< prakāśitaṁ 21 >
1 anantaraṁ navīnam ākāśamaṇḍalaṁ navīnā pṛthivī ca mayā dṛṣṭe yataḥ prathamam ākāśamaṇḍalaṁ prathamā pṛthivī ca lopaṁ gate samudro 'pi tataḥ paraṁ na vidyate|
Mo sì rí ọ̀run tuntun kan àti ayé tuntun kan, nítorí pé ọ̀run ti ìṣáájú àti ayé ìṣáájú ti kọjá lọ; Òkun kò sì ṣí mọ́.
2 aparaṁ svargād avarohantī pavitrā nagarī, arthato navīnā yirūśālamapurī mayā dṛṣṭā, sā varāya vibhūṣitā kanyeva susajjitāsīt|
Mo sì rí ìlú mímọ́, Jerusalẹmu tuntun ń ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run, tí a ti múra sílẹ̀ bí ìyàwó tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ fún ọkọ rẹ̀.
3 anantaraṁ svargād eṣa mahāravo mayā śrutaḥ paśyāyaṁ mānavaiḥ sārddham īśvarasyāvāsaḥ, sa taiḥ sārddhaṁ vatsyati te ca tasya prajā bhaviṣyanti, īśvaraśca svayaṁ teṣām īśvaro bhūtvā taiḥ sārddhaṁ sthāsyati|
Mo sì gbọ́ ohùn ńlá kan láti orí ìtẹ́ náà wá, ń wí pé, “Kíyèsi i, àgọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn, òun ó sì máa bá wọn gbé, wọn ó sì máa jẹ́ ènìyàn rẹ̀, àti Ọlọ́run tìkára rẹ̀ yóò wà pẹ̀lú wọn, yóò sì máa jẹ́ Ọlọ́run wọn.
4 teṣāṁ netrebhyaścāśrūṇi sarvvāṇīśvareṇa pramārkṣyante mṛtyurapi puna rna bhaviṣyati śokavilāpakleśā api puna rna bhaviṣyanti, yataḥ prathamāni sarvvāṇi vyatītini|
Ọlọ́run yóò sì nu omijé gbogbo nù kúrò ni ojú wọn; kì yóò sì ṣí ikú mọ́, tàbí ọ̀fọ̀, tàbí ẹkún, bẹ́ẹ̀ ni kí yóò sí ìrora mọ́, nítorí pé ohun àtijọ́ tí kọjá lọ.”
5 aparaṁ siṁhāsanopaviṣṭo jano'vadat paśyāhaṁ sarvvāṇi nūtanīkaromi| punaravadat likha yata imāni vākyāni satyāni viśvāsyāni ca santi|
Ẹni tí ó jókòó lórí ìtẹ́ náà, sì wí pé, “Kíyèsi i, mo sọ ohun gbogbo di ọ̀tun!” Ó sì wí fún mi pé, “Kọ̀wé rẹ̀, nítorí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí òdodo àti òtítọ́ ni wọ́n.”
6 pana rmām avadat samāptaṁ, ahaṁ kaḥ kṣaśca, aham ādirantaśca yaḥ pipāsati tasmā ahaṁ jīvanadāyiprasravaṇasya toyaṁ vināmūlyaṁ dāsyāmi|
Ó sì wí fún mi pé, “Ó parí. Èmi ni Alfa àti Omega, ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti òpin. Èmi ó sì fi omi fún ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ láti inú orísun omi ìyè lọ́fẹ̀ẹ́.
7 yo jayati sa sarvveṣām adhikārī bhaviṣyati, ahañca tasyeśvaro bhaviṣyāmi sa ca mama putro bhaviṣyati|
Ẹni tí ó ba ṣẹ́gun ni yóò jogún nǹkan wọ̀nyí; èmi ó sì máa jẹ́ Ọlọ́run rẹ̀, òun ó sì máa jẹ ọmọ mi.
8 kintu bhītānām aviśvāsināṁ ghṛṇyānāṁ narahantṛṇāṁ veśyāgāmināṁ mohakānāṁ devapūjakānāṁ sarvveṣām anṛtavādināñcāṁśo vahnigandhakajvalitahrade bhaviṣyati, eṣa eva dvitīyo mṛtyuḥ| (Limnē Pyr )
Ṣùgbọ́n àwọn ojo, àti aláìgbàgbọ́, àti ẹni ìríra, àti apànìyàn, àti àgbèrè, àti oṣó, àti abọ̀rìṣà, àti àwọn èké gbogbo, ni yóò ni ipa tiwọn nínú adágún tí ń fi iná àti sulfuru jó: èyí tí i ṣe ikú kejì.” (Limnē Pyr )
9 anantaraṁ śeṣasaptadaṇḍaiḥ paripūrṇāḥ sapta kaṁsā yeṣāṁ saptadūtānāṁ kareṣvāsan teṣāmeka āgatya māṁ sambhāṣyāvadat, āgacchāhaṁ tāṁ kanyām arthato meṣaśāvakasya bhāvibhāryyāṁ tvāṁ darśayāmi|
Ọ̀kan nínú àwọn angẹli méje, tí wọ́n ni ago méje, tí ó kún fún ìyọnu méje ìkẹyìn sì wá, ó sì ba mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wá níhìn-ín, èmi ó fi ìyàwó, aya Ọ̀dọ́-àgùntàn hàn ọ́.”
