< Ponovljeni Zakon 30 >

1 A kad doðe na tebe sve ovo, blagoslov i kletva koju iznesoh preda te, ako ih se opomeneš u srcu svom, gdje bi god bio meðu narodima, u koje te zagna Gospod Bog tvoj,
Nígbà tí gbogbo ìbùkún àti ègún wọ̀nyí tí mo ti gbé kalẹ̀ síwájú u yín bá wá sórí i yín àti tí o bá mú wọn sí àyà rẹ níbikíbi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá tú ọ ká sí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
2 I obratiš se ka Gospodu Bogu svojemu i poslušaš glas njegov u svemu što ti ja zapovijedam danas, ti i sinovi tvoji, iz svega srca svojega i iz sve duše svoje,
àti nígbà tí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ bá yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì gbọ́rọ̀ sí pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un yín lónìí.
3 Tada æe Gospod Bog tvoj povratiti roblje tvoje i smilovaæe se na tebe, i opet æe te sabrati izmeðu svijeh naroda, po kojima te bude rasijao Gospod Bog tvoj.
Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ohun ìní rẹ bọ̀ sípò yóò sì ṣàánú fún ọ, yóò sì tún ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè níbi tí ó ti fọ́n yín ká sí.
4 Ako bi ko tvoj i na kraj svijeta zagnan bio, otuda æe te opet sabrati Gospod Bog tvoj i otuda te uzeti.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti lé ẹni rẹ kan sí ilẹ̀ tí ó jìnnà jù lábẹ́ ọ̀run, láti ibẹ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò ṣà yín jọ yóò sì tún mú u yín padà.
5 I odvešæe te opet Gospod Bog tvoj u zemlju koju bijahu naslijedili oci tvoji, i naslijediæeš je, i uèiniæe ti dobro i umnožiæe te veæma nego oce tvoje.
Yóò mú ọ wá sí ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn baba yín, ìwọ yóò sì mú ìní níbẹ̀. Olúwa yóò mú ọ wà ní àlàáfíà kíkún, yóò mú ọ pọ̀ sí i ju àwọn baba yín lọ.
6 I obrezaæe Gospod Bog tvoj srce tvoje i srce sjemena tvojega, da bi ljubio Gospoda Boga svojega iz svega srca svojega i iz sve duše svoje, da budeš živ.
Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò kọ ọkàn rẹ ní ilà àti ọkàn àwọn ọmọ yín, nítorí kí o lè fẹ́ ẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, àti ayé rẹ.
7 A sve kletve ove obratiæe Gospod Bog tvoj na neprijatelje tvoje i na nenavidinike tvoje, koji su te gonili.
Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú gbogbo ègún yín wá sórí àwọn ọ̀tá à rẹ tí wọ́n kórìíra àti tí wọ́n ṣe inúnibíni rẹ.
8 A ti kad se obratiš i staneš slušati glas Gospoda Boga svojega i tvoriti sve zapovijesti njegove, koje ti ja danas zapovijedam,
Ìwọ yóò tún gbọ́rọ̀ sí Olúwa àti tẹ̀lé gbogbo àṣẹ rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí.
9 Daæe ti Gospod Bog tvoj sreæu u svakom djelu ruku tvojih, u plodu utrobe tvoje, u plodu stoke tvoje, u plodu zemlje tvoje; jer æe ti se Gospod Bog tvoj opet radovati èineæi ti dobro, kao što se radovao ocima tvojim,
Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ọ ṣe rere nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ, àti nínú gbogbo ọmọ inú rẹ, agbo ẹran ọ̀sìn rẹ àti èso ilẹ̀ rẹ. Olúwa yóò tún mú inú dídùn sínú rẹ yóò sì mú ọ ṣe déédé, gẹ́gẹ́ bí ó ti fi inú dídùn sínú àwọn baba rẹ.
10 Ako uzaslušaš glas Gospoda Boga svojega držeæi sve zapovijesti njegove i uredbe njegove, napisane u knjizi ovoga zakona; kad se obratiš ka Gospodu Bogu svojemu svijem srcem svojim i svom dušom svojom.
Bí o bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́ àti àṣẹ tí a kọ sínú ìwé òfin yìí kí o sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.
