< mathiḥ 26 >

1 yīśuretān prastāvān samāpya śiṣyānūce,
Nígbà tí Jesu ti parí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó wí fún wọn pé,
2 yuṣmābhi rjñātaṁ dinadvayāt paraṁ nistāramaha upasthāsyati, tatra manujasutaḥ kruśena hantuṁ parakareṣu samarpiṣyate|
“Bí ẹ̀yin tí mọ̀ ní ọjọ́ méjì sí i, àjọ ìrékọjá yóò bẹ̀rẹ̀. Àti pé, a ó fi Ọmọ Ènìyàn lé wọn lọ́wọ́, a ó sì kàn mí mọ́ àgbélébùú.”
3 tataḥ paraṁ pradhānayājakādhyāpakaprāñcaḥ kiyaphānāmno mahāyājakasyāṭṭālikāyāṁ militvā
Ní àsìkò tí Jesu ń sọ̀rọ̀ yìí, àwọn olórí àlùfáà àti àwọn àgbàgbà kó ara wọn jọ ní ààfin olórí àlùfáà náà tí à ń pè ní Kaiafa.
4 kenopāyena yīśuṁ dhṛtvā hantuṁ śaknuyuriti mantrayāñcakruḥ|
Láti gbèrò àwọn ọ̀nà tí wọ́n yóò fi mú Jesu pẹ̀lú ẹ̀tàn, kí wọn sì pa á.
5 kintu tairuktaṁ mahakāle na dharttavyaḥ, dhṛte prajānāṁ kalahena bhavituṁ śakyate|
Ṣùgbọ́n wọ́n fohùn ṣọ̀kan pé, “Kì í ṣe lásìkò àsè àjọ ìrékọjá, nítorí rògbòdìyàn yóò ṣẹlẹ̀.”
6 tato baithaniyāpure śimonākhyasya kuṣṭhino veśmani yīśau tiṣṭhati
Nígbà tí Jesu wà ní Betani ní ilé ọkùnrin tí à ń pè ní Simoni adẹ́tẹ̀.
7 kācana yoṣā śvetopalabhājanena mahārghyaṁ sugandhi tailamānīya bhojanāyopaviśatastasya śirobhyaṣecat|
Bí ó ti ń jẹun, obìnrin kan wá sọ́dọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú alabasita òróró ìkunra iyebíye, ó sì dà á sí i lórí.
8 kintu tadālokya tacchiṣyaiḥ kupitairuktaṁ, kuta itthamapavyayate?
Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rí i, inú bí wọn. Wọ́n wí pé, “Irú ìfowóṣòfò wo ni èyí?
9 cedidaṁ vyakreṣyata, tarhi bhūrimūlyaṁ prāpya daridrebhyo vyatāriṣyata|
Èéha ti ṣe, obìnrin yìí ìbá tà á ní owó púpọ̀, kí a sì fi owó náà fún àwọn aláìní.”
10 yīśunā tadavagatya te samuditāḥ, yoṣāmenāṁ kuto duḥkhinīṁ kurutha, sā māṁ prati sādhu karmmākārṣīt|
Jesu ti mọ èrò ọkàn wọn, ó wí pé, “Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń dá obìnrin yìí lẹ́bi? Ó ṣe ohun tí ó dára fún mi.
11 yuṣmākamaṁ samīpe daridrāḥ satatamevāsate, kintu yuṣmākamantikehaṁ nāse satataṁ|
Ẹ̀yin yóò ní àwọn aláìní láàrín yín nígbà gbogbo, ṣùgbọ́n, ẹ̀yin kò le rí mi nígbà gbogbo.
12 sā mama kāyopari sugandhitailaṁ siktvā mama śmaśānadānakarmmākārṣīt|
Nípa dída òróró ìkunra yìí sí mi lára, òun ń ṣe èyí fún ìsìnkú mi ni.
