< Brojevi 6 >

1 Još reèe Gospod Mojsiju govoreæi:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Reci sinovima Izrailjevijem, i kaži im: kad èovjek ili žena uèini zavjet nazirejski, da bude nazirej Gospodu,
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ pàtàkì, ẹ̀jẹ́ ìyara-ẹni-sọ́tọ̀ sí Olúwa nípa àìgé irun orí (Nasiri),
3 Neka se uzdržava od vina i silovita piæa, i neka ne pije octa vinskoga ni octa od silovita piæa niti kakvoga piæa od grožða i neka ne jede grožða ni novoga ni suhoga.
irú ẹni bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ yàgò fún wáìnì tàbí ọtí líle, ọtí wáìnì kíkan àti àwọn ohun mímu mìíràn tó bá kan. Kò gbọdọ̀ mu èso àjàrà tàbí kí ó jẹ èso àjàrà tútù tàbí gbígbẹ.
4 Dokle god traje njegovo nazirejstvo neka ne jede ništa od vinove loze, ni zrna ni ljuske.
Níwọ́n ìgbà tí ó sì jẹ́ Nasiri, ní kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi èso àjàrà ṣe, ìbá à ṣe kóró tàbí èèpo rẹ̀.
5 Dokle traje njegovo nazirejstvo, neka mu britva ne prijeðe preko glave; dokle se ne navrše dani za koje se uèinio nazirej Gospodu, neka bude svet i neka ostavlja kosu na glavi svojoj.
“‘Ní gbogbo ìgbà ẹ̀jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, kí abẹ kankan má ṣe kàn án ní orí. Ó gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ títí tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa yóò fi pé; ó gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí rẹ̀ gùn.
6 Dokle traju dani za koje se uèinio nazirej Gospodu, neka ne pristupa k mrtvacu.
“‘Ní gbogbo àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa kò gbọdọ̀ súnmọ́ òkú ènìyàn.
7 Ni za ocem svojim ni za materom svojom ni za bratom svojim ni za sestrom svojom, neka se za njima ne skvrni kad umru; jer je nazirejstvo Boga njegova na glavi njegovoj.
Ìbá à ṣe òkú baba, àti ìyá rẹ̀, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin tàbí àbúrò rẹ̀, kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nítorí wọn, nítorí pé àmì ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Ọlọ́run wà ní orí rẹ̀.
8 Dokle god traje nazirejstvo njegovo, svet je Gospodu.
Ní gbogbo àsìkò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
9 Ako li bi ko umro do njega na preèac, te bi oskvrnio nazirejstvo glave njegove, neka obrije glavu svoju u dan èišæenja svojega, sedmi dan neka je obrije.
“‘Bí ẹnìkan bá kú ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òjijì, tí ó sì ba irun rẹ̀ tó yà sọ́tọ̀ jẹ́; ó gbọdọ̀ gé irun rẹ̀ ní ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀ èyí tí í ṣe ọjọ́ keje.
10 A osmi dan neka donese dvije grlice ili dva golubiæa svešteniku na vrata šatora od sastanka.
Ní ọjọ́ kẹjọ, yóò mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé méjì wá sọ́dọ̀ àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
11 I sveštenik neka zgotovi od jednoga žrtvu za grijeh a od drugoga žrtvu paljenicu, i neka ga oèisti od onoga što je zgriješio kod mrtvaca; tako æe posvetiti glavu njegovu u taj dan.
Àlùfáà yóò fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun láti fi ṣe ètùtù fún un nítorí pé ó ti ṣẹ̀ nípa wíwà níbi tí òkú ènìyàn wà. Yóò sì ya orí rẹ̀ sí mímọ́ ní ọjọ́ náà gan an.
12 I neka odijeli Gospodu dane nazirejstva svojega, i donese jagnje od godine za krivicu; a preðašnji dani propadaju, jer mu se oskvrnilo nazirejstvo.
Ó gbọdọ̀ ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ sí Olúwa fún àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀, ó sì gbọdọ̀ mú akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀bi. Kò sì ní í ka àwọn ọjọ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ti tẹ́lẹ̀ nítorí pé ó tí ba ara rẹ̀ jẹ́ ní àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀.
