< yohanaḥ 6 >
1 tataḥ paraṁ yīśu rgālīl pradeśīyasya tiviriyānāmnaḥ sindhoḥ pāraṁ gatavān|
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jesu kọjá sí apá kejì Òkun Galili, tí í ṣe Òkun Tiberia.
2 tato vyādhimallokasvāsthyakaraṇarūpāṇi tasyāścaryyāṇi karmmāṇi dṛṣṭvā bahavo janāstatpaścād agacchan|
Ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, nítorí tí wọ́n rí iṣẹ́ àmì rẹ̀ tí ó ń ṣe lára àwọn aláìsàn.
3 tato yīśuḥ parvvatamāruhya tatra śiṣyaiḥ sākam|
Jesu sì gun orí òkè lọ, níbẹ̀ ni ó sì gbé jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
4 tasmin samaya nistārotsavanāmni yihūdīyānāma utsava upasthite
Àjọ ìrékọjá ọdún àwọn Júù sì súnmọ́ etílé.
5 yīśu rnetre uttolya bahulokān svasamīpāgatān vilokya philipaṁ pṛṣṭavān eteṣāṁ bhojanāya bhojadravyāṇi vayaṁ kutra kretuṁ śakrumaḥ?
Ǹjẹ́ bí Jesu ti gbé ojú rẹ̀ sókè, tí ó sì rí ọ̀pọ̀ ènìyàn wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó wí fún Filipi pé, “Níbo ni a ó ti ra àkàrà, kí àwọn wọ̀nyí lè jẹ?”
6 vākyamidaṁ tasya parīkṣārtham avādīt kintu yat kariṣyati tat svayam ajānāt|
Ó sì sọ èyí láti dán an wò; nítorí tí òun fúnra rẹ̀ mọ ohun tí òun ó ṣe.
7 philipaḥ pratyavocat eteṣām ekaiko yadyalpam alpaṁ prāpnoti tarhi mudrāpādadviśatena krītapūpā api nyūnā bhaviṣyanti|
Filipi dá a lóhùn pé, “Àkàrà igba owó idẹ kò lè tó fún wọn, bí olúkúlùkù wọn kò tilẹ̀ ní í rí ju díẹ̀ bù jẹ.”
8 śimon pitarasya bhrātā āndriyākhyaḥ śiṣyāṇāmeko vyāhṛtavān
Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Anderu, arákùnrin Simoni Peteru wí fún un pé,
9 atra kasyacid bālakasya samīpe pañca yāvapūpāḥ kṣudramatsyadvayañca santi kintu lokānāṁ etāvātāṁ madhye taiḥ kiṁ bhaviṣyati?
“Ọmọdékùnrin kan ń bẹ níhìn-ín yìí, tí ó ní ìṣù àkàrà barle márùn-ún àti ẹja wẹ́wẹ́ méjì, ṣùgbọ́n kín ni ìwọ̀nyí jẹ́ láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn wọ̀nyí?”
10 paścād yīśuravadat lokānupaveśayata tatra bahuyavasasattvāt pañcasahastrebhyo nyūnā adhikā vā puruṣā bhūmyām upāviśan|
Jesu sì wí pé, “Ẹ mú kí àwọn ènìyàn náà jókòó!” Koríko púpọ̀ sì wá níbẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin náà jókòó; ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún márùn-ún ènìyàn ní iye.
11 tato yīśustān pūpānādāya īśvarasya guṇān kīrttayitvā śiṣyeṣu samārpayat tataste tebhya upaviṣṭalokebhyaḥ pūpān yatheṣṭamatsyañca prāduḥ|
Jesu sì mú ìṣù àkàrà náà. Nígbà tí ó sì ti dúpẹ́, ó pín wọn fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì pín wọn fún àwọn tí ó jókòó; bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ sì ni ẹja ní ìwọ̀n bí wọ́n ti ń fẹ́.
