< Psalmi 12 >

1 Pomagaj, Gospode; jer nesta svetijeh, jer je malo vjernijeh meðu sinovima èovjeèijim.
Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa, nítorí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run kò sí mọ́; olóòtítọ́ tí pòórá kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
2 Laž govore jedan drugome, usnama lažljivijem govore iz srca dvolièna.
Olúkúlùkù ń parọ́ fún aládùúgbò rẹ̀; ètè èké wọn ń sọ ẹ̀tàn.
3 Istrijebiæe Gospod sva usta lažljiva, jezik velièavi,
Kí Olúwa kí ó gé ètè èké wọn àti gbogbo ahọ́n ìfọ́nnu
4 Ljude, koji govore: jezikom smo jaki, usta su naša u nas, ko je gospodar nad nama?
tí ó wí pé, “Àwa ó borí pẹ̀lú ahọ́n wa; àwa ní ètè wa, ta ni ọ̀gá wa?”
5 Videæi stradanje nevoljnih i uzdisanje ništih, sad æu ustati, veli Gospod, i izbaviti onoga kome zlobe.
“Nítorí ìnilára àwọn aláìlágbára àti ìkérora àwọn aláìní, Èmi yóò dìde nísinsin yìí,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn tí ń ṣe àrankàn wọn.”
6 Rijeèi su Gospodnje rijeèi èiste, srebro u vatri oèišæeno od zemlje, sedam puta pretopljeno.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì jẹ aláìlábùkù, gẹ́gẹ́ bí fàdákà tí a yọ́ nínú ìléru amọ̀, tí a sọ di mímọ́ nígbà méje.
7 Ti æeš nas, Gospode, odbraniti, i saèuvati nas od roda ovoga dovijeka.
Olúwa, ìwọ yóò pa wá mọ́ kí o sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí títí láé.
8 Bezbožnici idu naokolo; kad se oni podižu, sramote se sinovi èovjeèiji.
Àwọn ènìyàn búburú ń rin ìrìn fáàrí kiri nígbà tí wọn ń bọ̀wọ̀ fún òsì láàrín àwọn ènìyàn.

< Psalmi 12 >