< Luka 7 >

1 Nawamala onongwa zyakwe zyonti mmakutu gabhantu ahinjiye, hupapernaumu.
Nígbà tí ó sì parí gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀ fun àwọn ènìyàn, ó wọ Kapernaumu lọ.
2 Na obhambhambo wakwe oakida, omo ali bhinu tee alipapepe nefwa, wape alimntu yagene tee.
Ọmọ ọ̀dọ̀ balógun ọ̀rún kan, tí ó ṣọ̀wọ́n fún un, ṣàìsàn, ó sì ń kú lọ.
3 Nahovwezye enongwa ezye Yesu, asonte zyezye agosi abhayahudi, hwamwahale hulabhe aje aponie obhombambombo wakwe.
Nígbà tí ó sì gbúròó Jesu, ó rán àwọn àgbàgbà Júù sí i, ó ń bẹ̀ ẹ́ pé kí ó wá mú ọmọ ọ̀dọ̀ òun láradá.
4 Bhope nabhafishile hwa Yesu, bhalabhile tee bhajile abhajiye, “Ono ombombele anongwa ezi,
Nígbà tí wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Jesu, wọ́n fi ìtara bẹ̀ ẹ́, pé, “Ó yẹ ní ẹni tí òun ìbá ṣe èyí fún.
5 Afanaje aligene itaifa lyetu, wape atizenjeye isinagogi.”
Nítorí tí ó fẹ́ràn orílẹ̀-èdè wa, ó sì ti kọ́ Sinagọgu kan fún wa.”
6 Basi oYesu abhalile pandwemo. Nabho nasagalihutali nenyumba, eyola oakida asontezyezye orafiki hwamwahale wabhola. 'GOSI, ogaje ahwiluvye afwanaje ane sefaa aje ewe oyinjile pansi pigalo lyane.
Jesu sì ń bá wọn lọ. Nígbà tí kò sì jìn sí etí ilé mọ́, balógun ọ̀rún náà rán àwọn ọ̀rẹ́ sí i, pé, “Olúwa, má ṣe yọ ara rẹ lẹ́nu, nítorí tí èmi kò yẹ tí ìwọ ìbá fi wọ abẹ́ òrùlé mi.
7 Eshi ehwilolile aje sefaa nene ahwinze hwaho, lelo panga izu tu obhombambo wane abhapone.
Nítorí náà èmi kò sì rò pé èmi náà yẹ láti tọ̀ ọ́ wá, ṣùgbọ́n sọ ní gbólóhùn kan, a ó sì mú ọmọ ọ̀dọ̀ mi láradá.
8 Afwanaje nane endi muntu nembehwelwe pansi eye ulongozi, endina sikari pansi yane, nkebholele ono bhala abhala na ono “enza” ahwenza, na obhomba mbombo, “Wane” bhomba eshi, abhomba.”
Nítorí èmi náà pẹ̀lú jẹ́ ẹni tí a fi sí abẹ́ àṣẹ, tí ó ní ọmọ-ogun lẹ́yìn mi, mo sì wí fún ọ̀kan pé, ‘Lọ,’ a sì lọ; àti fún òmíràn pé, ‘Wá,’ a sì wá; àti fún ọmọ ọ̀dọ̀ mi pé, ‘Ṣe èyí,’ a sì ṣe é.”
9 OYesu namwovwa ego aswijire, wagugalushila, obngano gwagwabhinjelelaga wanyaga.” Embabhola, hata bha Israeli, sendilolile olyweteho ogosi neshe olu.
Nígbà tí Jesu gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ẹnu sì yà, ó sì yípadà sí ìjọ ènìyàn tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó wí pé, “Mo wí fún yín pé èmi kò rí irú ìgbàgbọ́ ńlá bí èyí nínú àwọn ènìyàn Israẹli.”
