< mārkaḥ 13 >

1 anantaraṁ mandirād bahirgamanakāle tasya śiṣyāṇāmekastaṁ vyāhṛtavān he guro paśyatu kīdṛśāḥ pāṣāṇāḥ kīdṛk ca nicayanaṁ|
Bí Jesu ti ń jáde láti inú tẹmpili ní ọjọ́ náà, ọ̀kan nínú ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sọ fún un pé, “Olùkọ́, wo ilé ńlá tí ó dára wọ̀nyí. Sì wo òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ lára àwọn ògiri ilé náà.”
2 tadā yīśustam avadat tvaṁ kimetad bṛhannicayanaṁ paśyasi? asyaikapāṣāṇopi dvitīyapāṣāṇopari na sthāsyati sarvve 'dhaḥkṣepsyante|
Jesu dáhùn pé, “Ìwọ rí ilé ńlá wọ̀nyí? Kì yóò sí òkúta kan tí a ó fi sílẹ̀ lórí èkejì tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
3 atha yasmin kāle jaitungirau mandirasya sammukhe sa samupaviṣṭastasmin kāle pitaro yākūb yohan āndriyaścaite taṁ rahasi papracchuḥ,
Bí Jesu si ti jókòó lórí òkè olifi tí ó kọjú sí tẹmpili, Peteru, Jakọbu, Johanu àti Anderu wà pẹ̀lú rẹ̀ níbẹ̀, wọ́n bi í léèrè ni ìkọ̀kọ̀ pé,
4 etā ghaṭanāḥ kadā bhaviṣyanti? tathaitatsarvvāsāṁ siddhyupakramasya vā kiṁ cihnaṁ? tadasmabhyaṁ kathayatu bhavān|
“Sọ fún wa, nígbà wo ni nǹkan wọ̀nyí yóò ṣẹlẹ̀ sí tẹmpili náà? Kí ni yóò sì jẹ́ àmì nígbà tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò ṣẹ?”
5 tato yāśustān vaktumārebhe, kopi yathā yuṣmān na bhrāmayati tathātra yūyaṁ sāvadhānā bhavata|
Jesu kìlọ̀ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tàn yín.
6 yataḥ khrīṣṭohamiti kathayitvā mama nāmnāneke samāgatya lokānāṁ bhramaṁ janayiṣyanti;
Nítorí pé ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò wá ní orúkọ mi, wọn yóò wí pé, ‘Èmi ni Kristi,’ wọn yóò tan ọ̀pọ̀ ènìyàn jẹ.
7 kintu yūyaṁ raṇasya vārttāṁ raṇāḍambarañca śrutvā mā vyākulā bhavata, ghaṭanā etā avaśyammāvinyaḥ; kintvāpātato na yugānto bhaviṣyati|
Nígbà tí ẹ̀yin bá ń gbọ́ ìró ogun àti ìdágìrì ogun, kí ẹ̀yin má ṣe jáyà, nítorí irú nǹkan wọ̀nyí kò le ṣe kí ó má ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin náà kì í ṣe ìgbà yìí.
8 deśasya vipakṣatayā deśo rājyasya vipakṣatayā ca rājyamutthāsyati, tathā sthāne sthāne bhūmikampo durbhikṣaṁ mahākleśāśca samupasthāsyanti, sarvva ete duḥkhasyārambhāḥ|
Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba ilẹ̀ yóò máa jì ní ibi púpọ̀. Ìyàn yóò sì wà níbi gbogbo. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni ìbẹ̀rẹ̀ ìpọ́njú tí ń bọ̀ níwájú.
9 kintu yūyam ātmārthe sāvadhānāstiṣṭhata, yato lokā rājasabhāyāṁ yuṣmān samarpayiṣyanti, tathā bhajanagṛhe prahariṣyanti; yūyaṁ madarthe deśādhipān bhūpāṁśca prati sākṣyadānāya teṣāṁ sammukhe upasthāpayiṣyadhve|
“Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn nǹkan wọ̀nyí bá bẹ̀rẹ̀ sí i ṣẹlẹ̀, ẹ kíyèsára! Nítorí ẹ̀yin yóò wà nínú ewu. Wọn yóò fà yín lọ ilé ẹjọ́ gbogbo. Wọn yóò fi ìyà jẹ yín nínú Sinagọgu wọn. Àwọn ènìyàn yóò fẹ̀sùn kàn yín níwájú àwọn baálẹ̀ àti níwájú àwọn ọba nítorí orúkọ mi, fún ẹ̀rí fún wọn.