13 atohaṁ yuṣmān tathyaṁ vadāmi sarvvasmin jagati yatra yatraiṣa susamācāraḥ pracāriṣyate, tatra tatraitasyā nāryyāḥ smaraṇārtham karmmedaṁ pracāriṣyate|
Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, a ó sì máa ṣe ìrántí rẹ̀ nígbà gbogbo fún ìṣesí rẹ̀ yìí. Níbikíbi tí a bá ti wàásù ìyìnrere yìí ní gbogbo àgbáyé ni a ó ti sọ ìtàn ohun tí obìnrin yìí ṣe.”
14 tato dvādaśaśiṣyāṇām īṣkariyotīyayihūdānāmaka ekaḥ śiṣyaḥ pradhānayājakānāmantikaṁ gatvā kathitavān,
Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn aposteli méjìlá ti à ń pè ní Judasi Iskariotu lọ sọ́dọ̀ àwọn olórí àlùfáà.
15 yadi yuṣmākaṁ kareṣu yīśuṁ samarpayāmi, tarhi kiṁ dāsyatha? tadānīṁ te tasmai triṁśanmudrā dātuṁ sthirīkṛtavantaḥ|
Òun sì béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin yóò san fún mi bí mo bá fi Jesu lé yín lọ́wọ́?” Wọ́n sì fún un ní ọgbọ́n owó fàdákà. Ó sì gbà á.
16 sa tadārabhya taṁ parakareṣu samarpayituṁ suyogaṁ ceṣṭitavān|
Láti ìgbà náà lọ ni Judasi ti bẹ̀rẹ̀ sí i wá ọ̀nà láti fà á lé wọn lọ́wọ́.
17 anantaraṁ kiṇvaśūnyapūpaparvvaṇaḥ prathamehni śiṣyā yīśum upagatya papracchuḥ bhavatkṛte kutra vayaṁ nistāramahabhojyam āyojayiṣyāmaḥ? bhavataḥ kecchā?
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní àjọ àìwúkàrà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn tọ Jesu wá pé, “Níbo ni ìwọ fẹ́ kí a pèsè sílẹ̀ láti jẹ àsè ìrékọjá?”
18 tadā sa gaditavān, madhyenagaramamukapuṁsaḥ samīpaṁ vrajitvā vadata, guru rgaditavān, matkālaḥ savidhaḥ, saha śiṣyaistvadālaye nistāramahabhojyaṁ bhokṣye|
Jesu sì dáhùn pé, “Ẹ wọ ìlú lọ, ẹ̀yin yóò rí ọkùnrin kan, ẹ wí fún un pé, ‘Olùkọ́ wa wí pé, àkókò mi ti dé. Èmi yóò sì jẹ àsè ìrékọjá pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mi ní ilé rẹ.’”
19 tadā śiṣyā yīśostādṛśanideśānurūpakarmma vidhāya tatra nistāramahabhojyamāsādayāmāsuḥ|
Nítorí náà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn náà ṣe gẹ́gẹ́ bí Jesu ti sọ fún wọn. Wọ́n sì tọ́jú oúnjẹ àsè ti ìrékọjá níbẹ̀.
20 tataḥ sandhyāyāṁ satyāṁ dvādaśabhiḥ śiṣyaiḥ sākaṁ sa nyaviśat|
Ní àṣálẹ́ ọjọ́ kan náà, bí Jesu ti jókòó pẹ̀lú àwọn méjìlá,
21 aparaṁ bhuñjāna uktavān yuṣmān tathyaṁ vadāmi, yuṣmākameko māṁ parakareṣu samarpayiṣyati|
nígbà tí wọ́n sì ń jẹun, ó wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ọ̀kan nínú yín yóò fi mí hàn.”
22 tadā te'tīva duḥkhitā ekaikaśo vaktumārebhire, he prabho, sa kimahaṁ?
Ìbànújẹ́ sì bo ọkàn wọn nígbà tí wọ́n gbọ́ èyí. Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí bi í pé, “Olúwa, èmi ni bí?”