11 Jer zapovijest ova koju ti ja zapovijedam danas niti je visoko ni daleko od tebe;
Nítorí àṣẹ yìí tí mo pa fún ọ lónìí, kò ṣòro jù fún ọ, bẹ́ẹ̀ ni kò kọjá agbára rẹ.
12 Nije na nebu, da reèeš: ko æe nam se popeti na nebo da nam je skine i kaže nam je, da bismo je tvorili?
Kò sí ní ọ̀run, tí ìwọ kò bá fi wí pé, “Ta ni yóò gòkè lọ sí ọ̀run fún wa, tí yóò sì mú wa fún wa, kí àwa lè gbọ́, kí a sì le ṣe é?”
13 Niti je preko mora, da reèeš: ko æe nam otiæi preko mora, da nam je donese i kaže nam je, da bismo je tvorili?
Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ìhà kejì Òkun, tí ìwọ ìbá fi wí pé, “Ta ni yóò rékọjá òkun lọ fún wa, tí yóò sì mú un wá fún wa, kí àwa lè gbọ́ ọ, kí a si le ṣe é?”
14 Nego ti je vrlo blizu ova rijeè, u ustima tvojima i u srcu tvojem, da bi je tvorio.
Kì í ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ náà súnmọ́ tòsí rẹ, ó wà ní ẹnu rẹ àti ní ọkàn rẹ kí ìwọ lè máa ṣe é.
15 Gle, iznesoh danas preda te život i dobro, smrt i zlo.
Wò ó mo gbé kalẹ̀ síwájú u yín lónìí, ìyè àti àlàáfíà, ikú àti ìparun.
16 Jer ti zapovijedam danas da ljubiš Gospoda Boga svojega hodeæi putovima njegovijem i držeæi zapovijesti njegove i uredbe njegove i zakone njegove, da bi živ bio i umnožio se, i da bi te blagoslovio Gospod Bog tvoj u zemlji u koju ideš da je naslijediš.
Ní èyí tí mo pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, láti máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ àti láti máa pa àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè yè, kí ó sì máa bí sí i, kí Olúwa Ọlọ́run lè bù si fún ọ ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ìwọ ń lọ láti gbà á.
17 Ako li se odvrati srce tvoje i ne uzaslušaš, nego zastraniš da se klanjaš drugim bogovima i njima služiš,
Ṣùgbọ́n tí ọkàn an yín bá yí padà tí ìwọ kò sì ṣe ìgbọ́ràn, àti bí o bá fà, lọ láti foríbalẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn àti sìn wọ́n,
18 Javljam vam danas da æete zaista propasti, niti æete produljiti dana svojih na zemlji, u koju ideš preko Jordana da je naslijediš.
èmi ń sọ fún un yín lónìí yìí pé ìwọ yóò parun láìsí àní àní. O kò ní í gbé pẹ́ ní ilẹ̀ tí ìwọ ń kọjá Jordani láti gbà àti láti ní.
19 Svjedoèim vam danas nebom i zemljom, da sam stavio pred vas život i smrt, blagoslov i prokletstvo; zato izberi život, da budeš živ ti i sjeme tvoje,
Èmi pe ọ̀run àti ilẹ̀ láti jẹ́rìí tì yín ní òní pé, èmi fi ìyè àti ikú, ìbùkún àti ègún síwájú rẹ: nítorí náà yan ìyè, kí ìwọ kí ó lè yè, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ,
20 Ljubeæi Gospoda Boga svojega, slušajuæi glas njegov i držeæi se njega; jer je on život tvoj i duljina dana tvojih; da bi nastavao na zemlji, za koju se zakleo Gospod ocima tvojim, Avramu, Isaku i Jakovu, da æe im je dati.
kí ìwọ kí ó le máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, fetísílẹ̀ sí ohùn un rẹ̀, kí o sì dúró ṣinṣin nínú rẹ̀. Nítorí Olúwa ni ìyè rẹ, yóò sì fún ọ ní ọdún púpọ̀ ní ilẹ̀ tí ó ti búra láti fi fún àwọn baba rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.

< Ponovljeni Zakon 30 >