< prakāśitaṁ 21 >

1 anantaraṁ navīnam ākāśamaṇḍalaṁ navīnā pṛthivī ca mayā dṛṣṭe yataḥ prathamam ākāśamaṇḍalaṁ prathamā pṛthivī ca lopaṁ gate samudro 'pi tataḥ paraṁ na vidyate|
Mo sì rí ọ̀run tuntun kan àti ayé tuntun kan, nítorí pé ọ̀run ti ìṣáájú àti ayé ìṣáájú ti kọjá lọ; Òkun kò sì ṣí mọ́.
2 aparaṁ svargād avarohantī pavitrā nagarī, arthato navīnā yirūśālamapurī mayā dṛṣṭā, sā varāya vibhūṣitā kanyeva susajjitāsīt|
Mo sì rí ìlú mímọ́, Jerusalẹmu tuntun ń ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run, tí a ti múra sílẹ̀ bí ìyàwó tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ fún ọkọ rẹ̀.
3 anantaraṁ svargād eṣa mahāravo mayā śrutaḥ paśyāyaṁ mānavaiḥ sārddham īśvarasyāvāsaḥ, sa taiḥ sārddhaṁ vatsyati te ca tasya prajā bhaviṣyanti, īśvaraśca svayaṁ teṣām īśvaro bhūtvā taiḥ sārddhaṁ sthāsyati|
Mo sì gbọ́ ohùn ńlá kan láti orí ìtẹ́ náà wá, ń wí pé, “Kíyèsi i, àgọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn, òun ó sì máa bá wọn gbé, wọn ó sì máa jẹ́ ènìyàn rẹ̀, àti Ọlọ́run tìkára rẹ̀ yóò wà pẹ̀lú wọn, yóò sì máa jẹ́ Ọlọ́run wọn.
4 teṣāṁ netrebhyaścāśrūṇi sarvvāṇīśvareṇa pramārkṣyante mṛtyurapi puna rna bhaviṣyati śokavilāpakleśā api puna rna bhaviṣyanti, yataḥ prathamāni sarvvāṇi vyatītini|
Ọlọ́run yóò sì nu omijé gbogbo nù kúrò ni ojú wọn; kì yóò sì ṣí ikú mọ́, tàbí ọ̀fọ̀, tàbí ẹkún, bẹ́ẹ̀ ni kí yóò sí ìrora mọ́, nítorí pé ohun àtijọ́ tí kọjá lọ.”
5 aparaṁ siṁhāsanopaviṣṭo jano'vadat paśyāhaṁ sarvvāṇi nūtanīkaromi| punaravadat likha yata imāni vākyāni satyāni viśvāsyāni ca santi|
Ẹni tí ó jókòó lórí ìtẹ́ náà, sì wí pé, “Kíyèsi i, mo sọ ohun gbogbo di ọ̀tun!” Ó sì wí fún mi pé, “Kọ̀wé rẹ̀, nítorí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí òdodo àti òtítọ́ ni wọ́n.”
6 pana rmām avadat samāptaṁ, ahaṁ kaḥ kṣaśca, aham ādirantaśca yaḥ pipāsati tasmā ahaṁ jīvanadāyiprasravaṇasya toyaṁ vināmūlyaṁ dāsyāmi|
Ó sì wí fún mi pé, “Ó parí. Èmi ni Alfa àti Omega, ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti òpin. Èmi ó sì fi omi fún ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ láti inú orísun omi ìyè lọ́fẹ̀ẹ́.
7 yo jayati sa sarvveṣām adhikārī bhaviṣyati, ahañca tasyeśvaro bhaviṣyāmi sa ca mama putro bhaviṣyati|
Ẹni tí ó ba ṣẹ́gun ni yóò jogún nǹkan wọ̀nyí; èmi ó sì máa jẹ́ Ọlọ́run rẹ̀, òun ó sì máa jẹ ọmọ mi.
8 kintu bhītānām aviśvāsināṁ ghṛṇyānāṁ narahantṛṇāṁ veśyāgāmināṁ mohakānāṁ devapūjakānāṁ sarvveṣām anṛtavādināñcāṁśo vahnigandhakajvalitahrade bhaviṣyati, eṣa eva dvitīyo mṛtyuḥ| (Limnē Pyr g3041 g4442)
Ṣùgbọ́n àwọn ojo, àti aláìgbàgbọ́, àti ẹni ìríra, àti apànìyàn, àti àgbèrè, àti oṣó, àti abọ̀rìṣà, àti àwọn èké gbogbo, ni yóò ni ipa tiwọn nínú adágún tí ń fi iná àti sulfuru jó: èyí tí i ṣe ikú kejì.” (Limnē Pyr g3041 g4442)
9 anantaraṁ śeṣasaptadaṇḍaiḥ paripūrṇāḥ sapta kaṁsā yeṣāṁ saptadūtānāṁ kareṣvāsan teṣāmeka āgatya māṁ sambhāṣyāvadat, āgacchāhaṁ tāṁ kanyām arthato meṣaśāvakasya bhāvibhāryyāṁ tvāṁ darśayāmi|
Ọ̀kan nínú àwọn angẹli méje, tí wọ́n ni ago méje, tí ó kún fún ìyọnu méje ìkẹyìn sì wá, ó sì ba mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wá níhìn-ín, èmi ó fi ìyàwó, aya Ọ̀dọ́-àgùntàn hàn ọ́.”