23 tataḥ sa jagāda, mayā sākaṁ yo jano bhojanapātre karaṁ saṁkṣipati, sa eva māṁ parakareṣu samarpayiṣyati|
Jesu dáhùn pé, “Ẹni ti ó bá mi tọwọ́ bọ inú àwo, ni yóò fi mi hàn.
24 manujasutamadhi yādṛśaṁ likhitamāste, tadanurūpā tadgati rbhaviṣyati; kintu yena puṁsā sa parakareṣu samarpayiṣyate, hā hā cet sa nājaniṣyata, tadā tasya kṣemamabhaviṣyat|
Ọmọ Ènìyàn ń lọ bí a ti kọ̀wé nípa rẹ̀: ṣùgbọ́n ègbé ni fún ọkùnrin náà lọ́wọ́ ẹni tí a ó ti fi Ọmọ Ènìyàn hàn! Ìbá kúkú sàn fún ẹni náà, bí a kò bá bí.”
25 tadā yihūdānāmā yo janastaṁ parakareṣu samarpayiṣyati, sa uktavān, he guro, sa kimahaṁ? tataḥ sa pratyuktavān, tvayā satyaṁ gaditam|
Judasi, ẹni tí ó fi í hàn pẹ̀lú béèrè pé, “Rabbi, èmi ni bí?” Jesu sì dá a lóhùn pé, “Ìwọ wí i.”
26 anantaraṁ teṣāmaśanakāle yīśuḥ pūpamādāyeśvarīyaguṇānanūdya bhaṁktvā śiṣyebhyaḥ pradāya jagāda, madvapuḥsvarūpamimaṁ gṛhītvā khādata|
Bí wọ́n ti ń jẹun, Jesu sì mú ìwọ̀n àkàrà kékeré kan, lẹ́yìn tí ó ti gbàdúrà sí i, ó bù ú, Ó fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Ó wí pé, “Gbà, jẹ; nítorí èyí ni ara mi.”
27 paścāt sa kaṁsaṁ gṛhlan īśvarīyaguṇānanūdya tebhyaḥ pradāya kathitavān, sarvvai ryuṣmābhiranena pātavyaṁ,
Bákan náà, ó sì mú ago wáìnì, ó dúpẹ́ fún un, ó sì gbé e fún wọn. Ó wí pé, “Kí gbogbo yín mu nínú rẹ̀.
28 yasmādanekeṣāṁ pāpamarṣaṇāya pātitaṁ yanmannūtnaniyamarūpaśoṇitaṁ tadetat|
Nítorí èyí ni ẹ̀jẹ̀ mi tí májẹ̀mú tuntun, tí a ta sílẹ̀ fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ ọ̀pọ̀ ènìyàn.
29 aparamahaṁ nūtnagostanīrasaṁ na pāsyāmi, tāvat gostanīphalarasaṁ punaḥ kadāpi na pāsyāmi|
Sì kíyèsi àwọn ọ̀rọ̀ mi. Èmi kì yóò tún mu nínú ọtí wáìnì yìí mọ́ títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò mu ún ní tuntun pẹ̀lú yín ní ìjọba Baba mi.”
30 paścāt te gītamekaṁ saṁgīya jaitunākhyagiriṁ gatavantaḥ|
Wọ́n sì kọ orin kan, lẹ́yìn náà wọ́n lọ sórí òkè Olifi.
31 tadānīṁ yīśustānavocat, asyāṁ rajanyāmahaṁ yuṣmākaṁ sarvveṣāṁ vighnarūpo bhaviṣyāmi, yato likhitamāste, "meṣāṇāṁ rakṣako yastaṁ prahariṣyāmyahaṁ tataḥ| meṣāṇāṁ nivaho nūnaṁ pravikīrṇo bhaviṣyati"||
Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Gbogbo yín ni yóò kọsẹ̀ lára mi ní òru òní. Nítorí a ti kọ ọ́ pé: “‘Èmi yóò kọlu olùṣọ́-àgùntàn a ó sì tú agbo àgùntàn náà ká kiri.’
