< Luca 14 >

1 Când a intrat în casa unuia dintre fruntașii fariseilor, în ziua de Sabat, ca să mănânce pâine, ei Îl urmăreau.
Nígbà tí ó wọ ilé ọ̀kan nínú àwọn olórí Farisi lọ ní ọjọ́ ìsinmi láti jẹun, wọ́n sì ń ṣọ́ ọ.
2 Iată că un om care avea hidropizie era în fața lui.
Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan tí ó ní ara wíwú níwájú rẹ̀.
3 Isus, răspunzând, a vorbit cu juriștii și cu fariseii și le-a zis: “Este îngăduit să vindeci în Sabat?”
Jesu sì dáhùn ó wí fún àwọn amòfin àti àwọn Farisi pé, “Ǹjẹ́ ó tọ́ láti mú ni láradá ní ọjọ́ ìsinmi, tàbí kò tọ́?”
4 Dar ei au tăcut. L-a luat, l-a vindecat și l-a lăsat să plece.
Wọ́n sì dákẹ́. Ó sì mú un, ó mú un láradá, ó sì jẹ́ kí ó lọ.
5 El le-a răspuns: “Cine dintre voi, dacă fiul său sau boul său ar cădea într-o fântână, nu l-ar scoate imediat într-o zi de Sabat?”
Ó sì dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ta ni nínú yín tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí màlúù rẹ̀ yóò bọ́ sínú ihò, tí kì yóò sì fà á sókè lójúkan náà ní ọjọ́ ìsinmi?”
6 Nu puteau să-i răspundă la aceste lucruri.
Wọn kò sì lè dá a lóhùn mọ́ sí nǹkan wọ̀nyí.
7 El a spus o pildă celor invitați, când a observat că ei își aleg locurile cele mai bune și le-a zis:
Ó sì pa òwe kan fún àwọn tí ó pè é wá jẹun, nígbà tí ó ṣàkíyèsí bí wọ́n ti ń yan ipò ọlá; ó sì wí fún wọn pé,
8 “Când sunteți invitați de cineva la o nuntă, nu vă așezați pe locul cel mai bun, căci poate că va fi invitat cineva mai de seamă decât voi,
“Nígbà tí ẹnìkan bá pè ọ́ wá sí ibi ìyàwó, má ṣe jókòó ní ipò ọlá; kí ó má ba à jẹ́ pé, a ó pe ẹni tí ó lọ́lá jù ọ́ lọ.
9 iar cel care v-a invitat pe amândoi va veni și vă va spune: “Faceți loc pentru acesta”. Atunci ați începe, cu rușine, să ocupați locul cel mai de jos.
Nígbà tí ẹni tí ó pè ọ́ bá dé, a sì wí fún ọ pé, ‘Fún ọkùnrin yìí ní ààyè!’ Ìwọ á sì wá fi ìtìjú mú ipò ẹ̀yìn.
10 Dar când ești invitat, du-te și stai în locul cel mai de jos, pentru ca, atunci când va veni cel care te-a invitat, să-ți spună: “Prietene, urcă-te mai sus”. Atunci vei fi onorat în prezența tuturor celor care stau la masă cu tine.
Ṣùgbọ́n nígbà tí a bá pè ọ́, lọ kí o sì jókòó ní ipò ẹ̀yìn; nígbà tí ẹni tí ó pè ọ́ bá dé, kí ó lè wí fún ọ pé, ‘Ọ̀rẹ́, bọ́ sókè!’ Nígbà náà ni ìwọ ó ní ìyìn lójú àwọn tí ó bá ọ jókòó ti oúnjẹ.
11 Căci oricine se înalță va fi smerit, iar oricine se smerește va fi înălțat.”
Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbé ara rẹ̀ ga, ni a ó rẹ̀ sílẹ̀; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, ni a ó sì gbéga.”
12 Și a mai zis celui care-l invitase: “Când faci o cină sau un prânz, nu chema pe prietenii tăi, nici pe frații tăi, nici pe rudele tale, nici pe vecinii tăi bogați, căci poate că și ei îți vor întoarce favoarea și-ți vor plăti.
