èkejì náà ń wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́! Ọmọ tirẹ̀ ni ó kú, ọmọ tèmi ni ó wà láààyè.’”
24 И рече цар: Дајте ми мач. И донесоше мач пред цара.
Nígbà náà ni ọba wí pé, “Ẹ mú idà fún mi wá.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú idà wá fún ọba.
25 Тада рече цар: Расеците живо дете на двоје, и подајте половину једној и половину другој.
Ọba sì pàṣẹ pé, “Ẹ gé alààyè ọmọ sí méjì, kí ẹ sì mú ìdajì fún ọ̀kan, àti ìdajì fún èkejì.”
26 Тада жена које син беше живи рече цару, јер јој се усколеба утроба за сином: Ах, господару, подајте њој дете живо, а немојте га убијати. А она рече: Нека не буде ни мени ни теби, расеците га.
Obìnrin tí ọmọ tirẹ̀ wà láààyè sì kún fún àánú fún ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, olúwa mi, ẹ fún un ní alààyè ọmọ! Ẹ má ṣe pa á!” Ṣùgbọ́n obìnrin èkejì sì wí pé, “Kì yóò jẹ́ tèmi tàbí tìrẹ. Ẹ gé e sí méjì!”
27 Тада одговори цар и рече: Подајте оној живо дете, немојте га убити, она му је мати.
Nígbà náà ni ọba dáhùn, ó wí pé, “Ẹ fi alààyè ọmọ fún obìnrin àkọ́kọ́. Ẹ má ṣe pa á: òun ni ìyá rẹ̀.”
28 И сав Израиљ чу суд који изрече цар, и побојаше се цара; јер видеше да је у њему мудрост Божја да суди.
Nígbà tí gbogbo Israẹli gbọ́ ìdájọ́ tí ọba ṣe, wọ́n sì bẹ̀rù níwájú ọba, nítorí wọ́n ti rí í pé ó ní ọgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run láti ṣe ìdájọ́.

< 1 Књига о царевима 3 >