< 2 Самуел 24 >

1 Домнул С-а апринс де мыние дин ноу ымпотрива луй Исраел ши а стырнит пе Давид ымпотрива лор, зикынд: „Ду-те ши фэ нумэрэтоаря луй Исраел ши а луй Иуда.”
Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli, ó sì ti Dafidi sí wọn, pé, “Lọ ka iye Israẹli àti Juda!”
2 Ши ымпэратул а зис луй Иоаб, кэпетения оштирий, каре се афла лынгэ ел: „Стрэбате тоате семинцииле луй Исраел, де ла Дан пынэ ла Беер-Шеба; сэ се факэ нумэрэтоаря попорулуй ши сэ штиу ла кыт се ридикэ нумэрул лор.”
Ọba sì wí fún Joabu olórí ogun, tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ ní ìsinsin yìí sí gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti Dani títí dé Beerṣeba, kí ẹ sì ka iye àwọn ènìyàn, kí èmi lè mọ iye àwọn ènìyàn náà!”
3 Иоаб а зис ымпэратулуй: „Домнул Думнезеул тэу сэ факэ попорул де о сутэ де орь май маре, ши ымпэратул, домнул меу, сэ вадэ ку окий луй лукрул ачеста! Дар пентру че вря ымпэратул, домнул меу, сэ факэ лукрул ачеста?”
Joabu sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi kún iye àwọn ènìyàn náà, iyekíye tí ó wù kí wọn jẹ́, ní ọ̀rọ̀ọ̀rún, ojú olúwa mi ọba yóò sì rí i, ṣùgbọ́n èétiṣe tí olúwa mi ọba fi fẹ́ nǹkan yìí?”
4 Ымпэратул а стэруит ын порунка пе каре о дэдя луй Иоаб ши кэпетениилор оштирий, ши Иоаб ши кэпетенииле оштирий ау плекат де ла ымпэрат ка сэ факэ нумэрэтоаря попорулуй Исраел.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí ti Joabu, àti ti àwọn olórí ogun. Joabu àti àwọn olórí ogun sì jáde lọ kúrò níwájú ọba, láti lọ ka àwọn ènìyàn Israẹli.
5 Ау трекут Йорданул ши ау тэбэрыт ла Ароер, ла дряпта четэций каре есте ын мижлокул вэий Гад ши лынгэ Иаезер.
Wọ́n sì kọjá odò Jordani, wọ́n sì pàgọ́ ní Aroeri, ní ìhà apá ọ̀tún ìlú tí ó wà láàrín àfonífojì Gadi, àti sí ìhà Jaseri.
6 Ау венит пынэ ла Галаад ши ын цара луй Тахтим-Ходши. С-ау дус пынэ ла Дан-Иаан ши ын ымпрежуримиле Сидонулуй.
Wọ́n sì wá sí Gileadi, àti sí ilé Tatimi Hodṣi; wọ́n sì wá sí Dani Jaani àti yíkákiri sí Sidoni.
7 Ау венит пынэ ла четэцуя Тир ши ын тоате четэциле хевицилор ши але канааницилор. Ау ешит спре партя де мязэзи а луй Иуда, ла Беер-Шеба.
Wọ́n sì wá sí ìlú olódi Tire, àti sí gbogbo ìlú àwọn Hifi, àti ti àwọn ará Kenaani, wọ́n sì jáde lọ síhà gúúsù ti Juda, àní sí Beerṣeba.
8 Ау стрэбэтут астфел тоатэ цара ши ау ажунс ла Иерусалим дупэ ноуэ лунь ши доуэзечь де зиле.
Wọ́n sì la gbogbo ilẹ̀ náà já, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu ní òpin oṣù kẹsànán àti ogúnjọ́.
9 Иоаб а дат ымпэратулуй нумэрул попорулуй: ерау ын Исраел опт суте де мий де оамень де рэзбой каре скотяу сабия ши ын Иуда чинч суте де мий де оамень.
Joabu sì fi iye tí àwọn ènìyàn náà jásí lé ọba lọ́wọ́. Ó sì jẹ́ ogójì ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára ní Israẹli, àwọn onídà, àwọn ọkùnrin Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn.
