< Жудекэторий 8 >

1 Бэрбаций луй Ефраим ау зис луй Гедеон: „Че ынсямнэ фелул ачеста де пуртаре фацэ де ной? Пентру че ну не-ай кемат кынд ай плекат сэ те лупць ымпотрива луй Мадиан?” Ши ау авут о маре чартэ ку ел.
Àwọn àgbàgbà ẹ̀yà Efraimu sì bínú gidigidi sí Gideoni wọ́n bi í léèrè pé, kí ló dé tí o fi ṣe irú èyí sí wa? Èéṣe tí ìwọ kò fi pè wá nígbà tí ìwọ kọ́kọ́ jáde lọ láti bá àwọn ará Midiani jagun? Ohùn ìbínú ni wọ́n fi bá a sọ̀rọ̀.
2 Гедеон ле-а рэспунс: „Че-ам фэкут еу пе лынгэ вой? Оаре ну фаче май мулт кулесул чоркинелор рэмасе ын вия луй Ефраим декыт кулесул ынтреӂий вий а луй Абиезер?
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Àṣeyọrí wo ni mo ti ṣe tí ó tó fiwé tiyín? Àṣàkù àjàrà Efraimu kò ha dára ju gbogbo ìkórè àjàrà Abieseri lọ bí?
3 Ын мыниле воастре а дат Думнезеу пе кэпетенииле луй Мадиан: Ореб ши Зееб. Че-ам путут фаче еу деч пе лынгэ вой?” Дупэ че ле-а ворбит астфел, ли с-а потолит мыния.
Ọlọ́run ti fi Orebu àti Seebu àwọn olórí àwọn ará Midiani lé yín lọ́wọ́. Kí ni ohun tí Mose ṣe tí ó tó fiwé e yín tàbí tí ó tó àṣeyọrí i yín?” Nígbà tí ó wí èyí ríru ìbínú wọn rọlẹ̀.
4 Гедеон а ажунс ла Йордан ши л-а трекут, ел ши чей трей суте де оамень каре ерау ку ел, обосиць, дар урмэринд мереу пе врэжмаш.
Gideoni àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ̀síwájú láti lépa àwọn ọ̀tá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ̀ wọ́n, wọ́n dé Jordani wọ́n sì kọjá sí òdìkejì.
5 Ел а зис челор дин Сукот: „Даць, вэ рог, кытева пынь попорулуй каре мэ ынсоцеште, кэч сунт обосиць ши сунт ын урмэриря луй Зебах ши Цалмуна, ымпэраций Мадианулуй.”
Ó wí fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Ẹ fún àwọn ọmọ-ogun mi ní oúnjẹ díẹ̀, nítorí ó ti rẹ̀ wọ́n, èmi sì ń lépa Seba àti Salmunna àwọn ọba Midiani.”
6 Кэпетенииле дин Сукот ау рэспунс: „Есте оаре мына луй Зебах ши Цалмуна ын стэпыниря та, ка сэ дэм пыне оштирий тале?”
Ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Sukkoti fèsì pé ṣé ọwọ́ rẹ ti tẹ Seba àti Salmunna náà ni? Èéṣe tí àwa yóò ṣe fún àwọn ológun rẹ ní oúnjẹ?
7 Ши Гедеон а зис: „Ей бине, дупэ че Домнул ва да ын мыниле ноастре пе Зебах ши пе Цалмуна, вэ вой скэрпина карня ку спинь дин пустиу ши ку мэрэчинь.”
Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Ó dára, nígbà tí Olúwa bá fi Seba àti Salmunna lé mi lọ́wọ́ tán èmi yóò fi ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún òṣùṣú ya ẹran-ara yín.”
8 Де аколо с-а суит ла Пенуел ши а фэкут челор дин Пенуел ачеяшь ругэминте. Ей й-ау рэспунс кум ый рэспунсесерэ чей дин Сукот.
Láti ibẹ̀, ó lọ sí Penieli ó sì bẹ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ṣùgbọ́n àwọn náà dá a lóhùn bí àwọn ará Sukkoti ti dá a lóhùn.
