< 2 Ымпэрацилор 10 >

1 Ын Самария ерау шаптезечь де фий ай луй Ахаб. Иеху а скрис скрисорь ши ле-а тримис ла Самария кэпетениилор дин Изреел, бэтрынилор ши ынгрижиторилор копиилор луй Ахаб. Ын еле зичя:
Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
2 „Акум, кынд вець прими скрисоаря ачаста – фииндкэ авець ку вой пе фиий стэпынулуй востру, кареле ши каий, о четате ынтэритэ ши арме –,
“Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
3 ведець каре дин фиий стэпынулуй востру есте чел май бун ши май вредник, пунеци-л пе скаунул де домние ал татэлуй сэу ши луптаць пентру каса стэпынулуй востру!”
yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
4 Ей с-ау темут фоарте мулт ши ау зис: „Ятэ кэ дой ымпэраць н-ау путут сэ-й стя ымпотривэ. Кум ый вом ста ной ымпотривэ?”
Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
5 Ши кэпетения касей ымпэрэтешть, кэпетения четэций, бэтрыний ши ынгрижиторий копиилор ау тримис сэ спунэ луй Иеху: „Ной сунтем служиторий тэй ши вом фаче тот че не вей спуне; ну вом пуне пе нимень ымпэрат, фэ че вей креде.”
Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
6 Иеху ле-а скрис о а доуа скрисоаре, ын каре спуня: „Дакэ сунтець ай мей ши дакэ аскултаць де гласул меу, луаць капетеле оаменилор ачелора, фиий стэпынулуй востру, ши вениць ла мине мыне, ла часул ачеста, ла Изреел.” Ши чей шаптезечь де фий ай ымпэратулуй ерау ла май-марий четэций, каре-й крештяу.
Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
7 Кынд ау примит скрисоаря, ау луат пе фиий ымпэратулуй ши ау тэят пе ачешть шаптезечь де оамень; апой ле-ау пус капетеле ын кошурь ши ле-ау тримис луй Иеху, ла Изреел.
Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
8 Солул а венит сэ-й спунэ, зикынд: „Ау адус капетеле фиилор ымпэратулуй.” Ши ел а зис: „Фачеци-ле доуэ грэмезь ла интраря порций, пынэ диминяцэ.”
Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
9 Диминяца а ешит ши, венинд ынаинтя ынтрегулуй попор, а зис: „Вой сунтець фэрэ винэ! Еу ам унелтит ымпотрива стэпынулуй меу ши л-ам оморыт. Дар чине а ловит пе тоць ачештя?
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
10 Сэ штиць дар кэ ну ва кэдя нимик ла пэмынт дин кувынтул Домнулуй, дин кувынтул пе каре л-а ростит Домнул ымпотрива касей луй Ахаб; Домнул ымплинеште че а спус прин робул Сэу Илие.”
Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
11 Ши Иеху а ловит пе тоць чей че май рэмэсесерэ дин каса луй Ахаб ла Изреел, пе тоць май-марий луй, пе приетений ши пе преоций луй ши н-а лэсат сэ скапе ничунул.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
12 Апой с-а скулат ши а плекат ла Самария. Кынд а ажунс ла колиба де ынтылнире а унор чобань, пе друм,
Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
13 Иеху а дат песте фраций луй Ахазия, ымпэратул луй Иуда, ши а зис: „Чине сунтець вой?” Ей ау рэспунс: „Сунтем фраций луй Ахазия ши не коборым сэ урэм де бине фиилор ымпэратулуй ши фиилор ымпэрэтесей.”
Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
14 Иеху а зис: „Приндеци-й де вий.” Ши й-ау принс де вий ши й-ау тэят ын нумэр де патрузечь ши дой, ла фынтына колибей де ынтылнире. Иеху н-а лэсат сэ скапе ничунул.
“Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
15 Плекынд де аколо, а ынтылнит пе Ионадаб, фиул луй Рекаб, каре веня ынаинтя луй. Л-а ынтребат де сэнэтате ши й-а зис: „Инима та есте тот аша де куратэ кум есте инима мя фацэ де а та?” Ши Ионадаб а рэспунс: „Есте.” „Дакэ есте”, а зис Иеху, „дэ-мь мына.” Ионадаб й-а дат мына. Ши Иеху л-а суит ла ел ын кар
Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
16 ши а зис: „Вино ку мине ши вей ведя рывна мя пентру Домнул.” Л-а луат астфел ын карул сэу.
Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
17 Кынд а ажунс Иеху ла Самария, а учис пе тоць чей рэмашь дин Ахаб ын Самария ши й-а нимичит ку десэвыршире, дупэ кувынтул пе каре-л спусесе луй Илие Домнул.
Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
18 Апой, а стрынс тот попорул ши ле-а зис: „Ахаб а служит пуцин луй Баал, Иеху ынсэ ый ва служи мулт.
Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
19 Акум кемаць ла мине пе тоць пророчий луй Баал, пе тоць служиторий луй ши пе тоць преоций луй, фэрэ сэ липсяскэ унул, кэч вряу сэ адук о маре жертфэ луй Баал: орьчине ва липси ва мури.” Иеху лукра ку викление, ка сэ омоаре пе тоць служиторий луй Баал.
Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
20 Ел а зис: „Вестиць о сэрбэтоаре ын чинстя луй Баал!” Ши ау вестит-о.
Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
21 А тримис соль ын тот Исраелул. Ши ау венит тоць служиторий луй Баал; н-а фост унул каре сэ ну фи венит. Ау интрат ын темплул луй Баал, аша ынкыт темплул луй Баал с-а умплут де ла ун капэт пынэ ла челэлалт.
Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
22 Иеху а зис челуй че пэзя одая ку вешминтеле: „Скоате вешминте пентру тоць служиторий луй Баал.” Ши омул ачела а скос вешминте пентру ей.
Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
23 Атунч, Иеху а венит ын темплул луй Баал ку Ионадаб, фиул луй Рекаб, ши а зис служиторилор луй Баал: „Кэутаць ши ведець сэ ну фие ничун служитор ал Домнулуй аич, чи сэ фие нумай служиторь де-ай луй Баал.”
Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
24 Ши ау интрат сэ адукэ жертфе ши ардерь-де-тот. Иеху пусесе афарэ оптзечь де оамень ши ле зисесе: „Чине ва лэса сэ скапе вреунул дин оамений пе каре-й дау пе мына воастрэ ва рэспунде де вяца луй ку а са.”
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
25 Кынд ау испрэвит де адус ардериле-де-тот, Иеху а зис алергэторилор ши кэпетениилор: „Интраць ши ловици-й – унул сэ ну ясэ.” Ши й-ау ловит ку аскуцишул сабией. Алергэторий ши кэпетенииле й-ау арункат аколо ши с-ау дус пынэ ла одая дин фунд а темплулуй луй Баал.
Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
26 Ау скос афарэ стылпий Астартеей дин каса луй Баал ши й-ау арс.
Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
27 Ау сфэрымат стылпул луй Баал, ау дэрымат ши темплул луй Баал ши л-ау префэкут ынтр-о хазна де гуной, каре а рэмас ын пичоаре пынэ ын зиуа де азь.
Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
28 Иеху а нимичит пе Баал дин мижлокул луй Исраел,
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
29 дар ну с-а абэтут де ла пэкателе луй Иеробоам, фиул луй Небат, каре фэкусе пе Исраел сэ пэкэтуяскэ, н-а пэрэсит вицеий де аур дин Бетел ши Дан.
Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
30 Домнул а зис луй Иеху: „Пентру кэ ай адус бине ла ындеплинире че есте плэкут ынаинтя Мя ши ай фэкут касей луй Ахаб тот че ера дупэ воя Мя, фиий тэй пынэ ла ал патруля ням вор шедя пе скаунул де домние ал луй Исраел.”
Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
31 Тотушь Иеху н-а луат сяма сэ умбле дин тоатэ инима луй ын леӂя Домнулуй Думнезеулуй луй Исраел ши ну с-а абэтут де ла пэкателе ын каре тырысе Иеробоам пе Исраел.
Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
32 Пе время ачея, Домнул а ынчепут сэ тае кыте о букатэ дин цинутул луй Исраел; ши Хазаел й-а бэтут ла тоате хотареле луй Исраел.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
33 Де ла Йордан спре соаре-рэсаре, а бэтут тоатэ цара Галаадулуй, пе гадиць, рубениць ши манасиць, де ла Ароер, каре есте пе пырыул Арнон, пынэ ла Галаад ши Басан.
Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
34 Челелалте фапте але луй Иеху, тот че а фэкут ел ши тоате испрэвиле луй ну сунт скрисе оаре ын Картя Кроничилор ымпэрацилор луй Исраел?
Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
35 Иеху а адормит ку пэринций сэй ши а фост ынгропат ла Самария. Ши ын локул луй а домнит фиул сэу Иоахаз.
Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
36 Иеху домнисе доуэзечь ши опт де ань песте Исраел ла Самария.
Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.

< 2 Ымпэрацилор 10 >