< Лука 13 >

1 Ын время ачея, ау венит уний ши ау историсит луй Исус че се ынтымпласе унор галилеень, ал кэрор сынӂе ыл аместекасе Пилат ку жертфеле лор.
Àwọn kan sì wá ní àkókò náà tí ó sọ ti àwọn ará Galili fún un, ẹ̀jẹ̀ ẹni tí Pilatu dàpọ̀ mọ́ ẹbọ wọn.
2 „Кредець вой”, ле-а рэспунс Исус, „кэ ачешть галилеень ау фост май пэкэтошь декыт тоць чейлалць галилеень, пентру кэ ау пэцит астфел?
Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ṣe bí àwọn ará Galili wọ̀nyí ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ará Galili lọ, nítorí wọ́n jẹ irú ìyà bá-wọ̀n-ọn-nì?
3 Еу вэ спун: ну, чи, дакэ ну вэ покэиць, тоць вець пери ла фел.
Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pẹ̀lú ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
4 Сау ачей оптспрезече иншь песте каре а кэзут турнул дин Силоам ши й-а оморыт, кредець кэ ау фост май пэкэтошь декыт тоць чейлалць оамень каре локуяу ын Иерусалим?
Tàbí àwọn méjìdínlógún, tí ilé ìṣọ́ ní Siloamu wó lù, tí ó sì pa wọ́n, ẹ̀yin ṣe bí wọ́n ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ ní Jerusalẹmu lọ?
5 Еу вэ спун: ну, чи, дакэ ну вэ покэиць, тоць вець пери ла фел.”
Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.”
6 Ел а спус ши пилда ачаста: „Уном авя ун смокин сэдит ын вия са. А венит сэ кауте род ын ел, ши н-а гэсит.
Ó sì pa òwe yìí fún wọn pé, “Ọkùnrin kan ní igi ọ̀pọ̀tọ́ kan tí a gbìn sí ọgbà àjàrà rẹ̀; ó sì dé, ó ń wá èso lórí rẹ̀, kò sì rí nǹkan.
7 Атунч а зис виерулуй: ‘Ятэ кэ сунт трей ань де кынд вин ши каут род ын смокинул ачеста, ши ну гэсеск. Тае-л. Ла че сэ май куприндэ ши пэмынтул деӂяба?’
Ó sì wí fún olùṣọ́gbà rẹ̀ pé, ‘Sá à wò ó, láti ọdún mẹ́ta ni èmi ti ń wá í wo èso lórí igi ọ̀pọ̀tọ́ yìí, èmi kò sì rí nǹkan: ké e lulẹ̀; èéṣe tí ó fi ń gbilẹ̀ lásán pẹ̀lú?’
8 ‘Доамне’, й-а рэспунс виерул, ‘май ласэ-л ши анул ачеста; ам сэ-л сап де жур ымпрежур ши ам сэ-й пун гуной ла рэдэчинэ.
“Ó sì dáhùn ó wí fún un pé, ‘Olúwa, jọ̀wọ́ rẹ̀ ní ọdún yìí pẹ̀lú, títí èmi ó fi tu ilẹ̀ ìdí rẹ̀ yíká, títí èmi ó sì fi bu ìlẹ̀dú sí i.
9 Поате кэ де акум ынаинте ва фаче род; дакэ ну, ыл вей тэя.’”
Bí ó bá sì so èso, o dara bẹ́ẹ̀: bí kò bá sì so, ǹjẹ́ lẹ́yìn èyí nì kí ìwọ kí ó ké e lulẹ̀.’”
10 Исус ынвэца пе нород ынтр-о синагогэ ын зиуа Сабатулуй.
Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu kan ní ọjọ́ ìsinmi.
11 Ши аколо ера о фемее стэпынитэ де оптспрезече ань де ун дух де непутинцэ; ера гырбовэ ши ну путя ничдекум сэ-шь ындрепте спателе.
Sì kíyèsi i, obìnrin kan wà níbẹ̀ tí ó ní ẹ̀mí àìlera, láti ọdún méjìdínlógún wá, ẹni tí ó tẹ̀ tán, tí kò le gbé ara rẹ̀ sókè bí ó ti wù kí ó ṣe.
12 Кынд а вэзут-о Исус, а кемат-о ши й-а зис: „Фемее, ешть дезлегатэ де непутинца та.”
Nígbà tí Jesu rí i, ó pè é sí ọ̀dọ̀, ó sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, a tú ọ sílẹ̀ lọ́wọ́ àìlera rẹ.”
13 Шь-а ынтинс мыниле песте еа: ындатэ с-а ындрептат ши слэвя пе Думнезеу.
Ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ lé e, Lójúkan náà a sì ti sọ ọ́ di títọ́, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo.
14 Дар фрунташул синагоӂий, мыният кэ Исус сэвыршисе виндекаря ачаста ын зиуа Сабатулуй, а луат кувынтул ши а зис нородулуй: „Сунт шасе зиле ын каре требуе сэ лукрезе омул; вениць дар ын ачесте зиле сэ вэ виндекаць, ши ну ын зиуа Сабатулуй!”