32 kintu śmaśānāt samutthāya yuṣmākamagre'haṁ gālīlaṁ gamiṣyāmi|
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn tí mo bá jí dìde, èmi yóò ṣáájú yín lọ sí Galili.”
33 pitarastaṁ provāca, bhavāṁścet sarvveṣāṁ vighnarūpo bhavati, tathāpi mama na bhaviṣyati|
Peteru sì dá a lóhùn pé, “Bí gbogbo ènìyàn tilẹ̀ kọ̀ ọ́ sílẹ̀, èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀.”
34 tato yīśunā sa uktaḥ, tubhyamahaṁ tathyaṁ kathayāmi, yāminyāmasyāṁ caraṇāyudhasya ravāt pūrvvaṁ tvaṁ māṁ tri rnāṅgīkariṣyasi|
Jesu wí fún un pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún ọ pé, ní òru yìí, kí àkùkọ kí ó tó kọ, ìwọ yóò sẹ́ mi nígbà mẹ́ta.”
35 tataḥ pitara uditavān, yadyapi tvayā samaṁ marttavyaṁ, tathāpi kadāpi tvāṁ na nāṅgīkariṣyāmi; tathaiva sarvve śiṣyāścocuḥ|
Peteru wí fún un pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ láti kú pẹ̀lú, èmi kò jẹ́ sẹ́ ọ.” Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ọmọ-ẹ̀yìn wí.
36 anantaraṁ yīśuḥ śiṣyaiḥ sākaṁ getśimānīnāmakaṁ sthānaṁ prasthāya tebhyaḥ kathitavān, adaḥ sthānaṁ gatvā yāvadahaṁ prārthayiṣye tāvad yūyamatropaviśata|
Nígbà náà ni Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ lọ sí ibi kan ti à ń pè ní ọgbà Getsemane, ó wí fún wọn pé, “Ẹ jókòó níhìn-ín nígbà tí mo bá lọ gbàdúrà lọ́hùn ún ni.”
37 paścāt sa pitaraṁ sivadiyasutau ca saṅginaḥ kṛtvā gatavān, śokākulo'tīva vyathitaśca babhūva|
Ó sì mú Peteru àti àwọn ọmọ Sebede méjèèjì Jakọbu àti Johanu pẹ̀lú rẹ̀, ìrora àti ìbànújẹ́ bẹ̀rẹ̀ sí gba ọkàn rẹ̀.
38 tānavādīcca mṛtiyātaneva matprāṇānāṁ yātanā jāyate, yūyamatra mayā sārddhaṁ jāgṛta|
Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé, “Ọkàn mi gbọgbẹ́ pẹ̀lú ìbànújẹ́ títí dé ojú ikú, ẹ dúró níhìn-ín yìí, kí ẹ máa ṣọ́nà pẹ̀lú mi.”
39 tataḥ sa kiñciddūraṁ gatvādhomukhaḥ patan prārthayāñcakre, he matpitaryadi bhavituṁ śaknoti, tarhi kaṁso'yaṁ matto dūraṁ yātu; kintu madicchāvat na bhavatu, tvadicchāvad bhavatu|
Òun lọ sí iwájú díẹ̀ sí i, ó sì dojúbolẹ̀, ó sì gbàdúrà pé, “Baba mi, bí ó bá ṣe é ṣe, jẹ́ kí a mú ago yìí ré mi lórí kọjá, ṣùgbọ́n ìfẹ́ tìrẹ ni mo fẹ́ kí ó ṣẹ, kì í ṣe ìfẹ́ tèmi.”
40 tataḥ sa śiṣyānupetya tān nidrato nirīkṣya pitarāya kathayāmāsa, yūyaṁ mayā sākaṁ daṇḍamekamapi jāgarituṁ nāśankuta?
Bí ó ti padà sọ́dọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, ó bá wọn, wọ́n ń sùn. Ó kígbe pé, “Peteru, ẹ̀yin kò tilẹ̀ lè bá mi ṣọ́nà fún wákàtí kan?