10 Давид а симцит кум ый бэтя инима дупэ че фэкусе нумэрэтоаря попорулуй. Ши а зис Домнулуй: „Ам сэвыршит ун маре пэкат фэкынд лукрул ачеста! Акум, Доамне, биневоеште ши яртэ нелеӂюиря робулуй Тэу, кэч ам лукрат ын тотул ка ун небун!”
Àyà Dafidi sì gbọgbẹ́ lẹ́yìn ìgbà tí ó ka àwọn ènìyàn náà tán. Dafidi sì wí fún Olúwa pé, “Èmi ṣẹ̀ gidigidi ní èyí tí èmi ṣe, ṣùgbọ́n, èmi bẹ̀ ọ, Olúwa, fi ẹ̀ṣẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ jì ní, nítorí pé èmi hùwà aṣiwèrè gidigidi!”
11 А доуа зи, кынд с-а скулат Давид, кувынтул Домнулуй а ворбит астфел пророкулуй Гад, вэзэторул луй Давид:
Dafidi sì dìde ní òwúrọ̀, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Gadi wòlíì wá, aríran Dafidi wí pé,
12 „Ду-те ши спуне луй Давид: ‘Аша ворбеште Домнул: «Ыць пун ынаинте трей ненорочирь; алеӂе уна дин еле, ши те вой лови ку еа.»’”
“Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
13 Гад с-а дус ла Давид ши й-а фэкут куноскут лукрул ачеста зикынд: „Врей шапте ань де фоамете ын цара та сау сэ фуӂь трей лунь динаинтя врэжмашилор тэй, каре те вор урмэри, сау сэ бынтуе чума трей зиле ын царэ? Акум алеӂе ши везь че требуе сэ рэспунд Челуй че мэ тримите.”
Gadi sì tọ Dafidi wá, ó sì bi í léèrè pé, “Kí ìyàn ọdún méje ó tọ̀ ọ́ wá ní ilẹ̀ rẹ bí? Tàbí kí ìwọ máa sá ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, nígbà tí wọn ó máa lé ọ? Tàbí kí ààrùn ìparun ọjọ́ mẹ́ta ó wá sí ilẹ̀ rẹ? Rò ó nísinsin yìí, kí o sì mọ èsì tí èmi ó mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
14 Давид а рэспунс луй Гад: „Сунт ынтр-о маре стрымтораре! О, май бине сэ кэдем ын мыниле Домнулуй, кэч ындурэриле Луй сунт немэрӂините, дар сэ ну кад ын мыниле оаменилор!”
Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí a fi ara wa lé Olúwa ní ọwọ́; nítorí pé àánú rẹ̀ pọ̀; kí ó má sì ṣe fi mí lé ènìyàn ní ọwọ́.”
15 Домнул а тримис чума ын Исраел де диминяцэ пынэ ла время хотэрытэ. Ши, дин Дан пынэ ла Беер-Шеба, ау мурит шаптезечь де мий де оамень дин попор.
Olúwa sì rán ààrùn ìparun sí Israẹli láti òwúrọ̀ títí dé àkókò tí a dá, ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn sì kú nínú àwọn ènìyàn náà láti Dani títí fi dé Beerṣeba.
16 Пе кынд ынӂерул ынтиндя мына песте Иерусалим ка сэ-л нимичяскэ, Домнул С-а кэит де рэул ачела ши а зис ынӂерулуй каре учидя попорул: „Дестул! Траӂе-ць мына акум.” Ынӂерул Домнулуй ера лынгэ ария луй Аравна, Иебуситул.
Nígbà tí angẹli náà sì nawọ́ rẹ̀ sí Jerusalẹmu láti pa á run, Olúwa sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì sọ fún angẹli tí ń pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó tó, dá ọwọ́ rẹ dúró wàyí!” Angẹli Olúwa náà sì wà níbi ìpakà Arauna ará Jebusi.
17 Давид, вэзынд пе ынӂерул каре ловя пе попор, а зис Домнулуй: „Ятэ кэ ам пэкэтуит! Еу сунт виноват. Дар оиле ачестя че ау фэкут? Мына Та сэ се ындрепте дар ымпотрива мя ши ымпотрива касей татэлуй меу!”