10 tataḥ sa ātmāviṣṭaṁ mām atyuccaṁ mahāparvvatameṁka nītveśvarasya sannidhitaḥ svargād avarohantīṁ yirūśālamākhyāṁ pavitrāṁ nagarīṁ darśitavān|
Ó sì mu mi lọ nínú Ẹ̀mí si òkè ńlá kan tí o sì ga, ó sì fi ìlú náà hàn mi, Jerusalẹmu mímọ́, tí ń ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run,
11 sā īśvarīyapratāpaviśiṣṭā tasyāstejo mahārgharatnavad arthataḥ sūryyakāntamaṇitejastulyaṁ|
tí ó ní ògo Ọlọ́run, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ sì dàbí òkúta iyebíye gidigidi, àní bí òkúta jasperi, ó mọ́ bí kirisitali;
12 tasyāḥ prācīraṁ bṛhad uccañca tatra dvādaśa gopurāṇi santi tadgopuropari dvādaśa svargadūtā vidyante tatra ca dvādaśa nāmānyarthata isrāyelīyānāṁ dvādaśavaṁśānāṁ nāmāni likhitāni|
Ó sì ní odi ńlá àti gíga, ó sì ni ẹnu ibodè méjìlá, àti ní àwọn ẹnu ibodè náà angẹli méjìlá àti orúkọ tí a kọ sára wọn tí i ṣe orúkọ àwọn ẹ̀yà méjìlá tí àwọn ọmọ Israẹli.
13 pūrvvadiśi trīṇi gopurāṇi uttaradiśi trīṇi gopurāṇi dakṣiṇadiṣi trīṇi gopurāṇi paścīmadiśi ca trīṇi gopurāṇi santi|
Ní ìhà ìlà-oòrùn ẹnu ibodè mẹ́ta; ní ìhà àríwá ẹnu ibodè mẹ́ta; ní ìhà gúúsù ẹnu ibodè mẹ́ta; àti ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹnu ibodè mẹ́ta.
14 nagaryyāḥ prācīrasya dvādaśa mūlāni santi tatra meṣāśāvākasya dvādaśapreritānāṁ dvādaśa nāmāni likhitāni|
Odi ìlú náà sì ni ìpìlẹ̀ méjìlá, àti lórí wọn orúkọ àwọn Aposteli méjìlá tí Ọ̀dọ́-Àgùntàn.
15 anaraṁ nagaryyāstadīyagopurāṇāṁ tatprācīrasya ca māpanārthaṁ mayā sambhāṣamāṇasya dūtasya kare svarṇamaya ekaḥ parimāṇadaṇḍa āsīt|
Ẹni tí o sì ń bá mi sọ̀rọ̀ ní ọ̀pá-ìwọ̀n wúrà kan láti fi wọn ìlú náà àti àwọn ẹnu ibodè rẹ̀, àti odi rẹ̀.
16 nagaryyā ākṛtiścaturasrā tasyā dairghyaprasthe same| tataḥ paraṁ sa tega parimāṇadaṇḍena tāṁ nagarīṁ parimitavān tasyāḥ parimāṇaṁ dvādaśasahasranalvāḥ| tasyā dairghyaṁ prastham uccatvañca samānāni|
Ìlú náà sì wà ní ibú mẹ́rin lọ́gbọọgba, gígùn rẹ̀ àti ìbú rẹ̀ sì dọ́gba: ó sì fi ọ̀pá-ìwọ̀n náà wọn ìlú náà wò, ó jẹ ẹgbàá mẹ́fà ibùsọ̀ gígùn rẹ̀ àti ìbú rẹ̀, àti gíga rẹ̀ sì dọ́gba.
17 aparaṁ sa tasyāḥ prācīraṁ parimitavān tasya mānavāsyārthato dūtasya parimāṇānusāratastat catuścatvāriṁśadadhikāśatahastaparimitaṁ |
Ó sì wọn odi rẹ̀ ó jẹ́ ogóje ìgbọ̀nwọ́ lé mẹ́rin, gẹ́gẹ́ bí òsùwọ̀n ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni tí angẹli náà.
