< Иеремия 7 >

1 Ятэ кувынтул ворбит луй Иеремия дин партя Домнулуй:
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
2 „Шезь ла поарта Касей Домнулуй, вестеште аколо кувынтул ачеста ши спуне: ‘Аскултаць Кувынтул Домнулуй, тоць бэрбаций луй Иуда каре интраць пе ачесте порць ка сэ вэ ынкинаць ынаинтя Домнулуй!’”
“Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
3 Аша ворбеште Домнул оштирилор, Думнезеул луй Исраел: „Ындрептаци-вэ кэиле ши фаптеле, ши вэ вой лэса сэ локуиць ын локул ачеста.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
4 Ну вэ хрэниць ку нэдеждь ыншелэтоаре, зикынд: ‘Ачеста есте Темплул Домнулуй, Темплул Домнулуй, Темплул Домнулуй!’
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
5 Кэч нумай дакэ вэ вець ындрепта кэиле ши фаптеле, дакэ вець ынфэптуи дрептатя уний фацэ де алций,
Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
6 дакэ ну вець асупри пе стрэин, пе орфан ши пе вэдувэ, дакэ ну вець вэрса сынӂе невиноват ын локул ачеста ши дакэ ну вець мерӂе дупэ алць думнезей, спре ненорочиря воастрэ,
Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
7 нумай аша вэ вой лэса сэ локуиць ын локул ачеста, ын цара пе каре ам дат-о пэринцилор воштри, дин вешничие ын вешничие.
Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
8 Дар ятэ кэ вой вэ хрэниць ку нэдеждь ыншелэтоаре, каре ну служеск ла нимик.
Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
9 Кум? Фураць, учидець, прякурвиць, жураць стрымб, адучець тэмые луй Баал, мерӂець дупэ алць думнезей пе каре ну-й куноаштець…
“‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
10 Ши апой вениць сэ вэ ынфэцишаць ынаинтя Мя, ын Каса ачаста песте каре есте кемат Нумеле Меу, ши зичець: ‘Сунтем избэвиць!’, ка ярэшь сэ фачець тоате ачесте урычунь!
Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
11 Есте Каса ачаста, песте каре есте кемат Нумеле Меу, о пештерэ де тылхарь ынаинтя воастрэ? Еу Ынсумь вэд лукрул ачеста”, зиче Домнул.
Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
12 „Дучеци-вэ дар ла локул каре-Мь фусесе ынкинат ла Сило, унде пусесем сэ локуяскэ одиниоарэ Нумеле Меу, ши ведець че й-ам фэкут дин причина рэутэций попорулуй Меу Исраел!
“‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
13 Ши акум, фииндкэ аць фэкут тоате ачесте фапте”, зиче Домнул, „фииндкэ в-ам ворбит дис-де-диминяцэ, ши н-аць аскултат, фииндкэ в-ам кемат, ши н-аць рэспунс,
Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
14 вой фаче Касей песте каре есте кемат Нумеле Меу, ын каре вэ пунець ынкредеря, ши локулуй пе каре ви л-ам дат воуэ ши пэринцилор воштри, ле вой фаче ынтокмай кум ам фэкут луй Сило.
Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
15 Ши вэ вой лепэда де ла Фаца Мя, кум ам лепэдат пе тоць фраций воштри, пе тоатэ сэмынца луй Ефраим!
Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
16 Ту ынсэ ну мижлочи пентру попорул ачеста, ну ынэлца нич черерь, нич ругэчунь пентру ей ши ну стэруи пе лынгэ Мине; кэч ну те вой аскулта!
“Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
17 Ну везь че фак ей ын четэциле луй Иуда ши пе улицеле Иерусалимулуй?
Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
18 Копиий стрынг лемне, пэринций апринд фокул ши фемеиле фрэмынтэ плэмэдяла, ка сэ прегэтяскэ турте ымпэрэтесей черулуй ши сэ тоарне жертфе де бэутурэ алтор думнезей, ка сэ Мэ мыние.
Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
19 Пе Мине Мэ мыние ей оаре?”, зиче Домнул. „Ну пе ей ыншишь, спре рушиня лор?”
Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
20 Де ачея, аша ворбеште Домнул Думнезеу: „Ятэ, мыния ши урӂия Мя се вор вэрса песте локул ачеста, песте оамень ши добитоаче, песте копачий де пе кымп ши песте роаделе пэмынтулуй, ши ва арде, ши ну се ва стинӂе.”
“‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
21 Аша ворбеште Домнул оштирилор, Думнезеул луй Исраел: „Адэугаць ардериле воастре де тот ла жертфеле воастре ши мынкаци-ле карня!
“‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
22 Кэч н-ам ворбит нимик ку пэринций воштри ши ну ле-ам дат ничо порункэ ку привире ла ардерь-де-тот ши жертфе ын зиуа кынд й-ам скос дин цара Еӂиптулуй.
Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
23 Чи ятэ порунка пе каре ле-ам дат-о: ‘Аскултаць гласул Меу, ши Еу вой фи Думнезеул востру, яр вой вець фи попорул Меу; умблаць пе тоате кэиле пе каре ви ле-ам порунчит, ка сэ фиць феричиць!’
Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
24 Дар ей н-ау аскултат ши н-ау луат аминте, чи ау урмат сфатуриле ши порнириле инимий лор реле, ау дат ынапой ши н-ау мерс ынаинте.
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
25 Дин зиуа кынд ау ешит пэринций воштри дин Еӂипт пынэ ын зиуа де азь, в-ам тримис пе тоць служиторий Мей, пророчий, й-ам тримис ын фиекаре зи, де диминяцэ.
Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
26 Дар ей ну М-ау аскултат, н-ау луат аминте, шь-ау ынцепенит гытул ши ау фэкут май рэу декыт пэринций лор.
Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
27 Ши, кяр дакэ ле вей спуне тоате ачесте лукрурь, тот ну те вор аскулта ши, дакэ вей стрига ла ей, ну-ць вор рэспунде.
“Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
28 Де ачея, спуне-ле: ‘Ачеста есте попорул каре н-аскултэ гласул Домнулуй Думнезеулуй сэу ши каре ну вря сэ я ынвэцэтурэ; с-а дус адевэрул, а фуӂит дин гура лор.
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
29 Акум, тунде-ць пэрул, Иерусалиме, ши арункэ-л департе; суе-те пе ынэлцимь ши фэ о кынтаре де жале! Кэч Домнул ляпэдэ ши ындепэртязэ нямул де оамень каре Й-а ацыцат урӂия.’
“‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
30 Кэч копиий луй Иуда ау фэкут че есте рэу ынаинтя Мя”, зиче Домнул, „шь-ау ашезат урычуниле лор ын Каса песте каре есте кемат Нумеле Меу, ка с-о спурче.
“‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
31 Ау зидит ши локурь ыналте ла Тофет, ын валя Бен-Хином, ка сэ-шь ардэ ын фок фиий ши фийчеле – лукру пе каре Еу ну-л порунчисем ши нич ну-Мь трекусе прин минте.
Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
32 Де ачея, ятэ, вин зиле”, зиче Домнул, „кынд ну се ва май зиче Тофет ши валя Бен-Хином, чи се ва зиче Валя Мэчелулуй ши се вор ынгропа морций ла Тофет, дин липсэ де лок.
Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
33 Трупуриле моарте але ачестуй попор вор фи храна пэсэрилор черулуй ши а фярелор пэмынтулуй, ши нимень ну ле ва сперия.
Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
34 Вой фаче астфел сэ ынчетезе ын четэциле луй Иуда ши пе улицеле Иерусалимулуй стригэтеле де букурие ши стригэтеле де веселие, кынтечеле мирелуй ши кынтечеле миресей, кэч цара ва ажунӂе ун пустиу!”
Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.

< Иеремия 7 >