< Jeremija 21 >
1 Rijeè koja doðe Jeremiji od Gospoda kad posla k njemu car Sedekija Pashora sina Melhijina i Sofoniju sina Masijina sveštenika, i poruèi:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
2 Upitaj Gospoda za nas, jer Navuhodonosor car Vavilonski zavojšti na nas; eda bi nam uèinio Gospod po svijem èudesima svojim, da otide od nas.
“Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
3 A Jeremija im reèe: ovako recite Sedekiji:
Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
4 Ovako veli Gospod Bog Izrailjev: evo, ja æu okrenuti natrag oružje što je u vašim rukama, kojim se bijete s carem Vavilonskim i s Haldejcima koji su vas opkolili iza zidova, i skupiæu ih usred toga grada.
‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
5 I ja æu vojevati na vas rukom podignutom i mišicom krjepkom i gnjevom i jarošæu i žestinom velikom.
Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
6 I pobiæu stanovnike toga grada, i ljude i stoku; od pomora velikoga pomrijeæe.
Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
7 A poslije, veli Gospod, daæu Sedekiju cara Judina i sluge njegove i narod, one koji ostanu u tom gradu od pomora, od maèa i od gladi, u ruke Navuhodonosoru caru Vavilonskom i u ruke neprijateljima njihovijem i u ruke onima koji traže dušu njihovu, te æe ih pobiti maèem, neæe ih žaliti ni štedjeti niti æe se smilovati.
Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
8 A narodu tome reci: ovako veli Gospod: evo ja stavljam pred vas put k životu i put k smrti.
“Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
9 Ko ostane u tom gradu, poginuæe od maèa ili od gladi ili od pomora; a ko izaðe i preda se Haldejcima koji su vas opkolili, ostaæe živ, i duša æe mu biti mjesto plijena.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
10 Jer okretoh lice svoje tome gradu na zlo a ne na dobro, govori Gospod; u ruke caru Vavilonskom biæe predan, i on æe ga spaliti ognjem.
Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
11 A za dom cara Judina èujte rijeè Gospodnju:
“Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Dome Davidov, tako veli Gospod, sudite svako jutro, i kome se otima izbavljajte ga iz ruku nasilnikovijeh da ne izaðe kao oganj gnjev moj i razgori se da ga niko ne može ugasiti za zloæu djela vaših.
Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
13 Evo me na tebe, koji sjediš u dolini, kao stijena u ravnici, govori Gospod, na vas, koji govorite: ko æe doæi na nas? i ko æe uæi u stanove naše?
Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
14 Jer æu vas pokarati po plodu djela vaših, veli Gospod, i raspaliæu oganj u šumi njegovoj, koji æe proždrijeti sve što je oko njega.
Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”