< Dud'uit Fefeu' a 28 >
1 Boe ma Isak noꞌe Yakob, de fee ne papala-babꞌanggiꞌ ma denu e nae, “Rena malolole! Ho afiꞌ sao ina Kanaꞌan.
Nítorí náà Isaaki pe Jakọbu, ó sì súre fún un, ó sì pàṣẹ fún un pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani.
2 Te muu sia Padan Aram, sia baꞌi Betuel ume na, fo sao mala toꞌo Labꞌan ma ana feto na esa.
Dípò bẹ́ẹ̀ lọ sí Padani-Aramu, sí ilé Betueli, baba ìyá rẹ, kí ìwọ kí ó sì fẹ́ aya fún ara rẹ nínú àwọn ọmọbìnrin Labani arákùnrin ìyá rẹ.
3 Au hule-oꞌe fo Lamatualain Mana Koasa fee nggo papala-babꞌanggiꞌ, fo ho umbu-ana mara ramahefu, ma tititi-nonosi mara dadꞌi leo manaseliꞌ.
Kí Ọlọ́run Olódùmarè El-Ṣaddai kí ó bùkún fún ọ, kí ó sì mú ọ bí sí i, kí ó sì mú ọ pọ̀ sí i ní iye títí tí ìwọ yóò di àgbájọ àwọn ènìyàn.
4 Naa fo, Lamatualain hehelu-fufuli Na neu Abraham tudꞌa neu nggo, mo tititi-nonosi ma. Dei fo hambu mala rae fo Lamatualain helu-fuli fee neu Abraham a.
Kí Ọlọ́run kí ó fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ní ìre tí ó sú fún Abrahamu, kí ìwọ kí ó le gba ilẹ̀ níbi tí a ti ń ṣe àtìpó yìí, ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi fún Abrahamu.”
5 Isak olaꞌ basa ma, ana mboꞌi Yakob Padan Aram neu, nisiꞌ toꞌo Labꞌan no baꞌi Betuel na umen.
Bẹ́ẹ̀ ni Isaaki sì rán Jakọbu lọ. Ó sì lọ sí Padani-Aramu, lọ́dọ̀ Labani ọmọ Betueli, ará Aramu, tí í ṣe arákùnrin Rebeka ìyá Jakọbu àti Esau.
6 Boe ma Esau rena oi Isak fee Yakob papala-babꞌanggiꞌ, ma ai e fo afiꞌ sao ina Kanaꞌan. Ana o rena oi, ama na denu odꞌi na neu sao toꞌo na ana feto na esa sia Padan Aram
Nígbà tí Esau gbọ́ pé, Isaaki ti súre fún Jakọbu, ó sì ti rán Jakọbu lọ sí Padani-Aramu láti fẹ́ aya níbẹ̀ àti pé nígbà tí ó súre fún un, ó kìlọ̀ fun un pé, kò gbọdọ̀ fẹ́ nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani
7 Yakob rena aman no inan parenda na, de lao Padan Aram neu.
àti pé, Jakọbu ti gbọ́rọ̀ sí ìyá àti baba rẹ̀ lẹ́nu, ó sì ti lọ sí Padani-Aramu.
8 Esau o bubꞌuluꞌ oi, ama na nda hii eni sao, atahori Kanaꞌan ra sa.
Nígbà náà ni Esau mọ bí Isaaki baba rẹ ti kórìíra àwọn ọmọbìnrin Kenaani tó.
9 De ana nisiꞌ ama aꞌa na Ismael, de sao nala Ismael anan, naran Mahalat. Mahalat ia, Nebayot feton.
Nítorí náà Esau tọ Iṣmaeli lọ, ó sì fẹ́ Mahalati, arábìnrin Nebaioti, ọmọbìnrin Iṣmaeli tí í ṣe ọmọ Abrahamu. Ó fẹ́ ẹ, kún àwọn ìyàwó tí ó ti ní tẹ́lẹ̀.
10 Leleꞌ naa Yakob lao hela Beer Syeba, fo nae Haran neu.
Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, ó sì kọrí sí ìlú Harani.
11 Relo a mopo ma, ana losa mamanaꞌ esa, de sungguꞌ sia naa. Ana nae sungguꞌ ma, haꞌi nala fatu esa, fo tao dadꞌi ainulu.
Nígbà tí ó dé ibìkan, ó dúró ní òru náà nítorí tí ilẹ̀ ti ń ṣú, ó sì gbé òkúta kan ó fi ṣe ìrọ̀rí, ó sì sùn.
12 Tetembaꞌ naa, ana nalamein nita eꞌedaꞌ esa nambariiꞌ sia rae ma tonggo na losa lalai. Lamatualain ate Nara mia sorga onda-hene eꞌedaꞌ a.
