< Лука 16 >
1 Исус а май спус ученичилор Сэй: „Ун ом богат авя ун исправник, каре а фост пырыт ла ел кэ-й рисипеште аверя.
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pẹ̀lú pé, “Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan wà, tí ó ní ìríjú kan; òun náà ni wọ́n fi sùn ún pé, ó ti ń fi ohun ìní rẹ̀ ṣòfò.
2 Ел л-а кемат ши й-а зис: ‘Че ауд еу ворбинду-се деспре тине? Дэ-ць сокотялэ де испрэвничия та, пентру кэ ну май поць фи исправник.’
Nígbà tí ó sì pè é, ó wí fún un pé, ‘Èéṣe tí èmi fi ń gbọ́ èyí sí ọ? Ṣírò iṣẹ́ ìríjú rẹ; nítorí ìwọ kò lè ṣe ìríjú mi mọ́.’
3 Исправникул шь-а зис: ‘Че ам сэ фак дакэ ымь я стэпынул испрэвничия? Сэ сап, ну пот; сэ чершеск, мь-е рушине.
“Ìríjú náà sì wí nínú ara rẹ̀ pé, ‘Èwo ni èmi ó ṣe? Nítorí tí olúwa mi gba iṣẹ́ ìríjú lọ́wọ́ mi: èmi kò le ṣiṣẹ́ oko, bẹ́ẹ̀ ni ojú ń tì mí láti ṣagbe.
4 Штиу че ам сэ фак, пентру ка, атунч кынд вой фи скос дин испрэвничие, ей сэ мэ примяскэ ын каселе лор.’
Mo mọ èyí tí èmi yóò ṣe, nígbà tí a bá mú mi kúrò níbi iṣẹ́ ìríjú, kí àwọn ènìyàn le gbà mí sínú ilé wọn.’
5 А кемат пе фиекаре дин даторничий стэпынулуй сэу ши а зис челуй динтый: ‘Кыт ешть датор стэпынулуй меу?’
“Ó sì pe àwọn ajigbèsè olúwa rẹ̀ sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí fún èkínní pé, ‘Èló ni ìwọ jẹ olúwa mi?’
6 ‘О сутэ де мэсурь де унтделемн’, а рэспунс ел. Ши й-а зис: ‘Я-ць записул ши шезь деграбэ де скрие чинчзечь.’
“Ó sì wí pé, ‘Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún òsùwọ̀n òróró.’ “Ó sì wí fún un pé, ‘Mú ìwé rẹ, sì jókòó nísinsin yìí, kí o sì kọ àádọ́ta lé ní irinwó.’
7 Апой а зис алтуя: ‘Дар ту кыт ешть датор?’ ‘О сутэ де мэсурь де грыу’, а рэспунс ел. Ши й-а зис: ‘Я-ць записул ши скрие оптзечь.’
“Nígbà náà ni ó sì bi ẹnìkejì pé, ‘Èló ni ìwọ jẹ?’ “Òun sì wí pé, ‘Ẹgbẹ̀rún òsùwọ̀n alikama.’ “Ó sì wí fún un pé, ‘Mú ìwé rẹ, kí o sì kọ ẹgbẹ̀rin.’
8 Стэпынул луй а лэудат пе исправникул недрепт, пентру кэ лукрасе ынцелепцеште. Кэч фиий вякулуй ачестуя, фацэ де семений лор, сунт май ынцелепць декыт фиийлуминий. (aiōn )
“Olúwa rẹ̀ sì yin aláìṣòótọ́ ìríjú náà, nítorí tí ó fi ọgbọ́n ṣe é, àwọn ọmọ ayé yìí sá à gbọ́n ní ìran wọn ju àwọn ọmọ ìmọ́lẹ̀ lọ. (aiōn )
9 Ши Еу вэ зик: Фачеци-вэприетень ку ажуторул богэциилор недрепте, пентру ка, атунч кынд вець мури, сэ вэ примяскэ ын кортуриле вешниче. (aiōnios )
Èmi sì wí fún yín, ẹ fi ọrọ̀ ayé yìí yan ọ̀rẹ́ fún ara yín pé, nígbà tí o ba lọ, kí wọn kí ó le gbà yín sí ibùjókòó wọn títí ayé. (aiōnios )
10 Чинеесте крединчос ын челе май мичь лукрурь есте крединчос ши ын челе марь; ши чине есте недрепт ын челе май мичь лукрурь есте недрепт ши ын челе марь.
“Ẹni tí ó bá ṣe olóòtítọ́ nínú ohun kínkínní, ó ṣe olóòtítọ́ ní púpọ̀ pẹ̀lú: ẹni tí ó bá sì ṣe aláìṣòótọ́ ní ohun kínkínní, ó ṣe aláìṣòótọ́ ní ohun púpọ̀ pẹ̀lú.