Nígbà náà ni ó sì wí fún alásè tí ó pè é pé, “Nígbà tí ìwọ bá ṣe àsè má ṣe pe àwọn arákùnrin rẹ tàbí àwọn ìbátan rẹ, tàbí àwọn ọlọ́rọ̀ aládùúgbò rẹ̀; nítorí kí wọn má ṣe pè ọ́ padà láti san ẹ̀san padà.
13 Ci, când faci un ospăț, invită-i pe săraci, pe mutilați, pe șchiopi sau pe orbi;
Ṣùgbọ́n nígbà tí ìwọ bá ṣe àsè, pe àwọn tálákà, àwọn alábùkún ara, àwọn amúnkùn ún, àti àwọn afọ́jú:
14 și vei fi binecuvântat, pentru că ei nu au resurse să-ți dea înapoi. Căci veți fi răsplătiți la învierea celor drepți.”
Ìwọ ó sì jẹ́ alábùkún fún; nítorí wọn kò ní ohun tí wọn ó fi san án fún ọ, ṣùgbọ́n a ó san án fún ọ ní àjíǹde, àwọn olóòtítọ́.”
15 Unul din cei ce ședeau la masă cu El, auzind aceste lucruri, i-a zis: “Ferice de cel ce va petrece în Împărăția lui Dumnezeu!”
Nígbà tí ọ̀kan nínú àwọn tí wọ́n jọ jókòó gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó wí fún Jesu pé, “Alábùkún ni fún ẹni tí yóò jẹ oúnjẹ àsè ní ìjọba Ọlọ́run!”
16 Dar El i-a zis: “Un om a făcut o cină mare și a invitat multă lume.
Jesu dá a lóhùn pé, “Ọkùnrin kan ṣe àsè alẹ́ ńlá, ó sì pe ènìyàn púpọ̀.
17 La ora cinei, a trimis pe slujitorul său să le spună celor invitați: “Veniți, căci totul este gata acum.
Ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní wákàtí àsè alẹ́ náà láti sọ fún àwọn tí a ti pè pé, ‘Ẹ wá; nítorí ohun gbogbo ṣetán!’
18 Toți, ca unul singur, au început să se scuze. “Cel dintâi i-a spus: “Am cumpărat un câmp și trebuie să mă duc să-l văd. Te rog să mă scuzi'.
“Gbogbo wọn sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣe àwáwí ohun kan. ‘Èkínní wí fún un pé, mo ra ilẹ̀ kan, mo sì fẹ́ lọ wò ó wò, mo bẹ̀ ọ́ ṣe gáfárà fún mi.’
19 Altul a zis: “Am cumpărat cinci juguri de boi și trebuie să mă duc să le încerc. Te rog să mă scuzi.''
“Èkejì sì wí pé, ‘Mo ra àjàgà màlúù márùn-ún, mo sì ń lọ wò wọ́n wò: mo bẹ̀ ọ́ ṣe gáfárà fún mi.’
20 Altul a zis: “M-am căsătorit cu o nevastă și nu pot să vin.
“Ẹ̀kẹta sì wí pé, ‘Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, nítorí náà ni èmi kò fi lè wá.’
21 Și a venit robul acela și a spus aceste lucruri domnului său. Atunci stăpânul casei, mâniindu-se, a zis robului său: “Ieși repede pe străzile și pe ulițele cetății și adu pe cei săraci, schilozi, orbi și șchiopi.
“Ọmọ ọ̀dọ̀ náà sì padà dé, ó sọ nǹkan wọ̀nyí fún olúwa rẹ̀. Nígbà náà ni baálé ilé bínú, ó wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, ‘Jáde lọ sí ìgboro, àti sí òpópó ọ̀nà, kí o sì mú àwọn tálákà, àti àwọn amúnkùn ún, àti àwọn arọ, àti àwọn afọ́jú wá sí ìhín yìí.’
22 Robul a zis: “Doamne, s-a făcut cum ai poruncit și mai este loc.
“Ọmọ ọ̀dọ̀ náà sì wí pé, ‘Olúwa a ti ṣe bí o ti pàṣẹ, ààyè sì ń bẹ síbẹ̀.’
23 Domnul a zis robului: “Ieși pe drumuri și pe ulițe și silește-i să intre, ca să se umple casa mea.
“Olúwa náà sì wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ náà pé, ‘Jáde lọ sí òpópó, àti sí ọ̀nà ọgbà, kí o sì rọ̀ wọ́n láti wọlé wá, kí ilé mi lè kún.
