< 1 Ымпэрацилор 17 >

1 Илие, Тишбитул, унул дин локуиторий Галаадулуй, а зис луй Ахаб: „Виу есте Домнул Думнезеул луй Исраел, ал кэруй служитор сунт, кэ ын аний ачештя ну ва фи нич роуэ, нич плоае, декыт дупэ кувынтул меу.”
Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
2 Ши кувынтул Домнулуй а ворбит луй Илие ку ачесте ворбе:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
3 „Плякэ де аич, ындряптэ-те спре рэсэрит ши аскунде-те лынгэ пырыул Керит, каре есте ын фаца Йорданулуй.
“Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
4 Вей бя апэ дин пырыу ши ам порунчит корбилор сэ те хрэняскэ аколо.”
Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
5 Ел а плекат ши а фэкут дупэ кувынтул Домнулуй. С-а дус ши с-а ашезат лынгэ пырыул Керит, каре есте ын фаца Йорданулуй.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
6 Корбий ый адучяу пыне ши карне диминяца ши пыне ши карне сяра ши бя апэ дин пырыу.
Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
7 Дар, дупэ кытэва време, пырыул а секат, кэч ну кэзусе плоае ын царэ.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
8 Атунч, кувынтул Домнулуй й-а ворбит астфел:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
9 „Скоалэ-те, ду-те ла Сарепта, каре цине де Сидон, ши рэмый аколо. Ятэ кэ ам порунчит аколо уней фемей вэдуве сэ те хрэняскэ.”
“Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
10 Илие с-а скулат ши с-а дус ла Сарепта. Кынд а ажунс ла поарта четэций, аколо ера о фемее вэдувэ каре стрынӂя лемне. Ел а кемат-о ши а зис: „Ду-те ши аду-мь, те рог, пуцинэ апэ ынтр-ун вас, ка сэ бяу.”
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
11 Пе кынд се дучя еа сэ-й адукэ, а кемат-о дин ноу ши а зис: „Аду-мь, те рог, ши о букатэ де пыне ын мына та.”
Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
12 Ши еа а рэспунс: „Виу есте Домнул Думнезеул тэу кэ н-ам нимик копт, н-ам декыт ун пумн де фэинэ ынтр-о оалэ ши пуцин унтделемн ынтр-ун урчор. Ши ятэ, стрынг доуэ букэць де лемне, апой мэ вой ынтоарче ши вой прегэти че ам пентру мине ши пентру фиул меу: вом мынка ши апой вом мури.”
Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
13 Илие й-а зис: „Ну те теме, ынтоарче-те ши фэ кум ай зис. Нумай прегэтеште-мь ынтый мие, ку унтделемнул ши фэина ачея, о микэ туртэ ши аду-мь-о; пе урмэ сэ фачь ши пентру тине ши пентру фиул тэу.
Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
14 Кэч аша ворбеште Домнул Думнезеул луй Исраел: ‘Фэина дин оалэ ну ва скэдя ши унтделемнул дин урчор ну се ва ымпуцина пынэ ын зиуа кынд ва да Домнул плоае пе фаца пэмынтулуй.’”
Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
15 Еа с-а дус ши а фэкут дупэ кувынтул луй Илие. Ши мултэ време ау авут че сэ мэнынче еа ши фамилия ей ши Илие.
Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
16 Фэина дин оалэ н-а скэзут ши унтделемнул дин урчор ну с-а ымпуцинат, дупэ кувынтул пе каре-л ростисе Домнул прин Илие.
Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
17 Дупэ ачея, фиул фемеий, стэпына касей, с-а ымболнэвит. Ши боала луй а фост атыт де кумплитэ, ынкыт н-а май рэмас суфларе ын ел.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
18 Фемея а зис атунч луй Илие: „Че ам еу а фаче ку тине, омуле ал луй Думнезеу? Ай венит ла мине доар ка сэ адучь аминте луй Думнезеу де нелеӂюиря мя ши сэ-мь оморь астфел фиул?”
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
19 Ел й-а рэспунс: „Дэ-мь ынкоаче пе фиул тэу.” Ши л-а луат де ла сынул фемеий, л-а суит ын одая де сус, унде локуя ел, ши л-а кулкат пе патул луй.
Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
20 Апой а кемат пе Домнул ши а зис: „Доамне Думнезеуле, оаре атыт де мулт сэ мыхнешть Ту кяр пе вэдува ачаста, ла каре ам фост примит ка оаспете, ынкыт сэ-й оморь фиул?”
Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
21 Ши с-а ынтинс де трей орь песте копил, а кемат пе Домнул ши а зис: „Доамне Думнезеуле, Те рог, фэ сэ се ынтоаркэ суфлетул копилулуй ын ел!”
Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
22 Домнул а аскултат гласул луй Илие, ши суфлетул копилулуй с-а ынторс ын ел ши а ынвият.
Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
23 Илие а луат копилул, л-а коборыт ын касэ дин одая де сус ши л-а дат мамей сале. Ши Илие а зис: „Ятэ, фиул тэу есте виу.”
Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
24 Ши фемея а зис луй Илие: „Куноск акум кэ ешть ун ом ал луй Думнезеу ши кувынтул Домнулуй ын гура та есте адевэр!”
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”

< 1 Ымпэрацилор 17 >