< 2 Самуел 11 >

1 Ын анул урмэтор, пе время кынд порняу ымпэраций ла рэзбой, Давид а тримис пе Иоаб, ку служиторий луй ши тот Исраелул, сэ пустияскэ цара луй Амон ши сэ ымпресоаре Раба. Дар Давид а рэмас ла Иерусалим.
Lẹ́yìn ìgbà tí ọdún yípo, ní àkókò ìgbà tí àwọn ọba máa ń jáde ogun, Dafidi sì rán Joabu, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, àti gbogbo Israẹli; wọ́n sì pa àwọn ọmọ Ammoni, wọ́n sì dó ti Rabba. Dafidi sì jókòó ní Jerusalẹmu.
2 Ынтр-о дупэ-амязэ спре сярэ, Давид с-а скулат де пе пат ши, пе кынд се плимба пе акоперишул касей ымпэрэтешть, а зэрит де аколо о фемее каре се скэлда ши каре ера фоарте фрумоасэ ла кип.
Ó sì ṣe, ní ìgbà àṣálẹ́ kan, Dafidi sì dìde ní ibùsùn rẹ̀, ó sì ń rìn lórí òrùlé ilé ọba, láti orí òrùlé náà ni ó sì rí obìnrin kan tí ó ń wẹ̀ ara rẹ̀; obìnrin náà sì ṣe arẹwà lójú láti wò.
3 Давид а ынтребат чине есте фемея ачаста ши й-ау спус: „Есте Бат-Шеба, фата луй Елиам, неваста луй Урие, Хетитул.”
Dafidi sì ránṣẹ́ ó sì béèrè obìnrin náà. Ẹnìkan sì wí pé, “Èyí ha kọ́ ni Batṣeba, ọmọbìnrin Eliamu, aya Uriah ará Hiti.”
4 Ши Давид а тримис ниште оамень с-о адукэ. Еа а венит ла ел, ши ел с-а кулкат ку еа. Дупэ че с-а курэцит де некурэция ей, еа с-а ынторс акасэ.
Dafidi sì rán àwọn ìránṣẹ́, ó sì mú un; ó sì wọ inú ilé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a dàpọ̀, nígbà tí ó sì wẹ ara rẹ̀ mọ́ tán, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.
5 Фемея а рэмас ынсэрчинатэ ши а тримис ворбэ луй Давид зикынд: „Сунт ынсэрчинатэ.”
Obìnrin náà sì lóyún, ó sì ránṣẹ́ ó sì sọ fún Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti lóyún.”
6 Атунч, Давид а тримис урмэтоаря порункэ луй Иоаб: „Тримите-мь пе Урие, Хетитул.” Ши Иоаб а тримис пе Урие ла Давид.
Dafidi sì ránṣẹ́ sí Joabu, pé, “Rán Uriah ará Hiti sí mi.” Joabu sì rán Uriah sí Dafidi.
7 Урие а венит ла Давид, каре л-а ынтребат деспре старя луй Иоаб, деспре старя попорулуй ши деспре мерсул рэзбоюлуй.
Nígbà tí Uriah sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Dafidi sì bi í léèrè báwo ni Joabu ti ṣe àti àlàáfíà àwọn ènìyàn náà, àti bí ogun náà ti ń ṣe.
8 Апой Давид а зис луй Урие: „Кобоарэ-те акасэ ши спалэ-ць пичоареле.” Урие а ешит дин каса ымпэрэтяскэ ши а фост урмат де ун дар дин партя ымпэратулуй.
Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ, kí o sì wẹ ẹsẹ̀ rẹ.” Uriah sì jáde kúrò ní ilé ọba, oúnjẹ láti ọ̀dọ̀ ọba wá sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
9 Дар Урие с-а кулкат ла поарта касей ымпэрэтешть, ку тоць служиторий стэпынулуй сэу, ши ну с-а коборыт акасэ ла ел.
Ṣùgbọ́n Uriah sun ní ẹnu-ọ̀nà ilé ọba lọ́dọ̀ gbogbo ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
10 Ау дат де штире луй Давид деспре ачаста ши й-ау спус: „Урие ну с-а коборыт ла ел акасэ.” Ши Давид а зис луй Урие: „Ну вий ту оаре дин кэлэторие? Пентру че ну те-ай коборыт акасэ?”
