< ЗАХАРИЯ 1 >
1 Ын луна а опта, ын анул ал дойля ал луй Дариус, кувынтул Домнулуй а ворбит пророкулуй Захария, фиул луй Берекия, фиул луй Идо, астфел:
Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
2 „Домнул С-а мыният фоарте таре пе пэринций воштри.
“Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
3 Спуне-ле дар: ‘Аша ворбеште Домнул оштирилор: «Ынтоарчеци-вэ ла Мине», зиче Домнул оштирилор, «ши Мэ вой ынтоарче ши Еу ла вой», зиче Домнул оштирилор.
Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
4 «Ну фиць ка пэринций воштри, кэрора ле ворбяу пророчий де май ынаинте, зикынд: ‹Аша ворбеште Домнул оштирилор: „Ынтоарчеци-вэ де ла кэиле воастре челе реле, де ла фаптеле воастре челе реле!”› Дар н-ау аскултат ши н-ау луат аминте ла Мине», зиче Домнул.
Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
5 «Унде сунт акум пэринций воштри? Ши путяу пророчий сэ трэяскэ вешник?
Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
6 Тотушь кувинтеле Меле ши порунчиле пе каре ле дэдусем служиторилор Мей, пророчий, ка сэ ле вестяскэ, н-ау атинс еле пе пэринций воштри? Ши атунч ей с-ау ынторс ши ау зис: ‹Домнул оштирилор не-а фэкут кум хотэрысе сэ не факэ, дупэ кэиле ши фаптеле ноастре!›»’”
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín? “Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’”
7 Ын а доуэзечь ши патра зи а луний а унспрезечя, каре есте луна Шебат, ын анул ал дойля ал луй Дариус, кувынтул Домнулуй а ворбит пророкулуй Захария, фиул луй Берекия, фиул луй Идо, астфел:
Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
8 М-ам уйтат ноаптя ши ятэ кэ ун ом ера кэларе пе ун кал рошу ши стэтя ынтре мирць ынтр-ун умбрар; ын урма луй ерау ниште кай роший, мурӂь ши албь.
Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
9 Ам ынтребат: „Че ынсямнэ каий ачештя, домнул меу?” Ши ынӂерул каре ворбя ку мине мь-а зис: „Ыць вой арэта че ынсямнэ каий ачештя!”
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?” Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”
10 Омул каре стэтя ынтре мирць а луат кувынтул ши а зис: „Ачештя сунт ачея пе каре й-а тримис Домнул сэ кутреере пэмынтул!”
Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
11 Ши ей ау ворбит Ынӂерулуй Домнулуй, каре стэтя ынтре мирць, ши ау зис: „Ам кутреерат пэмынтул ши ятэ кэ тот пэмынтул есте ын паче ши лиништит!”
Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
12 Атунч Ынӂерул Домнулуй а луат кувынтул ши а зис: „Доамне ал оштирилор, пынэ кынд ну вей авя милэ де Иерусалим ши де четэциле луй Иуда, пе каре Те-ай мыният ын ачешть шаптезечь де ань?”
Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
13 Домнул а рэспунс ку ворбе буне, ку ворбе де мынгыере, ынӂерулуй каре ворбя ку мине.
Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
14 Ши ынӂерул каре ворбя ку мине мь-а зис: „Стригэ ши зи: ‘Аша ворбеште Домнул оштирилор: «Сунт плин де о маре ӂелозие пентру Иерусалим ши пентру Сион
Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
15 ши сунт плин де о маре мыние ымпотрива нямурилор ынгымфате, кэч Мэ мыниясем нумай пуцин, дар еле ау ажутат спре ненорочире.»
Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
16 Де ачея аша ворбеште Домнул: «Мэ ынторк ку ындураре кэтре Иерусалим; Каса Мя ва фи зидитэ ярэшь ын ел ши фуния де мэсурат се ва ынтинде асупра Иерусалимулуй.»’
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
17 Стригэ дин ноу ши зи: ‘Аша ворбеште Домнул оштирилор: «Четэциле Меле вор авя ярэшь белшуг де бунэтэць, Домнул ва мынгыя ярэшь Сионул, ва алеӂе ярэшь Иерусалимул.»’”
“Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’”
18 Ам ридикат окий ши м-ам уйтат, ши ятэ кэ ерау патру коарне.
Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
19 Ам ынтребат ынӂерул каре ворбя ку мине: „Че ынсямнэ коарнеле ачестя?” Ши ел мь-а зис: „Ачестя сунт коарнеле каре ау рисипит пе Иуда, пе Исраел ши Иерусалимул.”
Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?” Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”
20 Домнул мь-а арэтат патру ферарь.
Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
21 Еу ам ынтребат: „Че вор сэ факэ ачештя?” Ши ел а зис: „Ачештя вин сэ сперие коарнеле каре ау рисипит пе Иуда, де н-а май путут ридика нимень капул; ферарий ачештя ау венит сэ сперие ши сэ тае коарнеле нямурилор каре ау ридикат корнул ымпотрива цэрий луй Иуда ка сэ-й рисипяскэ локуиторий.”
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?” O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”