< 2 Ымпэрацилор 22 >

1 Иосия авя опт ань кынд с-а фэкут ымпэрат ши а домнит трейзечь ши уну де ань ла Иерусалим. Мама са се кема Иедида, фата луй Адая, дин Боцкат.
Josiah jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jedida ọmọbìnrin Adaiah; ó wá láti Boskati.
2 Ел а фэкут че есте бине ынаинтя Домнулуй ши а умблат ын тоатэ каля татэлуй сэу Давид; ну с-а абэтут де ла еа нич ла дряпта, нич ла стынга.
Ó sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Dafidi baba a rẹ̀, kò sì yípadà sí apá ọ̀tún tàbí sí apá òsì.
3 Ын анул ал оптспрезечеля ал ымпэратулуй Иосия, ымпэратул а тримис ын Каса Домнулуй пе Шафан, логофэтул, фиул луй Ацалия, фиул луй Мешулам. Ел й-а зис:
Ní ọdún kejìdínlógún tí ó fi jẹ ọba. Ọba Josiah rán akọ̀wé, Ṣafani ọmọ Asalia, ọmọ Meṣullamu, sí ilé Olúwa. Ó wí pé,
4 „Суе-те ла мареле преот Хилкия ши спуне-й сэ стрынгэ арӂинтул адус ын Каса Домнулуй, пе каре л-ау примит де ла попор чей че пэзеск прагул.
“Gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, kí o sì jẹ́ kí ó ṣírò iye owó tí a mú wá sí ilé Olúwa, tí àwọn olùṣọ́nà ti gbà lọ́wọ́ àwọn ènìyàn.
5 Сэ се дя арӂинтул ачеста ын мыниле мештерилор ынсэрчинаць ку лукраря ын Каса Домнулуй. Ши сэ-л дя челор че лукрязэ ла дреӂеря стрикэчунилор Касей Домнулуй,
Ẹ sì jẹ́ kí wọn ó fi lé àwọn ọkùnrin tí a ti yàn láti bojútó iṣẹ́ náà lórí ilé Olúwa. Kí ẹ sì jẹ́ kí àwọn ọkùnrin san án fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń tún ilé Olúwa ṣe.
6 ануме: дулгерилор, зидарилор ши петрарилор, пентру кумпэрэтуриле де лемн ши де петре чоплите требуитоаре пентру дреӂеря стрикэчунилор касей.
Àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn akọ́lé. Bákan náà ni wọ́n ra igi àti òkúta ọlọ́ṣọ̀ọ́ láti fi tún tẹmpili ṣe.
7 Дар сэ ну ли се чарэ сокотялэ де арӂинтул дат ын мыниле лор, кэч ей лукрязэ чинстит.”
Ṣùgbọ́n wọn kò ní láti ṣe ìṣirò fún owó náà tí a fi fún wọn, nítorí wọ́n ṣe òtítọ́.”
8 Атунч, мареле преот Хилкия а зис луй Шафан, логофэтул: „Ам гэсит картя леӂий ын Каса Домнулуй.” Ши Хилкия а дат картя луй Шафан, ши Шафан а читит-о.
Hilkiah olórí àlùfáà sọ fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi rí ìwé òfin nílé Olúwa.” Ó fi fún Ṣafani, ẹni tí ó kà á.
9 Апой, логофэтул Шафан с-а дус сэ дя сокотялэ ымпэратулуй ши а зис: „Служиторий тэй ау стрынс арӂинтул каре се афла ын касэ ши л-ау дат ын мыниле мештерилор ынсэрчинаць ку фачеря лукрэрий ын Каса Домнулуй.”
Nígbà náà, Ṣafani akọ̀wé lọ sí ọ̀dọ̀ ọba. Ó sì sọ fún un pé, “Àwọn ìjòyè rẹ ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa. Èmi sì ti fi lé ọwọ́ àwọn tí ó ń ṣe iṣẹ́ náà àti àwọn alábojútó nílé Olúwa.”
10 Шафан, логофэтул, а май спус ымпэратулуй: „Преотул Хилкия мь-а дат о карте.” Ши Шафан а читит-о ынаинтя ымпэратулуй.
Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sọ fún ọba pé, “Hilkiah àlùfáà ti fún un ní ìwé kan.” Ṣafani kà lára rẹ̀ níwájú ọba.
11 Кынд а аузит ымпэратул кувинтеле дин картя леӂий, шь-а сфышият хайнеле.
Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
12 Ши ымпэратул а дат порунка ачаста преотулуй Хилкия, луй Ахикам, фиул луй Шафан, луй Акбор, фиул луй Мика, луй Шафан, логофэтул, ши луй Асая, служиторул ымпэратулуй:
Ó pa àṣẹ yìí fún Ahikamu àlùfáà, Hilkiah ọmọ Ṣafani, Akbori ọmọ Mikaiah, àti Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
13 „Дучеци-вэ ши ынтребаць пе Домнул пентру мине, пентру попор ши пентру Иуда, ку привире ла кувинтеле кэрций ачестея каре с-а гэсит, кэч маре есте мыния Домнулуй, каре с-а апринс ымпотрива ноастрэ, пентру кэ пэринций ноштри н-ау аскултат де кувинтеле кэрций ачестея ши н-ау ымплинит тот че не есте порунчит ын еа.”
“Lọ, ẹ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi àti fún àwọn ènìyàn àti fún gbogbo Juda nípa ohun tí a kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ń jó sí wa nítorí àwọn baba wa kò tẹ̀lé ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí; wọn kò ṣe ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ níbẹ̀ nípa wa.”
14 Преотул Хилкия, Ахикам, Акбор, Шафан ши Асая с-ау дус ла пророчица Хулда, неваста луй Шалум, фиул луй Тиква, фиул луй Хархас, пэзиторул вешминтелор. Еа локуя ла Иерусалим, ын чялалтэ махала а четэций. Дупэ че й-ау ворбит,
Hilkiah àlùfáà, Ahikamu àti Akbori Ṣafani pẹ̀lú Asaiah, lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin Hulda láti lọ bá a sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tikfa ọmọ Harhasi alábojútó ibi ìpa aṣọ mọ́ sí. Ó ń gbé ní Jerusalẹmu ní ìdàkejì.
15 еа ле-а зис: „Аша ворбеште Домнул Думнезеул луй Исраел: ‘Спунець омулуй каре в-а тримис ла мине:
Ó wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Sọ fún ọkùnrin tí ó rán an yín sí mi,
16 «Аша ворбеште Домнул: ‹Ятэ, вой тримите ненорочирь асупра локулуй ачестуя ши асупра локуиторилор луй, дупэ тоате кувинтеле кэрций пе каре а читит-о ымпэратул луй Иуда.
‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò mú ibi wá sí ibí àti àwọn ènìyàn rẹ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú ìwé tí ọba Juda ti kà.
17 Пентру кэ М-ау пэрэсит ши ау адус тэмые алтор думнезей, мыниинду-Мэ прин тоате лукрэриле мынилор лор, мыния Мя с-а апринс ымпотрива локулуй ачестуя ши ну се ва стинӂе.›»
Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì tún sun tùràrí fún ọlọ́run mìíràn. Wọ́n sì mú mi bínú nípa gbogbo àwọn òrìṣà tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn dá. Ìbínú mi yóò ru sí ibí yìí, kì yóò sì rọlẹ̀.’
18 Дар сэ спунець ымпэратулуй луй Иуда, каре в-а тримис сэ ынтребаць пе Домнул: «Аша ворбеште Домнул Думнезеул луй Исраел деспре кувинтеле пе каре ле-ай аузит:
Sọ fún ọba Juda tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí nípa ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí ìwọ ti gbọ́.
19 ‹Пентру кэ ци с-а мишкат инима, пентру кэ те-ай смерит ынаинтя Домнулуй кынд ай аузит че ам спус ымпотрива ачестуй лок ши ымпотрива локуиторилор луй, каре вор ажунӂе де спаймэ ши де блестем, ши пентру кэ ць-ай сфышият хайнеле ши ай плынс ынаинтя Мя, ши Еу ам аузит›, зиче Домнул.
Nítorí tí ọkàn rẹ rọ̀, tí ìwọ sì ti rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa, nígbà tí ìwọ gbọ́ èyí tí mo sọ sí ibí yìí àti sí àwọn ènìyàn rẹ pé wọn yóò di ahoro àti ẹni ègún tí ìwọ sì fa aṣọ ọ̀ rẹ ya pẹ̀lú níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ, ni Olúwa wí.
20 ‹Де ачея, ятэ, те вой адэуга ла пэринций тэй, вей фи адэугат ын паче ын мормынтул тэу ши ну-ць вор ведя окий тоате ненорочириле пе каре ле вой адуче асупра локулуй ачестуя.›»’” Ей ау адус ымпэратулуй рэспунсул ачеста.
Nítorí náà èmi yóò kó ọ jọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baba à rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kì yóò rí gbogbo àwọn ibi tí èmi yóò mú wá bá ibí yìí.’” Bẹ́ẹ̀ wọ́n mú èsì rẹ̀ padà tọ ọba wá.

< 2 Ымпэрацилор 22 >