Nígbà tí wọ́n sì sọ fún Dafidi pé, “Uriah kò sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀,” Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Ṣe bí ọ̀nà àjò ni ìwọ ti wá? Èéha ti ṣe tí ìwọ kò fi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ.”
11 Урие а рэспунс луй Давид: „Кивотул ши Исраел ши Иуда локуеск ын кортурь, домнул меу Иоаб ши служиторий домнулуй меу сунт тэбэрыць ын кымп, ши еу сэ интру ын касэ сэ мэнынк ши сэ бяу ши сэ мэ кулк ку невастэ-мя?! Виу ешть ту ши виу есте суфлетул тэу кэ ну вой фаче лукрул ачеста.”
Uriah sì wí fún Dafidi pé, “Àpótí ẹ̀rí, àti Israẹli, àti Juda jókòó nínú àgọ́; àti Joabu olúwa mi, àti àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi wà ní ibùdó ní pápá, èmi ó ha lọ sí ilé mi, láti jẹ àti láti mu, àti láti bá obìnrin mi sùn? Bí ìwọ bá wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ́ si ti ń bẹ láààyè, èmi kì yóò ṣe nǹkan yìí.”
12 Давид а зис луй Урие: „Май рэмый ши астэзь аич, ши мыне ыць вой да друмул.” Ши Урие а рэмас ла Иерусалим ын зиуа ачея ши а доуа зи.
Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sì dúró níhìn-ín lónìí, lọ́la èmi ó sì jẹ́ kí ìwọ ó lọ.” Uriah sì dúró ní Jerusalẹmu ní ọjọ́ náà, àti ọjọ́ kejì.
13 Давид л-а пофтит сэ мэнынче ши сэ бя ку ел ши л-а ымбэтат; ши сяра, Урие а ешит ши с-а кулкат ку служиторий стэпынулуй сэу, дар ну с-а коборыт акасэ.
Dafidi sì pè é, ó sì jẹ, ó sì mú nítorí rẹ̀; ó sì mu kí ọtí pa á; òun sì jáde ní alẹ́ lọ sí ibùsùn rẹ̀ lọ́dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
14 А доуа зи диминяца, Давид а скрис о скрисоаре луй Иоаб ши а тримис-о прин Урие.
Ó sì ṣe ní òwúrọ̀, Dafidi sì kọ̀wé sí Joabu, ó fi rán Uriah.
15 Ын скрисоаря ачаста скрия: „Пунець пе Урие ын локул чел май греу ал луптей ши траӂеци-вэ ынапой де ла ел, ка сэ фие ловит ши сэ моарэ.”
Ó sì kọ sínú ìwé pé, “Fi Uriah síwájú ibi tí ogun gbé le, kí ẹ sì fàsẹ́yìn, kí wọn lè kọlù ú, kí ó sì kú.”
16 Иоаб, ымпресурынд четатя, а пус пе Урие ын локул пе каре-л штия апэрат де осташь витежь.
Ó sì ṣe nígbà tí Joabu ṣe àkíyèsí ìlú náà, ó sì yan Uriah sí ibi kàn ní ibi tí òun mọ̀ pé àwọn alágbára ọkùnrin ń bẹ níbẹ̀.
17 Оамений дин четате ау фэкут о ешире ши с-ау бэтут ымпотрива луй Иоаб; ау кэзут мулць дин попор, дин служиторий луй Давид ши а фост учис ши Урие, Хетитул.
Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì jáde wá, wọ́n sì bá Joabu jà, díẹ̀ sì ṣubú nínú àwọn ènìyàn náà nínú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.
18 Иоаб а тримис ун сол сэ историсяскэ луй Давид тот че се петрекусе ын луптэ.
Joabu sì ránṣẹ́ ó sì ro gbogbo nǹkan ogun náà fún Dafidi.
19 Ши а дат солулуй урмэтоаря порункэ: „Кынд вей испрэви де историсит ымпэратулуй тоате амэнунтеле луптей,
Ó sì pàṣẹ fún ìránṣẹ́ náà pé, “Nígbà tí ìwọ bá sì parí àti máa ro gbogbo nǹkan ogun náà fún ọba.
