< 2 Кроничь 21 >
1 Иосафат а адормит ку пэринций сэй ши а фост ынгропат ку пэринций сэй ын четатя луй Давид. Ши, ын локул луй, а домнит фиул сэу Иорам.
Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
2 Иорам авя ка фраць, фий ай луй Иосафат, пе Азария, Иехиел, Захария, Азария, Микаел ши Шефатия, тоць фий ай луй Иосафат, ымпэратул луй Исраел.
Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
3 Татэл лор ле дэдусе дарурь ынсемнате ын арӂинт, ын аур ши ын лукрурь скумпе, ымпреунэ ку четэць ынтэрите ын Иуда, дар ымпэрэция а лэсат-о луй Иорам, пентру кэ ел ера ынтыюл нэскут.
Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
4 Кынд а луат Иорам ын стэпынире ымпэрэция татэлуй сэу ши кынд с-а ынтэрит, а оморыт ку сабия пе тоць фраций сэй ши пе врео кыцьва дин капий луй Исраел.
Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
5 Иорам авя трейзечь ши дой де ань кынд а ажунс ымпэрат ши а домнит опт ань ла Иерусалим.
Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
6 Ел а умблат ын каля ымпэрацилор луй Исраел кум фэкусе каса луй Ахаб, кэч авя де невастэ пе о фатэ а луй Ахаб, ши а фэкут че есте рэу ынаинтя Домнулуй.
Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
7 Дар Домнул н-а воит сэ пярдэ каса луй Давид, дин причина легэмынтулуй пе каре-л фэкусе ку Давид ши дин причина фэгэдуинцей пе каре о фэкусе кэ ый ва да тотдяуна о луминэ, луй ши фиилор луй.
Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
8 Пе время са, Едом с-а рэскулат ымпотрива стэпынирий луй Иуда ши шь-а пус ун ымпэрат.
Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
9 Иорам а порнит ку кэпетенииле ши ку тоате кареле сале. Скулынду-се ноаптя, а бэтут пе едомиций каре-л ынконжурау ши пе кэпетенииле карелор лор.
Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
10 Рэскоала луй Едом ымпотрива стэпынирий луй Иуда а цинут пынэ ын зиуа де азь. Ын ачелашь тимп с-а рэскулат ши Либна ымпотрива стэпынирий луй, пентру кэ пэрэсисе пе Домнул Думнезеул пэринцилор сэй.
Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
11 Иорам а фэкут кяр ынэлцимь ын мунций луй Иуда. А тырыт пе локуиторий Иерусалимулуй ла курвие ши а амэӂит пе Иуда.
Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
12 Й-а венит о скрисоаре де ла пророкул Илие, каре зичя: „Аша ворбеште Домнул Думнезеул татэлуй тэу Давид: ‘Пентру кэ н-ай умблат ын кэиле татэлуй тэу Иосафат ши ын кэиле луй Аса, ымпэратул луй Иуда,
Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
13 чи ай умблат ын каля ымпэрацилор луй Исраел; пентру кэ ай тырыт ла курвие пе Иуда ши локуиторий Иерусалимулуй, кум а фэкут каса луй Ахаб фацэ де Исраел, ши пентру кэ ай оморыт пе фраций тэй, каре ерау май бунь декыт тине ши каре фэчяу парте дин ынсэшь каса татэлуй тэу,
Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
14 ятэ, Домнул ва лови ку о маре урӂие пе попорул тэу, пе фиий тэй, пе невестеле тале ши тот че есте ал тэу.
Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
15 Яр пе тине, те ва лови ку о боалэ гря, ку о боалэ де мэрунтае, каре се ва ынгреуя дин зи ын зи, пынэ кынд ыць вор еши мэрунтаеле дин причина тэрией болий.’”
Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
16 Ши Домнул а ацыцат ымпотрива луй Иорам духул филистенилор ши ал арабилор, каре сунт ын вечинэтатя етиопенилор.
Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
17 С-ау суит ымпотрива луй Иуда, ау нэвэлит ын ел, ау жефуит тоате богэцииле каре се афлау ын каса ымпэратулуй ши й-ау луат фиий ши невестеле, аша ынкыт ну й-а май рэмас алт фиу декыт Иоахаз, чел май тынэр динтре фиий сэй.
Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
18 Дупэ тоате ачестя, Домнул л-а ловит ку о боалэ де мэрунтае, каре ера фэрэ ляк.
Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
19 Еа с-а ынгреуят дин зи ын зи ши, пе ла сфыршитул анулуй ал дойля, й-ау ешит луй Иорам мэрунтаеле дин причина тэрией болий. А мурит ын дурерь греле. Ши попорул луй н-а арс тэмые ын чинстя луй, кум фэкусе пентру пэринций луй.
Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
20 Авя трейзечь ши дой де ань кынд а ажунс ымпэрат ши а домнит опт ань ла Иерусалим. А мурит фэрэ сэ ласе пэрере де рэу ын урмэ ши л-ау ынгропат ын четатя луй Давид, дар ну ын морминтеле ымпэрацилор.
Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.