< mārkaḥ 1 >

1 īśvaraputrasya yīśukhrīṣṭasya susaṁvādārambhaḥ|
Ìbẹ̀rẹ̀ ìyìnrere nípa Jesu Kristi, Ọmọ Ọlọ́run.
2 bhaviṣyadvādināṁ grantheṣu lipiritthamāste, paśya svakīyadūtantu tavāgre preṣayāmyaham| gatvā tvadīyapanthānaṁ sa hi pariṣkariṣyati|
Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé wòlíì Isaiah pé, “Èmi yóò ran oníṣẹ́ mi síwájú rẹ, Ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe.”
3 "parameśasya panthānaṁ pariṣkuruta sarvvataḥ| tasya rājapathañcaiva samānaṁ kurutādhunā|" ityetat prāntare vākyaṁ vadataḥ kasyacidravaḥ||
“Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ ṣe ojú ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.’”
4 saeva yohan prāntare majjitavān tathā pāpamārjananimittaṁ manovyāvarttakamajjanasya kathāñca pracāritavān|
Johanu dé, ẹni tí ó ń tẹnibọmi ní aginjù, tí ó sì ń wàásù ìtẹ̀bọmi ìrònúpìwàdà fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀.
5 tato yihūdādeśayirūśālamnagaranivāsinaḥ sarvve lokā bahi rbhūtvā tasya samīpamāgatya svāni svāni pāpānyaṅgīkṛtya yarddananadyāṁ tena majjitā babhūvuḥ|
Gbogbo àwọn tí ń gbé ní agbègbè Judea, àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu jáde tọ̀ ọ́ lọ, a sì ti ọwọ́ rẹ̀ tẹ gbogbo wọn bọ omi ni odò Jordani, wọ́n ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
6 asya yohanaḥ paridheyāni kramelakalomajāni, tasya kaṭibandhanaṁ carmmajātam, tasya bhakṣyāṇi ca śūkakīṭā vanyamadhūni cāsan|
Johanu sì wọ aṣọ irun ìbákasẹ. Ó sì di àmùrè awọ mọ́ ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Eṣú àti oyin ìgàn sì ni oúnjẹ rẹ̀.
7 sa pracārayan kathayāñcakre, ahaṁ namrībhūya yasya pādukābandhanaṁ mocayitumapi na yogyosmi, tādṛśo matto gurutara ekaḥ puruṣo matpaścādāgacchati|
Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù wí pé, “Ẹnìkan tí ó tóbi jù mí lọ ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó ẹni tí ń tú.
8 ahaṁ yuṣmān jale majjitavān kintu sa pavitra ātmāni saṁmajjayiṣyati|
Èmi ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi yín, ṣùgbọ́n Òun yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ ṣe ìtẹ̀bọmi yín.”
9 aparañca tasminneva kāle gālīlpradeśasya nāsaradgrāmād yīśurāgatya yohanā yarddananadyāṁ majjito'bhūt|
Ó sì ṣe ní ọjọ́ kan Jesu ti Nasareti ti Galili jáde wá, a sì ti ọwọ́ Johanu ṣe ìtẹ̀bọmi fún ní odò Jordani.
10 sa jalādutthitamātro meghadvāraṁ muktaṁ kapotavat svasyopari avarohantamātmānañca dṛṣṭavān|
Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ tí Jesu ń ti inú omi jáde wá, ó rí ọ̀run tí ó ṣí sílẹ̀, Ẹ̀mí Mímọ́ bí àdàbà sọ̀kalẹ̀ lé e lórí.
11 tvaṁ mama priyaḥ putrastvayyeva mamamahāsantoṣa iyamākāśīyā vāṇī babhūva|
Ohùn kan sì ti ọ̀run wá wí pé, “Ìwọ ni àyànfẹ́ Ọmọ mi, ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
12 tasmin kāle ātmā taṁ prāntaramadhyaṁ nināya|
Lẹ́sẹ̀kan náà, Ẹ̀mí Mímọ́ sì darí Jesu sí ijù,
13 atha sa catvāriṁśaddināni tasmin sthāne vanyapaśubhiḥ saha tiṣṭhan śaitānā parīkṣitaḥ; paścāt svargīyadūtāstaṁ siṣevire|
Ó sì wà ní ogójì ọjọ́ ní aginjù. A sì ti ọwọ́ Satani dán an wò, ó sì wà pẹ̀lú àwọn ẹranko ìgbẹ́. Àwọn angẹli sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún un.