20 поате кэ се ва мыния ши ва зиче: ‘Пентру че в-аць апропият де четате сэ луптаць ымпотрива ей? Ну штияць кэ се арункэ сэӂець дин вырфул зидулуй?
Bí ó bá ṣe pé, ìbínú ọba bá ru, ti òun sì wí fún ọ pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi súnmọ́ ìlú náà láti bá wọn jà, ẹ̀yin kò mọ̀ pé wọn ó tafà láti orí odi wá.
21 Чине а оморыт пе Абимелек, фиул луй Иерубешет? Ну о фемее, каре а арункат песте ел дин вырфул зидулуй о пятрэ де моарэ, ши н-а мурит ел ла Тебец? Пентру че в-аць апропият де зид?’ Атунч сэ-й спуй: ‘А мурит ши робул тэу Урие, Хетитул.’”
Ta ni ó pa Abimeleki ọmọ Jerubu-Beṣeti? Kì í ṣe obìnrin ni ó yí òkúta-ọlọ lù ú láti orí odi wá, tí ó sì kú ní Tebesi? Èéha ti rí tí ẹ̀yin fi súnmọ́ odi náà? Ìwọ yóò sì wí fún un pé, Uriah ìránṣẹ́ rẹ ará Hiti kú pẹ̀lú.’”
22 Солул а плекат ши, ла сосире, а историсит луй Давид тот че-й порунчисе Иоаб.
Ìránṣẹ́ náà sì lọ, ó sì wá, ó sì jẹ́ gbogbo iṣẹ́ tí Joabu rán an fún Dafidi.
23 Солул а зис луй Давид: „Оамений ачея ау фост май тарь декыт ной; фэкусерэ о ешире ымпотрива ноастрэ ын кымп, ши й-ам дат ынапой, пынэ ла интраря порций,
Ìránṣẹ́ náà sì wí fún Dafidi pé, “Nítòótọ́ àwọn ọkùnrin náà lágbára jù wá lọ, wọ́n sì jáde tọ̀ wá wá ní pápá, àwa sì tẹ̀lé wọn títí wọ́n fi dé ẹ̀yìn odi.
24 дар аркаший ау трас де пе вырфул зидулуй асупра служиторилор тэй, ши мулць дин служиторий ымпэратулуй ау фост учишь ши а мурит ши робул тэу Урие, Хетитул.”
Àwọn tafàtafà sì ta sí ìránṣẹ́ rẹ láti orí odi wá, díẹ̀ nínú àwọn ìránṣẹ́ ọba sì kú, ìránṣẹ́ rẹ̀ Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.”
25 Давид а зис солулуй: „Ятэ че сэ спуй луй Иоаб: ‘Ну те мунчи пентру ынтымпларя ачаста, кэч сабия добоарэ кынд пе унул, кынд пе алтул; бате четатя ку путере, дэрым-о.’ Ши ту, ымбэрбэтязэ-л!”
Dafidi sì wí fún ìránṣẹ́ náà pé, “Báyìí ni ìwọ yóò wí fún Joabu pé, ‘Má ṣe jẹ́ kí nǹkan yìí burú ní ojú rẹ, nítorí pé idà a máa pa lọ́tùn ún lósì, mú ìjà rẹ le sí ìlú náà, kí o sì bì í ṣubú.’ Kí ìwọ sì mú un lọ́kàn le.”
26 Неваста луй Урие а афлат кэ бэрбатул ей мурисе ши а плынс пе бэрбатул ей.
Nígbà tí aya Uriah sì gbọ́ pé Uriah ọkọ rẹ̀ kú, ó sì ṣọ̀fọ̀ nítorí ọkọ rẹ̀.
27 Дупэ че ау трекут зилеле де жале, Давид а тримис с-о я ши а примит-о ын каса луй. Еа й-а фост невастэ ши й-а нэскут ун фиу. Фапта луй Давид н-а плэкут Домнулуй.
Nígbà tí ìṣọ̀fọ̀ náà sì kọjá tan, Dafidi sì ránṣẹ́, o sì mú un wá sí ilé rẹ̀, ó sì di aya rẹ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un, ṣùgbọ́n nǹkan náà tí Dafidi ṣe burú níwájú Olúwa.

< 2 Самуел 11 >