Olórí Sinagọgu sì kún fún ìrunú, nítorí tí Jesu mú ni láradá ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì wí fún ìjọ ènìyàn pé, ọjọ́ mẹ́fà ní ń bẹ tí a fi í ṣiṣẹ́, nínú wọn ni kí ẹ̀yin kí ó wá kí á ṣe dídá ara yín, kí ó má ṣe ní ọjọ́ ìsinmi.
15 „Фэцарничилор”, й-а рэспунс Домнул; „оаре ын зиуа Сабатулуй ну-шь дезлягэ фиекаредин вой боул сау мэгарул де ла есле ши-л дуче де-л адапэ?
Nígbà náà ni Olúwa dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀yin àgàbàgebè, olúkúlùkù yín kì í tú màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ kúrò ní ibùso, kì í sì í fà á lọ mu omi ní ọjọ́ ìsinmi.
16 Дар фемея ачаста, кареесте о фийкэ а луй Авраам ши пе каре Сатана о циня легатэ де оптспрезече ань, ну требуя оаре сэ фие дезлегатэ де легэтура ачаста ын зиуа Сабатулуй?”
Kò sì yẹ kí a tú obìnrin yìí tí í ṣe ọmọbìnrin Abrahamu sílẹ̀ ní ìdè yìí ní ọjọ́ ìsinmi, ẹni tí Satani ti dè, sá à wò ó láti ọdún méjìdínlógún yìí wá?”
17 Пе кынд ворбя Ел астфел, тоць потривничий Луй ау рэмас рушинаць; ши нородул се букура де тоате лукруриле минунате пе каре ле фэчя Ел.
Nígbà tí ó sì wí nǹkan wọ̀nyí, ojú ti gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn sì yọ̀ fún ohun ìyanu gbogbo tí ó ṣe.
18 Ел а май зис: „Ку че се асямэнэ Ымпэрэция луй Думнезеу ши ку че о вой асемэна?
Ó sì wí pé, “Kín ni ìjọba Ọlọ́run jọ? Kín ni èmi ó sì fiwé?
19 Се асямэнэ ку ун грэунте де муштар пе каре л-а луат ун ом ши л-а арункат ын грэдина са; ел а крескут, с-а фэкут копак маре, ши пэсэриле черулуй шь-ау фэкут куйбурь ын рамуриле луй.”
Ó dàbí hóró musitadi, tí ọkùnrin kan mú, tí ó sì sọ sínú ọgbà rẹ̀; tí ó sì hù, ó sì di igi ńlá; àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ń gbé orí ẹ̀ka rẹ̀.”
20 Ел а зис ярэшь: „Ку че вой асемэна Ымпэрэция луй Думнезеу?
Ó sì tún wí pé, “Kín ni èmi ìbá fi ìjọba Ọlọ́run wé?
21 Се асямэнэ ку алуатул пе каре л-а луат о фемее ши л-а пус ын трей мэсурь де фэинэ, пынэ с-а доспит тоатэ.”
Ó dàbí ìwúkàrà, tí obìnrin kan mú, tí ó fi sínú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun mẹ́ta, títí gbogbo rẹ̀ ó fi di wíwú.”
22 Исус умбла прин четэць ши прин сате, ынвэцынд пе нород ши кэлэторинд спре Иерусалим.
Ó sì ń la àárín ìlú àti ìletò lọ, ó ń kọ́ni, ó sì ń rìn lọ sí Jerusalẹmu.
23 Чинева Й-а зис: „Доамне, оаре пуцинь сунт чей че сунт пе каля мынтуирий?” Ел ле-а рэспунс:
Ẹnìkan sì bi í pé, Olúwa, díẹ̀ ha kọ ni àwọn tí a ó gbàlà? Ó sì wí fún wọn pé,
24 „Невоици-вэсэ интраць пе уша чя стрымтэ. Кэч вэ спун кэ мулцьвор кэута сэ интре, ши ну вор путя.
“Ẹ làkàkà láti gba ojú ọ̀nà tóóró wọlé, nítorí mo wí fún yín, ènìyàn púpọ̀ ni yóò wá ọ̀nà láti wọ̀ ọ́, wọn kì yóò sì lè wọlé.
25 Одатэче Стэпынул касей Се ва скула ши ваынкуя уша, ши вой вець фи афарэ ши вець ынчепе сэ батець ла ушэ ши сэ зичець: ‘Доамне, Доамне, дескиде-не!’ дрепт рэспунс, Ел вэ ва зиче: ‘Нуштиу де унде сунтець.’