41 parīkṣāyāṁ na patituṁ jāgṛta prārthayadhvañca; ātmā samudyatosti, kintu vapu rdurbbalaṁ|
Ẹ máa ṣọ́ra, kí ẹ sì máa gbàdúrà kí ẹ̀yin má ba à bọ́ sínú ìdẹwò. Nítorí ẹ̀mí ń fẹ́ nítòótọ́, ṣùgbọ́n ó ṣe àìlera fún ara.”
42 sa dvitīyavāraṁ prārthayāñcakre, he mattāta, na pīte yadi kaṁsamidaṁ matto dūraṁ yātuṁ na śaknoti, tarhi tvadicchāvad bhavatu|
Ó tún fi wọ́n sílẹ̀ nígbà kejì, ó sí gbàdúrà pé, “Baba mi, bí ago yìí kò bá lè ré mi lórí kọjá bí kò ṣe pé mo bá mu ún, ìfẹ́ tìrẹ ni kí a ṣe.”
43 sa punaretya tān nidrato dadarśa, yatasteṣāṁ netrāṇi nidrayā pūrṇānyāsan|
Nígbà tí ó tún padà dé sọ́dọ̀ wọn, Ó rí i pé wọn ń sùn, nítorí ojú wọn kún fún oorun.
44 paścāt sa tān vihāya vrajitvā tṛtīyavāraṁ pūrvvavat kathayan prārthitavān|
Nítorí náà, ó fi wọn sílẹ̀ ó tún padà lọ láti gbàdúrà nígbà kẹta, ó ń wí ohun kan náà.
45 tataḥ śiṣyānupāgatya gaditavān, sāmprataṁ śayānāḥ kiṁ viśrāmyatha? paśyata, samaya upāsthāt, manujasutaḥ pāpināṁ kareṣu samarpyate|
Nígbà náà ni ó tọ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá, ó wí pé, “Àbí ẹ̀yin sì ń sùn síbẹ̀, ti ẹ sì ń sinmi? Wò ó wákàtí náà tí dé ti a ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ lọ́wọ́.
46 uttiṣṭhata, vayaṁ yāmaḥ, yo māṁ parakareṣu masarpayiṣyati, paśyata, sa samīpamāyāti|
Ẹ dìde! Ẹ jẹ́ kí a máa lọ! Ẹ wò ó, ẹni tí yóò fi mi hàn ń bọ̀ wá!”
47 etatkathākathanakāle dvādaśaśiṣyāṇāmeko yihūdānāmako mukhyayājakalokaprācīnaiḥ prahitān asidhāriyaṣṭidhāriṇo manujān gṛhītvā tatsamīpamupatasthau|
Bí ó ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, Judasi, ọ̀kan nínú àwọn méjìlá dé pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn pẹ̀lú idà àti kùmọ̀ lọ́wọ́ wọn, wọ́n ti ọ̀dọ̀ àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà Júù wá.
48 asau parakareṣvarpayitā pūrvvaṁ tān itthaṁ saṅketayāmāsa, yamahaṁ cumbiṣye, so'sau manujaḥ, saeva yuṣmābhi rdhāryyatāṁ|
Ẹni tí ó sì fi í hàn ti fi àmì fún wọn, pé, “Ẹnikẹ́ni tí mo bá fi ẹnu kò ní ẹnu, òun náà ni; ẹ mú un.”
49 tadā sa sapadi yīśumupāgatya he guro, praṇamāmītyuktvā taṁ cucumbe|
Nísinsin yìí, Judasi wá tààrà sọ́dọ̀ Jesu, ó wí pé, “Àlàáfíà, Rabbi!” Ó fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
50 tadā yīśustamuvāca, he mitraṁ kimarthamāgatosi? tadā tairāgatya yīśurākramya daghre|
Jesu wí pé, “Ọ̀rẹ́, kí ni nǹkan tí ìwọ bá wá.” Àwọn ìyókù sì sún síwájú wọ́n sì mú Jesu.
