< Luca 15 >

1 Și toți vameșii și păcătoșii se apropiau de El ca să-L asculte.
Gbogbo àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sì súnmọ́ ọn láti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
2 Fariseii și cărturarii murmurau și ziceau: “Omul acesta îi primește pe păcătoși și mănâncă cu ei.”
Àti àwọn Farisi àti àwọn akọ̀wé ń kùn pé, “Ọkùnrin yìí ń gba ẹlẹ́ṣẹ̀, ó sì ń bá wọn jẹun.”
3 Și le-a spus pilda aceasta:
Ó sì pa òwe yìí fún wọn, pé,
4 “Cine dintre voi, dacă ar avea o sută de oi și ar pierde una dintre ele, nu ar lăsa cele nouăzeci și nouă în pustiu și nu s-ar duce după cea pierdută, până o va găsi?
“Ọkùnrin wo ni nínú yín, tí ó ní ọgọ́rùn-ún àgùntàn, bí ó bá sọ ọ̀kan nù nínú wọn, tí kì yóò fi mọ́kàndínlọ́gọ́rùn-ún yokù sílẹ̀ ni ijù tí kì yóò sì tọ ipasẹ̀ èyí tí ó nù lọ, títí yóò fi rí i?
5 După ce o găsește, o poartă pe umeri, bucurându-se.
Nígbà tí ó bá sì rí i tán, yóò gbé e lé èjìká rẹ̀ pẹ̀lú ayọ̀.
6 Când se întoarce acasă, își cheamă prietenii și vecinii, spunându-le: “Bucurați-vă cu mine, căci am găsit oaia mea care era pierdută!”.
Nígbà tí ó bá sì dé ilé yóò pe àwọn ọ̀rẹ́ àti aládùúgbò rẹ̀ jọ, yóò sì wí fún wọn pé, ‘Ẹ bá mí yọ̀; nítorí tí mo ti rí àgùntàn mi tí ó nù.’
7 Eu vă spun că și așa va fi mai multă bucurie în cer pentru un singur păcătos care se pocăiește, decât pentru nouăzeci și nouă de oameni drepți care nu au nevoie de pocăință.
Mo wí fún yín, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ayọ̀ yóò wà ní ọ̀run lórí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan tí ó ronúpìwàdà, ju lórí olóòtítọ́ mọ́kàndínlọ́gọ́rùn-ún lọ, tí kò nílò ìrònúpìwàdà.
8 “Sau ce femeie, dacă ar avea zece drahme, dacă ar pierde o drahmă, nu ar aprinde o lampă, nu ar mătura casa și nu ar căuta cu sârguință până ce ar găsi-o?
“Tàbí obìnrin wo ni ó ní owó fàdákà mẹ́wàá bí ó bá sọ ọ̀kan nù, tí kì yóò tan fìtílà, kí ó fi gbá ilé, kí ó sì wá a gidigidi títí yóò fi rí i?
9 După ce o găsește, își cheamă prietenele și vecinele, spunând: “Bucurați-vă cu mine, căci am găsit drahma pe care o pierdusem!”.
Nígbà tí ó sì rí i, ó pe àwọn ọ̀rẹ́ àti àwọn aládùúgbò rẹ̀ jọ, ó wí pé, ‘Ẹ bá mi yọ̀; nítorí mo rí owó fàdákà tí mo ti sọnù.’
10 Tot așa, vă spun, există bucurie în prezența îngerilor lui Dumnezeu pentru un păcătos care se pocăiește.”
Mo wí fún yín, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ayọ̀ ń bẹ níwájú àwọn angẹli Ọlọ́run lórí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan tí ó ronúpìwàdà.”
11 El a zis: “Un om avea doi fii.
Ó sì wí pé ọkùnrin kan ní ọmọ méjì:
12 Cel mai tânăr dintre ei a zis tatălui său: “Tată, dă-mi partea mea din averea ta. Așa că a împărțit între ei averea lui.