13 A ovo je zakon za nazireje: kad se navrše dani nazirejstvu njegovu, neka doðe na vrata šatora od sastanka.
“‘Èyí ni òfin fún Nasiri nígbà tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ bá pé. Wọn ó mu wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
14 I neka donese za žrtvu Gospodu jagnje muško od godine zdravo za žrtvu paljenicu, i jagnje žensko od godine zdravo za grijeh, i ovna zdrava za žrtvu zahvalnu,
Níbẹ̀ ni yóò ti mú ọrẹ wá fún Olúwa, akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan tí kò ní àbùkù fún ẹbọ sísun àti ẹgbọrọ-àgùntàn ọlọ́dún kan, tí kò ní àbùkù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àgbò kan tí kò ní àbùkù fún ọrẹ àlàáfíà,
15 I kotaricu hljebova prijesnijeh, kolaèa od bijeloga brašna zamiješenijeh s uljem, i pogaèa prijesnijeh namazanijeh uljem, s darom njihovijem i s naljevom njihovijem.
pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu, apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí a kò fi ìwúkàrà ṣe, àkàrà tí a fi ìyẹ̀fun dáradára pò mọ́ òróró àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí a fi òróró sọjọ̀ lé lórí.
16 A to æe sveštenik prinijeti pred Gospodom i uèiniti žrtvu za grijeh njegov i žrtvu njegovu paljenicu.
“‘Àlùfáà yóò gbé gbogbo rẹ̀ wá síwájú Olúwa, yóò sì rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ sísun.
17 A ovna æe prinijeti na žrtvu zahvalnu Gospodu s kotaricom prijesnijeh hljebova; prinijeæe sveštenik i dar njegov i naljev njegov.
Àlùfáà yóò fi àgbò náà rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa, pẹ̀lú apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà; yóò rú ẹbọ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu.
18 Tada nazirej neka obrije glavu svojega nazirejstva na vratima šatora od sastanka; i uzev kosu nazirejstva svojega neka je metne u oganj koji je pod žrtvom zahvalnom.
“‘Nígbà náà ni Nasiri náà yóò fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Yóò fi irun náà sínú iná tó wà lábẹ́ ẹbọ àlàáfíà.
19 I sveštenik neka uzme pleæe kuhano od ovna i jedan kolaè prijesan iz kotarice i jednu pogaèu prijesnu, i neka metne na ruke nazireju, pošto obrije nazirejstvo svoje.
“‘Lẹ́yìn tí Nasiri bá ti fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ tan, àlùfáà yóò mú apá àgbò bíbọ̀, àkàrà aláìwú kan àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí kò ní ìwúkàrà láti inú apẹ̀rẹ̀ yóò sì kó gbogbo rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 I sveštenik neka obræe te stvari na žrtvu obrtanu pred Gospodom; to je svetinja, koja pripada svešteniku osim grudi obrtanih i pleæa podignutoga; a poslije toga nazirej može piti vina.
Àlùfáà yóò fi gbogbo rẹ̀ níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì, wọ́n jẹ́ mímọ́, wọ́n sì jẹ́ ti àlùfáà pẹ̀lú igẹ̀ tí a fì àti itan tí wọ́n mú wá. Lẹ́yìn èyí, Nasiri náà lè mu wáìnì.
21 To je zakon za nazireja koji se zavjetuje, i to je prinos njegov Gospodu za nazirejstvo njegovo, osim onoga što bi više mogao uèiniti; kakav mu bude zavjet kojim se zavjetuje, tako neka uèini osim zakona svojega nazirejstva.
“‘Èyí ni òfin Nasiri tó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ rẹ̀ sí Olúwa, yóò wà ní ìbámu pẹ̀lú ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Nasiri, ní àfikún sí àwọn ohun mìíràn tó lágbára láti mú wá. Ó gbọdọ̀ mú ẹ̀jẹ́ tó jẹ́ ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin Nasiri.’”
22 Još reèe Gospod Mojsiju govoreæi:
Olúwa sọ fún Mose pé,
23 Reci Aronu i sinovima njegovijem i kaži: ovako blagosiljajte sinove Izrailjeve govoreæi im:
“Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé, ‘Báyìí ni kí ẹ ṣe máa súre fún àwọn ọmọ Israẹli. Ẹ sọ fún wọn pé,
24 Da te blagoslovi Gospod i da te èuva!
“‘“Kí Olúwa bùkún un yín, kí ó sì pa yín mọ́.
25 Da te obasja Gospod licem svojim i bude ti milostiv!
Kí Olúwa kí o mú ojú rẹ̀ kí ó mọ́lẹ̀ sí i yín lára. Kí ó sì ṣàánú fún un yín.
26 Da Gospod obrati lice svoje k tebi i dade ti mir!
Kí Olúwa bojú wò yín, kí ó sì fún un yín ní àlàáfíà.”’
27 I neka prizivlju ime moje na sinove Izrailjeve, i ja æu ih blagosloviti.
“Báyìí ni wọn ó ṣe fi orúkọ mi sára àwọn ọmọ Israẹli, Èmi ó sì bùkún wọn.”

< Brojevi 6 >