< mathiH 3 >
1 tadAnoM yohnnAmA majjayitA yihUdIyadeshasya prAntaram upasthAya prachArayan kathayAmAsa,
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Johanu onítẹ̀bọmi wá, ó ń wàásù ní aginjù Judea.
2 manAMsi parAvarttayata, svargIyarAjatvaM samIpamAgatam|
Ó ń wí pé, “Ẹ ronúpìwàdà, nítorí ìjọba ọ̀run kù sí dẹ̀dẹ̀.”
3 parameshasya panthAnaM pariShkuruta sarvvataH| tasya rAjapathAMshchaiva samIkuruta sarvvathA| ityetat prAntare vAkyaM vadataH kasyachid ravaH||
Èyí ni ẹni náà ti wòlíì Isaiah sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ pé, “Ohùn ẹni ti ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ ṣe ojú ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.’”
4 etadvachanaM yishayiyabhaviShyadvAdinA yohanamuddishya bhAShitam| yohano vasanaM mahA NgaromajaM tasya kaTau charmmakaTibandhanaM; sa cha shUkakITAn madhu cha bhuktavAn|
Aṣọ Johanu náà sì jẹ́ ti irun ìbákasẹ, ó sì di àmùrè awọ sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Eṣú àti oyin ìgàn sì ni oúnjẹ rẹ̀.
5 tadAnIM yirUshAlamnagaranivAsinaH sarvve yihUdideshIyA yarddantaTinyA ubhayataTasthAshcha mAnavA bahirAgatya tasya samIpe
Àwọn ènìyàn jáde lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ láti Jerusalẹmu àti gbogbo Judea àti àwọn ènìyàn láti gbogbo ìhà Jordani.
6 svIyaM svIyaM duritam a NgIkR^itya tasyAM yarddani tena majjitA babhUvuH|
Wọ́n ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn, a sì ń bamitiisi wọn ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní odò Jordani.
7 aparaM bahUn phirUshinaH sidUkinashcha manujAn maMktuM svasamIpam AgachChto vilokya sa tAn abhidadhau, re re bhujagavaMshA AgAmInaH kopAt palAyituM yuShmAn kashchetitavAn?
Ṣùgbọ́n nígbà tí ó rí ọ̀pọ̀ àwọn Farisi àti Sadusi tí wọ́n ń wá ṣe ìtẹ̀bọmi, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ọmọ paramọ́lẹ̀! Ta ni ó kìlọ̀ fún yín pé kí ẹ́ sá kúrò nínú ìbínú tí ń bọ̀?
8 manaHparAvarttanasya samuchitaM phalaM phalata|
Ẹ so èso tí ó yẹ fún ìrònúpìwàdà.
9 kintvasmAkaM tAta ibrAhIm astIti sveShu manaHsu chIntayanto mA vyAharata| yato yuShmAn ahaM vadAmi, Ishvara etebhyaH pAShANebhya ibrAhImaH santAnAn utpAdayituM shaknoti|
Kí ẹ má sì ṣe rò nínú ara yin pé, ‘Àwa ní Abrahamu ní baba.’ Èmi wí fún yín, Ọlọ́run lè mu àwọn ọmọ jáde láti inú àwọn òkúta wọ̀nyí wá fún Abrahamu.
10 aparaM pAdapAnAM mUle kuThAra idAnImapi lagan Aste, tasmAd yasmin pAdape uttamaM phalaM na bhavati, sa kR^itto madhye. agniM nikShepsyate|
Nísinsin yìí, a ti fi àáké lè gbòǹgbò igi, àti pé gbogbo igi tí kò bá so èso rere ni a óò ge lulẹ̀ ti a ó sì wọ jù sínú iná.
11 aparam ahaM manaHparAvarttanasUchakena majjanena yuShmAn majjayAmIti satyaM, kintu mama pashchAd ya AgachChati, sa mattopi mahAn, ahaM tadIyopAnahau voDhumapi nahi yogyosmi, sa yuShmAn vahnirUpe pavitra Atmani saMmajjayiShyati|
“Èmi fi omi bamitiisi yín fún ìrònúpìwàdà. Ṣùgbọ́n lẹ́yìn mi ẹnìkan tí ó pọ̀jù mí lọ ń bọ̀, bàtà ẹni tí èmi kò tó gbé. Òun ni yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ àti iná bamitiisi yín.
12 tasya kAre sUrpa Aste, sa svIyashasyAni samyak prasphoTya nijAn sakalagodhUmAn saMgR^ihya bhANDAgAre sthApayiShyati, kiMntu sarvvANi vuShANyanirvvANavahninA dAhayiShyati|
Ẹni ti àmúga ìpakà rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀, yóò gbá ilẹ̀ ìpakà rẹ̀, yóò kó alikama rẹ̀ sínú àká, ṣùgbọ́n ìyàngbò ni yóò fi iná àjóòkú sun.”
13 anantaraM yIshu ryohanA majjito bhavituM gAlIlpradeshAd yarddani tasya samIpam AjagAma|
Nígbà náà ni Jesu ti Galili wá sí odò Jordani kí Johanu bá à lè ṣe ìtẹ̀bọmi fún un.
14 kintu yohan taM niShidhya babhAShe, tvaM kiM mama samIpam AgachChasi? varaM tvayA majjanaM mama prayojanam Aste|
Ṣùgbọ́n Johanu kò fẹ́ ṣe ìtẹ̀bọmi fún un, ó wí pé, “Ìwọ ni ìbá bamitiisi fún mi, ìwọ sì tọ̀ mí wá?”
15 tadAnIM yIshuH pratyavochat; IdAnIm anumanyasva, yata itthaM sarvvadharmmasAdhanam asmAkaM karttavyaM, tataH so. anvamanyata|
Jesu sì dáhùn pé, “Jọ̀wọ́ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ náà, nítorí bẹ́ẹ̀ ni ó yẹ fún wa láti mú gbogbo òdodo ṣẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni Johanu gbà, ó sì ṣe ìtẹ̀bọmi fún un.
16 anantaraM yIshurammasi majjituH san tatkShaNAt toyamadhyAd utthAya jagAma, tadA jImUtadvAre mukte jAte, sa IshvarasyAtmAnaM kapotavad avaruhya svoparyyAgachChantaM vIkShA nchakre|
Bí ó si tí ṣe ìtẹ̀bọmi fún Jesu tán, Ó jáde láti inú omi. Ní àkókò náà ọ̀run ṣí sílẹ̀ fún un, Ó sì rí Ẹ̀mí Ọlọ́run ń sọ̀kalẹ̀ bí àdàbà, ó sì bà lé e.
17 aparam eSha mama priyaH putra etasminneva mama mahAsantoSha etAdR^ishI vyomajA vAg babhUva|
Ohùn kan láti ọ̀run wá sì wí pé, “Èyí sì ni àyànfẹ́ ọmọ mi, ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”