< مَتھِح 22 >
اَنَنْتَرَں یِیشُح پُنَرَپِ درِشْٹانْتینَ تانْ اَوادِیتْ، | 1 |
Jesu tún fi òwe sọ̀rọ̀ fún wọn wí pé:
سْوَرْگِییَراجْیَمْ ایتادرِشَسْیَ نرِپَتیح سَمَں، یو نِجَ پُتْرَں وِواہَیَنْ سَرْوّانْ نِمَنْتْرِتانْ آنیتُں داسییانْ پْرَہِتَوانْ، | 2 |
“Ìjọba ọ̀run dàbí ọba kan ti ó múra àsè ìgbéyàwó ńlá fún ọmọ rẹ̀ ọkùnrin.
کِنْتُ تے سَماگَنْتُں نیشْٹَوَنْتَح۔ | 3 |
Ó rán àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ pe àwọn tí a ti pè tẹ́lẹ̀ sí ibi àsè ìgbéyàwó. Ṣùgbọ́n wọn kò fẹ́ wá.
تَتو راجا پُنَرَپِ داسانَنْیانْ اِتْیُکْتْوا پْریشَیاماسَ، نِمَنْتْرِتانْ وَدَتَ، پَشْیَتَ، مَمَ بھیجْیَماسادِتَماسْتے، نِجَوْٹَشادِپُشْٹَجَنْتُونْ مارَیِتْوا سَرْوَّں کھادْیَدْرَوْیَماسادِتَوانْ، یُویَں وِواہَماگَچّھَتَ۔ | 4 |
“Lẹ́yìn náà ó tún rán àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mìíràn pé, ‘Ẹ sọ fún àwọn tí mo ti pè wí pé, mo ti ṣe àsè náà tán. A pa màlúù àti ẹran àbọ́pa mi, a ti ṣe ohun gbogbo tán, ẹ wa sí ibi àsè ìgbéyàwó.’
تَتھَپِ تے تُچّھِیکرِتْیَ کیچِتْ نِجَکْشیتْرَں کیچِدْ وانِجْیَں پْرَتِ سْوَسْوَمارْگینَ چَلِتَوَنْتَح۔ | 5 |
“Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀n-ọn-nì tí ó ránṣẹ́ lọ pè kò kà á si. Wọ́n ń bá iṣẹ́ wọn lọ, ọ̀kan sí ọ̀nà oko rẹ̀, òmíràn sí ibi òwò rẹ̀.”
اَنْیے لوکاسْتَسْیَ داسییانْ دھرِتْوا دَوراتْمْیَں وْیَوَہرِتْیَ تانَوَدھِشُح۔ | 6 |
Àwọn ìyókù sì mú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n ṣe àbùkù sí wọn, wọ́n lù wọ́n pa.
اَنَنْتَرَں سَ نرِپَتِسْتاں وارْتّاں شْرُتْوا کْرُدھْیَنْ سَینْیانِ پْرَہِتْیَ تانْ گھاتَکانْ ہَتْوا تیشاں نَگَرَں داہَیاماسَ۔ | 7 |
Ọba yìí bínú gidigidi, ó sì rán àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, ó sì pa àwọn apànìyàn náà run, ó sì jó ìlú wọn.
تَتَح سَ نِجَداسییانْ بَبھاشے، وِواہِییَں بھوجْیَماسادِتَماسْتے، کِنْتُ نِمَنْتْرِتا جَنا اَیوگْیاح۔ | 8 |
“Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, ‘Àsè ìgbéyàwó ti ṣe tàn, ṣùgbọ́n àwọn tí a pè kò yẹ fún ọlá náà.
تَسْمادْ یُویَں راجَمارْگَں گَتْوا یاوَتو مَنُجانْ پَشْیَتَ، تاوَتَایوَ وِواہِییَبھوجْیایَ نِمَنْتْرَیَتَ۔ | 9 |
Ẹ lọ sí ìgboro àti òpópónà kí ẹ sì pe ẹnikẹ́ni tí ẹ bá lè rí wá àsè ìgbéyàwó náà.’