51 tato yīśoḥ saṅgināmekaḥ karaṁ prasāryya koṣādasiṁ bahiṣkṛtya mahāyājakasya dāsamekamāhatya tasya karṇaṁ ciccheda|
Sì wò ó, ọ̀kan nínú àwọn tí ó wà pẹ̀lú Jesu na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fa idà yọ, ó sì sá ọ̀kan tí i ṣe ọmọ ọ̀dọ̀ olórí àlùfáà, ó sì gé e ní etí sọnù.
52 tato yīśustaṁ jagāda, khaḍgaṁ svasthāne nidhehi yato ye ye janā asiṁ dhārayanti, taevāsinā vinaśyanti|
Jesu wí fún un pé, “Fi idà rẹ bọ àkọ̀ nítorí àwọn tí ó ń fi idà pa ni a ó fi idà pa.
53 aparaṁ pitā yathā madantikaṁ svargīyadūtānāṁ dvādaśavāhinīto'dhikaṁ prahiṇuyāt mayā tamuddiśyedānīmeva tathā prārthayituṁ na śakyate, tvayā kimitthaṁ jñāyate?
Ìwọ kò mọ̀ pé èmi lè béèrè lọ́wọ́ Baba mi kí ó fún mi ju légíónì angẹli méjìlá? Òun yóò sì fi wọ́n ránṣẹ́ lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀.
54 tathā satītthaṁ ghaṭiṣyate dharmmapustakasya yadidaṁ vākyaṁ tat kathaṁ sidhyet?
Ṣùgbọ́n bí mo bá ṣe eléyìí ọ̀nà wo ni a ó fi mú Ìwé Mímọ́ ṣẹ, èyí tí ó ti sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nísinsin yìí?”
55 tadānīṁ yīśu rjananivahaṁ jagāda, yūyaṁ khaḍgayaṣṭīn ādāya māṁ kiṁ cauraṁ dharttumāyātāḥ? ahaṁ pratyahaṁ yuṣmābhiḥ sākamupaviśya samupādiśaṁ, tadā māṁ nādharata;
Nígbà náà ni Jesu wí fún ìjọ ènìyàn náà pé, “Ǹjẹ́ èmi ni ẹ kà sí ọ̀daràn ti ẹ múra pẹ̀lú idà àti kùmọ̀ kí ẹ tó lé mú mi? Ẹ rántí pé mo ti wà pẹ̀lú yín, tí mo ń kọ́ yín lójoojúmọ́ nínú tẹmpili, ẹ̀yin kò sì mú mi nígbà náà.
56 kintu bhaviṣyadvādināṁ vākyānāṁ saṁsiddhaye sarvvametadabhūt|tadā sarvve śiṣyāstaṁ vihāya palāyanta|
Ṣùgbọ́n gbogbo wọ̀nyí ń ṣẹlẹ̀ kí ọ̀rọ̀ tí a tì ẹnu àwọn wòlíì sọ, tí a kọ sínú Ìwé Mímọ́ lè ṣẹ.” Nígbà yìí gan an ni gbogbo àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ti kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì sálọ.
57 anantaraṁ te manujā yīśuṁ dhṛtvā yatrādhyāpakaprāñcaḥ pariṣadaṁ kurvvanta upāviśan tatra kiyaphānāmakamahāyājakasyāntikaṁ ninyuḥ|
Àwọn tí ó mú Jesu fà á lọ sí ilé Kaiafa, olórí àlùfáà, níbi ti àwọn olùkọ́ òfin àti gbogbo àwọn àgbàgbà Júù péjọ sí.
58 kintu śeṣe kiṁ bhaviṣyatīti vettuṁ pitaro dūre tatpaścād vrajitvā mahāyājakasyāṭṭālikāṁ praviśya dāsaiḥ sahita upāviśat|
Ṣùgbọ́n Peteru ń tẹ̀lé e lókèèrè. Òun sì wá sí àgbàlá olórí àlùfáà. Ó wọlé, ó sì jókòó pẹ̀lú àwọn olùṣọ́. Ó ń dúró láti ri ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí Jesu.