10 Na bhala bhabhatumwilyu nabhahwela okhaya bhamwaga ola obhombambombo mwinza.
Nígbà tí àwọn oníṣẹ́ sì padà sí ilé, wọ́n bá ọmọ ọ̀dọ̀ náà tí ń ṣàìsàn, ara rẹ̀ ti dá.
11 Napamande hashe, abhalile hwiboma limo lyakwiwaga Naini. Asambelezye wa bhakwe bhabhenjelezenye nalwo pandwemo no bongona ogosi.
Ní ọjọ́ kejì, ó lọ sí ìlú kan tí a ń pè ní Naini, àwọn púpọ̀ nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì ń bá a lọ àti ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn.
12 Nawafiha apalamile nolwango ogwi boma eye, omntu yafyiye au anyetulwe, na mwana weka hwa nyina wakwe. Yali fwele, na mabungano wabhantu afume hwiboma bhali pandwemo nawo.
Bí ó sì ti súnmọ́ ẹnu ibodè ìlú náà, sì kíyèsi i, wọ́n ń gbé òkú ọkùnrin kan jáde, ọmọ kan ṣoṣo náà tí ìyá rẹ̀ bí, ó sì jẹ́ opó: ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn ìlú náà sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
13 GOSI nawalola aloleye husajile wabhala, “Laha lile.”
Nígbà tí Olúwa sì rí i, àánú rẹ̀ ṣe é, ó sì wí fún un pé, “Má sọkún mọ́.”
14 Wasojela walipalamasya ijeneza bhala bhabanyetuye bhahemeleye, wayanga sahala ehubhala “imelela”
Ó sì wá, ó sì fi ọwọ́ tọ́ pósí náà: àwọn tí ń rù ú dúró jẹ́. Ó sì wí pé, “Ọ̀dọ́mọkùnrin, mo wí fún ọ, dìde!”
15 Ola ofwe wemelela. Wakhala wanda aje wapela onyina wakwe.
Ẹni tí ó kú náà sì dìde jókòó, ó bẹ̀rẹ̀ sí i fọhùn. Ó sì fà á lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́.
16 Owoga wabhakhata wonti. Bhasomba ONGOLOBHE bhayanga okuwa “OGOSI afumiye hwilite” na “ONGOLOBHE abhenyizye abhantu bhakwe”
Ẹ̀rù sì ba gbogbo wọn: wọ́n sì yin Ọlọ́run lógo, pé, “Wòlíì ńlá dìde nínú wa,” àti pé, “Ọlọ́run sì wá bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò!”
17 Enogwa zyakwe ezi zyazyambanile huyudea hwonti na ensi zyonti zyazili mshe mshe.
Òkìkí rẹ̀ sì kàn ní gbogbo Judea, àti gbogbo agbègbè tí ó yí i ká.
18 Asambelezyewa abha Yohana bhaletela enogwa zyego gonti.
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu sì sọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún un.
19 Esho oYohana wabhakwizya bhabhele asombeleziwa bhakwe wabhasondelezya hwa Yesu abhozye “Awe wewe ola yayenza, au timwenyelezyaje owenje?
Nígbà tí Johanu sì pe àwọn méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó rán wọn sọ́dọ̀ Olúwa, wí pé, “Ìwọ ni ẹni tí ń bọ̀, tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?”
20 Wape nabhafiha hwamwahale bhayanjile, “oYohana ya hwozya atisondezyezye hwiliwe aganjile aje awe, 'Wewe ola yahwenza au timwenyelezyaje owenje?”
Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n wí pé, “Johanu onítẹ̀bọmi rán wa sọ́dọ̀ rẹ, pé, ‘Ìwọ ni ẹni tí ń bọ̀, tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?’”
21 Ne sala yeyo abhaponizye abhinji abhinu bhabho na efwa, eye mpepo embibhi, na avipofu abhinji bhalolile.
Ní wákàtí náà, ó sì ṣe ìmúláradá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn nínú àìsàn, àti ààrùn, àti ẹ̀mí búburú; ó sì fi ìríran fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn afọ́jú.