11 Деч, дакэ н-аць фост крединчошь ын богэцииленедрепте, чине вэ ва ынкрединца адевэрателе богэций?
Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin kò bá ti jẹ́ olóòtítọ́ nínú ọrọ̀ ayé yìí, ta ni yóò fi ọ̀rọ̀ tòótọ́ fún yín?
12 Ши дакэ н-аць фост крединчошь ын лукрул алтуя, чине вэ ва да че есте ал востру?
Bí ẹ̀yin kò bá sì ti jẹ́ olóòtítọ́ nínú ohun tí í ṣe ti ẹlòmíràn, ta ni yóò fún yín ní ohun tí í ṣe ti ẹ̀yin tìkára yín?
13 Ничослугэ ну поате служи ла дой стэпынь; кэч сау ва уры пе унул ши ва юби пе челэлалт, сау ва цине нумай ла унул ши ва несокоти пе челэлалт. Ну путець служи луй Думнезеу ши луй Мамона.”
“Kò sì í ẹnìkan tí ó lè sin ọ̀gá méjì. Òun yóò yà kórìíra ọ̀kan tí yóò fẹ́ràn èkejì, tàbí kí ó fi ara mọ́ ọ̀kan kí ó sì yan èkejì ní ìpọ̀sí. Ẹ̀yin kò lè sin Ọlọ́run àti owó papọ̀.”
14 Фарисеий, каре ерау юбиторь де бань, аскултау ши ей тоате лукруриле ачестя ши ышь бэтяу жок де Ел.
Àwọn Farisi, tí wọ́n ní ojúkòkòrò sì gbọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, wọ́n sì yọ ṣùtì sí i.
15 Исус ле-а зис: „Вой кэутаць сэ вэ арэтацьнеприхэниць ынаинтя оаменилор, дар Думнезеувэ куноаште инимиле; пентру кэ чеесте ынэлцат ынтре оамень есте о урычуне ынаинтя луй Думнезеу.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni àwọn tí ń dá àre fún ara yín níwájú ènìyàn; ṣùgbọ́n Ọlọ́run mọ ọkàn yín, nítorí ohun ti a gbéga lójú ènìyàn, ìríra ni níwájú Ọlọ́run.
16 Леӂяши пророчий ау цинут пынэ ла Иоан; де атунч ынкоаче, Евангелия Ымпэрэцией луй Думнезеу се проповэдуеште: ши фиекаре, ка сэ интре ын еа, дэ нэвалэ.
“Òfin àti àwọn wòlíì ń bẹ títí di ìgbà Johanu, Láti ìgbà náà wá ni a ti ń wàásù ìròyìn ayọ̀ ìjọba Ọlọ́run, olúkúlùkù sì ń fi ipá wọ inú rẹ̀.
17 Естемай лесне сэ трякэ черул ши пэмынтул декыт сэ кадэ о сингурэ фрынтурэ де словэ дин Леӂе.
Ṣùgbọ́n ó rọrùn fún ọ̀run òun ayé láti kọjá lọ, ju kí èyí tí ó kéré jù nínú òfin kí ó yẹ.
18 Орьчинеышь ласэ неваста ши я пе алта де невастэ прякурвеште; ши чине я де невастэ пе чя лэсатэ де бэрбатул ей прякурвеште.”
“Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì gbé ẹlòmíràn ní ìyàwó, ó ṣe panṣágà: ẹnikẹ́ni tí ó bá sì gbé, ẹni tí ọkọ rẹ̀ kọ̀sílẹ̀ ní ìyàwó náà, ó ṣe panṣágà.
19 „Ера ун ом богат, каре се ымбрэка ын порфирэ ши ин субцире; ши ын фиекаре зи дучя о вяцэ плинэ де веселие ши стрэлучире.
“Ǹjẹ́ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan wà, tí ó ń wọ aṣọ elése àlùkò àti aṣọ àlà dáradára, a sì máa jẹ dídùndídùn lójoojúmọ́.
20 Ла уша луй, зэчя ун сэрак нумит Лазэр, плин де бубе.
Alágbe kan sì wà tí à ń pè ní Lasaru, tí wọ́n máa ń gbé wá kalẹ̀ lẹ́bàá ọ̀nà ilé rẹ̀, ó kún fún ooju,
21 Ши доря мулт сэ се сатуре ку фиримитуриле каре кэдяу де ла маса богатулуй; пынэ ши кыний веняу ши-й линӂяу бубеле.