10 śeṣībhavanāt pūrvvaṁ sarvvān deśīyān prati susaṁvādaḥ pracārayiṣyate|
Nítorí pé ẹ gbọdọ̀ kọ́kọ́ wàásù ìyìnrere náà fún gbogbo orílẹ̀-èdè kí òpin tó dé.
11 kintu yadā te yuṣmān dhṛtvā samarpayiṣyanti tadā yūyaṁ yadyad uttaraṁ dāsyatha, tadagra tasya vivecanaṁ mā kuruta tadarthaṁ kiñcidapi mā cintayata ca, tadānīṁ yuṣmākaṁ manaḥsu yadyad vākyam upasthāpayiṣyate tadeva vadiṣyatha, yato yūyaṁ na tadvaktāraḥ kintu pavitra ātmā tasya vaktā|
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n bá ń fà yín lọ, tí wọ́n bá sì ń fi yín lé wọn lọ́wọ́, ẹ má ṣe ṣàníyàn ṣáájú ohun tí ẹ ó sọ. Ṣùgbọ́n ohun tí bá fi fún yín ní wákàtí náà, òun ni kí ẹ̀yin kí ó wí. Nítorí kì í ṣe ẹ̀yin ni ó ń wí, bí kò ṣe Ẹ̀mí Mímọ́.
12 tadā bhrātā bhrātaraṁ pitā putraṁ ghātanārthaṁ parahasteṣu samarpayiṣyate, tathā patyāni mātāpitro rvipakṣatayā tau ghātayiṣyanti|
“Arákùnrin yóò máa fi ẹ̀sùn kan arákùnrin rẹ̀, tí yóò sì yọrí sí ikú. Baba yóò máa ṣe ikú pa ọmọ rẹ̀. Àwọn ọmọ yóò máa dìtẹ̀ sí òbí wọn. Àní, àwọn ọmọ pẹ̀lú yóò máa ṣe ikú pa òbí wọn.
13 mama nāmahetoḥ sarvveṣāṁ savidhe yūyaṁ jugupsitā bhaviṣyatha, kintu yaḥ kaścit śeṣaparyyantaṁ dhairyyam ālambiṣyate saeva paritrāsyate|
Àwọn ènìyàn yóò kórìíra yín nítorí tí ẹ jẹ́ tèmi. Ṣùgbọ́n ẹni tó bá fi ara da ìyà títí dé òpin tí kò sì kọ̀ mí sílẹ̀ òun ni yóò rí ìgbàlà.
14 dāniyelbhaviṣyadvādinā proktaṁ sarvvanāśi jugupsitañca vastu yadā tvayogyasthāne vidyamānaṁ drakṣatha (yo janaḥ paṭhati sa budhyatāṁ) tadā ye yihūdīyadeśe tiṣṭhanti te mahīdhraṁ prati palāyantāṁ;
“Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìríra ìsọdahoro, tí ó dúró níbí tí kò yẹ (ẹnikẹ́ni tí ó bá kà á kí ó yé e), nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ni Judea sálọ sí orí òkè.
15 tathā yo naro gṛhopari tiṣṭhati sa gṛhamadhyaṁ nāvarohatu, tathā kimapi vastu grahītuṁ madhyegṛhaṁ na praviśatu;
Kí ẹni ti ń bẹ lórí ilé má ṣe sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ilé, bẹ́ẹ̀ ni kí ó má sì ṣe wọ inú rẹ̀, láti mú ohunkóhun jáde nínú ilé rẹ̀.
16 tathā ca yo naraḥ kṣetre tiṣṭhati sopi svavastraṁ grahītuṁ parāvṛtya na vrajatu|
Kí ẹni tí ó wà lóko má ṣe padà sẹ́yìn láti wá mú aṣọ rẹ̀.
17 tadānīṁ garbbhavatīnāṁ stanyadātrīṇāñca yoṣitāṁ durgati rbhaviṣyati|
Ègbé ní fún àwọn tí ó lóyún, àti fún obìnrin tí ń fún ọ́mọ lọ́mú ní ọjọ́ wọ̀nyí.
18 yuṣmākaṁ palāyanaṁ śītakāle yathā na bhavati tadarthaṁ prārthayadhvaṁ|
Kí ẹ sì máa gbàdúrà pé èyí ṣẹlẹ̀ ní àkókò òtútù.