تَدا تے داسییا راجَمارْگَں گَتْوا بھَدْرانْ اَبھَدْرانْ وا یاوَتو جَنانْ دَدرِشُح، تاوَتَایوَ سَںگرِہْیانَیَنْ؛ تَتوبھْیاگَتَمَنُجَے رْوِواہَگرِہَمْ اَپُورْیَّتَ۔ | 10 |
Nítorí náà, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ náà sì jáde lọ sí òpópónà. Wọ́n sì mú oríṣìíríṣìí ènìyàn tí wọ́n lè rí wá, àwọn tí ò dára àti àwọn tí kò dára, ilé àsè ìyàwó sì kún fún àlejò.
تَدانِیں سَ راجا سَرْوّانَبھْیاگَتانْ دْرَشْٹُمْ اَبھْیَنْتَرَماگَتَوانْ؛ تَدا تَتْرَ وِواہِییَوَسَنَہِینَمیکَں جَنَں وِیکْشْیَ تَں جَگادْ، | 11 |
“Ṣùgbọ́n nígbà tí ọba sì wọlé wá láti wo àwọn àlejò tí a pè, ó sì rí ọkùnrin kan nínú wọn tí kò wọ aṣọ ìgbéyàwó.
ہے مِتْرَ،تْوَں وِواہِییَوَسَنَں وِنا کَتھَمَتْرَ پْرَوِشْٹَوانْ؟ تینَ سَ نِرُتَّرو بَبھُووَ۔ | 12 |
Ọba sì bi í pé, ‘Ọ̀rẹ́, báwo ni ìwọ ṣe wà níhìn-ín yìí láìní aṣọ ìgbéyàwó?’ Ṣùgbọ́n ọkùnrin náà kò ní ìdáhùn kankan.
تَدا راجا نِجانُچَرانْ اَوَدَتْ، ایتَسْیَ کَرَچَرَنانْ بَدّھا یَتْرَ رودَنَں دَنْتَیرْدَنْتَگھَرْشَنَنْچَ بھَوَتِ، تَتْرَ وَہِرْبھُوتَتَمِسْرے تَں نِکْشِپَتَ۔ | 13 |
“Nígbà náà ni ọba wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ dì í tọwọ́ tẹsẹ̀, kí ẹ sì sọ ọ́ sínú òkùnkùn lóde níbi tí ẹkún àti ìpayínkeke wà.’
اِتّھَں بَہَوَ آہُوتا اَلْپے مَنوبھِمَتاح۔ | 14 |
“Nítorí ọ̀pọ̀ ni a pè ṣùgbọ́n díẹ̀ ni a yàn.”
اَنَنْتَرَں پھِرُوشِنَح پْرَگَتْیَ یَتھا سَںلاپینَ تَمْ اُنْماتھے پاتَیییُسْتَتھا مَنْتْرَیِتْوا | 15 |
Nígbà náà ni àwọn Farisi péjọpọ̀ láti ronú ọ̀nà tì wọn yóò gbà fi ọ̀rọ̀ ẹnu mú un.
ہیرودِییَمَنُجَیح ساکَں نِجَشِشْیَگَنینَ تَں پْرَتِ کَتھَیاماسُح، ہے گُرو، بھَوانْ سَتْیَح سَتْیَمِیشْوَرِییَمارْگَمُپَدِشَتِ، کَمَپِ مانُشَں نانُرُدھْیَتے، کَمَپِ ناپیکْشَتے چَ، تَدْ وَیَں جانِیمَح۔ | 16 |
Wọ́n sì rán àwọn ọmọ-ẹ̀yìn wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Herodu lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Olùkọ́, àwa mọ̀ pé olóòtítọ́ ni ìwọ, ìwọ sì ń kọ́ni ní ọ̀nà Ọlọ́run ní òtítọ́. Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì í wo ojú ẹnikẹ́ni; nítorí tí ìwọ kì í ṣe ojúsàájú ènìyàn.