59 tadānīṁ pradhānayājakaprācīnamantriṇaḥ sarvve yīśuṁ hantuṁ mṛṣāsākṣyam alipsanta,
Nígbà náà ni àwọn olórí àlùfáà àti gbogbo ìgbìmọ̀ Júù ní ilé ẹjọ́ tí ó ga jùlọ ti Júù péjọ síbẹ̀, wọ́n wá àwọn ẹlẹ́rìí tí yóò purọ́ mọ́ Jesu, kí a ba à lè rí ẹjọ́ rò mọ́ ọn lẹ́sẹ̀, eléyìí tí yóò yọrí si ìdájọ́ ikú fún un.
60 kintu na lebhire| anekeṣu mṛṣāsākṣiṣvāgateṣvapi tanna prāpuḥ|
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde, ṣùgbọ́n wọn kò rí ohun kan. Níkẹyìn, àwọn ẹlẹ́rìí méjì dìde.
61 śeṣe dvau mṛṣāsākṣiṇāvāgatya jagadatuḥ, pumānayamakathayat, ahamīśvaramandiraṁ bhaṁktvā dinatrayamadhye tannirmmātuṁ śaknomi|
Wọn wí pé, “Ọkùnrin yìí sọ pé, ‘Èmi lágbára láti wó tẹmpili Ọlọ́run lulẹ̀, èmi yóò sì tún un mọ ní ọjọ́ mẹ́ta.’”
62 tadā mahāyājaka utthāya yīśum avādīt| tvaṁ kimapi na prativadasi? tvāmadhi kimete sākṣyaṁ vadanti?
Nígbà náà ni olórí àlùfáà sì dìde, ó wí fún Jesu pé, “Ẹ̀rí yìí ń kọ́? Ìwọ sọ bẹ́ẹ̀ tàbí ìwọ kò sọ bẹ́ẹ̀?”
63 kintu yīśu rmaunībhūya tasyau| tato mahāyājaka uktavān, tvām amareśvaranāmnā śapayāmi, tvamīśvarasya putro'bhiṣikto bhavasi naveti vada|
Ṣùgbọ́n Jesu dákẹ́ rọ́rọ́. Nígbà náà ni olórí àlùfáà wí fún un pé, “Mo fi ọ́ bú ní orúkọ Ọlọ́run alààyè, kí ó sọ fún wa, bí ìwọ bá í ṣe Kristi Ọmọ Ọlọ́run.”
64 yīśuḥ pratyavadat, tvaṁ satyamuktavān; ahaṁ yuṣmān tathyaṁ vadāmi, itaḥparaṁ manujasutaṁ sarvvaśaktimato dakṣiṇapārśve sthātuṁ gagaṇasthaṁ jaladharānāruhyāyāntaṁ vīkṣadhve|
Jesu sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, ìwọ wí.” Ṣùgbọ́n mo wí fún gbogbo yín. “Ẹ̀yin yóò rí Ọmọ Ènìyàn ti yóò jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún alágbára, tí yóò sì máa bọ̀ wá láti inú ìkùùkuu.”
65 tadā mahāyājako nijavasanaṁ chittvā jagāda, eṣa īśvaraṁ ninditavān, asmākamaparasākṣyeṇa kiṁ prayojanaṁ? paśyata, yūyamevāsyāsyād īśvaranindāṁ śrutavantaḥ,
Nígbà náà ni olórí àlùfáà fa aṣọ òun tìkára rẹ̀ ya. Ó sì kígbe pé, “Ọ̀rọ̀-òdì! Kí ni a tún ń wá ẹlẹ́rìí fún? Gbogbo yín ti gbọ́ ọ̀rọ̀-òdì rẹ̀. Kí ni ìdájọ́ yín?”