12 teṣu tṛpteṣu sa tānavocad eteṣāṁ kiñcidapi yathā nāpacīyate tathā sarvvāṇyavaśiṣṭāni saṁgṛhlīta|
Nígbà tí wọ́n sì yó, ó wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ẹ kó àjẹkù tí ó kù jọ, kí ohunkóhun má ṣe ṣòfò.”
13 tataḥ sarvveṣāṁ bhojanāt paraṁ te teṣāṁ pañcānāṁ yāvapūpānāṁ avaśiṣṭānyakhilāni saṁgṛhya dvādaśaḍallakān apūrayan|
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kó wọn jọ wọ́n sì fi àjẹkù ìṣù àkàrà barle márùn-ún náà kún agbọ̀n méjìlá, èyí tí àwọn tí ó jẹun jẹ kù.
14 aparaṁ yīśoretādṛśīm āścaryyakriyāṁ dṛṣṭvā lokā mitho vaktumārebhire jagati yasyāgamanaṁ bhaviṣyati sa evāyam avaśyaṁ bhaviṣyadvakttā|
Nítorí náà nígbà tí àwọn ọkùnrin náà rí iṣẹ́ àmì tí Jesu ṣe, wọ́n wí pé, “Lóòótọ́ èyí ni wòlíì náà tí ń bọ̀ wá sí ayé.”
15 ataeva lokā āgatya tamākramya rājānaṁ kariṣyanti yīśusteṣām īdṛśaṁ mānasaṁ vijñāya punaśca parvvatam ekākī gatavān|
Nígbà tí Jesu sì wòye pé wọ́n ń fẹ́ wá fi agbára mú òun láti lọ fi jẹ ọba, ó tún padà lọ sórí òkè, òun nìkan.
16 sāyaṁkāla upasthite śiṣyā jaladhitaṭaṁ vrajitvā nāvamāruhya nagaradiśi sindhau vāhayitvāgaman|
Nígbà tí alẹ́ sì lẹ́, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun.
17 tasmin samaye timira upātiṣṭhat kintu yīṣusteṣāṁ samīpaṁ nāgacchat|
Wọ́n sì bọ́ sínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n sì rékọjá Òkun lọ sí Kapernaumu. Ilẹ̀ sì ti ṣú, Jesu kò sì tí ì dé ọ̀dọ̀ wọn.
18 tadā prabalapavanavahanāt sāgare mahātaraṅgo bhavitum ārebhe|
Òkun sì ń ru nítorí ẹ̀fúùfù líle tí ń fẹ́.
19 tataste vāhayitvā dvitrān krośān gatāḥ paścād yīśuṁ jaladherupari padbhyāṁ vrajantaṁ naukāntikam āgacchantaṁ vilokya trāsayuktā abhavan
Nígbà tí wọ́n wa ọkọ̀ ojú omi tó bí ìwọ̀n ibùsọ̀ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n tàbí ọgbọ̀n, wọ́n rí Jesu ń rìn lórí Òkun, ó sì súnmọ́ ọkọ̀ ojú omi náà; ẹ̀rù sì bà wọ́n.
20 kintu sa tānukttavān ayamahaṁ mā bhaiṣṭa|
Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Èmi ni; ẹ má bẹ̀rù.”
21 tadā te taṁ svairaṁ nāvi gṛhītavantaḥ tadā tatkṣaṇād uddiṣṭasthāne naurupāsthāt|
Nítorí náà wọ́n fi ayọ̀ gbà á sínú ọkọ̀; lójúkan náà ọkọ̀ náà sì dé ilẹ̀ ibi tí wọ́n ń lọ.
22 yayā nāvā śiṣyā agacchan tadanyā kāpi naukā tasmin sthāne nāsīt tato yīśuḥ śiṣyaiḥ sākaṁ nāgamat kevalāḥ śiṣyā agaman etat pārasthā lokā jñātavantaḥ|
Ní ọjọ́ kejì nígbà tí àwọn ènìyàn tí ó dúró ní òdìkejì Òkun rí i pé, kò sí ọkọ̀ ojú omi mìíràn níbẹ̀, bí kò ṣe ọ̀kan náà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wọ̀, àti pé Jesu kò bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wọ inú ọkọ̀ ojú omi náà, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ nìkan ni ó lọ.