اَتَح کَیسَرَبھُوپایَ کَروسْماکَں داتَوْیو نَ وا؟ اَتْرَ بھَوَتا کِں بُدھْیَتے؟ تَدْ اَسْمانْ وَدَتُ۔ | 17 |
Nísinsin yìí sọ fún wa, kí ni èrò rẹ? Ǹjẹ́ ó tọ́ láti san owó orí fún Kesari tàbí kò tọ́?”
تَتو یِیشُسْتیشاں کھَلَتاں وِجْنایَ کَتھِتَوانْ، رے کَپَٹِنَح یُیَں کُتو ماں پَرِکْشَدھْوے؟ | 18 |
Ṣùgbọ́n Jesu ti mọ èrò búburú inú wọn, ó wí pé, “Ẹ̀yin àgàbàgebè, èéṣe ti ẹ̀yin fi ń dán mi wò?
تَتْکَرَدانَسْیَ مُدْراں ماں دَرْشَیَتَ۔ تَدانِیں تَیسْتَسْیَ سَمِیپَں مُدْراچَتُرْتھَبھاگَ آنِیتی | 19 |
Ẹ fi owó ẹyọ tí a fi ń san owó orí kan hàn mi.” Wọn mú dínárì kan wá fún un,
سَ تانْ پَپْرَچّھَ، اَتْرَ کَسْیییَں مُورْتِّ رْنامَ چاسْتے؟ تے جَگَدُح، کَیسَرَبھُوپَسْیَ۔ | 20 |
ó sì bi wọ́n pé, “Àwòrán ta ni èyí? Àkọlé tà sì ní?”
تَتَح سَ اُکْتَوانَ، کَیسَرَسْیَ یَتْ تَتْ کَیسَرایَ دَتَّ، اِیشْوَرَسْیَ یَتْ تَدْ اِیشْوَرایَ دَتَّ۔ | 21 |
Wọ́n sì dáhùn pé, “Ti Kesari ni.” “Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé,” “Ẹ fi èyí tí í ṣe ti Kesari fún Kesari, ẹ sì fi èyí ti ṣe ti Ọlọ́run fún Ọlọ́run.”
اِتِ واکْیَں نِشَمْیَ تے وِسْمَیَں وِجْنایَ تَں وِہایَ چَلِتَوَنْتَح۔ | 22 |
Nígbà tí wọ́n gbọ́ èyí, ẹnu yà wọ́n. Wọ́n fi í sílẹ̀, wọ́n sì bá tiwọn lọ.
تَسْمِنَّہَنِ سِدُوکِنورْتھاتْ شْمَشاناتْ نوتّھاسْیَنْتِیتِ واکْیَں یے وَدَنْتِ، تے یِیشےرَنْتِکَمْ آگَتْیَ پَپْرَچّھُح، | 23 |
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kan náà, àwọn Sadusi tí wọ́n sọ pé kò si àjíǹde lẹ́yìn ikú tọ Jesu wá láti bi í ní ìbéèrè,
ہے گُرو، کَشْچِنْمَنُجَشْچیتْ نِحسَنْتانَح سَنْ پْرانانْ تْیَجَتِ، تَرْہِ تَسْیَ بھْراتا تَسْیَ جایاں وْیُہْیَ بھْراتُح سَنْتانَمْ اُتْپادَیِشْیَتِیتِ مُوسا آدِشْٹَوانْ۔ | 24 |
wọ́n wí pé, “Olùkọ́, Mose wí fún wa pé, bí ọkùnrin kan bá kú ní àìlọ́mọ, kí arákùnrin rẹ̀ ṣú aya rẹ̀ lópó, kí ó sì bí ọmọ fún un.
کِنْتْوَسْماکَمَتْرَ کےپِ جَناح سَپْتَسَہودَرا آسَنْ، تیشاں جْییشْٹھَ ایکاں کَنْیاں وْیَوَہاتْ، اَپَرَں پْرانَتْیاگَکالے سْوَیَں نِحسَنْتانَح سَنْ تاں سْتْرِیَں سْوَبھْراتَرِ سَمَرْپِتَوانْ، | 25 |
Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, láàrín wa níhìn-ín yìí, ìdílé kan wà tí ó ní arákùnrin méje. Èyí èkínní nínú wọn gbéyàwó, lẹ́yìn náà ó kú ní àìlọ́mọ. Nítorí náà ìyàwó rẹ̀ di ìyàwó arákùnrin kejì.