22 Eshi nkawagalula. Wabhabhola, bhalaji mubhale oYohana ega gamgalolilena govwe. avipofu bhalola alema bhajenda, abheukoma bhapona, adinda makutu bhahwovwa, bhabhafwiye bhazyoba, apena bhalombelelwa enongwa enyinza.
Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹ padà lọ, ẹ ròyìn nǹkan tí ẹ̀yin rí, tí ẹ̀yin sì gbọ́ fún Johanu: àwọn afọ́jú ń ríran, àwọn amúnkùn ún rìn, a sọ àwọn adẹ́tẹ̀ di mímọ́, àwọn adití ń gbọ́rọ̀, a ń jí àwọn òkú dìde, àti fún àwọn òtòṣì ni à ń wàásù ìyìnrere.
23 Wape heri omntu yeyonti yasavisiwa nane.”
Alábùkún fún sì ni ẹnikẹ́ni tí kò kọsẹ̀ lára mi.”
24 Basi eshi asontelezewe bha Yohana na bhasogola, ahandile abhabhole amabongono enongwa ezya Yohana, “Mwafumile abhale mwipoli ahwenye yenu, isole wauyiziwa nehala?
Nígbà tí àwọn oníṣẹ́ Johanu padà lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún ìjọ ènìyàn ní ti Johanu pé, “Kí ni ẹ̀yin jáde lọ sí ijù lọ wò? Ewéko tí afẹ́fẹ́ ń mì?
25 Eshi mwafumile abhale ahwenye yenu, omntu yakwatiziwe amenda aminza? mmanye abhantu bhabhali namwenda ageu tukufu bhabhalya raha bhali mnyumba ezye shimwene.
Ṣùgbọ́n kín ni ẹ̀yin jáde lọ wò? Ọkùnrin tí a wọ̀ ní aṣọ fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́? Wò ó, àwọn tí á wọ̀ ní aṣọ ògo, tí wọ́n sì ń jayé, ń bẹ ní ààfin ọba!
26 Eshi mwafumile abhale ahwegegenu okuwa, Antele? Embabhole, na yali zaidi ya okuwa.
Ṣùgbọ́n kí ni ẹ̀yin jáde lọ wò? Wòlíì? Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ó sì ju wòlíì lọ!
27 Oyo yayo asimbiliwa, “Ega, enya ehusontelezya ojumbe wane hwitagalila elye maso gaho, yabhalenganya idala lyaho hwitagalila lyaho,
Èyí yìí ni ẹni tí a ti kọ̀wé nítorí rẹ̀ pé: “‘Wò ó, èmi yóò rán oníṣẹ́ mi síwájú rẹ; ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe níwájú rẹ.’
28 Nane embabhola, neshi bhala bhapepwe na bhashe, nomo yaligosi neshe oYohana, lelo yalidodo humwene owa NGOLOBHE GOSI ashile omwene.”
Mo wí fún yín nínú àwọn tí a bí nínú obìnrin, kò sí wòlíì tí ó pọ̀ ju Johanu Onítẹ̀bọmi lọ, ṣùgbọ́n ẹni tí ó kéré jùlọ ní ìjọba Ọlọ́run, ó pọ̀jù ú lọ.”
29 Abhantu bhonti bhabhasonjezya esonga nabhahovwezye ego bhaheteshe, elyoli ya NGOLOBHE afwanaje bhoziwe. Huwoziwa uYohana.
(Gbogbo àwọn ènìyàn tí ó gbọ́ àti àwọn agbowó òde, wọ́n dá Ọlọ́run láre, nítorí tí a fi ìtẹ̀bọmi Johanu tẹ̀ wọn bọ mi.
30 Lelo abhafarisayo na bhana sheria bhali khene isunde elya NGOLOBHEhwabhene afwanaje sebhohoziwe nomwene.
Ṣùgbọ́n àwọn Farisi àti àwọn amòfin kọ ète Ọlọ́run fún ara wọn, a kò bamitiisi wọn lọ́dọ̀ rẹ̀.)
