< ОБАДИЯ 1 >

1 Пророчия луй Обадия. Аша ворбеште Домнул Думнезеу деспре Едом: (Ной ам аузит о весте дин партя Домнулуй ши ун сол а фост тримис ку еа принтре нямурь, зикынд: „Скулаци-вэ сэ мерӂем ымпотрива Едомулуй ка сэ не рэзбоим ку ел!”)
Ìran ti Obadiah. Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu. Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, a sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé, “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”
2 „Ятэ, те вой фаче мик принтре нямурь, вей фи чел май диспрецуит.
“Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí; ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
3 Кэч мындрия инимий тале те-а дус ын рэтэчире пе тине, каре локуешть ын крэпэтуриле стынчилор ши домнешть ын ынэлциме, де ачея ту зичь ын тине ынсуць: ‘Чине мэ ва арунка ла пэмынт?’
Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ, ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta, tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga, ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé, ‘Ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
4 Дар, кяр дакэ ай локуи тот атыт де сус ка вултурул, кяр дакэ ць-ай ашеза куйбул ынтре стеле, тот те вой арунка жос ши де аколо”, зиче Домнул.
Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì, bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,” ni Olúwa wí.
5 „Дакэ ар фи интрат ла тине ниште хоць сау ниште тылхарь де ноапте – кум ешть де пустиит! – ар фи луат ей оаре май мулт декыт ар фи путут? Дакэ ар фи венит ниште кулегэторь де вие ла тине, н-ар фи лэсат ей ничун стругуре пе урмэ?
“Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá, bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru, Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́, wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́? Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá, wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
6 Вай! Че скормонит есте Есау! Кум и с-ау дескоперит комориле!
Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau, tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
7 Тоць чей униць ку тине те-ау изгонит ынапой пынэ ла хотар, приетений тэй те-ау ыншелат ши те-ау стэпынит. Чей че мынкау дин пыня та ць-ау ынтинс курсе пе каре ну ле-ай бэгат де сямэ!
Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ; àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”
8 Оаре”, зиче Домнул, „ну вой перде Еу ын зиуа ачея пе чей ынцелепць дин Едом ши причеперя дин мунтеле луй Есау?
Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà, Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run, àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
9 Витежий тэй, Темане, се вор ынспэймынта, пентру ка тоць чей дин мунтеле луй Есау сэ пярэ ын мэчел.
A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, ìwọ Temani, gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
10 Дин причина силничией фэкуте ымпотрива фрателуй тэу Иаков, вей фи акоперит де рушине ши вей фи нимичит ку десэвыршире пентру тотдяуна.
Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ, ìtìjú yóò bò ọ, a ó sì pa ọ run títí láé.
11 Кэч ын зиуа кынд стэтяй ын фаца луй, ын зиуа кынд стрэиний ый луау аверя, кынд стрэиний интрау пе порциле луй ши арункау сорцул асупра Иерусалимулуй, ши ту ерай атунч ка унул дин ей!
Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan, ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ, tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ, tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu, ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
12 Ну требуя сэ те уйць мулцумит ла зиуа фрателуй тэу, ын зиуа ненорочирий луй, ну требуя сэ те букурь де копиий луй Иуда ын зиуа пеирий лор ши ну требуя сэ ворбешть ку семецие ын зиуа стрымторэрий!
Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ, ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀ ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda, ní ọjọ́ ìparun wọn ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
13 Нич ну требуя сэ интри пе порциле попорулуй Меу ын зиуа ненорочирий луй, нич ну требуя сэ те букурь де ненорочиря луй ын зиуа прэпэдулуй луй ши ну требуя сэ пуй мына пе богэцииле луй ын зиуа прэпэдулуй луй!
Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀ nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó, ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
14 Ну требуя сэ стай ла рэспынтий, ка сэ нимичешть пе фугарий луй, ши нич ну требуя сэ дай ын мына врэжмашулуй пе чей че скэпасерэ дин ел ын зиуа неказулуй луй!
Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò. Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
15 Кэч зиуа Домнулуй есте апроапе пентру тоате нямуриле. Кум ай фэкут, аша ци се ва фаче; фаптеле тале се вор ынтоарче асупра капулуй тэу.
“Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé lórí gbogbo àwọn kèfèrí. Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà; ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
16 Кэч, дупэ кум аць бэут пахарул мынией вой, чей де пе мунтеле Меу чел сфынт, тот аша тоате нямуриле ыл вор бя некурмат; вор бя, вор сорби дин ел ши вор фи ка ши кынд н-ар фи фост ничодатэ.
Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí; wọn yóò mu ún ní àmutẹ́rùn wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò mu ún rí.
17 Дар мынтуиря ва фи пе мунтеле Сионулуй, ел ва фи сфынт ши каса луй Иаков ышь ва луа ынапой мошииле.
Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni, wọn yóò sì jẹ́ mímọ́, àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn.
18 Каса луй Иаков ва фи ун фок ши каса луй Иосиф, о флакэрэ, дар каса луй Есау ва фи мириштя пе каре о вор апринде ши о вор мистуи, ши ну ва май рэмыне ничунул дин каса луй Есау”, кэч Домнул а ворбит.
Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko wọn yóò fi iná sí i, wọn yóò jo run. Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.” Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
19 Чей де ла мязэзи вор стэпыни мунтеле луй Есау ши чей дин кымпие, цара филистенилор; вор стэпыни ши цинутул луй Ефраим ши ал Самарией, ши Бениамин ва стэпыни Галаадул.
Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau, àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní. Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria; Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
20 Дар принший де рэзбой ай ачестей оштиря копиилор луй Исраел вор стэпыни цара канааницилор пынэ ла Сарепта ши принший де рэзбой ай Иерусалимулуй каре сунт ла Сефарад вор стэпыни четэциле де мязэзи.
Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati; àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní.
21 Избэвиторий се вор суи пе мунтеле Сионулуй ка сэ жудече мунтеле луй Есау. Дар ымпэрэция ва фи а Домнулуй.
Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau. Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.

< ОБАДИЯ 1 >