23 kintu tataḥ paraṁ prabhu ryatra īśvarasya guṇān anukīrttya lokān pūpān abhojayat tatsthānasya samīpasthativiriyāyā aparāstaraṇaya āgaman|
Ṣùgbọ́n àwọn ọkọ̀ ojú omi mìíràn ti Tiberia wá, létí ibi tí wọn gbé jẹ àkàrà, lẹ́yìn ìgbà tí Olúwa ti dúpẹ́.
24 yīśustatra nāsti śiṣyā api tatra nā santi lokā iti vijñāya yīśuṁ gaveṣayituṁ taraṇibhiḥ kapharnāhūm puraṁ gatāḥ|
Nítorí náà nígbà tí àwọn ènìyàn rí i pé Jesu tàbí ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kò sí níbẹ̀, àwọn pẹ̀lú wọ ọkọ̀ ojú omi lọ sí Kapernaumu, wọ́n ń wá Jesu.
25 tataste saritpateḥ pāre taṁ sākṣāt prāpya prāvocan he guro bhavān atra sthāne kadāgamat?
Nígbà tí wọ́n sì rí i ní apá kejì Òkun, wọ́n wí fún un pé, “Rabbi, nígbà wo ni ìwọ wá síyìn-ín yìí?”
26 tadā yīśustān pratyavādīd yuṣmānahaṁ yathārthataraṁ vadāmi āścaryyakarmmadarśanāddheto rna kintu pūpabhojanāt tena tṛptatvāñca māṁ gaveṣayatha|
Jesu dá wọn lóhùn ó sì wí pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín. Ẹ̀yin ń wá mi, kì í ṣe nítorí tí ẹ̀yin rí iṣẹ́ àmì, ṣùgbọ́n nítorí ẹ̀yin jẹ àjẹyó ìṣù àkàrà.
27 kṣayaṇīyabhakṣyārthaṁ mā śrāmiṣṭa kintvantāyurbhakṣyārthaṁ śrāmyata, tasmāt tādṛśaṁ bhakṣyaṁ manujaputro yuṣmābhyaṁ dāsyati; tasmin tāta īśvaraḥ pramāṇaṁ prādāt| (aiōnios )
Ẹ má ṣe ṣiṣẹ́ fún oúnjẹ tí ń ṣègbé, ṣùgbọ́n fún oúnjẹ tí ó wà títí di ayé àìnípẹ̀kun, èyí tí Ọmọ Ènìyàn yóò fi fún yín. Nítorí pé òun ni, àní Ọlọ́run Baba ti fi èdìdì dì í.” (aiōnios )
28 tadā te'pṛcchan īśvarābhimataṁ karmma karttum asmābhiḥ kiṁ karttavyaṁ?
Nígbà náà ni wọ́n wí fún wọn pé, “Kín ni àwa ó ha ṣe, kí a lè ṣe iṣẹ́ Ọlọ́run?”
29 tato yīśuravadad īśvaro yaṁ prairayat tasmin viśvasanam īśvarābhimataṁ karmma|
Jesu dáhùn, ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni iṣẹ́ Ọlọ́run pé, kí ẹ̀yin gba ẹni tí ó rán an gbọ́.”
30 tadā te vyāharan bhavatā kiṁ lakṣaṇaṁ darśitaṁ yaddṛṣṭvā bhavati viśvasiṣyāmaḥ? tvayā kiṁ karmma kṛtaṁ?
Nígbà náà ni wọ́n wí fún wọn pé, “Iṣẹ́ àmì kín ní ìwọ ń ṣe, tí àwa lè rí, kí a sì gbà ọ́ gbọ́? Iṣẹ́ kín ní ìwọ ṣe?