“Èyí àbúrò nínú wọn wí fún baba rẹ̀ pé, ‘Baba, fún mi ní ìní tí ó kàn mí.’ Ó sì pín ohun ìní rẹ̀ fún wọn.
13 Nu după multe zile, fiul cel mai tânăr a adunat toate acestea și a călătorit într-o țară îndepărtată. Acolo și-a risipit averea cu un trai desfrânat.
“Kò sì tó ọjọ́ mélòó kan lẹ́yìn náà, èyí àbúrò kó ohun gbogbo tí ó ní jọ, ó sì mú ọ̀nà àjò rẹ̀ pọ̀n lọ sí ilẹ̀ òkèrè, níbẹ̀ ni ó sì gbé fi ìwà wọ̀bìà ná ohun ìní rẹ̀ ní ìnákúnàá.
14 După ce a cheltuit totul, s-a ivit o foamete cruntă în țara aceea și a început să fie în nevoie.
Nígbà tí ó sì ba gbogbo rẹ̀ jẹ́ tan, ìyàn ńlá wá mú ní ilẹ̀ náà; ó sì bẹ̀rẹ̀ sí di aláìní.
15 S-a dus și s-a unit cu unul dintre cetățenii acelei țări, care l-a trimis pe câmpurile sale să hrănească porcii.
Ó sì fi ara rẹ sọfà fun ọ̀kan lára àwọn ọmọ ìlú náà; òun sì rán an lọ sí oko rẹ̀ láti tọ́jú ẹlẹ́dẹ̀.
16 El a vrut să-și umple burta cu păstăile pe care le mâncau porcii, dar nimeni nu i-a dat nimic.
Ayọ̀ ni ìbá fi jẹ oúnjẹ tí àwọn ẹlẹ́dẹ̀ ń jẹ ní àjẹyó, ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni kò sì fi fún un.
17 Când și-a revenit, a zis: “Câți dintre angajații tatălui meu au pâine de prisos, iar eu mor de foame!
“Ṣùgbọ́n nígbà tí ojú rẹ̀ wálẹ̀, ó ní ‘Mélòó mélòó àwọn alágbàṣe baba mí ni ó ní oúnjẹ àjẹyó, àti àjẹtì, èmi sì ń kú fún ebi níhìn-ín.
18 Mă voi scula și mă voi duce la tatăl meu și-i voi spune: “Tată, am păcătuit împotriva cerului și în fața ta.
Èmi ó dìde, èmi ó sì tọ baba mi lọ, èmi ó sì wí fún un pé, Baba, èmí ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ̀run, àti níwájú rẹ,
19 Nu mai sunt vrednic să fiu numit fiul tău. Fă-mă ca pe unul dintre robii tăi angajați!””'”.
èmi kò sì yẹ, ní ẹni tí à bá pè ní ọmọ rẹ mọ́; fi mí ṣe ọ̀kan nínú àwọn alágbàṣe rẹ.’
20 “S-a sculat și a venit la tatăl său. Dar, pe când era încă departe, tatăl său l-a văzut și, mișcat de milă, a alergat, s-a aruncat la gâtul lui și l-a sărutat.
Ó sì dìde, ó sì tọ baba rẹ̀ lọ. “Ṣùgbọ́n nígbà tí ó sì wà ní òkèrè, baba rẹ̀ rí i, àánú ṣe é, ó sì súré, ó rọ̀ mọ́ ọn ní ọrùn, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
21 Fiul i-a zis: “Tată, am păcătuit împotriva cerului și în fața ta. Nu mai sunt vrednic să mă numesc fiul tău'.
“Ọmọ náà sì wí fún un pé, Baba, èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ̀run, àti níwájú rẹ, èmi kò yẹ ní ẹni tí à bá pè ní ọmọ rẹ mọ́!