10 tataḥ sa ātmāviṣṭaṁ mām atyuccaṁ mahāparvvatameṁka nītveśvarasya sannidhitaḥ svargād avarohantīṁ yirūśālamākhyāṁ pavitrāṁ nagarīṁ darśitavān|
Ó sì mu mi lọ nínú Ẹ̀mí si òkè ńlá kan tí o sì ga, ó sì fi ìlú náà hàn mi, Jerusalẹmu mímọ́, tí ń ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run,
11 sā īśvarīyapratāpaviśiṣṭā tasyāstejo mahārgharatnavad arthataḥ sūryyakāntamaṇitejastulyaṁ|
tí ó ní ògo Ọlọ́run, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ sì dàbí òkúta iyebíye gidigidi, àní bí òkúta jasperi, ó mọ́ bí kirisitali;
12 tasyāḥ prācīraṁ bṛhad uccañca tatra dvādaśa gopurāṇi santi tadgopuropari dvādaśa svargadūtā vidyante tatra ca dvādaśa nāmānyarthata isrāyelīyānāṁ dvādaśavaṁśānāṁ nāmāni likhitāni|
Ó sì ní odi ńlá àti gíga, ó sì ni ẹnu ibodè méjìlá, àti ní àwọn ẹnu ibodè náà angẹli méjìlá àti orúkọ tí a kọ sára wọn tí i ṣe orúkọ àwọn ẹ̀yà méjìlá tí àwọn ọmọ Israẹli.
13 pūrvvadiśi trīṇi gopurāṇi uttaradiśi trīṇi gopurāṇi dakṣiṇadiṣi trīṇi gopurāṇi paścīmadiśi ca trīṇi gopurāṇi santi|
Ní ìhà ìlà-oòrùn ẹnu ibodè mẹ́ta; ní ìhà àríwá ẹnu ibodè mẹ́ta; ní ìhà gúúsù ẹnu ibodè mẹ́ta; àti ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹnu ibodè mẹ́ta.
14 nagaryyāḥ prācīrasya dvādaśa mūlāni santi tatra meṣāśāvākasya dvādaśapreritānāṁ dvādaśa nāmāni likhitāni|
Odi ìlú náà sì ni ìpìlẹ̀ méjìlá, àti lórí wọn orúkọ àwọn Aposteli méjìlá tí Ọ̀dọ́-Àgùntàn.
15 anaraṁ nagaryyāstadīyagopurāṇāṁ tatprācīrasya ca māpanārthaṁ mayā sambhāṣamāṇasya dūtasya kare svarṇamaya ekaḥ parimāṇadaṇḍa āsīt|
Ẹni tí o sì ń bá mi sọ̀rọ̀ ní ọ̀pá-ìwọ̀n wúrà kan láti fi wọn ìlú náà àti àwọn ẹnu ibodè rẹ̀, àti odi rẹ̀.
16 nagaryyā ākṛtiścaturasrā tasyā dairghyaprasthe same| tataḥ paraṁ sa tega parimāṇadaṇḍena tāṁ nagarīṁ parimitavān tasyāḥ parimāṇaṁ dvādaśasahasranalvāḥ| tasyā dairghyaṁ prastham uccatvañca samānāni|
Ìlú náà sì wà ní ibú mẹ́rin lọ́gbọọgba, gígùn rẹ̀ àti ìbú rẹ̀ sì dọ́gba: ó sì fi ọ̀pá-ìwọ̀n náà wọn ìlú náà wò, ó jẹ ẹgbàá mẹ́fà ibùsọ̀ gígùn rẹ̀ àti ìbú rẹ̀, àti gíga rẹ̀ sì dọ́gba.
17 aparaṁ sa tasyāḥ prācīraṁ parimitavān tasya mānavāsyārthato dūtasya parimāṇānusāratastat catuścatvāriṁśadadhikāśatahastaparimitaṁ |
Ó sì wọn odi rẹ̀ ó jẹ́ ogóje ìgbọ̀nwọ́ lé mẹ́rin, gẹ́gẹ́ bí òsùwọ̀n ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni tí angẹli náà.