14 anantaraṁ yohani bandhanālaye baddhe sati yīśu rgālīlpradeśamāgatya īśvararājyasya susaṁvādaṁ pracārayan kathayāmāsa,
Lẹ́yìn ìgbà tí ọba Herodu ti fi Johanu sínú ẹ̀wọ̀n tan, Jesu lọ sí Galili, ó ń wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run.
15 kālaḥ sampūrṇa īśvararājyañca samīpamāgataṁ; atoheto ryūyaṁ manāṁsi vyāvarttayadhvaṁ susaṁvāde ca viśvāsita|
Ó sì kéde wí pé, “Àkókò náà dé wàyí, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀. Ẹ yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, kí ẹ sì gba ìyìnrere yìí gbọ́.”
16 tadanantaraṁ sa gālīlīyasamudrasya tīre gacchan śimon tasya bhrātā andriyanāmā ca imau dvau janau matsyadhāriṇau sāgaramadhye jālaṁ prakṣipantau dṛṣṭvā tāvavadat,
Ní ọjọ́ kan, bí Jesu ti ń rìn létí Òkun Galili, Ó rí Simoni àti Anderu arákùnrin rẹ̀, wọ́n ń fi àwọ̀n wọn pẹja torí pé apẹja ni wọ́n.
17 yuvāṁ mama paścādāgacchataṁ, yuvāmahaṁ manuṣyadhāriṇau kariṣyāmi|
Jesu sì ké sí wọn wí pé, “Ẹ máa tọ̀ mí lẹ́yìn. Èmi yóò sì sọ yín di apẹja ènìyàn.”
18 tatastau tatkṣaṇameva jālāni parityajya tasya paścāt jagmatuḥ|
Ní kánkán wọ́n fi àwọ̀n wọn sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ Ọ́ lẹ́yìn.
19 tataḥ paraṁ tatsthānāt kiñcid dūraṁ gatvā sa sivadīputrayākūb tadbhrātṛyohan ca imau naukāyāṁ jālānāṁ jīrṇamuddhārayantau dṛṣṭvā tāvāhūyat|
Bí Ó sì ti rìn síwájú díẹ̀, ní etí Òkun, Ó rí Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu arákùnrin rẹ̀ nínú ọkọ̀, wọ́n ń tún àwọ̀n wọn ṣe.
20 tatastau naukāyāṁ vetanabhugbhiḥ sahitaṁ svapitaraṁ vihāya tatpaścādīyatuḥ|
Ó sì ké sí àwọn náà lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, wọ́n fi Sebede baba wọn sílẹ̀ nínú ọkọ̀ pẹ̀lú àwọn alágbàṣe, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
21 tataḥ paraṁ kapharnāhūmnāmakaṁ nagaramupasthāya sa viśrāmadivase bhajanagrahaṁ praviśya samupadideśa|
Lẹ́yìn náà, Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wọ ìlú Kapernaumu, nígbà tí ó di òwúrọ̀ ọjọ́ ìsinmi, ó lọ sínú Sinagọgu, ó sì ń kọ́ni.
22 tasyopadeśāllokā āścaryyaṁ menire yataḥ sodhyāpakāiva nopadiśan prabhāvavāniva propadideśa|
Ẹnu sì ya ìjọ ènìyàn nítorí ìkọ́ni rẹ̀, nítorí pé ó ń kọ́ni bí ẹni tí ó ní àṣẹ, kì í ṣe bí àwọn olùkọ́ òfin ṣe ń kọ́ àwọn ènìyàn.
23 aparañca tasmin bhajanagṛhe apavitrabhūtena grasta eko mānuṣa āsīt| sa cītśabdaṁ kṛtvā kathayāñcake
Ní àsìkò náà gan an ni ọkùnrin kan tí ó wà nínú Sinagọgu wọn, tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́, bẹ̀rẹ̀ sí í kígbe wí pé,
24 bho nāsaratīya yīśo tvamasmān tyaja, tvayā sahāsmākaṁ kaḥ sambandhaḥ? tvaṁ kimasmān nāśayituṁ samāgataḥ? tvamīśvarasya pavitraloka ityahaṁ jānāmi|
“Kí ni ìwọ ń wá lọ́dọ̀ wa, Jesu ti Nasareti? Ṣé ìwọ wá láti pa wá run ni? Èmí mọ ẹni tí ìwọ í ṣe; Ìwọ ní ẹni Mímọ́ Ọlọ́run!”