31 asmākaṁ pūrvvapuruṣā mahāprāntare mānnāṁ bhokttuṁ prāpuḥ yathā lipirāste| svargīyāṇi tu bhakṣyāṇi pradadau parameśvaraḥ|
Àwọn baba wa jẹ manna ní aginjù; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, ‘Ó fi oúnjẹ láti ọ̀run wá fún wọn jẹ.’”
32 tadā yīśuravadad ahaṁ yuṣmānatiyathārthaṁ vadāmi mūsā yuṣmābhyaṁ svargīyaṁ bhakṣyaṁ nādāt kintu mama pitā yuṣmābhyaṁ svargīyaṁ paramaṁ bhakṣyaṁ dadāti|
Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kì í ṣe Mose ni ó fi oúnjẹ fún yín láti ọ̀run wá, ṣùgbọ́n Baba mi ni ó fi oúnjẹ òtítọ́ náà fún yín láti ọ̀run wá.
33 yaḥ svargādavaruhya jagate jīvanaṁ dadāti sa īśvaradattabhakṣyarūpaḥ|
Nítorí pé oúnjẹ Ọlọ́run ni èyí tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, tí ó sì fi ìyè fún aráyé.”
34 tadā te prāvocan he prabho bhakṣyamidaṁ nityamasmabhyaṁ dadātu|
Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Olúwa, máa fún wa ní oúnjẹ yìí títí láé.”
35 yīśuravadad ahameva jīvanarūpaṁ bhakṣyaṁ yo jano mama sannidhim āgacchati sa jātu kṣudhārtto na bhaviṣyati, tathā yo jano māṁ pratyeti sa jātu tṛṣārtto na bhaviṣyati|
Jesu wí fún wọn pé, “Èmi ni oúnjẹ ìyè, ẹnikẹ́ni tí ó bá tọ̀ mí wá, ebi kì yóò pa á; ẹni tí ó bá sì gbà mí gbọ́, òǹgbẹ kì yóò gbẹ ẹ́ mọ́ láé.
36 māṁ dṛṣṭvāpi yūyaṁ na viśvasitha yuṣmānaham ityavocaṁ|
Ṣùgbọ́n mo wí fún yín pé, Ẹ̀yin ti rí mi, ẹ kò sì gbàgbọ́.
37 pitā mahyaṁ yāvato lokānadadāt te sarvva eva mamāntikam āgamiṣyanti yaḥ kaścicca mama sannidhim āyāsyati taṁ kenāpi prakāreṇa na dūrīkariṣyāmi|
Gbogbo èyí tí Baba fi fún mi, yóò tọ̀ mí wá; ẹni tí ó bá sì tọ̀ mí wá, èmi kì yóò tà á nù, bí ó tí wù kó rí.
38 nijābhimataṁ sādhayituṁ na hi kintu prerayiturabhimataṁ sādhayituṁ svargād āgatosmi|
Nítorí èmi sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá, kì í ṣe láti máa ṣe ìfẹ́ ti èmi fúnra mi, bí kò ṣe ìfẹ́ ti ẹni tí ó rán mi.
39 sa yān yān lokān mahyamadadāt teṣāmekamapi na hārayitvā śeṣadine sarvvānaham utthāpayāmi idaṁ matprerayituḥ piturabhimataṁ|
Èyí sì ni ìfẹ́ Baba tí ó rán mi pé ohun gbogbo tí o fi fún mi, kí èmi má ṣe sọ ọ̀kan nù nínú wọn, ṣùgbọ́n kí èmi lè jí wọn dìde níkẹyìn ọjọ́.