18 tasya prācīrasya nirmmitiḥ sūryyakāntamaṇibhi rnagarī ca nirmmalakācatulyena śuddhasuvarṇena nirmmitā|
A sì fi jasperi mọ odi ìlú náà. Ìlú náà sì jẹ́ kìkì wúrà, ó dàbí dígí tí o mọ́ kedere.
19 nagaryyāḥ prācīrasya mūlāni ca sarvvavidhamahārghamaṇibhi rbhūṣitāni| teṣāṁ prathamaṁ bhittimūlaṁ sūryyakāntasya, dvitīyaṁ nīlasya, tṛtīyaṁ tāmramaṇeḥ, caturthaṁ marakatasya,
A fi onírúurú òkúta iyebíye ṣe ìpìlẹ̀ ògiri ìlú náà lọ́ṣọ̀ọ́. Ìpìlẹ̀ èkínní jẹ́ jasperi; èkejì, safiru; ẹ̀kẹta, kalkedoni; ẹ̀kẹrin, emeradi;
20 pañcamaṁ vaidūryyasya, ṣaṣṭhaṁ śoṇaratnasya, saptamaṁ candrakāntasya, aṣṭamaṁ gomedasya, navamaṁ padmarāgasya, daśamaṁ laśūnīyasya, ekādaśaṁ ṣerojasya, dvādaśaṁ marṭīṣmaṇeścāsti|
ẹ̀karùnún, sardoniki; ẹ̀kẹfà, kaneliani; èkeje, krisoliti; ẹ̀kẹjọ, berili; ẹ̀kẹsànán, topasi; ẹ̀kẹwàá, krisoprasu; ẹ̀kọkànlá, jakiniti; èkejìlá, ametisiti.
21 dvādaśagopurāṇi dvādaśamuktābhi rnirmmitāni, ekaikaṁ gopuram ekaikayā muktayā kṛtaṁ nagaryyā mahāmārgaścācchakācavat nirmmalasuvarṇena nirmmitaṁ|
Ẹnu ibodè méjèèjìlá jẹ́ perli méjìlá: olúkúlùkù ẹnu ibodè jẹ́ peali kan; ọ̀nà ìgboro ìlú náà sì jẹ́ kìkì wúrà, ó dàbí dígí dídán.
22 tasyā antara ekamapi mandiraṁ mayā na dṛṣṭaṁ sataḥ sarvvaśaktimān prabhuḥ parameśvaro meṣaśāvakaśca svayaṁ tasya mandiraṁ|
Èmi kò sì ri tẹmpili nínú rẹ̀, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run Olódùmarè ni tẹmpili rẹ̀, àti Ọ̀dọ́-àgùntàn.
23 tasyai nagaryyai dīptidānārthaṁ sūryyācandramasoḥ prayojanaṁ nāsti yata īśvarasya pratāpastāṁ dīpayati meṣaśāvakaśca tasyā jyotirasti|
Ìlú náà kò sì ní oòrùn, tàbí òṣùpá, láti máa tan ìmọ́lẹ̀ sí i, nítorí pé ògo Ọlọ́run ni ó ń tàn ìmọ́lẹ̀ sí i, Ọ̀dọ́-àgùntàn sì ni fìtílà rẹ̀.
24 paritrāṇaprāptalokanivahāśca tasyā āloke gamanāgamane kurvvanti pṛthivyā rājānaśca svakīyaṁ pratāpaṁ gauravañca tanmadhyam ānayanti|
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì máa rìn nípa ìmọ́lẹ̀ rẹ̀, àwọn ọba ayé sì ń mú ògo wọn wá sínú rẹ̀.
25 tasyā dvārāṇi divā kadāpi na rotsyante niśāpi tatra na bhaviṣyati|
A kì yóò sì ṣé àwọn ẹnu ibodè rẹ̀ rárá ní ọ̀sán: nítorí ki yóò si òru níbẹ̀.
26 sarvvajātīnāṁ gauravapratāpau tanmadhyam āneṣyete|
Wọ́n ó sì máa mú ògo àti ọlá àwọn orílẹ̀-èdè wá sínú rẹ̀.
27 parantvapavitraṁ ghṛṇyakṛd anṛtakṛd vā kimapi tanmadhyaṁ na pravekṣyati meṣaśāvakasya jīvanapustake yeṣāṁ nāmāni likhitāni kevalaṁ ta eva pravekṣyanti|
Ohun aláìmọ́ kan ki yóò sì wọ inú rẹ̀ rárá, tàbí ohun tí ń ṣiṣẹ́ ìríra àti èké; bí kò ṣe àwọn tí a kọ sínú ìwé ìyè Ọ̀dọ́-àgùntàn.

< prakāśitaṁ 21 >