Nígbà tí baálé ilé bá dìde lẹ́ẹ̀kan fùú, tí ó bá sí ti ìlẹ̀kùn, ẹ̀yin ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í dúró lóde, tí ẹ ó máa kan ìlẹ̀kùn, wí pé, ‘Olúwa, Olúwa, ṣí i fún wa!’ “Òun ó sì dáhùn wí fún yín pé, ‘Èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mọ̀ yín.
26 Атунч вець ынчепе сэ зичець: ‘Ной ам мынкат ши ам бэут ын фаца Та ши ын улицеле ноастре ай ынвэцат пе нород.’
“Nígbà náà ni ẹ̀yin ó bẹ̀rẹ̀ sí wí pé, ‘Àwa ti jẹ, àwa sì ti mu níwájú rẹ, ìwọ sì kọ́ni ní ìgboro ìlú wa.’
27 ШиЕл ва рэспунде: ‘Вэ спун кэ ну штиу де унде сунтець; депэртаци-вэде ла Мине, вой тоць лукрэторий фэрэделеӂий.’
“Òun ó sì wí pé, ‘Èmi wí fún yín èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá; ẹ lọ kúrò lọ́dọ̀ mi gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.’
28 Ворфи плынсул ши скрышниря динцилор кындвець ведя пе Авраам, пе Исаак ши пе Иаков, ши пе тоць пророчий ын Ымпэрэция луй Думнезеу, яр пе вой, скошь афарэ.
“Níbẹ̀ ni ẹkún àti ìpayínkeke yóò wà, nígbà tí ẹ̀yin ó rí Abrahamu, àti Isaaki, àti Jakọbu, àti gbogbo àwọn wòlíì, ní ìjọba Ọlọ́run, tí a ó sì ti ẹ̀yin sóde.
29 Вор вени де ла рэсэрит ши де ла апус, де ла мязэноапте ши де ла мязэзи ши вор шедя ла масэ ын Ымпэрэция луй Думнезеу.
Wọn ó sì ti ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti ìwọ̀-oòrùn wá, àti láti àríwá, àti gúúsù wá, wọn ó sì jókòó ní ìjọba Ọlọ́run.
30 Ши ятэкэ сунт уний дин чей де пе урмэ, каре вор фи чей динтый ши сунт уний дин чей динтый, каре вор фи чей де пе урмэ.”
Sì wò ó, àwọn ẹni ẹ̀yìn ń bẹ tí yóò di ẹni iwájú, àwọn ẹni iwájú ń bẹ tí yóò di ẹni ẹ̀yìn.”
31 Ын ачеяшь зи, ау венит кыцьва фарисей ши Й-ау зис: „Плякэ ши ду-Те де аич, кэч Ирод вря сэ Те омоаре.”
Ní wákàtí kan náà, díẹ̀ nínú àwọn Farisi tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Jáde, kí ìwọ sì lọ kúrò níhìn-ín yìí: nítorí Herodu ń fẹ́ pa ọ́.”
32 „Дучеци-вэ”, ле-а рэспунс Ел, „ши спунець вулпий ачелея: Ятэ кэ скот драчий ши сэвыршеск виндекэрь астэзь ши мыне, яр а трея зи войиспрэви.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ, kí ẹ̀yin sì sọ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ náà pé, ‘Kíyèsi i, èmi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, èmi ń ṣe ìmúláradá lónìí àti lọ́la, àti ní ọjọ́ mẹ́ta èmi ó ṣe àṣepé.’
33 Дар требуе сэ умблу астэзь, мыне ши поймыне, фииндкэ ну се поате ка ун пророк сэ пярэ афарэ дин Иерусалим.
Ṣùgbọ́n èmi kò jẹ́ má rìn lónìí, àti lọ́la, àti ní ọ̀túnla: dájúdájú wòlíì kan ki yóò ṣègbé lẹ́yìn odi Jerusalẹmu.
34 Иерусалиме, Иерусалиме, каре оморь пе пророчь ши учизь ку петре пе чей тримишь ла тине; де кыте орь ам врут сэ стрынг пе фиий тэй кум ышь стрынӂе гэина пуий суб арипь, ши н-аць врут!
“Jerusalẹmu, Jerusalẹmu, ìwọ tí o pa àwọn wòlíì, tí o sì sọ òkúta lu àwọn tí a rán sí ọ pa; nígbà mélòó ni èmi ń fẹ́ ràgà bo àwọn ọmọ rẹ, bí àgbébọ̀ adìyẹ ti í ràgà bo àwọn ọmọ rẹ̀ lábẹ́ apá rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́!
35 Ятэ кэ висе ва лэса каса пустие, дар вэ спун кэ ну Мэ вець май ведя пынэ вець зиче: ‘Бинекувынтатесте Чел че вине ын Нумеле Домнулуй!’”
Sá wò ó, a fi ilé yín sílẹ̀ fún yín ní ahoro. Lóòtítọ́ ni mo sì wí fún yín, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi títí yóò fi di àkókò tí ẹ̀yin ó wí pé, ‘Olùbùkún ni ẹni tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa.’”

< Лука 13 >