Ó sì lá àlá pé, a gbé àkàsọ̀ kan dúró ti ó fi ìdí lélẹ̀, orí rẹ̀ sì kan ọ̀run, àwọn angẹli Ọlọ́run sì ń gòkè, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀.
13 Sia meit naa, Yakob nita LAMATUALAIN nambariiꞌ sia bobꞌoa na, de olaꞌ nae, “Au ia LAMATUALAIN, ho baꞌi ma Abraham no Isak Lamatualain na. Dei fo Au fee rae ia neu nggo ma tititi-nonosi mara.
Olúwa sì dúró lókè rẹ̀, ó sì wí pé, “Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Abrahamu àti Ọlọ́run Isaaki, ìwọ àti ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ tí ìwọ dùbúlẹ̀ sórí rẹ̀ yìí fún.
14 Mete te, tititi-nonosi mara ramahefu onaꞌ afu. Ara sea-sarangganggaa bee-bꞌee reu sia basa mamanaꞌ. Mia tititi-nonosi mara, basa nusaꞌ sia raefafoꞌ hambu papala-babꞌanggiꞌ.
Ìran rẹ yóò pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, ìwọ yóò sì tànkálẹ̀ dé ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, àti dé gúúsù àti àríwá. A ó sì bùkún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nípasẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ.
15 Musunedꞌa malolole! Ho muu sia sudꞌiꞌ a bee-bꞌee o, Au unea nggo. Dei fo Au o baliꞌ nggo misiꞌ nusaꞌ ia. Au nda hela mesaꞌ nggo sa. Ma Au o tao utetu basa hehelu-fufuliꞌ fo Au helu fee nggoꞌ a.”
Èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì pa ọ mọ́ ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmi yóò sì mú ọ padà wá sí ilẹ̀ yìí ní àlàáfíà. Èmi kì yóò fi ọ sílẹ̀ ní ìgbà kan, títí tí èmi yóò fi mú gbogbo ìlérí mi ṣẹ.”
16 Yakob sungguꞌ fela ma nae, “Au feꞌe uhine ae, LAMATUALAIN o sia ia boe!”
Nígbà tí Jakọbu jí lójú oorun rẹ̀, ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Dájúdájú Olúwa ń bẹ ní ìhín yìí, èmi kò sì mọ̀.”
17 Ma ana namatau, de duꞌa nae, “We! Mamanaꞌ ia tao au ao fulu ngga tenggou. Memaꞌ Lamatualain ume na sia ia! Ia, lelesu nisiꞌ sorga neu.”
Ẹ̀rù sì bà á, ó sì wí pé, “Ìhín yìí ní ẹ̀rù gidigidi; ibí kì í ṣe ibòmíràn bí kò ṣe ilé Ọlọ́run, àní ẹnu ibodè ọ̀run nìyìí.”
18 Mbila fefetu ana na, Yakob fela, haꞌi nala fatu ainuluꞌ a, de naririi e dadꞌi tatandaꞌ. Ana mbori mina nisiꞌ fatu a ata, de beꞌutee neu Lamatualain.
Jakọbu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì gbé òkúta tí ó fi ṣe ìrọ̀rí lélẹ̀ bí ọ̀wọ́n, ó sì da òróró si lórí.
19 Ana babꞌae mamanaꞌ naa naran Betel, sosoa na nae ‘Lamatualain ume na’. (Maꞌahulu na, mamanaꞌ naa, naran Lus).
Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Beteli, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìlú náà ń jẹ́ Lusi tẹ́lẹ̀ rí.
20 Boe ma Yakob sumba nae, “Mete ma Lamatualain no au, ma nanea au sia dala ngga, ma fee nanaat ma bua-baꞌus,
Jakọbu sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ níbẹ̀ pé, “Bí Ọlọ́run yóò bá wà pẹ̀lú mi, tí yóò sì pa mí mọ́ ní ìrìnàjò mi tí mo ń lọ, tí yóò sì fún mi ní oúnjẹ láti jẹ àti aṣọ láti wọ̀,
21 losa au baliꞌ no masodꞌaꞌ, naa, LAMATUALAIN dadꞌi au Lamatua ngga.
tí mo sì padà sílé baba mi ní àlàáfíà, nígbà náà Olúwa ni yóò jẹ́ Ọlọ́run mi,
22 Fatu fo au uririiꞌ ia, dadꞌi mamana beꞌuteeꞌ neu Lamatualain. Ma basa saa fo Ana fee au, dei fo au fee baliꞌ babanggiꞌ esa mia sanahulu.”
Òkúta yìí tí mo gbé kalẹ̀ bí ọ̀wọ́n yóò jẹ́ ilé Ọlọ́run, nínú gbogbo ohun tí ìwọ ó fi fún mi, èmi yóò sì fi ìdámẹ́wàá rẹ̀ fún ọ.”