22 Dar tatăl a zis slugilor sale: “Scoateți cea mai bună haină și îmbrăcați-l. Puneți-i un inel la mână și sandale la picioare.
“Ṣùgbọ́n baba náà wí fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, Ẹ mú ààyò aṣọ wá kánkán, kí ẹ sì fi wọ̀ ọ́; ẹ sì fi òrùka bọ̀ ọ́ lọ́wọ́, àti bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ̀:
23 Aduceți vițelul îngrășat, înjunghiați-l, să mâncăm și să sărbătorim;
Ẹ sì mú ẹgbọrọ màlúù àbọ́pa wá, kí ẹ sì pa á, kí a máa ṣe àríyá.
24 căci acesta, fiul meu, a fost mort și a înviat. Era pierdut și s-a regăsit”. Atunci au început să sărbătorească.
Nítorí ọmọ mi yìí ti kú, ó sì tún yè, ó ti nù, a sì rí i. Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àríyá.
25 “Și fiul său cel mare era la câmp. Când s-a apropiat de casă, a auzit muzică și dansuri.
“Ṣùgbọ́n ọmọ rẹ̀ èyí ẹ̀gbọ́n ti wà ní oko: bí ó sì ti ń bọ̀, tí ó súnmọ́ etí ilé, ó gbọ́ orin àti ijó.
26 A chemat la el pe unul dintre servitori și l-a întrebat ce se întâmplă.
Ó sì pe ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ wọn, ó béèrè, kín ni a mọ nǹkan wọ̀nyí sí?
27 Acesta i-a spus: “A venit fratele tău, iar tatăl tău a omorât vițelul îngrășat, pentru că l-a primit înapoi sănătos și nevătămat.
Ó sì wí fún un pé, ‘Arákùnrin rẹ dé, baba rẹ sì pa ẹgbọrọ màlúù àbọ́pa, nítorí tí ó rí i padà ní àlàáfíà àti ní ìlera.’
28 Dar el s-a mâniat și nu a vrut să intre. De aceea tatăl său a ieșit și l-a rugat.
“Ó sì bínú, ó sì kọ̀ láti wọlé; baba rẹ̀ sì jáde, ó sì wá í ṣìpẹ̀ fún un.
29 Dar el a răspuns tatălui său: “Iată, în acești mulți ani te-am slujit și niciodată nu am nesocotit o poruncă de-a ta, dar niciodată nu mi-ai dat un țap, ca să sărbătoresc cu prietenii mei.
Ó sì dáhùn ó wí fún baba rẹ̀ pé, ‘Wò ó, láti ọdún mélòó wọ̀nyí ni èmi ti ń sìn ọ́, èmi kò sì rú òfin rẹ rí, ìwọ kò sì tí ì fi ọmọ ewúrẹ́ kan fún mi, láti fi bá àwọn ọ̀rẹ́ mi ṣe àríyá.
30 Dar când a venit acest fiu al tău, care ți-a devorat traiul cu prostituatele, ai ucis vițelul îngrășat pentru el.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọmọ rẹ yìí dé, ẹni tí ó fi panṣágà fi ọrọ̀ rẹ̀ ṣòfò, ìwọ sì ti pa ẹgbọrọ màlúù àbọ́pa fún un.’
31 El i-a zis: “Fiule, tu ești totdeauna cu mine și tot ce este al meu este al tău.
“Ó sì wí fún un pé, ‘Ọmọ, nígbà gbogbo ni ìwọ ń bẹ lọ́dọ̀ mi, ohun gbogbo tí mo sì ní, tìrẹ ni.
32 Darse cuvenea să sărbătorim și să ne bucurăm, pentru că acesta, fratele tău, era mort și a înviat. Era pierdut și s-a găsit”.”
Ó yẹ kí a ṣe àríyá kí a sì yọ̀: nítorí arákùnrin rẹ yìí ti kú, ó sì tún yè; ó ti nù, a sì rí i.’”

< Luca 15 >