< Marcu 9 >

1 El le-a zis: “Adevărat vă spun că sunt unii care stau aici și care nu vor gusta moartea până nu vor vedea venind cu putere Împărăția lui Dumnezeu.”
Ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún un yín àwọn mìíràn wa nínú àwọn tó dúró níhìn-ín yìí, tí kì yóò tọ́ ikú wò, títí yóò fi rí ìjọba Ọlọ́run tí yóò fi dé pẹ̀lú agbára.”
2 După șase zile, Isus a luat cu El pe Petru, Iacov și Ioan și i-a dus singuri pe un munte înalt, în particular, și S-a schimbat în fața lor.
Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́fà tí Jesu sọ̀rọ̀ yìí, Jesu mú Peteru, Jakọbu àti Johanu lọ sí orí òkè gíga ní apá kan. Kò sí ẹlòmíràn pẹ̀lú wọn, ara rẹ̀ sì yípadà níwájú wọn.
3 Hainele Lui au devenit strălucitoare, extrem de albe, ca zăpada, așa cum nici un spălător de pe pământ nu le poate albi.
Aṣọ rẹ̀ sì di dídán, ó sì funfun gbòò, tí alágbàfọ̀ kan ní ayé kò lè sọ di funfun bẹ́ẹ̀.
4 Le-au apărut Ilie și Moise, care stăteau de vorbă cu Isus.
Nígbà náà ni Elijah àti Mose farahàn fún wọn, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀ pẹ̀lú Jesu.
5 Petru a răspuns lui Isus: “Rabi, este bine să fim aici. Să facem trei corturi: unul pentru tine, unul pentru Moise și unul pentru Ilie.”
Peteru sì wí fún Jesu pé, “Rabbi, ó dára fún wa láti máa gbé níhìn-ín, si jẹ́ kí a pa àgọ́ mẹ́ta, ọ̀kan fun ọ, ọ̀kan fún Mose, àti ọ̀kan fún Elijah.”
6 Căci nu știa ce să spună, pentru că erau foarte speriați.
Nítorí òun kò mọ ohun tí òun ìbá sọ, nítorí ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
7 Un nor a venit și i-a acoperit cu umbră, iar din nor a ieșit un glas: “Acesta este Fiul Meu preaiubit. Ascultați-l.”
Ìkùùkuu kan sì bò wọ́n, ohùn kan sì ti inú ìkùùkuu náà wá wí pé, “Èyí ni àyànfẹ́ ọmọ mi. Ẹ máa gbọ́ ti rẹ̀!”
8 Și, uitându-se deodată în jur, n-au mai văzut pe nimeni cu ei, decât numai pe Isus.
Lójijì, wọ́n wo àyíká wọn, wọn kò sì rí ẹnìkankan mọ́, bí kò ṣe Jesu nìkan ṣoṣo ni ó sì wà pẹ̀lú wọn.
9 Pe când se coborau de pe munte, le-a poruncit să nu spună nimănui cele ce văzuseră, până ce Fiul Omului nu va învia din morți.
Bí wọ́n ti ń sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, Jesu kìlọ̀ fún wọn kí wọ́n má ṣe sọ ohun tí wọ́n ti rí fún ẹnikẹ́ni títí Ọmọ Ènìyàn yóò fi jíǹde kúrò nínú òkú.
10 Ei au păstrat pentru ei înșiși acest cuvânt, întrebându-se ce înseamnă “învierea din morți”.
Nítorí náà, wọ́n pa nǹkan náà mọ́ ní ọkàn wọn. Ṣùgbọ́n wọ́n ń béèrè lọ́wọ́ ara wọn ohun tí àjíǹde kúrò nínú òkú túmọ̀ sí.
11 Și L-au întrebat: “Pentru ce zic cărturarii că Ilie trebuie să vină mai întâi?”
Nísinsin yìí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, èéṣe tí àwọn olùkọ́ òfin ń sọ wí pé, “Elijah ní yóò kọ́kọ́ dé.”
12 El le-a zis: “Ilie vine mai întâi și restaurează toate lucrurile. Cum este scris despre Fiul Omului că trebuie să sufere multe și să fie disprețuit?
Ó sì dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni Elijah yóò kọ́kọ́ dé yóò sì mú nǹkan gbogbo padà bọ̀ sípò. Àní gẹ́gẹ́ bí a ti kọ̀wé rẹ nípa ti Ọmọ Ènìyàn pé kò le ṣàìmá jìyà ohun púpọ̀ àti pé a ó sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
13 Dar Eu vă spun că Ilie a venit și i-au făcut și lui tot ce au vrut, așa cum este scris despre El.”
Ṣùgbọ́n mo wí fún yín pé, Elijah ti wa ná, wọ́n sì ti ṣe ohunkóhun tí ó wù wọ́n sí i, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ̀wé nípa rẹ̀.”