19 yatastadā yādṛśī durghaṭanā ghaṭiṣyate tādṛśī durghaṭanā īśvarasṛṣṭeḥ prathamamārabhyādya yāvat kadāpi na jātā na janiṣyate ca|
Nítorí ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì yóò jẹ́ àkókò ìpọ́njú, irú èyí tí kò ì ṣẹlẹ̀ láti ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀dá Ọlọ́run. Irú rẹ̀ kò sì ni ṣẹlẹ̀ mọ́.
20 aparañca parameśvaro yadi tasya samayasya saṁkṣepaṁ na karoti tarhi kasyāpi prāṇabhṛto rakṣā bhavituṁ na śakṣyati, kintu yān janān manonītān akarot teṣāṁ svamanonītānāṁ hetoḥ sa tadanehasaṁ saṁkṣepsyati|
“Àfi tí Olúwa bá gé àkókò ìjìyà náà kúrú, ẹyọ ẹ̀mí kan ní ayé kì yóò là. Ṣùgbọ́n nítorí àwọn tí Ọlọ́run yàn, ni yóò ṣe dín àwọn ọjọ́ náà kù.
21 anyacca paśyata khrīṣṭotra sthāne vā tatra sthāne vidyate, tasminkāle yadi kaścid yuṣmān etādṛśaṁ vākyaṁ vyāharati, tarhi tasmin vākye bhaiva viśvasita|
Nígbà náà, bí ẹnikẹ́ni bá sọ fún un yín pé, ‘Ẹ wò ó, Kristi wa níbi yìí!’ tàbí, sọ fún un yín pé, ‘Ẹ wò ó, ó wà lọ́hùn ún nì!’ Ẹ má ṣe gbà wọ́n gbọ́.
22 yatoneke mithyākhrīṣṭā mithyābhaviṣyadvādinaśca samupasthāya bahūni cihnānyadbhutāni karmmāṇi ca darśayiṣyanti; tathā yadi sambhavati tarhi manonītalokānāmapi mithyāmatiṁ janayiṣyanti|
Nítorí àwọn èké Kristi àti àwọn wòlíì èké ni yóò wá, wọn yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu tí yóò tan ènìyàn jẹ hàn. Bí ó bá ṣe é ṣe, wọn yóò tan àwọn àyànfẹ́ pàápàá jẹ.
23 paśyata ghaṭanātaḥ pūrvvaṁ sarvvakāryyasya vārttāṁ yuṣmabhyamadām, yūyaṁ sāvadhānāstiṣṭhata|
Nítorí náà, ẹ ṣọ́ra. Mo ti kìlọ̀ fún un yín ṣáájú tó!
24 aparañca tasya kleśakālasyāvyavahite parakāle bhāskaraḥ sāndhakāro bhaviṣyati tathaiva candraścandrikāṁ na dāsyati|
“Ṣùgbọ́n ni ọjọ́ wọ̀nyí lẹ́yìn ìpọ́njú tí mo sọ yìí, “‘oòrùn yóò ṣókùnkùn, òṣùpá kò ní tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀.
25 nabhaḥsthāni nakṣatrāṇi patiṣyanti, vyomamaṇḍalasthā grahāśca vicaliṣyanti|
Àwọn ìràwọ̀ pẹ̀lú yóò já lulẹ̀ láti ojú ọ̀run, àti agbára tí ń bẹ ní ọ̀run ni a ó sì mì tìtì.’
26 tadānīṁ mahāparākrameṇa mahaiśvaryyeṇa ca meghamāruhya samāyāntaṁ mānavasutaṁ mānavāḥ samīkṣiṣyante|
“Nígbà náà ni gbogbo ayé yóò sì rí i tí èmi Ọmọ Ènìyàn yóò máa bọ̀ wá láti inú àwọsánmọ̀ pẹ̀lú agbára àti ògo ńlá.
27 anyacca sa nijadūtān prahitya nabhobhūmyoḥ sīmāṁ yāvad jagataścaturdigbhyaḥ svamanonītalokān saṁgrahīṣyati|
Nígbà náà ni yóò sì rán àwọn angẹli rẹ̀ láti kó àwọn àyànfẹ́ ní gbogbo ayé jọ láti orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé láti ìkangun ayé títí dé ìkangun ọ̀run.