9 Ши а зис ши челор дин Пенуел: „Кынд мэ вой ынтоарче ын паче, вой дэрыма турнул ачеста.”
Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ọkùnrin Penieli pé, “Nígbà tí mo bá ṣẹ́gun tí mo sì padà dé ní àlàáfíà, èmi yóò wó ilé ìṣọ́ yìí.”
10 Зебах ши Цалмуна ерау ла Каркор ымпреунэ ку оштиря лор де апроапе чинчспрезече мий де оамень; тоць чей че май рэмэсесерэ дин тоатэ оштиря фиилор Рэсэритулуй, о сутэ доуэзечь де мий де оамень каре скотяу сабия, фусесерэ учишь.
Ní àsìkò náà Seba àti Salmunna wà ní Karkori pẹ̀lú ọmọ-ogun wọn tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọkùnrin, àwọn wọ̀nyí ni ó ṣẹ́kù nínú gbogbo ogun àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn, nítorí ọ̀kẹ́ mẹ́fà ọkùnrin tí ó fi idà jà ti kú ní ojú ogun.
11 Гедеон с-а суит пе друмул челор че локуеск ын кортурь ла рэсэрит де Нобах ши де Иогбеха ши а бэтут оштиря каре се кредя ла адэпост.
Gideoni gba ọ̀nà tí àwọn darandaran máa ń rìn ní apá ìhà ìlà-oòrùn Noba àti Jogbeha ó sì kọjú ogun sí àwọn ọmọ-ogun náà nítorí wọ́n ti túra sílẹ̀.
12 Зебах ши Цалмуна ау луат фуга; Гедеон й-а урмэрит, а принс пе чей дой ымпэраць ай Мадианулуй, Зебах ши Цалмуна, ши а пус пе фугэ тоатэ оштиря.
Seba àti Salmunna, àwọn ọba Midiani méjèèjì sá, ṣùgbọ́n Gideoni lépa wọn ó sì mú wọn, ó run gbogbo ogun wọn.
13 Гедеон, фиул луй Иоас, с-а ынторс де ла луптэ прин суишул Херес.
Gideoni ọmọ Joaṣi gba ọ̀nà ìgòkè Heresi padà sẹ́yìn láti ojú ogun.
14 А принс динтре чей дин Сукот ун тынэр пе каре л-а ынтребат ши каре й-а дат ын скрис нумеле кэпетениилор ши бэтрынилор дин Сукот; ерау шаптезечь ши шапте де бэрбаць.
Ó mú ọ̀dọ́mọkùnrin kan ará Sukkoti, ó sì béèrè àwọn ìbéèrè ní ọwọ́ rẹ̀, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì kọ orúkọ àwọn ìjòyè Sukkoti mẹ́tàdínlọ́gọ́rin fún un tí wọ́n jẹ́ àgbàgbà ìlú náà.
15 Апой а венит ла чей дин Сукот ши а зис: „Ятэ пе Зебах ши Цалмуна, пентру каре м-аць батжокорит зикынд: ‘Оаре мына луй Зебах ши Цалмуна есте ын стэпыниря та, ка сэ дэм пыне оаменилор тэй обосиць?’”
Nígbà náà ni Gideoni wá ó sọ fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Seba àti Salmunna nìwọ̀nyí nípa àwọn tí ẹ̀yin fi mí ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ẹ wí pé, ‘Ṣé ó ti ṣẹ́gun Seba àti Salmunna? Èéṣe tí àwa ó fi fún àwọn ọmọ-ogun rẹ tí ó ti rẹ̀ ní oúnjẹ?’”
16 Ши а луат пе бэтрыний четэций ши а педепсит пе оамений дин Сукот ку спинь дин пустиу ши ку мэрэчинь.
Ó mú àwọn àgbàgbà ìlú náà, ó sì fi kọ́ àwọn Sukkoti lọ́gbọ́n nípa jíjẹ wọ́n ní yà pẹ̀lú àwọn ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún ọ̀gàn.