40 yaḥ kaścin mānavasutaṁ vilokya viśvasiti sa śeṣadine mayotthāpitaḥ san anantāyuḥ prāpsyati iti matprerakasyābhimataṁ| (aiōnios )
Èyí sì ni ìfẹ́ ẹni tí ó rán mi, pé ẹnikẹ́ni tí ó bá wo ọmọ, tí ó bá sì gbà á gbọ́, kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun, Èmi ó sì jí i dìde níkẹyìn ọjọ́.” (aiōnios )
41 tadā svargād yad bhakṣyam avārohat tad bhakṣyam ahameva yihūdīyalokāstasyaitad vākye vivadamānā vakttumārebhire
Nígbà náà ni àwọn Júù ń kùn sí i, nítorí tí ó wí pé, “Èmi ni oúnjẹ tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá.”
42 yūṣaphaḥ putro yīśu ryasya mātāpitarau vayaṁ jānīma eṣa kiṁ saeva na? tarhi svargād avāroham iti vākyaṁ kathaṁ vaktti?
Wọ́n sì wí pé, “Jesu ha kọ́ èyí, ọmọ Josẹfu, baba àti ìyá ẹni tí àwa mọ̀? Báwo ni ó ṣe wí pé, ‘Èmi ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá’?”
43 tadā yīśustān pratyavadat parasparaṁ mā vivadadhvaṁ
Nítorí náà Jesu dáhùn, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe kùn láàrín yín!
44 matprerakeṇa pitrā nākṛṣṭaḥ kopi jano mamāntikam āyātuṁ na śaknoti kintvāgataṁ janaṁ carame'hni protthāpayiṣyāmi|
Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè wá sọ́dọ̀ mi, bí kò ṣe pé Baba tí ó rán mi fà á, Èmi ó sì jí i dìde níkẹyìn ọjọ́.
45 te sarvva īśvareṇa śikṣitā bhaviṣyanti bhaviṣyadvādināṁ grantheṣu lipiritthamāste ato yaḥ kaścit pituḥ sakāśāt śrutvā śikṣate sa eva mama samīpam āgamiṣyati|
A sá à ti kọ ọ́ nínú ìwé àwọn wòlíì pé, ‘A ó sì kọ́ gbogbo wọn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá,’ nítorí náà ẹnikẹ́ni tí ó bá ti gbọ́, tí a sì ti ọ̀dọ̀ Baba kọ́, òun ni ó ń tọ̀ mí wá.
46 ya īśvarād ajāyata taṁ vinā kopi manuṣyo janakaṁ nādarśat kevalaḥ saeva tātam adrākṣīt|
Kì í ṣe pé ẹnìkan ti rí Baba bí kò ṣe ẹni tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, òun ni ó ti rí Baba.
47 ahaṁ yuṣmān yathārthataraṁ vadāmi yo jano mayi viśvāsaṁ karoti sonantāyuḥ prāpnoti| (aiōnios )
Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́, ó ní ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios )
48 ahameva tajjīvanabhakṣyaṁ|
Èmi ni oúnjẹ ìyè.
49 yuṣmākaṁ pūrvvapuruṣā mahāprāntare mannābhakṣyaṁ bhūkttāpi mṛtāḥ
Àwọn baba yín jẹ manna ní aginjù, wọ́n sì kú.
50 kintu yadbhakṣyaṁ svargādāgacchat tad yadi kaścid bhuṅktte tarhi sa na mriyate|
Èyí ni oúnjẹ tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, kí ènìyàn lè máa jẹ nínú rẹ̀ kí ó má sì kú.
51 yajjīvanabhakṣyaṁ svargādāgacchat sohameva idaṁ bhakṣyaṁ yo jano bhuṅktte sa nityajīvī bhaviṣyati| punaśca jagato jīvanārthamahaṁ yat svakīyapiśitaṁ dāsyāmi tadeva mayā vitaritaṁ bhakṣyam| (aiōn )
Èmi ni oúnjẹ ìyè náà tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, bí ẹnikẹ́ni bá jẹ nínú oúnjẹ yìí, yóò yè títí láéláé, oúnjẹ náà tí èmi ó sì fi fún ni fún ìyè aráyé ni ara mi.” (aiōn )
52 tasmād yihūdīyāḥ parasparaṁ vivadamānā vakttumārebhire eṣa bhojanārthaṁ svīyaṁ palalaṁ katham asmabhyaṁ dāsyati?