28 uḍumbarataro rdṛṣṭāntaṁ śikṣadhvaṁ yadoḍumbarasya taro rnavīnāḥ śākhā jāyante pallavādīni ca rnigacchanti, tadā nidāghakālaḥ savidho bhavatīti yūyaṁ jñātuṁ śaknutha|
“Nísinsin yìí, ẹ kọ́ òwe lára igi ọ̀pọ̀tọ́, nígbà tí ẹ̀ka rẹ bá ń yọ tuntun, tí ó bá sì ń rú ewé, èyí fihàn pé àkókò ẹ̀rùn ti dé.
29 tadvad etā ghaṭanā dṛṣṭvā sa kālo dvāryyupasthita iti jānīta|
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, nígbà tí ẹ ba ri àwọn ohun wọ̀nyí ti n ṣẹlẹ̀, kí ẹ mọ̀ pé ó súnmọ́ etílé tán, bi ìgbà tí ó wà lẹ́yìn ìlẹ̀kùn.
30 yuṣmānahaṁ yathārthaṁ vadāmi, ādhunikalokānāṁ gamanāt pūrvvaṁ tāni sarvvāṇi ghaṭiṣyante|
Lóòótọ́ ni mo wí fún un yín, ìran yìí kì yóò rékọjá títí a ó fi mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí ṣẹ.
31 dyāvāpṛthivyo rvicalitayoḥ satyo rmadīyā vāṇī na vicaliṣyati|
Ọ̀run àti ayé yóò kọjá lọ, ṣùgbọ́n àwọn ọ̀rọ̀ mi dúró dájú títí ayé àìnípẹ̀kun.
32 aparañca svargasthadūtagaṇo vā putro vā tātādanyaḥ kopi taṁ divasaṁ taṁ daṇḍaṁ vā na jñāpayati|
“Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó mọ ọjọ́ tàbí wákàtí tí nǹkan wọ̀nyí yóò ṣẹlẹ̀. Àwọn angẹli ọ̀run pàápàá kò mọ̀. Àní, èmi pẹ̀lú kò mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe baba nìkan.
33 ataḥ sa samayaḥ kadā bhaviṣyati, etajjñānābhāvād yūyaṁ sāvadhānāstiṣṭhata, satarkāśca bhūtvā prārthayadhvaṁ;
Ẹ máa ṣọ́ra, ẹ dúró wámú, kí ẹ sì máa gbàdúrà, nítorí ẹ̀yin kò mọ ìgbà tí àkókò ná yóò dé.
34 yadvat kaścit pumān svaniveśanād dūradeśaṁ prati yātrākaraṇakāle dāseṣu svakāryyasya bhāramarpayitvā sarvvān sve sve karmmaṇi niyojayati; aparaṁ dauvārikaṁ jāgarituṁ samādiśya yāti, tadvan naraputraḥ|
Ó dà bí ọkùnrin kan tí ó lọ sí ìrìnàjò tí ó jìnnà rere, ẹni tí ó fi ilé rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì fi àṣẹ fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti iṣẹ́ tí ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò ṣe, ó sì fi àṣẹ fún ẹni tó dúró lẹ́nu-ọ̀nà láti máa ṣọ́nà.
35 gṛhapatiḥ sāyaṁkāle niśīthe vā tṛtīyayāme vā prātaḥkāle vā kadāgamiṣyati tad yūyaṁ na jānītha;
“Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ẹ̀yin pẹ̀lú ní láti máa fi ìrètí ṣọ́nà, nítorí pé ẹ kò mọ àkókò tí baálé ilé yóò dé. Bóyá ní ìrọ̀lẹ́ ni o, tàbí ní ọ̀gànjọ́ òru, tàbí nígbà tí àkùkọ máa ń kọ, tàbí ní òwúrọ̀.
36 sa haṭhādāgatya yathā yuṣmān nidritān na paśyati, tadarthaṁ jāgaritāstiṣṭhata|
Àti wí pé nígbà tí ó bá dé lójijì, kó má ṣe bá yín lójú oorun.
37 yuṣmānahaṁ yad vadāmi tadeva sarvvān vadāmi, jāgaritāstiṣṭhateti|
Ohun tí mo wí fún un yín, mo wí fun gbogbo ènìyàn: ‘Ẹ máa ṣọ́nà!’”

< mārkaḥ 13 >