25 tadā yīśustaṁ tarjayitvā jagāda tūṣṇīṁ bhava ito bahirbhava ca|
Jesu si bá a wí, ó wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́, kí ó sì jáde kúrò lára rẹ̀.”
26 tataḥ so'pavitrabhūtastaṁ sampīḍya atyucaiścītkṛtya nirjagāma|
Ẹ̀mí àìmọ́ náà sì gbé e ṣánlẹ̀ lógèdèǹgbé, ó ké ní ohùn rara, ó sì jáde kúrò lára ọkùnrin náà.
27 tenaiva sarvve camatkṛtya parasparaṁ kathayāñcakrire, aho kimidaṁ? kīdṛśo'yaṁ navya upadeśaḥ? anena prabhāvenāpavitrabhūteṣvājñāpiteṣu te tadājñānuvarttino bhavanti|
Ẹnu sì ya àwọn ènìyàn, tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi ń sọ láàrín ara wọn ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀. Wọ́n béèrè pẹ̀lú ìgbóná ara, pé, “Kí ni èyí? Irú ẹ̀kọ́ tuntun wo ni èyí? Ó ń fi agbára pàṣẹ fún àwọn ẹ̀mí àìmọ́ pàápàá wọ́n sì gbọ́ tirẹ̀.”
28 tadā tasya yaśo gālīlaścaturdiksthasarvvadeśān vyāpnot|
Ìròyìn nípa rẹ̀ tàn ká gbogbo agbègbè Galili.
29 aparañca te bhajanagṛhād bahi rbhūtvā yākūbyohanbhyāṁ saha śimona āndriyasya ca niveśanaṁ praviviśuḥ|
Nígbà tí wọn sì jáde kúrò nínú Sinagọgu, wọ́n lọ pẹ̀lú Jakọbu àti Johanu sí ilé Simoni àti Anderu.
30 tadā pitarasya śvaśrūrjvarapīḍitā śayyāyāmāsta iti te taṁ jhaṭiti vijñāpayāñcakruḥ|
Ìyá ìyàwó Simoni tí ó dùbúlẹ̀ àìsàn ibà, wọ́n sì sọ fún Jesu nípa rẹ̀.
31 tataḥ sa āgatya tasyā hastaṁ dhṛtvā tāmudasthāpayat; tadaiva tāṁ jvaro'tyākṣīt tataḥ paraṁ sā tān siṣeve|
Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó fà á lọ́wọ́, ó sì gbé e dìde; lójúkan náà ibà náà fi sílẹ̀, ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
32 athāstaṁ gate ravau sandhyākāle sati lokāstatsamīpaṁ sarvvān rogiṇo bhūtadhṛtāṁśca samāninyuḥ|
Nígbà tí ó di àṣálẹ́, tí oòrùn wọ̀, wọ́n gbé gbogbo àwọn aláìsàn àti àwọn tó ni ẹ̀mí àìmọ́ tọ̀ ọ́ wá.
33 sarvve nāgarikā lokā dvāri saṁmilitāśca|
Gbogbo ìlú si péjọ ni ẹnu-ọ̀nà.
34 tataḥ sa nānāvidharogiṇo bahūn manujānarogiṇaścakāra tathā bahūn bhūtān tyājayāñcakāra tān bhūtān kimapi vākyaṁ vaktuṁ niṣiṣedha ca yatohetoste tamajānan|
Jesu sì wo ọ̀pọ̀ tí wọ́n ní onírúurú ààrùn sàn. Bákan náà ni ó lé ọ̀pọ̀ ẹ̀mí àìmọ́ jáde. Ṣùgbọ́n kò sì jẹ́ kí àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà kí ó sọ̀rọ̀, nítorí tí wọ́n mọ ẹni tí òun í ṣe.
