< Езекиел 31 >

1 Ын анул ал унспрезечеля, ын зиуа ынтый а луний а трея, кувынтул Домнулуй мь-а ворбит астфел:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kẹta ọdún kọkànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 „Фиул омулуй, спуне луй Фараон, ымпэратул Еӂиптулуй, ши мулцимий луй: ‘Ку чине те асемень ту ын мэримя та?
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún Farao ọba Ejibiti àti sí ìjọ rẹ̀: “‘Ta ní a le fiwé ọ ní ọláńlá?
3 Ятэ кэ асириянул ера ун чедру фалник ын Либан; рамуриле луй ерау стуфоасе, фрунзишул умброс, тулпина ыналтэ, яр вырфул ый ажунӂя пынэ ла норь.
Kíyèsi Asiria, tí ó jẹ́ igi kedari ni Lebanoni ní ìgbà kan rí, pẹ̀lú àwọn ẹ̀ka dáradára tí ó ṣẹ́ ìji bo igbó náà; tí ó ga sókè, òkè rẹ̀ lókè ni ewé tí ó nípọn wà.
4 Апеле ыл фэкусерэ сэ кряскэ, адынкул ыл фэкусе ыналт, рыуриле луй ый скэлдау рэсадница ши ышь тримитяу пыраеле ла тоць копачий де пе кымп.
Omi mú un dàgbàsókè: orísun omi tí ó jinlẹ̀ mú kí o dàgbàsókè; àwọn odo rẹ̀ ń sàn yí ìdí rẹ̀ ká, ó sì rán ìṣàn omi rẹ̀ sí gbogbo igi orí pápá.
5 Де ачея, тулпина луй се ынэлца дясупра тутурор копачилор де пе кымп, кренӂиле и се ынмулцисерэ ши рамуриле и се ынтиндяу де мулцимя апелор каре-л фэкусерэ сэ дя лэстарь.
Nítorí náà ó ga sí òkè fíofío ju gbogbo igi orí pápá lọ; ẹ̀ka rẹ̀ pọ̀ sí i àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì gùn, wọn tẹ́ rẹrẹ nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
6 Тоате пэсэриле черулуй ышь фэчяу куйбурь ын кренӂиле луй; тоате фяреле кымпулуй фэтау суб рамуриле луй ши тот фелул де нямурь мулте локуяу суб умбра луй.
Ẹyẹ ojú ọ̀run kọ ilé sí ẹ̀ka rẹ̀ gbogbo ẹranko igbó ń bímọ ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè ńlá ń gbé abẹ́ ìji rẹ̀.
7 Ера фрумос прин мэримя луй, прин ынтиндеря рамурилор луй, кэч рэдэчиниле ый ерау ынфипте ын апе марь.
Ọláńlá ní ẹwà rẹ̀ jẹ́, pẹ̀lú títẹ́ rẹrẹ ẹ̀ka rẹ̀, nítorí gbòǹgbò rẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ sí ibi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi wà.
8 Чедрий дин грэдина луй Думнезеу ну-л ынтречяу, кипароший ну ерау де асемуит ку кренӂиле луй ши платаний ну ерау ка рамуриле луй; ничун копак дин грэдина луй Думнезеу ну ера ка ел ын фрумусеце.
Àwọn igi kedari nínú ọgbà Ọlọ́run kò lè è bò ó mọ́lẹ̀; tàbí kí àwọn igi junifa ṣe déédé pẹ̀lú ẹ̀ka rẹ̀, tàbí kí a fi igi títẹ́ rẹrẹ wé ẹ̀ka rẹ̀, kò sí igi nínú ọgbà Ọlọ́run tí ó dà bí rẹ̀ ní ẹwà rẹ̀.
9 Ыл фэкусем атыт де фрумос прин мулцимя кренӂилор луй, кэ-л пизмуяу тоць копачий Еденулуй, каре се афлау ын грэдина луй Думнезеу.’
Mo mú kí ó ní ẹwà pẹ̀lú ẹ̀ka lọ́pọ̀lọ́pọ̀ tó fi jẹ́ ìlara àwọn igi gbogbo ní Edeni tí í ṣe ọgbà Ọlọ́run.
10 Де ачея, аша ворбеште Домнул Думнезеу: ‘Пентру кэ авя о тулпинэ аша де ыналтэ, пентру кэ ышь ынэлца вырфул пынэ ла норь ши инима и се мындря ку ынэлцимя луй,
“‘Nítorí náà, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ó ga lọ sókè fíofío, tí ó sì gbé òkè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ, àti nítorí pé gíga rẹ mú kí ó gbéraga,
11 л-ам дат ын мыниле витязулуй нямурилор, каре-й ва фаче дупэ рэутатя луй, кэч л-ам изгонит.
mo fi lé alákòóso àwọn orílẹ̀-èdè náà lọ́wọ́, fún un láti fi ṣe ẹ̀tọ́ fún un gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀. Mo pa á tì sí ẹ̀gbẹ́ kan,
12 Стрэиний, челе май грозаве попоаре, л-ау тэят ши л-ау лепэдат. Кренӂиле й-ау кэзут ын мунць ши ын тоате вэиле. Рамуриле и с-ау сфэрымат ын тоате пухоаеле цэрий ши тоате попоареле пэмынтулуй ау плекат де ла умбра луй ши л-ау пэрэсит.