31 OGOSI wayanga embalenganisye neye abhantu abheshikho eshi? bhape bhalengene neyenu?
Jesu sì wí pé, “Kí ni èmi ìbá fi àwọn ènìyàn ìran yìí wé? Kí ni wọ́n sì jọ?
32 Bhalengene nabhana bhakheye pasokoni, na kwizanye nabhayanga, 'tabhakhomeye efilimbi antele semwahanjile, tazondile antele semwalilile.'
Wọ́n dàbí àwọn ọmọ kékeré tí ó jókòó ní ibi ọjà, tí wọ́n sì ń kọ sí ara wọn, tí wọ́n sì ń wí pé, “‘Àwa fọn fèrè fún yín, ẹ̀yin kò jó, àwa sì ṣọ̀fọ̀ fún yín, ẹ̀yin kò sọkún!’
33 Afwanaje oYohana owahozye ahenzele salya ibumnda wala samwela divai, namwa myanga myiga “Ano pepo obhibhi.
Nítorí Johanu Onítẹ̀bọmi wá, kò jẹ àkàrà, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu ọtí wáìnì, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Ó ní ẹ̀mí èṣù?’
34 Omwana owa Adamu ayenzile alya na mwele, namwe myanga, enye, lyavi ono, na mwezi owe divai, rafiki wabho asonjezya!
Ọmọ ènìyàn dé, ó ń jẹ, ó sì ń mu, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Wò ó, ọ̀jẹun, àti ọ̀mùtí, ọ̀rẹ́ àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀!’
35 Neshinshi ebhoneshe aje elinelyoli hwabhana bhakwe bhonti.”
Ṣùgbọ́n ọgbọ́n ni a dá láre nípasẹ̀ ọmọ rẹ.”
36 Omntu omo owa mafarisayo amwanile alye eshalye hwamwene. Winjila mnyumba yakwe ofarisayo, wakhala pashalye.
Farisi kan sì rọ̀ ọ́ kí ó wá bá òun jẹun, ó sì wọ ilé Farisi náà lọ ó sì jókòó láti jẹun.
37 Enya oshe omo owiboma lila wali wemabhibhi. Nazyoyile enongwa aje akheye pashalye panyumba eyola ofarisayo, aletile insupa marimari yeli nemaruhamu.
Sì kíyèsi i, obìnrin kan wà ní ìlú náà, ẹni tí i ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀, nígbà tí ó mọ̀ pé Jesu jókòó, ó ń jẹun ní ilé Farisi, ó mú ṣágo kékeré alabasita òróró ìkunra wá,
38 Wemelela hwisalo papepe na manama gakwe nawalila. Wanda hulagazizye mmagaga gakwe amansozi gakwe, na syomwole ni sisi elyamwitwe lyakwe, na humyante myante mmagaya gwakwe, na pashe gala amaruhamu.
Ó sì dúró tì í lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀ lẹ́yìn, ó ń sọkún, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí i fi omijé wẹ̀ ẹ́ ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi irun orí rẹ nù ún nù, ó sì ń fi ẹnu kò ó ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi òróró kùn wọ́n.
39 Basi ola ofarisayo yamwanile nawolola shila wanyanga humwoyo gwakwe, omntu ono khashile alikuwe, “Handamenye oshe ono yahupalamasyasya, wenu wape aliwelewele yaje wemabhibhi.
Nígbà tí Farisi tí ó pè é sì rí i, ó wí nínú ara rẹ̀ pé, “Ọkùnrin yìí ìbá ṣe wòlíì, ìbá mọ ẹni àti irú ẹni tí obìnrin yìí jẹ́ tí ń fi ọwọ́ kàn an, nítorí ẹlẹ́ṣẹ̀ ni.”