14 Când a venit la ucenici, a văzut o mulțime mare în jurul lor și cărturari care îi întrebau.
Nígbà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ pátápátá sí ẹsẹ̀ òkè náà, wọ́n bá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn tí wọ́n yí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mẹ́sàn-án ìyókù ká. Àwọn olùkọ́ òfin díẹ̀ sì ń bá wọn jiyàn.
15 Îndată toată mulțimea, văzându-l, a fost foarte uimită și, alergând la el, l-a salutat.
Bí Jesu ti ń súnmọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn wọ̀nyí ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí í wò ó pẹ̀lú ìbẹ̀rù, nígbà náà ni wọ́n sáré lọ kí i.
16 El i-a întrebat pe cărturari: “Ce-i întrebați?”
Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ló fa àríyànjiyàn?”
17 Unul din mulțime a răspuns: “Învățătorule, ți-am adus pe fiul meu, care are un duh mut,
Ọkùnrin kan láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn dáhùn pé, “Olùkọ́, èmi ni mo mú ọmọ yìí wá fún ọ láti wò ó sàn. Kò lè sọ̀rọ̀ rárá, nítorí tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́.
18 și oriunde îl apucă, îl aruncă la pământ; face spume la gură, scrâșnește din dinți și se înțeapă. I-am rugat pe discipolii tăi să-l scoată afară, dar n-au fost în stare.”
Àti pé, nígbàkígbà tí ó bá mú un, á gbé e ṣánlẹ̀, a sì máa hó itọ́ lẹ́nu, a sì máa lọ́ eyín rẹ̀. Òun pàápàá a wá le gbagidi. Mo sì bẹ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ kí wọn lé ẹ̀mí àìmọ́ náà jáde, ṣùgbọ́n wọ́n kò lè ṣe é.”
19 El i-a răspuns: “Neam necredincios, până când voi fi cu voi? Până când voi mai suporta cu voi? Aduceți-l la Mine!”
Ó sì dá wọn lóhùn, ó wí pé, “Ẹ̀yin ìran aláìgbàgbọ́ yìí, èmi yóò ti bá a yín gbé pẹ́ tó? Èmi yóò sì ti mú sùúrù fún un yín pẹ́ tó? Ẹ mú ọmọ náà wá sọ́dọ̀ mi.”
20 L-au adus la el și, când l-a văzut, îndată l-a cuprins duhul și a căzut la pământ, zvârcolindu-se și făcând spume la gură.
Wọ́n sì mú un wá sọ́dọ̀ rẹ̀: nígbà tí ó sì rí i, lójúkan náà ẹ̀mí náà nà án tàntàn ó sì ṣubú lu ilẹ̀, ó sì ń fi ara yílẹ̀, ó sì ń yọ ìfófó lẹ́nu.
21 Și a întrebat pe tatăl său: “De când i se întâmplă asta?” El a spus: “Din copilărie.
Jesu béèrè lọ́wọ́ baba ọmọ náà pé, “Ó tó ìgbà wo tí ọmọ rẹ̀ ti wà nínú irú ipò báyìí?” Baba ọmọ náà dáhùn pé, “Láti kékeré ni.”
22 De multe ori l-a aruncat atât în foc, cât și în apă, pentru a-l distruge. Dar dacă poți face ceva, ai milă de noi și ajută-ne.”
Nígbàkígbà ni ó sì máa ń gbé e sínú iná àti sínú omi, láti pa á run, ṣùgbọ́n bí ìwọ bá lè ṣe ohunkóhun, ṣàánú fún wa, kí o sì ràn wá lọ́wọ́.
23 Isus i-a zis: “Dacă poți crede, toate sunt cu putință celui ce crede.”
“Jesu sì wí fún un pé, ‘Bí ìwọ bá le gbàgbọ́: ohun gbogbo ni ó ṣe é ṣe fún ẹni tí ó bá gbàgbọ́.’”
24 Și îndată tatăl copilului a strigat cu lacrimi: “Cred. Ajută-mi necredința!”
Lójúkan náà baba ọmọ náà kígbe ní ohùn rara, ó sì wí pé, “Olúwa, mo gbàgbọ́, ran àìgbàgbọ́ mi lọ́wọ́.”
25 Isus, văzând că o mulțime alerga laolaltă, a mustrat pe duhul necurat și i-a zis: “Duh mut și surd, îți poruncesc să ieși din el și să nu mai intri niciodată în el!”