Òun a sì máa fẹ́ kí a fi èérún tí ó ti orí tábìlì ọlọ́rọ̀ bọ́ sílẹ̀ bọ́ òun, àwọn ajá sì wá, wọ́n sì fá a ní ooju lá.
22 Ку время, сэракул а мурит ши а фост дус де ынӂерь ын сынул луй Авраам. А мурит ши богатул ши л-ау ынгропат.
“Ó sì ṣe, alágbe kú, a sì ti ọwọ́ àwọn angẹli gbé e lọ sí oókan àyà Abrahamu: ọlọ́rọ̀ náà sì kú pẹ̀lú, a sì sin ín;
23 Пе кынд ера ел ын Локуинца морцилор, ын кинурь, шь-а ридикат окий ын сус, а вэзут де департе пе Авраам ши пе Лазэр ын сынул луй (Hadēs )
Ní ipò òkú ni ó gbé ojú rẹ̀ sókè, ó ń bẹ nínú ìjìyà oró, ó sì rí Abrahamu ní òkèrè, àti Lasaru ní oókan àyà rẹ̀. (Hadēs )
24 ши а стригат: ‘Пэринте Аврааме, фие-ць милэ де мине ши тримите пе Лазэр сэ-шь ынмоае вырфул деӂетулуй ын апэ ши сэ-мь рэкоряскэлимба, кэч грозав сунткинуит ын вэпая ачаста.’
Ó sì ké, ó wí pé, ‘Baba Abrahamu, ṣàánú fún mi, kí o sì rán Lasaru, kí ó tẹ orí ìka rẹ̀ bọ omi, kí ó sì fi tù mí ní ahọ́n; nítorí èmi ń joró nínú ọ̀wọ́n iná yìí.’
25 ‘Фиуле’, й-а рэспунс Авраам, ‘аду-цьаминте кэ, ын вяца та, ту ць-ай луат лукруриле буне, ши Лазэр шь-а луат пе челе реле; акум, аич, ел есте мынгыят, яр ту ешть кинуит.
“Ṣùgbọ́n Abrahamu wí pé, ‘Ọmọ, rántí pé, nígbà ayé rẹ, ìwọ ti gba ohun rere tìrẹ, àti Lasaru ohun búburú, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ara rọ̀ ọ́, ìwọ sì ń joró.
26 Пе лынгэ тоате ачестя, ынтре ной ши ынтре вой есте о прэпастие маре, аша ка чей че ар вря сэ трякэ де аич ла вой сау де аколо ла ной сэ ну поатэ.’
Àti pẹ̀lú gbogbo èyí, a gbé ọ̀gbun ńlá kan sí agbede-méjì àwa àti ẹ̀yin, kí àwọn tí ń fẹ́ má ba á le rékọjá láti ìhín lọ sọ́dọ̀ yín, kí ẹnikẹ́ni má sì le ti ọ̀hún rékọjá tọ̀ wá wá.’
27 Богатул а зис: ‘Рогу-те дар, пэринте Аврааме, сэ тримиць пе Лазэр ын каса татэлуй меу,
“Ó sì wí pé, ‘Ǹjẹ́ mo bẹ̀ ọ́, baba, kí ìwọ kí ó rán Lasaru lọ sí ilé baba mi,
28 кэч ам чинч фраць, ши сэ ле адеверяскэ ачесте лукрурь, ка сэ ну винэ ши ей ын ачест лок де кин.’
nítorí mo ní arákùnrin márùn-ún; kí ó lè rò fún wọn kí àwọn kí ó má ba á wá sí ibi oró yìí pẹ̀lú.’
29 Авраам а рэспунс: ‘Аупе Мойсе ши пе пророчь; сэ аскулте де ей.’
“Abrahamu sì wí fún un pé, ‘Wọ́n ní Mose àti àwọn wòlíì; kí wọn kí ó gbọ́ tiwọn.’
30 ‘Ну, пэринте Аврааме’, а зис ел, ‘чи, дакэ се ва дуче ла ей чинева дин морць, се вор покэи.’
“Ó sì wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, Abrahamu baba; ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ti inú òkú tọ̀ wọ́n lọ, wọn ó ronúpìwàdà.’
31 Ши Авраам й-а рэспунс: ‘Дакэ ну аскултэ пе Мойсе ши пе пророчь, ну вор креде нич кярдакэ ар ынвия чинева дин морць.’”
“Ó sì wí fún un pé, ‘Bí wọn kò bá gbọ́ ti Mose àti ti àwọn wòlíì, a kì yóò yí wọn ní ọkàn padà bí ẹnìkan tilẹ̀ ti inú òkú dìde.’”