40 OYesu wagamla wabhozya, “Simoni endine nongwa mbahubhole. “Wayanga” “sambilizi yanga!”
Jesu sì dáhùn, ó wí fún un pé, “Simoni, Mo ní ohun kan sọ fún ọ.” Ó sì dáhùn pé, “Olùkọ́ máa wí.”
41 Wayanga “Omntu omo yakhopezya alinabhe madeni bhabhele, omo adagaya ehela miatano nowabhele amsini.
“Ayánilówó kan wà tí ó ní ajigbèsè méjì: ọ̀kan jẹ ẹ́ ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta owó idẹ, èkejì sì jẹ ẹ́ ní àádọ́ta.
42 Bhape nabhali sebhalinahahuripe, abhasajiye wonti. bhabhele neshe bhabhele yo nanu yayihugana tee?
Nígbà tí wọn kò sì ní ohun tí wọn ó san, ó dáríjì àwọn méjèèjì. Wí nínú àwọn méjèèjì, ta ni yóò fẹ́ ẹ jù?”
43 Simoni wagalula wayanga, “Amenyeje yayola yasajiye enyinji.” Wabhola oyamliye lyoli.”
Simoni dáhùn wí pé, “Mo ṣe bí ẹni tí ó dáríjì jù ni.” Jesu wí fún un pé, “Ìwọ ti dájọ́ náà dáradára.”
44 Wagarushila ola oshe wabhola Simoni, “Walota oshe. Ono nahinjiye mnyumba yaho. Sohampiye amenze mmagagagane, eshi ono andayazyezye amansozi mmagagagane, na syomwole nisisi elya mwitwe lyakwe.
Ó sì yípadà sí obìnrin náà, ó wí fún Simoni pé, “Wo obìnrin yìí? Èmi wọ ilé rẹ, ìwọ kò fi omi wẹ ẹsẹ̀ fún mi: ṣùgbọ́n, omijé rẹ̀ ni ó fi ń rọ̀jò sí mi lẹ́sẹ̀ irun orí ni ó fi ń nù wọ́n nù.
45 Awe sohanjayiye, lelo ono, awande pana hinjiye sagaleshile njayile tee mmagaga gane.
Ìwọ kò fi ìfẹnukonu fún mi: ṣùgbọ́n òun, nígbà tí mo ti wọ ilé, kò dẹ́kun ẹnu fífi kò mí lẹ́sẹ̀.
46 Sagapashile mwitwe lyane amafuta, eshi ono ampeshe amagaga gane amaruhamu.
Ìwọ kò fi òróró pa mí lórí, ṣùgbọ́n òun ti fi òróró pa mí lẹ́sẹ̀.
47 Afwanaje nago, ehubhozya asajiye embibhi zyekwe zyazyalinjili, afwanaje asongwezye tee. Lelo yasajilya hasheoyo asongwelye hashe.”
Ǹjẹ́ mo wí fún ọ, A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó pọ̀ jì í: nítorí tí ó ní ìfẹ́ púpọ̀: ẹni tí a sì dárí díẹ̀ jì, òun náà ni ó ní ìfẹ́ díẹ̀.”
48 Eshi abholele oshe, “Osajilye embibhi zyaho zyonti”
Ó sì wí fún un pé, “A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́!”
49 Esho bhala bhabhakheye pandwemo nawo bhahandile ayanje humoyo gabho wenu ono yasajilo embibhi?”
Àwọn tí ó bá a jókòó jẹun sì bẹ̀rẹ̀ sí í rò nínú ara wọn pé, “Ta ni èyí tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ ji ni pẹ̀lú?”
50 Wabhola ola oshe, “Olweteho lyaho lumwauye. Bhalaga hulweteho lwaho”
Ó sì dáhùn wí fún obìnrin náà pé, “Ìgbàgbọ́ rẹ gbà ọ́ là, máa lọ ní àlàáfíà.”

< Luka 7 >