Nítorí náà ni àwọn Júù ṣe ń bá ara wọn jiyàn, pé, “Ọkùnrin yìí yóò ti ṣe lè fi ara rẹ̀ fún wa láti jẹ?”
53 tadā yīśustān āvocad yuṣmānahaṁ yathārthataraṁ vadāmi manuṣyaputrasyāmiṣe yuṣmābhi rna bhuktte tasya rudhire ca na pīte jīvanena sārddhaṁ yuṣmākaṁ sambandho nāsti|
Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin bá jẹ ara Ọmọ Ènìyàn, kí ẹ sì mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, ẹ̀yin kò ní ìyè nínú yin.
54 yo mamāmiṣaṁ svādati mama sudhirañca pivati sonantāyuḥ prāpnoti tataḥ śeṣe'hni tamaham utthāpayiṣyāmi| (aiōnios )
Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ara mi, tí ó bá sì mu ẹ̀jẹ̀ mi, ó ní ìyè tí kò nípẹ̀kun. Èmi o sì jí i dìde níkẹyìn ọjọ́. (aiōnios )
55 yato madīyamāmiṣaṁ paramaṁ bhakṣyaṁ tathā madīyaṁ śoṇitaṁ paramaṁ peyaṁ|
Nítorí ara mi ni ohun jíjẹ nítòótọ́, àti ẹ̀jẹ̀ mi ni ohun mímu nítòótọ́.
56 yo jano madīyaṁ palalaṁ svādati madīyaṁ rudhirañca pivati sa mayi vasati tasminnahañca vasāmi|
Ẹni tí ó bá jẹ ara mi, tí ó bá sì mu ẹ̀jẹ̀ mi, ó ń gbé inú mi, èmi sì ń gbé inú rẹ̀.
57 matprerayitrā jīvatā tātena yathāhaṁ jīvāmi tadvad yaḥ kaścin māmatti sopi mayā jīviṣyati|
Gẹ́gẹ́ bí Baba alààyè ti rán mi, tí èmi sì yè nípa Baba gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó jẹ mí, òun pẹ̀lú yóò yè nípa mi.
58 yadbhakṣyaṁ svargādāgacchat tadidaṁ yanmānnāṁ svāditvā yuṣmākaṁ pitaro'mriyanta tādṛśam idaṁ bhakṣyaṁ na bhavati idaṁ bhakṣyaṁ yo bhakṣati sa nityaṁ jīviṣyati| (aiōn )
Èyí sì ni oúnjẹ náà tí ó sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá, kì í ṣe bí àwọn baba yín ti jẹ manna, tí wọ́n sì kú, ẹni tí ó bá jẹ́ oúnjẹ yìí yóò yè láéláé.” (aiōn )
59 yadā kapharnāhūm puryyāṁ bhajanagehe upādiśat tadā kathā etā akathayat|
Nǹkan wọ̀nyí ni ó sọ nínú Sinagọgu, bí ó ti ń kọ́ni ní Kapernaumu.
60 tadetthaṁ śrutvā tasya śiṣyāṇām aneke parasparam akathayan idaṁ gāḍhaṁ vākyaṁ vākyamīdṛśaṁ kaḥ śrotuṁ śakruyāt?
Nítorí náà nígbà tí ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ gbọ́ èyí, wọ́n wí pé, “Ọ̀rọ̀ tí ó le ni èyí; ta ní lè gbọ́ ọ?”
61 kintu yīśuḥ śiṣyāṇām itthaṁ vivādaṁ svacitte vijñāya kathitavān idaṁ vākyaṁ kiṁ yuṣmākaṁ vighnaṁ janayati?
