< Осея 13 >

1 Кынд ворбя, Ефраим рэспындя гроаза ын Исраел. Дар кум а пэкэтуит ку Баал, а мурит.
Nígbà ti Efraimu bá ń sọ̀rọ̀, àwọn ènìyàn máa ń wárìrì, a gbé e ga ní Israẹli ṣùgbọ́n ó jẹ̀bi ẹ̀sùn pé ó ń sin òrìṣà Baali, ó sì kú.
2 Ши акум ей пэкэтуеск ынтруна, ышь фак кипурь турнате дин арӂинтул лор, идоль нэскочиць де ей, лукраре фэкутэ де мештерь. Ачестора ле ворбеск ей ши, жертфинд оамень, сэрутэ вицей!
Báyìí, wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀; wọn fi fàdákà ṣe ère òrìṣà fúnra wọn; ère tí a fi ọgbọ́n dá àrà sí, gbogbo wọn jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ oníṣọ̀nà. Wọn ń sọ nípa àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Pé, “Jẹ́ kí àwọn ènìyàn tí ń rú ẹbọ fi ẹnu, ko àwọn ẹgbọrọ màlúù ni ẹnu.”
3 Де ачея вор фи ка норул де диминяцэ, ка роуа каре трече репеде, ка плява суфлатэ де вынт дин арие, ка фумул каре есе дин хорн.
Nítorí náà wọn yóò dàbí ìkùùkuu òwúrọ̀, bí ìrì òwúrọ̀ kùtùkùtù tó máa ń parẹ́, bí i èèpo ìyẹ̀fun tí afẹ́fẹ́ gbé láti ibi ìpakà bí èéfín tó rú jáde gba ojú fèrèsé.
4 „Дар Еу сунт Домнул Думнезеул тэу, дин цара Еӂиптулуй ынкоаче. Ту куношть кэ ну есте алт Думнезеу афарэ де Мине ши ну есте алт Мынтуитор афарэ де Мине.
“Ṣùgbọ́n Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ẹni tó mú ọ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá. Ìwọ̀ kì yóò sì mọ ọlọ́run mìíràn àfi èmi kò sí olùgbàlà mìíràn lẹ́yìn mi.
5 Еу те-ам куноскут ын пустиу, ынтр-ун пэмынт фэрэ апэ.
Mo ṣe ìtọ́jú rẹ ní aginjù, ní ilẹ̀ tí ó gbẹ tí kò ní omi.
6 Дар, кынд ау дат де пэшуне, с-ау сэтурат ши, кынд с-ау сэтурат, инима ли с-а умфлат де мындрие, де ачея М-ау уйтат.
Wọn ni ìtẹ́lọ́rùn nígbà tí mo fún wọn ní oúnjẹ, Nígbà tí wọ́n ní ìtẹ́lọ́rùn tan wọ́n di agbéraga. Nígbà náà ni wọ́n sì gbàgbé mi.
7 Еу М-ам фэкут ка ун леу пентру ей ши-й пындеск ка ун пардос пе друм.
Nítorí náà, Èmi yóò dìde sí wọn bí i kìnnìún, Èmi yóò fi ara pamọ́ dè wọ́n lọ́nà bí i ẹkùn.
8 Мэ нэпустеск асупра лор ка о урсоайкэ липситэ де пуий ей, ле сфыший ынвелишул инимий, ый ынгит пе датэ ка ун леу ши фяреле кымпулуй ый вор фаче букэць.
Beari igbó tí a já ọmọ rẹ̀ gbà, Èmi yóò bá wọn jà bí? Èmi yóò sì fà wọ́n ya bí ìgbà tí ẹkùn bá fa ara wọn ya bi ẹranko búburú ni èmi yóò fa wọn ya.
9 Пеиря та, Исраеле, есте кэ ай фост ымпотрива Мя, ымпотрива Челуй че те путя ажута.
“A ti pa ọ́ run, ìwọ Israẹli, nítorí pé ìwọ lòdì sí mi, ìwọ lòdì sí olùrànlọ́wọ́ rẹ.
10 Унде есте ымпэратул тэу ка сэ те скапе ын тоате четэциле тале? Унде сунт жудекэторий тэй деспре каре зичяй: ‘Дэ-мь ун ымпэрат ши домнь’?
Níbo ni ọba rẹ gbé wà nísinsin yìí kí ó bá à le gbà ọ là? Níbo ni àwọn olórí ìlú yín wà, àwọn tí ẹ sọ pé, ‘Fún wa ní ọba àti ọmọ-aládé’?
11 Ць-ам дат ун ымпэрат ын мыния Мя ши ци-л яу ын урӂия Мя!
Nítorí èyí nínú ìbínú mi ni mo fún un yín ní ọba, nínú ìbínú gbígbóná mi, mo sì mú un kúrò.
12 Нелеӂюиря луй Ефраим есте стрынсэ, пэкатул луй есте пэстрат.
Ẹ̀bi Efraimu ni a tí ko jọ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ wà nínú àkọsílẹ̀.
13 Ыл вор апука дурериле наштерий; есте ун копил неынцелепт, кэч ну поате сэ наскэ ла время сорочитэ!
Ìrora bí obìnrin tó fẹ́ bímọ ti dé bá a, ṣùgbọ́n ó jẹ́ ọmọ tí kò lọ́gbọ́n, nígbà tí àsìkò tó, ó kọ̀ láti jáde síta láti inú.
14 Ый вой рэскумпэра дин мына Локуинцей морцилор, ый вой избэви де ла моарте. Моарте, унде ыць есте чума? Локуинцэ а морцилор, унде ыць есте нимичиря? Кэинца есте аскунсэ де привириле Меле!” (Sheol h7585)
“Èmi yóò rà wọ́n padà kúrò lọ́wọ́ agbára isà òkú. Èmi yóò rà wọ́n padà lọ́wọ́ ikú, ikú, àjàkálẹ̀-ààrùn rẹ dà? Isà òkú, ìparun rẹ dà? “Èmi kò ní ṣàánú mọ́. (Sheol h7585)
15 Орькыт де родитор ар фи Ефраим ын мижлокул фрацилор сэй, тот ва вени вынтул де рэсэрит, се ва стырни дин пустиу ун вынт ал Домнулуй, ый ва уска извоареле ши-й ва сека фынтыниле; ва жефуи вистиерия де тоате васеле ей де прец.
Bí ó tilẹ̀ gbilẹ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀ afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀dọ̀ Olúwa yóò wá, yóò fẹ́ wá láti inú aginjù orísun omi rẹ̀ yóò gbẹ kànga rẹ̀ yóò gbẹ pẹ̀lú olè yóò fọ́ ilé ẹrù àti gbogbo ilé ìṣúra rẹ̀.
16 Самария есте педепситэ пентру кэ с-а рэзврэтит ымпотрива Думнезеулуй ей. Вор кэдя учишь де сабие; прунчий лор вор фи здробиць ши вор спинтека пынтечеле фемеилор лор ынсэрчинате.
Ará Samaria gbọdọ̀ ru ẹ̀bi wọn, nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí Ọlọ́run wọn. Wọn ó ti ipa idà ṣubú; a ó fọ́ àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀, a ó sì la àwọn aboyún wọn nínú.”

< Осея 13 >