< Jona 1 >

1 Doðe rijeè Gospodnja Joni sinu Amatijevu govoreæi:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona ọmọ Amittai wá, wí pé:
2 Ustani, idi u Nineviju grad veliki, i propovijedaj protiv njega, jer izaðe zloæa njihova preda me.
“Dìde lọ sí ìlú ńlá Ninefe kí o sì wàásù sí i, nítorí ìwà búburú rẹ̀ gòkè wá iwájú mi.”
3 A Jona usta da bježi u Tarsis od Gospoda, i sišav u Jopu naðe laðu koja iðaše u Tarsis, i plativ vozarinu uðe u nju da otide s njima u Tarsis od Gospoda.
Ṣùgbọ́n Jona dìde kúrò láti sálọ sí Tarṣiṣi kúrò níwájú Olúwa, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Joppa, ìbí ti ó tí rí ọkọ̀ kan tí ń lọ sí Tarṣiṣi: lẹ́yìn ti ó sanwó ọkọ̀, ó wọlé sínú rẹ̀, láti bá wọn lọ sí Tarṣiṣi kúrò níwájú Olúwa.
4 Ali Gospod podiže velik vjetar na moru, i posta velika bura na moru da mišljahu da æe se razbiti laða.
Nígbà náà ni Olúwa rán ìjì ńlá jáde sí ojú Òkun, ìjì líle sì wà nínú Òkun tó bẹ́ẹ̀ tí ọkọ̀ náà dàbí ẹni pé yóò fọ́.
5 I laðari uplašivši se prizivahu svaki svojega boga, i bacahu što bješe u laði u more da bi bila lakša; a Jona bješe sišao na dno laði, i legav spavaše tvrdo.
Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ bẹ̀rù, olúkúlùkù sì ń kígbe sí ọlọ́run rẹ̀, wọ́n kó ẹrù tí ó wà nínú ọkọ̀ dà sínú Òkun, kí ó bá à lè fúyẹ́. Ṣùgbọ́n Jona sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ ọkọ̀ ó sì dùbúlẹ̀, ó sùn wọra.
6 A upravitelj od laðe pristupi k njemu i reèe mu: šta ti spavaš! ustani, prizivaj Boga svojega, ne bi li nas se opomenuo Bog da ne poginemo.
Bẹ́ẹ̀ ni olórí ọkọ̀ tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi sùn, ìwọ olóòórùn? Dìde kí o ké pe Ọlọ́run rẹ! Bóyá yóò ro tiwa, kí àwa má ba à ṣègbé.”
7 Potom rekoše jedan drugome: hodite, da bacimo ždrijeb da vidimo sa koga doðe na nas ovo zlo. I baciše ždrijeb, i pade ždrijeb na Jonu.
Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ sọ fún ara wọn pé, “Wá, ẹ jẹ́ kí a sẹ́ kèké, kí àwa kí o le mọ̀ nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa.” Wọ́n ṣẹ́ kèké, kèké sì mú Jona.
8 Tada mu rekoše: kaži nam zašto doðe ovo zlo na nas; koje si radnje? i odakle ideš? iz koje si zemlje? i od koga si naroda?
Nígbà náà ni wọn wí fún un pé, “Sọ fún wa, àwa bẹ̀ ọ́, nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa? Kí ni iṣẹ́ rẹ? Níbo ni ìwọ ti wá? Kí ni orúkọ ìlú rẹ? Ẹ̀yà orílẹ̀-èdè wo sì ni ìwọ sì í ṣe?”
9 A on im reèe: Jevrejin sam, i bojim se Gospoda Boga nebeskoga, koji je stvorio more i suhu zemlju.
Òun sì dá wọn lóhùn pé, “Heberu ni èmi, mo sì bẹ̀rù Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run ẹni tí ó dá Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀.”
10 Tada se vrlo uplašiše ljudi, i rekoše mu: što si uèinio? Jer doznaše ljudi da bježi od Gospoda, jer im on kaza.
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù gidigidi, wọn sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ṣe èyí?” (Nítorí àwọn ọkùnrin náà mọ̀ pé ó ń sá kúrò ní iwájú Olúwa ni, nítorí òun ti sọ fun wọn bẹ́ẹ̀).
11 I rekoše mu: što æemo èiniti s tobom, da bi nam more utolilo? Jer bura na moru bivaše sve veæa.
Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Kí ni kí àwa ó ṣe sí ọ kí Òkun lè dákẹ́ fún wa?” Nítorí Òkun ru, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle.
12 A on im reèe: uzmite me i bacite me u more, i more æe vam utoliti, jer vidim da je s mene došla na vas ova velika bura.
Òun sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé mi, kí ẹ sì sọ mi sínú Òkun, bẹ́ẹ̀ ni okun yóò sì dákẹ́ fún un yin. Nítorí èmi mọ̀ pé, nítorí mi ni ẹ̀fúùfù líle yìí ṣe dé bá a yín.”
13 A ljudi stadoše veslati da bi došli ka kraju; ali ne mogahu, jer im bura na moru bivaše sve veæa.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà gbìyànjú gidigidi láti mú ọkọ̀ wà sí ilẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò lè ṣe é: nítorí tí Òkun túbọ̀ ru sí i, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle sí wọn.
14 Tada prizvaše Gospoda i rekoše: molimo ti se, Gospode, da ne poginemo radi duše ovoga èovjeka, i nemoj metnuti na nas krvi prave, jer ti, Gospode, èiniš kako hoæeš.
Nítorí náà wọ́n kígbe sí Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Olúwa àwa bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí àwa ṣègbé nítorí ẹ̀mí ọkùnrin yìí. Má sì ka ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sí wa ní ọrùn, nítorí ìwọ, Olúwa, ti ṣe bí ó ti wù ọ́.”
15 Potom uzeše Jonu i baciše ga u more, i presta bura na moru.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé Jona, tí wọ́n sì sọ ọ́ sínú Òkun, Òkun sì dẹ́kun ríru rẹ̀.
16 Tada se pobojaše oni ljudi Gospoda vrlo, i prinesoše žrtvu Gospodu i uèiniše zavjete.
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù Olúwa gidigidi, wọn si rú ẹbọ sí Olúwa, wọ́n sì jẹ́ ẹ̀jẹ́.
17 A Gospod zapovjedi, te velika riba proguta Jonu; i Jona bi u trbuhu ribljem tri dana i tri noæi.
Ṣùgbọ́n Olúwa ti pèsè ẹja ńlá kan láti gbé Jona mì. Jona sì wà nínú ẹja náà ni ọ̀sán mẹ́ta àti òru mẹ́ta.

< Jona 1 >