< Иеремия 49 >

1 Асупра копиилор луй Амон. Аша ворбеште Домнул: „Н-аре Исраел фий? Ши н-аре моштениторь? Атунч пентру че стэпынеште Малком Гадул ши локуеште попорул луй ын четэциле луй?
Nípa Ammoni. Báyìí ni Olúwa wí, “Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin? Israẹli kò ha ní àrólé bí? Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi? Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
2 Де ачея, ятэ кэ вин зиле”, зиче Домнул, „кынд вой фаче сэ рэсуне стригэтул де рэзбой ымпотрива Рабей копиилор луй Амон. Еа ва ажунӂе ун морман де дэрымэтурь, ши сателе сале вор фи арсе де фок. Атунч, Исраел ва изгони пе чей че-л изгонисерэ”, зиче Домнул.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí; “nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba tí Ammoni; yóò sì di òkìtì ahoro, gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná. Nígbà náà ni Israẹli yóò lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,” ni Olúwa wí.
3 „Ӂемь, Хесбонуле, кэч Ай есте пустиит! Стригаць, фийчеле Рабей, ымбрэкаци-вэ ку сачь ши бочици-вэ, алергынд ынкоаче ши ынколо де-а лунгул зидурилор! Кэч Малком се дуче ын робие ку преоций ши кэпетенииле сале!
“Hu, ìwọ Heṣboni, nítorí Ai tí rún! Kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba! Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà, nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
4 Че те лаузь ку вэиле? Валя та се скурӂе, фийкэ рэзврэтитэ, каре те ынкредяй ын вистиерииле тале ши зичяй: ‘Чине ва вени ымпотрива мя?’
Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú àfonífojì rẹ, ṣògo nínú àfonífojì rẹ fún èso? Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé, ‘Ta ni yóò kò mí lójú?’
5 Ятэ, вой адуче гроаза песте тине”, зиче Домнул Думнезеул оштирилор; „еа ва вени дин тоате ымпрежуримиле тале, фиекаре дин вой ва фи изгонит дрепт ынаинте, ши нимень ну ва стрынӂе пе фугарь!
Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,” ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
6 Дар, дупэ ачея, вой адуче ынапой пе принший де рэзбой ай копиилор луй Амон”, зиче Домнул.
“Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,” ni Olúwa wí.
7 Асупра Едомулуй. Аша ворбеште Домнул оштирилор: „Ну май есте ынцелепчуне ын Теман? А перит кибзуинца де ла оамений причепуць? С-а дус ынцелепчуня лор?
Nípa Edomu. Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani? Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè? Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
8 Фуӂиць, даць досул, плекаць ын пештерь, локуиторь ай Деданулуй! Кэч вой адуче ненорочиря песте Есау ла время кынд ыл вой педепси.
Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò, ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani, nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau, ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
9 Оаре, дакэ ар вени ниште кулегэторь де стругурь ла тине, ну ць-ар лэса нимик де кулес пе урма кулегэторилор? Дакэ ар вени ниште хоць ноаптя, н-ар пустий декыт пынэ с-ар сэтура!
Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá; ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀? Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
10 Дар Еу Ынсумь вой деспуя пе Есау, ый вой дескопери аскунзэториле ши ну ва путя сэ се аскундэ. Копиий луй, фраций луй, вечиний луй вор пери, ши ел ну ва май фи!
Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò, èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn, nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́. Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti àwọn ará ilé rẹ yóò parun. Wọn kò sì ní sí mọ́.
11 Ласэ пе орфаний тэй! Еу ый вой цине ын вяцэ, ши вэдувеле тале сэ се ынкрядэ ын Мине!”
Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀ èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn. Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
12 Кэч аша ворбеште Домнул: „Ятэ кэ чей че ну требуяу сэ бя потирул тотушь ыл вор бя, ши ту сэ рэмый непедепсит? Ну, ну вей рэмыне непедепсит, чи ыл вей бя ши ту!
Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un.
13 Кэч пе Мине Ынсумь жур”, зиче Домнул, „кэ Боцра ва фи датэ прадэ пустиирий, окэрий, нимичирий ши блестемулуй, ши тоате четэциле ей се вор префаче ын ниште дэрымэтурь вешниче.”
Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
14 Ам аузит о весте де ла Домнул ши ун сол а фост тримис принтре нямурь: „Стрынӂеци-вэ ши порниць ымпотрива ей! Скулаци-вэ пентру рэзбой!
Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, a rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé, ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
15 Кэч ятэ, те вой фаче мик принтре нямурь, диспрецуит принтре оамень.
“Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
16 Ынфумураря та, ынгымфаря инимий тале, те-а рэтэчит пе тине, каре локуешть ын крэпэтуриле стынчилор ши каре стай пе вырфул дялурилор. Дар, кяр дакэ ць-ай ашеза куйбул тот атыт де сус ка ал вултурулуй, ши де аколо те вой прэбуши”, зиче Домнул.
Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ; ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta, tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì; láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,” ni Olúwa wí.
17 „Едомул ва фи пустиит; тоць чей че вор трече пе лынгэ ел се вор мира ши вор флуера пентру тоате рэниле луй.
“Edomu yóò di ahoro gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ.
18 Ка ши Содома ши Гомора ши четэциле вечине каре ау фост нимичите”, зиче Домнул, „нич ел ну ва май фи локуит ши нимень ну се ва май ашеза аколо…
Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó wà ní àyíká rẹ,” ní Olúwa wí. “Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀; kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
19 Ятэ, врэжмашул се суе ка ун леу де пе малуриле ынгымфате але Йорданулуй ымпотрива локуинцей тале тарь; деодатэ вой фаче Едомул сэ фугэ де аколо ши вой пуне песте ел пе ачела пе каре л-ам алес. Кэч чине есте ка Мине? Чине-Мь ва порунчи? Чине-Мь ва ста ымпотривэ?”
“Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
20 Де ачея, аскултаць хотэрыря пе каре а луат-о Домнул ымпотрива Едомулуй ши плануриле пе каре ле-а фэкут ымпотрива локуиторилор дин Теман: „Ку адевэрат, ый вор тыры ка пе ниште ой слабе, ку адевэрат ли се ва пустий локуинца!
Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Edomu, ohun tí ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani. Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde; pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
21 Де вуетул кэдерий лор се кутремурэ пэмынтул; стригэтул лор се ауде пынэ ла Маря Рошие…
Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn, a ó gbọ́ igbe wọn ní Òkun pupa.
22 Ятэ, ка вултурул ынаинтязэ врэжмашул ши збоарэ, ышь ынтинде арипиле песте Боцра ши ын зиуа ачея инима витежилор Едомулуй есте ка инима уней фемей ын дурериле наштерий.”
Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀, yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
23 Асупра Дамаскулуй: „Хаматул ши Арпадул сунт роший де рушине, кэч ау аузит о весте ря ши тремурэ; фрика лор есте ка о маре ынфуриятэ, каре ну се поате потоли.
Nípa Damasku. “Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn, wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
24 Дамаскул есте топит, се ынтоарче сэ фугэ, ыл я гроаза, ыл апукэ нелиништя ши дурериле, ка пе о фемее ын дурериле наштерий. –
Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a; ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
25 Ах, кум ну есте круцатэ четатя слэвитэ, четатя букурией меле! –
Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀; ìlú tí mo dunnú sí.
26 Де ачея тинерий ей вор кэдя пе улице ши тоць бэрбаций ей де рэзбой вор пери ын зиуа ачея”, зиче Домнул оштирилор.
Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
27 „Вой пуне фок зидурилор Дамаскулуй ши ва мистуи каселе ымпэрэтешть дин Бен-Хадад.”
“Èmi yóò fi iná sí odi Damasku, yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
28 Асупра Кедарулуй ши ымпэрэциилор Хацорулуй, пе каре ле-а бэтут Небукаднецар, ымпэратул Бабилонулуй. Аша ворбеште Домнул: „Скулаци-вэ, суици-вэ ымпотрива Кедарулуй ши нимичиць пе фиий Рэсэритулуй!
Nípa ìlú Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ, èyí ni ohun tí Olúwa sọ, “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ ìlú Kedari, kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
29 Ле вор луа кортуриле ши турмеле, ле вор ридика пынзеле, тот калабалыкул ши кэмилеле ши ле вор стрига: ‘Спаймэ, де жур ымпрежур!’
Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ; àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn. Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé, ‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
30 Фуӂиць, фуӂиць дин тоате путериле воастре, кэутаць о локуинцэ деопарте, локуиторь ай Хацорулуй”, зиче Домнул, „кэч Небукаднецар, ымпэратул Бабилонулуй, а луат о хотэрыре ымпотрива воастрэ, а фэкут ун план ымпотрива воастрэ!
“Sálọ kíákíá! Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,” ni Olúwa wí. “Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
31 Скулаци-вэ, суици-вэ ымпотрива унуй ням лиништит, каре локуеште фэрэ тямэ”, зиче Домнул; „н-аре нич порць, нич зэвоаре ши локуеште сингур.
“Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn, èyí tí ó gbé ní àìléwu,” ní Olúwa wí. “Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
32 Кэмилеле лор вор фи де жаф ши мулцимя турмелор лор вор фи о прадэ. Вой рисипи ын тоате вынтуриле пе ей, чей че-шь рад колцуриле бэрбий, ши ле вой адуче пеиря дин тоате пэрциле”, зиче Домнул.
Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun. Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́. Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,” báyìí ní Olúwa wí.
33 „Хацорул ва фи астфел визуина шакалилор, ун пустиу пе вечие; нимень ну ва локуи ын ел ши ничун ом ну ва шедя ын ел.”
“Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé, kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
34 Кувынтул Домнулуй, каре а фост спус пророкулуй Иеремия, асупра Еламулуй, ла ынчепутул домнией луй Зедекия, ымпэратул луй Иуда, сунэ астфел:
Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda.
35 „Аша ворбеште Домнул оштирилор: ‘Ятэ, вой сфэрыма аркул Еламулуй, путеря луй де кэпетение.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu, ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
36 Вой адуче асупра Еламулуй челе патру вынтурь де ла челе патру марӂинь але черулуй, ый вой рисипи ын тоате вынтуриле ачестя ши ну ва фи ничун попор ла каре сэ н-ажунгэ фугарь дин Елам.
Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àgbáyé lòdì sí Elamu. Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
37 Вой фаче ка локуиторий Еламулуй сэ тремуре ынаинтя врэжмашилор лор ши ынаинтя челор че вор сэ-й омоаре. Вой адуче ненорочирь песте ей, мыния Мя апринсэ’, зиче Домнул, ‘ши-й вой урмэри ку сабия пынэ че ый вой нимичи.
Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn, àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn, Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn, àní, ìbínú gbígbóná mi,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
38 Ымь вой ашеза скаунул де домние ын Елам ши-й вой нимичи ымпэратул ши кэпетенииле’, зиче Домнул.
Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,” báyìí ni Olúwa wí.
39 ‘Дар ын зилеле де апой вой адуче ынапой пе принший де рэзбой ай Еламулуй’, зиче Домнул.”
“Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,” báyìí ni Olúwa wí.

< Иеремия 49 >