66 yuṣmābhiḥ kiṁ vivicyate? te pratyūcuḥ, vadhārho'yaṁ|
Ki ni ẹ ti rò èyí sí. Gbogbo wọn sì kígbe lọ́hùn kan pé, “Ó jẹ̀bi ikú!”
67 tato lokaistadāsye niṣṭhīvitaṁ kecit pratalamāhatya kecicca capeṭamāhatya babhāṣire,
Wọ́n tu itọ́ sí i ní ojú. Wọ́n kàn án lẹ́ṣẹ̀ẹ́. Àwọn ẹlòmíràn sì gbá a lójú.
68 he khrīṣṭa tvāṁ kaścapeṭamāhatavān? iti gaṇayitvā vadāsmān|
Wọ́n wí pé, “Sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún wa! Ìwọ Kristi, ta ni ẹni tí ó ń lù Ọ́?”
69 pitaro bahiraṅgana upaviśati, tadānīmekā dāsī tamupāgatya babhāṣe, tvaṁ gālīlīyayīśoḥ sahacaraekaḥ|
Lákòókò yìí, bí Peteru ti ń jókòó ní àgbàlá, ọmọbìnrin kan sì tọ̀ ọ́ wá, ó ní, “Ìwọ wà pẹ̀lú Jesu ti Galili.”
70 kintu sa sarvveṣāṁ samakṣam anaṅgīkṛtyāvādīt, tvayā yaducyate, tadarthamahaṁ na vedmi|
Ṣùgbọ́n Peteru sẹ̀ ní ojú gbogbo wọn pé, “Èmi kò tilẹ̀ mọ ohun tí ẹ ń sọ nípa rẹ̀.”
71 tadā tasmin bahirdvāraṁ gate 'nyā dāsī taṁ nirīkṣya tatratyajanānavadat, ayamapi nāsaratīyayīśunā sārddham āsīt|
Lẹ́yìn èyí, ní ìta ní ẹnu-ọ̀nà, ọmọbìnrin mìíràn tún rí i, ó sì wí fún àwọn tí ó dúró yíká pé, “Ọkùnrin yìí wà pẹ̀lú Jesu ti Nasareti.”
72 tataḥ sa śapathena punaranaṅgīkṛtya kathitavān, taṁ naraṁ na paricinomi|
Peteru sì tún sẹ́ lẹ́ẹ̀kejì pẹ̀lú ìbúra pé, “Èmi kò tilẹ̀ mọ ọkùnrin náà rárá.”
73 kṣaṇāt paraṁ tiṣṭhanto janā etya pitaram avadan, tvamavaśyaṁ teṣāmeka iti tvaduccāraṇameva dyotayati|
Nígbà tí ó pẹ́ díẹ̀, àwọn ọkùnrin tí ó ń dúró níbi ìran yìí tọ̀ ọ́ wá, wọ́n wí fún Peteru pé, “Lóòótọ́, ìwọ jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn, àwa mọ̀ ọ́n. Èyí sì dá wa lójú nípa àmì ohùn rẹ̀ tí ó ń ti ẹnu rẹ jáde.”
74 kintu so'bhiśapya kathitavān, taṁ janaṁ nāhaṁ paricinomi, tadā sapadi kukkuṭo rurāva|
Peteru sì tún bẹ̀rẹ̀ sí í búra ó sì fi ara rẹ̀ ré wí pé, “Mo ní èmi kò mọ ọkùnrin yìí rárá.” Lójúkan náà àkùkọ sì kọ.
75 kukkuṭaravāt prāk tvaṁ māṁ trirapāhnoṣyase, yaiṣā vāg yīśunāvādi tāṁ pitaraḥ saṁsmṛtya bahiritvā khedād bhṛśaṁ cakranda|
Nígbà náà ni Peteru rántí nǹkan tí Jesu ti sọ pé, “Kí àkùkọ tó ó kọ, ìwọ yóò sẹ́ mi nígbà mẹ́ta.” Òun sì bọ́ sí òde, ó sọkún kíkorò.

< mathiḥ 26 >