< Плач Иеремии 3 >
1 Я человек, испытавший горе от жезла гнева Его.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 Он повел меня и ввел во тьму, а не во свет.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 Так, Он обратился на меня и весь день обращает руку Свою;
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 измождил плоть мою и кожу мою, сокрушил кости мои;
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 огородил меня и обложил горечью и тяготою;
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 посадил меня в темное место, как давно умерших;
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 окружил меня стеною, чтобы я не вышел, отяготил оковы мои,
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 и когда я взывал и вопиял, задерживал молитву мою;
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 каменьями преградил дороги мои, извратил стези мои.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 Он стал для меня как бы медведь в засаде, как бы лев в скрытном месте;
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 извратил пути мои и растерзал меня, привел меня в ничто;
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 натянул лук Свой и поставил меня как бы целью для стрел;
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 послал в почки мои стрелы из колчана Своего.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 Я стал посмешищем для всего народа моего, вседневною песнью их.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 Он пресытил меня горечью, напоил меня полынью.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 Сокрушил камнями зубы мои, покрыл меня пеплом.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 И удалился мир от души моей; я забыл о благоденствии,
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 и сказал я: погибла сила моя и надежда моя на Господа.
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Помысли о моем страдании и бедствии моем, о полыни и желчи.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 Твердо помнит это душа моя и падает во мне.
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 Вот что я отвечаю сердцу моему и потому уповаю:
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 по милости Господа мы не исчезли, ибо милосердие Его не истощилось.
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 Оно обновляется каждое утро; велика верность Твоя!
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 Господь часть моя, говорит душа моя, итак буду надеяться на Него.
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 Благ Господь к надеющимся на Него, к душе, ищущей Его.
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 Благо тому, кто терпеливо ожидает спасения от Господа.
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 Благо человеку, когда он несет иго в юности своей;
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 сидит уединенно и молчит, ибо Он наложил его на него;
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 полагает уста свои в прах, помышляя: “может быть, еще есть надежда”;
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 подставляет ланиту свою биющему его, пресыщается поношением,
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 ибо не навек оставляет Господь.
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 Но послал горе, и помилует по великой благости Своей.
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 Ибо Он не по изволению сердца Своего наказывает и огорчает сынов человеческих.
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 Но, когда попирают ногами своими всех узников земли,
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 когда неправедно судят человека пред лицoм Всевышнего,
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 когда притесняют человека в деле его: разве не видит Господь?
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 Кто это говорит: “и то бывает, чему Господь не повелел быть”?
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 Не от уст ли Всевышнего происходит бедствие и благополучие?
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 Зачем сетует человек живущий? всякий сетуй на грехи свои.
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Испытаем и исследуем пути свои, и обратимся к Господу.
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Вознесем сердце наше и руки к Богу, сущему на небесах:
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 мы отпали и упорствовали; Ты не пощадил.
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 Ты покрыл Себя гневом и преследовал нас, умерщвлял, не щадил;
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 Ты закрыл Себя облаком, чтобы не доходила молитва наша;
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 сором и мерзостью Ты сделал нас среди народов.
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 Разинули на нас пасть свою все враги наши.
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 Ужас и яма, опустошение и разорение - доля наша.
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 Потоки вод изливает око мое о гибели дщери народа моего.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 Око мое изливается и не перестает, ибо нет облегчения,
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 доколе не призрит и не увидит Господь с небес.
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 Око мое опечаливает душу мою ради всех дщерей моего города.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 Всячески усиливались уловить меня, как птичку, враги мои, без всякой причины;
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 повергли жизнь мою в яму и закидали меня камнями.
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 Воды поднялись до головы моей; я сказал: “погиб я”.
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 Я призывал имя Твое, Господи, из ямы глубокой.
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 Ты слышал голос мой; не закрой уха Твоего от воздыхания моего, от вопля моего.
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 Ты приближался, когда я взывал к Тебе, и говорил: “не бойся”.
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 Ты защищал, Господи, дело души моей; искуплял жизнь мою.
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 Ты видишь, Господи, обиду мою; рассуди дело мое.
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 Ты видишь всю мстительность их, все замыслы их против меня.
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 Ты слышишь, Господи, ругательство их, все замыслы их против меня,
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 речи восстающих на меня и их ухищрения против меня всякий день.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Воззри, сидят ли они, встают ли, я для них - песнь.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 Воздай им, Господи, по делам рук их;
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 пошли им помрачение сердца и проклятие Твое на них;
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 преследуй их, Господи, гневом, и истреби их из поднебесной.
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.