17 А дэрымат ши турнул дин Пенуел ши а учис пе оамений четэций.
Ó wó ilé ìṣọ́ Penieli, ó sì pa àwọn ọkùnrin ìlú náà.
18 Ел а зис луй Зебах ши луй Цалмуна: „Кум ерау оамений пе каре й-аць учис ла Табор?” Ей ау рэспунс: „Ерау ка тине, фиекаре авя ынфэцишаря унуй фиу де ымпэрат.”
Gideoni bi Seba àti Salmunna pé, “Irú ọkùnrin tí ẹ pa ní Tabori, báwo ni wọ́n ṣe rí?” “Àwọn ọkùnrin náà dàbí rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dàbí ọmọ ọba,” ní ìdáhùn wọn.
19 Ел а зис: „Ерау фраций мей, фиий мамей меле. Виу есте Домнул кэ, дакэ й-аць фи лэсат ку вяцэ, ну в-аш учиде.”
Gideoni dáhùn pé, “Arákùnrin mi ni wọ́n, àwọn ọmọ ìyá mi. Mo fi Olúwa búra, bí ó bá ṣe pé ẹ dá ẹ̀mí wọn sí, èmi náà ò nípa yín.”
20 Ши а зис луй Иетер, ынтыюл луй нэскут: „Скоалэ-те ши учиде-й!” Дар тынэрул ну шь-а скос сабия, пентру кэ-й ера тямэ, кэч ера ынкэ ун копил.
Ó yí padà sí Jeteri, ọmọ rẹ̀ tí ó dàgbà jùlọ, ó wí fún un pé, “Pa wọ́n!” Ṣùgbọ́n Jeteri kò fa idà rẹ̀ yọ láti pa wọ́n nítorí ó jẹ́ ọ̀dọ́mọdé ẹ̀rù sì bà á láti pa wọ́n.
21 Зебах ши Цалмуна ау зис: „Скоалэ-те ту ынсуць ши учиде-не! Кэч кум е омул аша е ши путеря луй.” Ши Гедеон с-а скулат ши а учис пе Зебах ши Цалмуна. А луат апой лунишоареле де ла гытул кэмилелор лор.
Seba àti Salmunna dá Gideoni lóhùn pé, “Wá pa wá fún raàrẹ, ‘Nítorí bí ènìyàn bá ti rí bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóò rí.’” Gideoni bọ́ síwájú ó sì pa wọ́n, ó sì mú ohun ọ̀ṣọ́ tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
22 Бэрбаций луй Исраел ау зис луй Гедеон: „Домнеште песте ной, ту ши фиул тэу, ши фиул фиулуй тэу, кэч не-ай избэвит дин мына луй Мадиан.”
Àwọn ará Israẹli wí fún Gideoni pé, “Jọba lórí wa—ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ pẹ̀lú, nítorí tí ìwọ ti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ará Midiani.”
23 Гедеон ле-а зис: „Еу ну вой домни песте вой, нич фиий мей ну вор домни песте вой, чи Домнул ва домни песте вой.”
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Èmi kì yóò jẹ ọba lórí yín, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ mi kì yóò jẹ ọba lórí yín. Olúwa ni yóò jẹ ọba lórí yín.”
24 Гедеон ле-а зис: „Ам сэ вэ фак о ругэминте: даци-мь фиекаре вериӂиле де нас пе каре ле-аць луат ка прадэ.” (Врэжмаший авяу вериӂь де аур, кэч ерау исмаелиць.)
Gideoni sì wí pé, “Mo ní ẹ̀bẹ̀ kan tí mo fẹ́ bẹ̀ yín kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín fún mi ní yẹtí kọ̀ọ̀kan láti inú ohun ti ó kàn yín láti inú ìkógun.” (Àṣà àwọn ará Iṣmaeli ni láti máa fi yẹtí wúrà sétí.)
25 Ей ау зис: „Ци ле вом да ку плэчере.” Ши ау ынтинс о манта, пе каре а арункат фиекаре вериӂиле пе каре ле прэдасе.