Nígbà tí Jesu sì mọ̀ nínú ara rẹ̀ pé àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń kùn sí ọ̀rọ̀ náà, ó wí fún wọn pé, “Èyí jẹ́ ìkọ̀sẹ̀ fún yín bí?
62 yadi manujasutaṁ pūrvvavāsasthānam ūrdvvaṁ gacchantaṁ paśyatha tarhi kiṁ bhaviṣyati?
Ǹjẹ́, bí ẹ̀yin bá sì rí i tí Ọmọ Ènìyàn ń gòkè lọ sí ibi tí ó gbé ti wà rí ń kọ́?
63 ātmaiva jīvanadāyakaḥ vapu rniṣphalaṁ yuṣmabhyamahaṁ yāni vacāṁsi kathayāmi tānyātmā jīvanañca|
Ẹ̀mí ní ń sọ ni di ààyè; ara kò ní èrè kan; ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí mo sọ fún yín, ẹ̀mí ni, ìyè sì ni pẹ̀lú.
64 kintu yuṣmākaṁ madhye kecana aviśvāsinaḥ santi ke ke na viśvasanti ko vā taṁ parakareṣu samarpayiṣyati tān yīśurāprathamād vetti|
Ṣùgbọ́n àwọn kan wà nínú yín tí kò gbàgbọ́.” Nítorí Jesu mọ̀ láti ìbẹ̀rẹ̀ wá ẹni tí wọ́n jẹ́ tí kò gbàgbọ́, àti ẹni tí yóò fi òun hàn.
65 aparamapi kathitavān asmāt kāraṇād akathayaṁ pituḥ sakāśāt śakttimaprāpya kopi mamāntikam āgantuṁ na śaknoti|
Ó sì wí pé, “Nítorí náà ni mo ṣe wí fún yín pé, kò sí ẹni tí ó lè tọ̀ mí wá, bí kò ṣe pé a fi fún un láti ọ̀dọ̀ Baba mi wá.”
66 tatkāle'neke śiṣyā vyāghuṭya tena sārddhaṁ puna rnāgacchan|
Nítorí èyí ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ padà sẹ́yìn, wọn kò sì bá a rìn mọ́.
67 tadā yīśu rdvādaśaśiṣyān ukttavān yūyamapi kiṁ yāsyatha?
Nítorí náà Jesu wí fún àwọn méjìlá pé, “Ẹ̀yin pẹ̀lú ń fẹ́ lọ bí?”
68 tataḥ śimon pitaraḥ pratyavocat he prabho kasyābhyarṇaṁ gamiṣyāmaḥ? (aiōnios )
Nígbà náà ni Simoni Peteru dá a lóhùn pé, “Olúwa, ọ̀dọ̀ ta ni àwa ó lọ? Ìwọ ni ó ni ọ̀rọ̀ ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios )
69 anantajīvanadāyinyo yāḥ kathāstāstavaiva| bhavān amareśvarasyābhiṣikttaputra iti viśvasya niścitaṁ jānīmaḥ|
Àwa sì ti gbàgbọ́, a sì mọ̀ pé ìwọ ni Kristi náà, Ọmọ Ọlọ́run alààyè.”
70 tadā yīśuravadat kimahaṁ yuṣmākaṁ dvādaśajanān manonītān na kṛtavān? kintu yuṣmākaṁ madhyepi kaścideko vighnakārī vidyate|
Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin méjìlá kọ́ ni mo yàn, ọ̀kan nínú yín kò ha sì ya èṣù?”
71 imāṁ kathaṁ sa śimonaḥ putram īṣkarīyotīyaṁ yihūdām uddiśya kathitavān yato dvādaśānāṁ madhye gaṇitaḥ sa taṁ parakareṣu samarpayiṣyati|
(Ó ń sọ ti Judasi Iskariotu ọmọ Simoni ọ̀kan nínú àwọn méjìlá, nítorí pé òun ni ẹni tí yóò fi í hàn.)