àwọn orílẹ̀-èdè àjèjì aláìláàánú jùlọ ké e lulẹ̀, wọn sì fi kalẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ṣubú sórí òkè àti sí gbogbo àárín àwọn òkè; àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tí ó ṣẹ nà sílẹ̀ ní gbogbo àlàfo jíjìn ilẹ̀. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé jáde kúrò ní abẹ́ ìji rẹ̀ wọn sì fi sílẹ̀.
13 Пе сфэрымэтуриле луй ау венит ши с-ау ашезат тоате пэсэриле черулуй ши тоате фяреле кымпулуй шь-ау фэкут кулкушул ынтре рамуриле луй,
Gbogbo àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ni orí igi tí ó ṣubú lulẹ̀ náà, gbogbo àwọn ẹranko igbó wà ní àárín ẹ̀ka rẹ̀.
14 ка сэ ну се май ынгымфе ничунул дин копачий де лынгэ апе ку ынэлцимя лор ши сэ ну-шь май ридиче вырфул пынэ ын норь, ка сэ ну се май фэляскэ стежарий удаць де апэ ку ынэлцимя лор, кэч тоць сунт даць прадэ морций, ын адынчимиле пэмынтулуй, принтре копиий оаменилор, ымпреунэ ку чей че се кобоарэ ын гроапэ.’
Nítorí náà kò sí igi mìíràn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi tí ó lè fi ìgbéraga ga sókè fíofío, tí yóò sì gbé sókè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ. Kò sí igi mìíràn tí ó ní omi tó bẹ́ẹ̀ tí ó lè ga tó bẹ́ẹ̀; gbogbo wọn ni a kádàrá ikú fún, fún ìsàlẹ̀ ilẹ̀, ní àárín àwọn alààyè ènìyàn, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ọ̀gbun ní ìsàlẹ̀.
15 Аша ворбеште Домнул Думнезеу: ‘Ын зиуа кынд с-а коборыт ын Локуинца морцилор, ам рэспындит жаля, ам акоперит адынкул дин причина луй ши й-ам оприт рыуриле; апеле челе марь ау фост оприте; ам ынтристат Либанул пентру ел ши тоць копачий де пе кымп с-ау ускат. (Sheol h7585)
“‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ ti a mú u wá sí isà òkú mo fi ọ̀fọ̀ ṣíṣe bo orísun omi jíjìn náà, mo dá àwọn ìṣàn omi rẹ̀ dúró, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi rẹ̀ ní a dí lọ́nà. Nítorí rẹ̀ mo fi ìwúwo ọkàn wọ Lebanoni ní aṣọ, gbogbo igi igbó gbẹ dànù. (Sheol h7585)
16 Де вуетул кэдерий луй ам фэкут сэ се кутремуре нямуриле кынд л-ам арункат ын Локуинца морцилор ымпреунэ ку чей че се кобоарэ ын гроапэ ши с-ау мынгыят ын адынчимиле пэмынтулуй тоць копачий Еденулуй, чей май фрумошь ши чей май бунь копачь дин Либан, тоць чей удаць де апе. (Sheol h7585)
Mo mú kí orílẹ̀-èdè wárìrì sì ìró ìṣubú rẹ̀ nígbà tí mo mú un wá sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun ìsàlẹ̀. Nígbà náà gbogbo igi Edeni, àṣàyàn àti èyí tí ó dára jùlọ nínú Lebanoni, gbogbo igi tí ó ní omi dáradára ni a tù nínú ni ayé ìsàlẹ̀. (Sheol h7585)
17 С-ау коборыт ши ей ку ел ын Локуинца морцилор, ла чей че ау перит учишь де сабие, ей, каре ерау брацул луй ши локуяу ла умбра луй принтре нямурь. (Sheol h7585)
Àwọn tí ó ń gbé ní abẹ́ òjìji rẹ̀, àwọn àjèjì rẹ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè náà, ti lọ sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú rẹ̀, ní dídárapọ̀ mọ́ àwọn tí a fi idà pa. (Sheol h7585)
18 Ку чине поць фи асемуит ту ын славэ ши ын мэриме ынтре копачий Еденулуй? Тотушь вей фи арункат ымпреунэ ку копачий Еденулуй ын адынчимиле пэмынтулуй ши вей фи кулкат ын мижлокул челор нетэяць ымпрежур, ымпреунэ ку чей че ау перит учишь де сабие. Ятэ че есте Фараон ши тоатэ мулцимя луй’, зиче Домнул Думнезеу.”
“‘Èwo lára igi Edeni ní a lè fiwé ọ ní dídán àti ọláńlá? Síbẹ̀ ìwọ, gan an wá sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn igi Edeni lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀; ìwọ yóò sùn ni àárín àwọn aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. “‘Èyí yìí ní Farao àti ìjọ rẹ̀, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”

< Езекиел 31 >