24 Căci îți spun că niciunul dintre acei oameni care au fost invitați nu va gusta din cina mea.””
Nítorí mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn wọ̀nyí tí a ti pè, kì yóò tọ́wò nínú àsè ńlá mi!’”
25 O mare mulțime de oameni mergeau cu El. El s-a întors și le-a zis:
Àwọn ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn ń bá a lọ; ó sì yípadà, ó sì wí fún wọn pé,
26 “Dacă vine cineva la Mine și nu face abstracție de tatăl său, de mama sa, de soția sa, de copii, de frați și de surori, da, și chiar și de viața sa, nu poate fi ucenicul Meu.
“Bí ẹnìkan bá tọ̀ mí wá, tí kò sì kórìíra baba àti ìyá, àti aya, àti ọmọ, àti arákùnrin, àti arábìnrin, àní àti ọkàn ara rẹ̀ pẹ̀lú, kò lè ṣe ọmọ-ẹ̀yìn mi.
27 Oricine nu-și poartă propria cruce și nu vine după mine, nu poate fi discipolul meu.
Ẹnikẹ́ni tí kò bá ru àgbélébùú rẹ̀, kí ó sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn, kò lè ṣe ọmọ-ẹ̀yìn mi.
28 Căci care dintre voi, dorind să zidească un turn, nu stă mai întâi și numără costurile, ca să vadă dacă are destul pentru a-l termina?
“Nítorí ta ni nínú yín tí ń pète láti kọ́ ilé ìṣọ́, tí kì yóò kọ́kọ́ jókòó kí ó ṣírò iye owó rẹ̀, bí òun ní tó tí yóò fi parí rẹ̀.
29 Sau poate că, după ce a pus temelia și nu poate să o termine, toți cei care îl văd încep să râdă de el,
Kí ó má ba à jẹ́ pé nígbà tí ó bá fi ìpìlẹ̀ ilé sọlẹ̀ tan, tí kò lè parí rẹ̀ mọ́, gbogbo àwọn tí ó rí i a bẹ̀rẹ̀ sí í fi í ṣe ẹlẹ́yà.
30 spunând: “Omul acesta a început să zidească și nu a putut să termine”.
Wí pé, ‘Ọkùnrin yìí bẹ̀rẹ̀ sí kọ́ ilé, kò sì lè parí rẹ̀.’
31 Sau ce rege, când merge să se întâlnească cu un alt rege în război, nu se așează mai întâi și nu se gândește dacă este în stare cu zece mii de oameni să-l înfrunte pe cel care vine împotriva lui cu douăzeci de mii?
“Tàbí ọba wo ni ó ń lọ bá ọba mìíràn jà, tí kì yóò kọ́kọ́ jókòó, kí ó sì gbèrò bí yóò lè fi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá pàdé ẹni tí ń mú ogún ẹgbẹ̀rún bọ̀ wá ko òun lójú?
32 Sau altfel, pe când celălalt este încă la mare distanță, trimite un trimis și cere condiții de pace.
Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, nígbà tí onítọ̀hún bá sì wà ní òkèrè, òun a rán ikọ̀ sí i, a sì bẹ̀rẹ̀ àdéhùn àlàáfíà.
33 Așadar, oricine dintre voi care nu renunță la tot ceea ce are, nu poate fi discipolul meu.
Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni, ẹnikẹ́ni tí ó wù kí ó ṣe nínú yín, tí kò kọ ohun gbogbo tí ó ní sílẹ̀, kò lè ṣe ọmọ-ẹ̀yìn mi.
34 “Sarea este bună, dar dacă sarea devine plată și fără gust, cu ce o condimentezi?
“Iyọ̀ dára: ṣùgbọ́n bí iyọ̀ bá di òbu, kín ni a ó fi mú un dùn?
35 Eanu este potrivită nici pentru pământ, nici pentru grămada de gunoi de grajd. Ea este aruncată la gunoi. Cine are urechi de auzit, să audă.”
Kò yẹ fún ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò yẹ fún ààtàn; bí kò ṣe pé kí a kó o dànù. “Ẹni tí ó bá ní etí láti fi gbọ́ kí ó gbọ́.”

< Luca 14 >