تَتو دْوِتِییادِسَپْتَمانْتاشْچَ تَتھَیوَ چَکْرُح۔ | 26 |
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ arákùnrin èkejì náà sì tún kú láìlọ́mọ. A sì fi ìyàwó rẹ̀ fún arákùnrin tí ó tún tẹ̀lé e. Bẹ́ẹ̀ sì ni títí tí òun fi di ìyàwó ẹni keje.
شیشے ساپِی نارِی مَمارَ۔ | 27 |
Níkẹyìn obìnrin náà pàápàá sì kú.
مرِتانامْ اُتّھانَسَمَیے تیشاں سَپْتاناں مَدھْیے سا نارِی کَسْیَ بھارْیّا بھَوِشْیَتِ؟ یَسْماتْ سَرْوَّایوَ تاں وْیَوَہَنْ۔ | 28 |
Nítorí tí ó ti ṣe ìyàwó àwọn arákùnrin méjèèje, ìyàwó ta ni yóò jẹ́ ní àjíǹde òkú?”
تَتو یِیشُح پْرَتْیَوادِیتْ، یُویَں دھَرْمَّپُسْتَکَمْ اِیشْوَرِییاں شَکْتِنْچَ نَ وِجْنایَ بھْرانْتِمَنْتَح۔ | 29 |
Ṣùgbọ́n Jesu dá wọn lóhùn pé, “Àìmọ̀kan yín ni ó fa irú ìbéèrè báyìí. Nítorí ẹ̀yin kò mọ Ìwé Mímọ́ àti agbára Ọlọ́run.
اُتّھانَپْراپْتا لوکا نَ وِوَہَنْتِ، نَ چَ واچا دِییَنْتے، کِنْتْوِیشْوَرَسْیَ سْوَرْگَسْتھَدُوتاناں سَدرِشا بھَوَنْتِ۔ | 30 |
Nítorí ní àjíǹde kò ní sí ìgbéyàwó, a kò sì ní fi í fún ni ní ìyàwó. Gbogbo ènìyàn yóò sì dàbí àwọn angẹli ní ọ̀run.
اَپَرَں مرِتانامُتّھانَمَدھِ یُشْمانْ پْرَتِییَمِیشْوَروکْتِح، | 31 |
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nípa ti àjíǹde òkú, tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ pé Ọlọ́run ń bá yín sọ̀rọ̀ nígbà ti ó wí pé:
"اَہَمِبْراہِیمَ اِیشْوَرَ اِسْہاکَ اِیشْوَرو یاکُوبَ اِیشْوَرَ" اِتِ کِں یُشْمابھِ رْناپاٹھِ؟ کِنْتْوِیشْوَرو جِیوَتامْ اِیشْوَرَ: ، سَ مرِتانامِیشْوَرو نَہِ۔ | 32 |
‘Èmi ni Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu.’ Ọlọ́run kì í ṣe Ọlọ́run òkú, ṣùgbọ́n tí àwọn alààyè.”
اِتِ شْرُتْوا سَرْوّے لوکاسْتَسْیوپَدیشادْ وِسْمَیَں گَتاح۔ | 33 |
Nígbà ti àwọn ènìyàn gbọ́ èyí ẹnu yà wọ́n sí ẹ̀kọ́ rẹ.
اَنَنْتَرَں سِدُوکِنامْ نِرُتَّرَتْوَوارْتاں نِشَمْیَ پھِرُوشِنَ ایکَتْرَ مِلِتَوَنْتَح، | 34 |
Nígbà ti wọ́n sì gbọ́ pé ó ti pa àwọn Sadusi lẹ́nu mọ́, àwọn Farisi pé ara wọn jọ.
تیشامیکو وْیَوَسْتھاپَکو یِیشُں پَرِیکْشِتُں پَپَچّھَ، | 35 |
Ọ̀kan nínú wọn tí ṣe amòfin dán an wò pẹ̀lú ìbéèrè yìí.