Nígbà tí Jesu rí i pé ọ̀pọ̀ ènìyàn ń péjọ sọ́dọ̀ wọn, ó bá ẹ̀mí àìmọ́ náà wí pé, “Ìwọ ẹ̀mí àìmọ́, adití àti odi, mo pàṣẹ fún ọ, kí ó jáde kúrò lára ọmọ yìí, kí ó má ṣe padà sí ibẹ̀ mọ́.”
26 Și după ce a strigat și a fost cuprins de mari convulsii, a ieșit din el. Băiatul s-a făcut ca un mort, atât de mult încât cei mai mulți dintre ei au spus: “A murit”.
Òun sì kígbe ńlá, ó sì nà án tàntàn, ó sì jáde kúrò lára rẹ̀, ọmọ náà sì dàbí ẹni tí ó kú tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀pọ̀ ènìyàn ké wí pé, “Hé è, ọmọ náà ti kú.”
27 Dar Isus l-a luat de mână și l-a înviat; și s-a ridicat.
Ṣùgbọ́n Jesu fà á lọ́wọ́, ó sì ràn án lọ́wọ́ láti dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀. Ó dìde dúró.
28 După ce a intrat în casă, ucenicii Lui L-au întrebat în particular: “De ce n-am putut să-l scoatem afară?”
Nígbà tí ó sì wọ ilé, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ bi í léèrè níkọ̀kọ̀ wí pé, “Èéṣe tí àwa kò fi lè lé e jáde?”
29 Și le-a zis: “Nu se poate ieși așa ceva decât prin rugăciune și prin post.”
Ó sì wí fún wọn pé, “Irú èyí kò le ti ipa ohun kan jáde, bí kò ṣe nípa àdúrà.”
30 Au plecat de acolo și au trecut prin Galileea. El nu voia să știe nimeni,
Wọ́n sì kúrò níbẹ̀, wọ́n gba Galili kọjá. Níbẹ̀ ni Jesu ti gbìyànjú láti yẹra kí ó bá à lè wà pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, kí ó lè ráàyè kọ́ wọn lẹ́kọ̀ọ́ sí i.
31 pentru că îi învăța pe ucenicii Săi și le spunea: “Fiul Omului va fi dat în mâinile oamenilor și ei Îl vor ucide; iar după ce va fi ucis, a treia zi va învia.”
Nítorí ó kọ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó sì wí fun wọn pe, “A ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́, wọn ó sì pa á, lẹ́yìn ìgbà tí a bá sì pa á tan yóò jíǹde ní ọjọ́ kẹta.”
32 Dar ei nu înțelegeau cuvântul acesta și se temeau să-L întrebe.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ náà kò yé wọn, ẹ̀rù sì bà wọ́n láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, ìtumọ̀ ohun tí ó sọ náà.
33 Când a ajuns în Capernaum, i-a întrebat pe cei din casă: “Ce vă certați între voi pe drum?”
Wọ́n dé sí Kapernaumu. Lẹ́yìn tí wọ́n sinmi tán nínú ilé tí wọ́n wọ̀, Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ni ohun tí ẹ́ ń bá ara yín jiyàn lé lórí?”
34 Dar ei au tăcut, pentru că pe drum se certau între ei cine este cel mai mare.
Ṣùgbọ́n wọ́n dákẹ́; nítorí wọn ti ń bá ara wọn jiyàn pé, ta ni ẹni tí ó pọ̀jù?
35 A șezut jos, a chemat pe cei doisprezece și le-a zis: “Dacă cineva vrea să fie cel dintâi, să fie cel din urmă dintre toți și slujitorul tuturor.”
Ó jókòó, ó sì pè àwọn méjìlá náà, ó sọ fún wọn pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ ṣe ẹni ìṣáájú, òun ni yóò ṣe ẹni ìkẹyìn gbogbo wọn. Ó ní láti jẹ́ ìránṣẹ́ gbogbo ènìyàn.”
36 A luat un copilaș și l-a așezat în mijlocul lor. Luându-l în brațe, le-a spus:
Ó sì mú ọmọ kékeré kan, ó fi sáàárín wọn, nígbà tí ó sì gbé e sí apá rẹ̀, ó wí fún wọn pé,
37 “Oricine primește un astfel de copilaș în numele meu, pe mine mă primește; și oricine mă primește pe mine, nu pe mine mă primește, ci pe cel care m-a trimis pe mine.”
“Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ́wọ́gbà ọmọ kékeré bí èyí ní orúkọ mi, òun gbà mí. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì gbà mi, ó gba Baba mi, tí ó rán mi.”
38 Ioan I-a zis: “Învățătorule, am văzut pe cineva care nu ne urmează, care scoate demoni în Numele Tău, și i-am interzis, pentru că nu ne urmează.”
Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Johanu sọ fún un ní ọjọ́ kan pé, “Olùkọ́, àwa rí ọkùnrin kan, tí ń fi orúkọ rẹ̀ lé àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde, ṣùgbọ́n a sọ fún un pé kò gbọdọ̀ ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́, nítorí kì í ṣe ọ̀kan nínú wa.”
39 Dar Isus a zis: “Nu-i interziceți, căci nu este nimeni care să facă o lucrare mare în Numele Meu și să poată repede să vorbească de rău despre Mine.
Jesu sì sọ fún un pé, “Má ṣe dá irú ènìyàn bẹ́ẹ̀ dúró, nítorí kò sí ẹnìkan ti ó fi orúkọ mi ṣe iṣẹ́ ìyanu tí yóò tún lè máa sọ ohun búburú nípa mi.
40 Căci oricine nu este împotriva noastră este de partea noastră.
Nítorí ẹni tí kò bá kọ ojú ìjà sí wa, ó wà ní ìhà tiwa.
41 Căci oricine vă va da să beți un pahar cu apă în numele meu, pentru că sunteți ai lui Hristos, cu siguranță vă spun că nu-și va pierde în niciun fel răsplata.
Lóòótọ́ ni mo sọ fún ún yín bí ẹnikẹ́ni bá fún un yín ní ife omi kan nítorí pé ẹ jẹ́ ti Kristi, dájúdájú ẹni náà kì yóò sọ èrè rẹ̀ nù bí ó ti wù kí ó rí.
42 Oricine va face să se poticnească pe unul din acești mici care cred în Mine, mai bine ar fi să fie aruncat în mare, cu o piatră de moară atârnată de gât.
“Ṣùgbọ́n ti ẹnikẹ́ni bá mú ọ̀kan nínú àwọn ọmọ kékeré wọ̀nyí tí ó gbà mí gbọ́ ṣìnà nínú ìgbàgbọ́ rẹ́, ó sàn fún un kí a so òkúta ńlá mọ́ ọn ni ọ̀run, kí a sì sọ ọ́ sínú òkun.
43 Dacă mâna ta te face să te poticnești, taie-ți-o! Este mai bine pentru tine să intri în viață mutilat, decât să ai cele două mâini pentru a merge în Gheena, în focul nestins, (Geenna g1067)
Bí ọwọ́ rẹ bá sì mú ọ kọsẹ̀, gé e sọnù, ó sàn fún ọ kí o ṣe akéwọ́ lọ sí ibi ìyè, ju kí o ní ọwọ́ méjèèjì, kí o lọ sí ọ̀run àpáàdì, sínú iná àjóòkú. (Geenna g1067)
44 “unde viermele lor nu moare și focul nu se stinge”.
45 Dacă piciorul tău te face să te poticnești, taie-l! Este mai bine pentru tine să intri în viață șchiop, decât ca cele două picioare să fie aruncate în Gheena, în focul care nu se va stinge niciodată — (Geenna g1067)
Bí ẹsẹ̀ rẹ bá sì mú ọ kọsẹ̀, gé é sọnù, ó sàn kí ó di akesẹ̀, kí o sì gbé títí ayé àìnípẹ̀kun ju kí o ní ẹsẹ̀ méjì tí ó gbé ọ lọ sí ọ̀run àpáàdì. (Geenna g1067)
46 'unde viermele lor nu moare și focul nu se stinge'.
47 Dacă ochiul tău te face să te poticnești, aruncă-l afară. Este mai bine pentru tine să intri în Împărăția lui Dumnezeu cu un singur ochi, decât să ai doi ochi pentru a fi aruncat în Gheena de foc, (Geenna g1067)
Bí ojú rẹ bá sì mú ọ kọsẹ̀, yọ ọ́ sọnù, ó sàn kí o wọ ìjọba Ọlọ́run pẹ̀lú ojú kan ju kí ó ní ojú méjì kí ó sì lọ sínú iná ọ̀run àpáàdì. (Geenna g1067)
48 'unde viermele lor nu moare și focul nu se stinge'.
Níbi ti “‘kòkòrò wọn kì í kú, tí iná kì í sì í kú.’
49 Căci toată lumea va fi sărată cu foc și orice jertfă va fi condimentată cu sare.
Níbẹ̀ ni a ó ti fi iná dán ẹnìkọ̀ọ̀kan wò.
50 Sarea este bună, dar, dacă sarea și-a pierdut savoarea, cu ce o vei asezona? Aveți sare în voi înșivă și fiți în pace unii cu alții.”
“Iyọ̀ dára, ṣùgbọ́n tí ó bá sọ adùn rẹ̀ nù, báwo ni ẹ ṣè lè padà mú un dùn? Ẹ ni iyọ̀ nínú ara yín, ki ẹ sì máa gbé ní àlàáfíà pẹ̀lú ara yín.”

< Marcu 9 >