Dafidi sì wí fún Olúwa nígbà tí ó rí angẹli tí ń kọlu àwọn ènìyàn pé, “Wò ó, èmi ti ṣẹ̀, èmi sì ti hùwà búburú ṣùgbọ́n àwọn àgùntàn wọ̀nyí, kín ni wọ́n ha ṣe? Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, kí ó wà lára mi àti ìdílé baba mi.”
18 Ын зиуа ачея, Гад а венит ла Давид ши й-а зис: „Суе-те ши ыналцэ ун алтар Домнулуй ын ария луй Аравна, Иебуситул.”
Gadi sì tọ Dafidi wá ní ọjọ́ náà, ó sì wí fún un pé, “Gòkè, tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.”
19 Давид с-а суит, дупэ кувынтул луй Гад, кум порунчисе Домнул.
Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Gadi, Dafidi sì gòkè lọ bí Olúwa ti pa á ní àṣẹ.
20 Аравна с-а уйтат ши а вэзут пе ымпэрат ши пе служиторий луй ындрептынду-се спре ел ши Аравна а ешит ши с-а ынкинат ынаинтя ымпэратулуй, ку фаца ла пэмынт.
Arauna sì wò, ó sì rí ọba àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ wá lọ́dọ̀ rẹ̀, Arauna sì jáde, ó sì wólẹ̀ níwájú ọba ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀.
21 Аравна а зис: „Пентру че вине домнул меу ымпэратул ла служиторул луй?” Ши Давид а рэспунс: „Ка сэ кумпэр де ла тине ария ши сэ зидеск ын еа ун алтар Домнулуй, пентру ка сэ ынчетезе урӂия ачаста де песте попор.”
Arauna sì wí pé, “Nítorí kín ni olúwa mi ọba ṣe tọ ìránṣẹ́ rẹ̀ wá?” Dafidi sì dáhùn pé, “Láti ra ibi ìpakà rẹ lọ́wọ́ rẹ, láti tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa, kí ààrùn ìparun lè dá lára àwọn ènìyàn náà.”
22 Аравна а зис луй Давид: „Сэ я домнул меу ымпэратул ария ши сэ адукэ ын еа жертфеле каре-й вор плэчя; везь, боий вор фи пентру ардеря-де-тот ши кареле ку унелтеле лор вор цине лок де лемне.”
Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Jẹ́ kí olúwa mi ọba ó mú èyí tí ó dára lójú rẹ̀, kí o sì fi í rú ẹbọ, wò ó, màlúù nìyìí láti fi ṣe ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà, àti ohun èlò mìíràn ti màlúù fún igi.
23 Аравна а дат ымпэратулуй тотул. Ши Аравна а зис ымпэратулуй: „Домнул Думнезеул тэу сэ те примяскэ!”
Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni Arauna fi fún ọba, bí ọba.” Arauna sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ ó gba ọrẹ rẹ.”
24 Дар ымпэратул а зис луй Аравна: „Ну! Вряу с-о кумпэр де ла тине пе прец де арӂинт ши ну вой адуче Домнулуй Думнезеулуй меу ардерь-де-тот каре сэ ну мэ косте нимик.” Ши Давид а кумпэрат ария ши боий ку чинчзечь де сикли де арӂинт.
Ọba sì wí fún Arauna pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́; ṣùgbọ́n èmi ó rà á ní iye kan lọ́wọ́ rẹ, bí ó ti wù kí ó ṣe; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò fi èyí tí èmi kò náwó fún, rú ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run mi.” Dafidi sì ra ibi ìpakà náà, àti àwọn màlúù náà ní àádọ́ta ṣékélì fàdákà.
25 Давид а зидит аколо ун алтар Домнулуй ши а адус ардерь-де-тот ши жертфе де мулцумире. Атунч, Домнул а фост потолит фацэ де царэ ши а ынчетат урӂия де дясупра луй Исраел.
Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ sí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ti ìlàjà. Olúwa sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ fún ilẹ̀ náà, ààrùn náà sì dá kúrò ní Israẹli.

< 2 Самуел 24 >