35 aparañca so'tipratyūṣe vastutastu rātriśeṣe samutthāya bahirbhūya nirjanaṁ sthānaṁ gatvā tatra prārthayāñcakre|
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ilẹ̀ tó mọ́, Jesu nìkan jáde lọ sí aginjù kan, láti lọ gbàdúrà.
36 anantaraṁ śimon tatsaṅginaśca tasya paścād gatavantaḥ|
Simoni àti àwọn ènìyàn rẹ̀ yòókù lọ láti wá a.
37 taduddeśaṁ prāpya tamavadan sarvve lokāstvāṁ mṛgayante|
Nígbà tí wọ́n sì rí I, wọ́n sọ fún wí pé, “Gbogbo ènìyàn ń wá ọ!”
38 tadā so'kathayat āgacchata vayaṁ samīpasthāni nagarāṇi yāmaḥ, yato'haṁ tatra kathāṁ pracārayituṁ bahirāgamam|
Jesu sì dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sí àwọn ìlú mìíràn, kí ń lè wàásù níbẹ̀ pẹ̀lú. Nítorí èyí ni èmi sá à ṣe wá.”
39 atha sa teṣāṁ gālīlpradeśasya sarvveṣu bhajanagṛheṣu kathāḥ pracārayāñcakre bhūtānatyājayañca|
Nítorí náà, ó ń kiri gbogbo agbègbè Galili, ó ń wàásù nínú Sinagọgu. Ó sì ń lé àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde.
40 anantaramekaḥ kuṣṭhī samāgatya tatsammukhe jānupātaṁ vinayañca kṛtvā kathitavān yadi bhavān icchati tarhi māṁ pariṣkarttuṁ śaknoti|
Ọkùnrin adẹ́tẹ̀ kan tọ̀ ọ́ wá, ó sì kúnlẹ̀ níwájú rẹ̀. Ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ìmúláradá. Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, ìwọ lè mú mi láradá.”
41 tataḥ kṛpālu ryīśuḥ karau prasāryya taṁ spaṣṭvā kathayāmāsa
Jesu kún fún àánú, ó na ọwọ́ rẹ̀, ó fi ọwọ́ rẹ̀ bà a, ó wí pé, “Èmí fẹ́. Di mímọ́.”
42 mamecchā vidyate tvaṁ pariṣkṛto bhava| etatkathāyāḥ kathanamātrāt sa kuṣṭhī rogānmuktaḥ pariṣkṛto'bhavat|
Lójúkan náà ẹ̀tẹ̀ náà fi sílẹ̀ lọ, ọkùnrin náà sì rí ìwòsàn.
43 tadā sa taṁ visṛjan gāḍhamādiśya jagāda
Jesu sì kìlọ̀ fún un gidigidi
44 sāvadhāno bhava kathāmimāṁ kamapi mā vada; svātmānaṁ yājakaṁ darśaya, lokebhyaḥ svapariṣkṛteḥ pramāṇadānāya mūsānirṇītaṁ yaddānaṁ tadutsṛjasva ca|
Ó wí pé, “Lọ fi ara rẹ̀ hàn àlùfáà Júù fún àyẹ̀wò. Ṣùgbọ́n má ṣe dúró sọ ohunkóhun fún ẹnikẹ́ni ní ọ̀nà. Mú ẹ̀bùn lọ́wọ́, èyí tí Mose pàṣẹ fún adẹ́tẹ̀ tí a mú láradá. Èyí tí í ṣe ẹ̀rí pé, ó ti rí ìwòsàn.”
45 kintu sa gatvā tat karmma itthaṁ vistāryya pracārayituṁ prārebhe tenaiva yīśuḥ punaḥ saprakāśaṁ nagaraṁ praveṣṭuṁ nāśaknot tatohetorbahiḥ kānanasthāne tasyau; tathāpi caturddigbhyo lokāstasya samīpamāyayuḥ|
Ṣùgbọ́n ó jáde lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í pòkìkí, ó ń tan ìròyìn kálẹ̀. Nítorí èyí, Jesu kò sì le wọ ìlú ní gbangba mọ́, ṣùgbọ́n ó wà lẹ́yìn odi ìlú ní aginjù. Síbẹ̀, àwọn ènìyàn tọ̀ ọ́ wá láti ibi gbogbo.

< mārkaḥ 1 >