18 tasya prācīrasya nirmmitiḥ sūryyakāntamaṇibhi rnagarī ca nirmmalakācatulyena śuddhasuvarṇena nirmmitā|
A sì fi jasperi mọ odi ìlú náà. Ìlú náà sì jẹ́ kìkì wúrà, ó dàbí dígí tí o mọ́ kedere.
19 nagaryyāḥ prācīrasya mūlāni ca sarvvavidhamahārghamaṇibhi rbhūṣitāni| teṣāṁ prathamaṁ bhittimūlaṁ sūryyakāntasya, dvitīyaṁ nīlasya, tṛtīyaṁ tāmramaṇeḥ, caturthaṁ marakatasya,
A fi onírúurú òkúta iyebíye ṣe ìpìlẹ̀ ògiri ìlú náà lọ́ṣọ̀ọ́. Ìpìlẹ̀ èkínní jẹ́ jasperi; èkejì, safiru; ẹ̀kẹta, kalkedoni; ẹ̀kẹrin, emeradi;
20 pañcamaṁ vaidūryyasya, ṣaṣṭhaṁ śoṇaratnasya, saptamaṁ candrakāntasya, aṣṭamaṁ gomedasya, navamaṁ padmarāgasya, daśamaṁ laśūnīyasya, ekādaśaṁ ṣerojasya, dvādaśaṁ marṭīṣmaṇeścāsti|
ẹ̀karùnún, sardoniki; ẹ̀kẹfà, kaneliani; èkeje, krisoliti; ẹ̀kẹjọ, berili; ẹ̀kẹsànán, topasi; ẹ̀kẹwàá, krisoprasu; ẹ̀kọkànlá, jakiniti; èkejìlá, ametisiti.
21 dvādaśagopurāṇi dvādaśamuktābhi rnirmmitāni, ekaikaṁ gopuram ekaikayā muktayā kṛtaṁ nagaryyā mahāmārgaścācchakācavat nirmmalasuvarṇena nirmmitaṁ|
Ẹnu ibodè méjèèjìlá jẹ́ perli méjìlá: olúkúlùkù ẹnu ibodè jẹ́ peali kan; ọ̀nà ìgboro ìlú náà sì jẹ́ kìkì wúrà, ó dàbí dígí dídán.
22 tasyā antara ekamapi mandiraṁ mayā na dṛṣṭaṁ sataḥ sarvvaśaktimān prabhuḥ parameśvaro meṣaśāvakaśca svayaṁ tasya mandiraṁ|
Èmi kò sì ri tẹmpili nínú rẹ̀, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run Olódùmarè ni tẹmpili rẹ̀, àti Ọ̀dọ́-àgùntàn.
23 tasyai nagaryyai dīptidānārthaṁ sūryyācandramasoḥ prayojanaṁ nāsti yata īśvarasya pratāpastāṁ dīpayati meṣaśāvakaśca tasyā jyotirasti|
Ìlú náà kò sì ní oòrùn, tàbí òṣùpá, láti máa tan ìmọ́lẹ̀ sí i, nítorí pé ògo Ọlọ́run ni ó ń tàn ìmọ́lẹ̀ sí i, Ọ̀dọ́-àgùntàn sì ni fìtílà rẹ̀.
24 paritrāṇaprāptalokanivahāśca tasyā āloke gamanāgamane kurvvanti pṛthivyā rājānaśca svakīyaṁ pratāpaṁ gauravañca tanmadhyam ānayanti|
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì máa rìn nípa ìmọ́lẹ̀ rẹ̀, àwọn ọba ayé sì ń mú ògo wọn wá sínú rẹ̀.
25 tasyā dvārāṇi divā kadāpi na rotsyante niśāpi tatra na bhaviṣyati|
A kì yóò sì ṣé àwọn ẹnu ibodè rẹ̀ rárá ní ọ̀sán: nítorí ki yóò si òru níbẹ̀.
26 sarvvajātīnāṁ gauravapratāpau tanmadhyam āneṣyete|
Wọ́n ó sì máa mú ògo àti ọlá àwọn orílẹ̀-èdè wá sínú rẹ̀.
27 parantvapavitraṁ ghṛṇyakṛd anṛtakṛd vā kimapi tanmadhyaṁ na pravekṣyati meṣaśāvakasya jīvanapustake yeṣāṁ nāmāni likhitāni kevalaṁ ta eva pravekṣyanti|
Ohun aláìmọ́ kan ki yóò sì wọ inú rẹ̀ rárá, tàbí ohun tí ń ṣiṣẹ́ ìríra àti èké; bí kò ṣe àwọn tí a kọ sínú ìwé ìyè Ọ̀dọ́-àgùntàn.