Wọ́n dáhùn pé, “Tayọ̀tayọ̀ ni àwa yóò fi wọ́n sílẹ̀.” Wọ́n tẹ́ aṣọ kan sílẹ̀ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan sì ń sọ yẹtí kọ̀ọ̀kan tí ó kàn wọ́n láti ibi ìkógun síbẹ̀.
26 Греутатя вериӂилор де аур пе каре ле-а черут Гедеон а фост де о мие шапте суте де сикли де аур, афарэ де лунишоаре, де черчеий де аур ши де хайнеле де пурпурэ пе каре ле пуртау ымпэраций Мадианулуй ши афарэ де лэнцишоареле де ла гытул кэмилелор лор.
Ìwọ̀n òrùka wúrà tí ó béèrè fún tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ìwọ̀n ṣékélì, láìka àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àti ohun sísorọ̀ tí ó wà lára ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn àti aṣọ elése àlùkò tí àwọn ọba Midiani ń wọ̀ tàbí àwọn ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
27 Гедеон а фэкут дин еле ун ефод ши л-а пус ын четатя луй, ла Офра, унде а ажунс о причинэ де курвие пентру тот Исраелул ши а фост о курсэ пентру Гедеон ши пентру каса луй.
Gideoni fi àwọn wúrà náà ṣe efodu èyí tí ó gbé kalẹ̀ ní Ofira ìlú rẹ̀. Àwọn ọmọ Israẹli sì sọ ara wọn di àgbèrè nípa sínsin-ín ní ibẹ̀. Ó sì di ìdẹ̀kùn fún Gideoni àti ìdílé rẹ̀.
28 Мадианул а фост смерит ынаинтя копиилор луй Исраел ши н-а май ридикат капул. Ши цара а авут одихнэ патрузечь де ань, ын тимпул веций луй Гедеон.
Báyìí ni a ṣe tẹrí àwọn ará Midiani ba níwájú àwọn ọmọ Israẹli bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tún gbé orí mọ́. Ní ọjọ́ Gideoni, Israẹli wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún.
29 Иерубаал, фиул луй Иоас, с-а ынторс ши а локуит ын каса луй.
Jerubbaali ọmọ Joaṣi padà lọ láti máa gbé ní ìlú rẹ̀.
30 Гедеон а авут шаптезечь де фий ешиць дин ел, кэч а авут май мулте невесте.
Àádọ́rin ọmọ ni Gideoni bí, nítorí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìyàwó.
31 Циитоаря луй, каре ера ла Сихем, й-а нэскут де асеменя ун фиу, кэруя й-ау пус нумеле Абимелек.
Àlè rẹ̀, tó ń gbé ní Ṣekemu, pàápàá bí ọmọkùnrin kan fún un tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Abimeleki.
32 Гедеон, фиул луй Иоас, а мурит дупэ о бэтрынеце феричитэ ши а фост ынгропат ын мормынтул татэлуй сэу Иоас, ла Офра, каре ера а фамилией луй Абиезер.
Gideoni ọmọ Joaṣi kú ní ògbólógbòó ọjọ́ rẹ̀, ó sì pọ̀ ní ọjọ́ orí, wọ́n sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀ ní Ofira ti àwọn ará Abieseri.
33 Дупэ моартя луй Гедеон, копиий луй Исраел ау ынчепут ярэшь сэ курвяскэ ку баалий ши ау луат пе Баал-Берит ка думнезеу ал лор.
Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gideoni ni àwọn ará Israẹli ṣe àgbèrè tọ Baali lẹ́yìn, wọ́n fi Baali-Beriti ṣe òrìṣà wọn.
34 Копиий луй Исраел ну шь-ау адус аминте де Домнул Думнезеул лор, каре-й избэвисе дин мына тутурор врэжмашилор каре-й ынконжурау.
Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.
35 Ши н-ау цинут ла каса луй Иерубаал, а луй Гедеон, дупэ тот бинеле пе каре-л фэкусе ел луй Исраел.
Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jerubbaali (èyí ni Gideoni) fún gbogbo oore tí ó ṣe fún wọn.

< Жудекэторий 8 >