ہے گُرو وْیَوَسْتھاشاسْتْرَمَدھْیے کاجْنا شْریشْٹھا؟ | 36 |
Ó wí pé, “Olùkọ́ èwo ni ó ga jùlọ nínú àwọn òfin?”
تَتو یِیشُرُواچَ، تْوَں سَرْوّانْتَحکَرَنَیح سَرْوَّپْرانَیح سَرْوَّچِتَّیشْچَ ساکَں پْرَبھَو پَرَمیشْوَرے پْرِییَسْوَ، | 37 |
Jesu dáhùn pé, “‘Fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, gbogbo ẹ̀mí rẹ àti gbogbo inú rẹ.’
ایشا پْرَتھَمَمَہاجْنا۔ تَسْیاح سَدرِشِی دْوِتِییاجْنَیشا، | 38 |
Èyí ni òfin àkọ́kọ́ àti èyí tí ó tóbi jùlọ.
تَوَ سَمِیپَواسِنِ سْواتْمَنِیوَ پْریمَ کُرُ۔ | 39 |
Èkejì tí ó tún dàbí rẹ̀ ní pé, ‘Fẹ́ràn ọmọnìkejì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ.’
اَنَیو رْدْوَیوراجْنَیوح کرِتْسْنَوْیَوَسْتھایا بھَوِشْیَدْوَکْترِگْرَنْتھَسْیَ چَ بھارَسْتِشْٹھَتِ۔ | 40 |
Lórí àwọn òfin méjèèjì yìí ni gbogbo òfin àti àwọn wòlíì rọ̀ mọ́.”
اَنَنْتَرَں پھِرُوشِنامْ ایکَتْرَ سْتھِتِکالے یِیشُسْتانْ پَپْرَچّھَ، | 41 |
Bí àwọn Farisi ti kó ara wọn jọ, Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé,
کھْرِیشْٹَمَدھِ یُشْماکَں کِیدرِگْبودھو جایَتے؟ سَ کَسْیَ سَنْتانَح؟ تَتَسْتے پْرَتْیَوَدَنْ، دایُودَح سَنْتانَح۔ | 42 |
“Kí ni ẹ rò nípa Kristi? Ọmọ ta ni òun ń ṣe?” Wọ́n dáhùn pé, “Ọmọ Dafidi.”
تَدا سَ اُکْتَوانْ، تَرْہِ دایُودْ کَتھَمْ آتْمادھِشْٹھانینَ تَں پْرَبھُں وَدَتِ ؟ | 43 |
Ó sì wí fún wọn pé, “Kí lo dé tí Dafidi, tí ẹ̀mí ń darí, pè é ní ‘Olúwa’? Nítorí ó wí pé,
یَتھا مَمَ پْرَبھُمِدَں واکْیَمَوَدَتْ پَرَمیشْوَرَح۔ تَوارِینْ پادَپِیٹھَں تے یاوَنَّہِ کَرومْیَہَں۔ تاوَتْ کالَں مَدِییے تْوَں دَکْشَپارْشْوَ اُپاوِشَ۔ اَتو یَدِ دایُودْ تَں پْرَبھُں وَدَتِ، رْتِہَ سَ کَتھَں تَسْیَ سَنْتانو بھَوَتِ؟ | 44 |
“‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé, “Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi títí tí èmi yóò fi fi àwọn ọ̀tá rẹ sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ.”’
تَدانِیں تیشاں کوپِ تَدْواکْیَسْیَ کِمَپْیُتَّرَں داتُں ناشَکْنوتْ؛ | 45 |
Ǹjẹ́ bí Dafidi bá pè é ni ‘Olúwa,’ báwo ni òun ṣe lè jẹ́ ọmọ rẹ̀?”
تَدِّنَمارَبھْیَ تَں کِمَپِ واکْیَں پْرَشْٹُں کَسْیاپِ ساہَسو نابھَوَتْ۔ | 46 |
Kò sí ẹnìkan tí ó lè sọ ọ̀rọ̀ kan ni ìdáhùn, kò tún sí ẹni tí ó tún bí i léèrè ohun kan mọ́ láti ọjọ́ náà mọ́.